< Exodus 35 >

1 Mose pe gbogbo ìjọ Israẹli ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ohun ti Olúwa ti pàṣẹ fún un yín láti ṣe.
Musa nĩonganirie mũingĩ wothe wa andũ a Isiraeli, akĩmeera atĩrĩ, “Maya nĩmo maũndũ marĩa Jehova aamwathĩte mwĩkage:
2 Fún ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje yóò jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún yín, ọjọ́ ìsinmi ni sí Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ni ọjọ́ náà ní a ó pa.
Wĩra nĩũrutagwo mĩthenya ĩtandatũ, no mũthenya wa mũgwanja ũrĩkoragwo ũrĩ mũthenya wanyu mũtheru, Thabatũ ya Jehova ya kũhurũka. Ũrĩa ũkaaruta wĩra mũthenya ũcio no nginya ooragwo.
3 Ẹ má ṣe dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”
Mũtigaakagie mwaki mũthenya ũcio wa Thabatũ kũrĩa guothe mũrĩtũũraga.”
4 Mose sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ.
Musa akĩĩra mũingĩ wothe wa andũ a Isiraeli atĩrĩ, “Ũũ nĩguo Jehova aathanĩte:
5 Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti: “wúrà, fàdákà àti idẹ;
Rutĩrai Jehova maruta kuuma indo-inĩ iria mũrĩ nacio. Mũndũ ũrĩa wothe ũkũigua akĩenda, nĩarehere Jehova iruta rĩa thahabu, na rĩa betha na rĩa gĩcango;
6 aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára; àti irun ewúrẹ́;
na rĩa ndigi cia rangi wa bururu, na cia rangi wa ndathi, na cia rangi mũtune ta gakarakũ; o na gatani ĩrĩa njega; na guoya wa mbũri;
7 awọ àgbò tí a kùn ní pupa àti awọ màlúù; odò igi kasia;
njũa cia ndũrũme itoboketio rangi-inĩ mũtune igatunĩha, na njũa cia pomboo; na mbaũ cia mũgaa;
8 òróró olifi fún títan iná; olóòórùn fún òróró ìtasórí, àti fún tùràrí dídùn;
na maguta ma mũtamaiyũ ma gwakia tawa; na mahuti manungi wega ma gwĩkĩrwo maguta-inĩ ma gũitanĩrĩrio, na ma ũbumba ũrĩa mũnungi wega;
9 òkúta óníkìsì àti òkúta tí a tò sí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
na tũhiga twa onigithi na tũhiga tũngĩ twa goro twa gũtumĩrĩrwo nguo ya ebodi na gakuo ga gĩthũri.
10 “Gbogbo ẹni tí ó ní ọgbọ́n láàrín yín, kí ó wa, kí ó sì wá ṣe gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ:
“Arĩa othe marĩ na ũũgĩ wa ũbundi gatagatĩ-inĩ kanyu, nĩmoke mathondeke indo ciothe iria Jehova aathanĩte, nacio nĩ:
11 “àgọ́ náà pẹ̀lú àgọ́ rẹ àti ìbòrí rẹ̀, kọ́kọ́rọ́ rẹ̀, pákó rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, ọ̀wọ́n rẹ̀ àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀;
Hema ĩrĩa nyamũre na hema yayo o na kĩndũ gĩa kũmĩhumbĩra, na ngathĩka cia kũnyiita, na mbaũ ciakĩo, na mĩgamba yakĩo, na itugĩ na itina ciayo;
12 Àpótí náà pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀, ìbò àánú àti aṣọ títa náà tí ó síji bò ó.
na ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro hamwe na mĩtĩ yarĩo, na gĩtĩ gĩa tha, hamwe na gĩtambaya gĩa gũcuurio kĩrĩa gĩa kũhakania;
13 Tábìlì náà pẹ̀lú òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀ àti àkàrà ìfihàn náà.
metha na mĩtĩ yayo, na indo ciayo ciothe, hamwe na mĩgate ya kũigwo mbere ya Jehova,
14 Ọ̀pá fìtílà tí ó wà fún títanná pẹ̀lú ohun èlò rẹ̀, fìtílà àti òróró fún títanná.
na mũtĩ wa kũigĩrĩrwo matawa ma kũmũrĩkaga, hamwe na indo ciaguo, na matawa hamwe na maguta ma kũmaakia;
15 Pẹpẹ tùràrí náà pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀, òróró ìtasórí àti tùràrí dídùn; aṣọ títa fún ọ̀nà ìlẹ̀kùn ní ẹnu-ọ̀nà sí àgọ́ náà.
na kĩgongona kĩa ũbumba na mĩtĩ yakĩo, na maguta ma gũitanĩrĩrio, na ũbumba mũnungi wega; na gĩtambaya gĩa gũcuurio mũrango-inĩ wa itoonyero-inĩ rĩa hema ĩyo nyamũre;
16 Pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú ojú ààrò idẹ rẹ̀, òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀; agbada idẹ pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
na kĩgongona kĩa iruta rĩa njino hamwe na gĩtara gĩakĩo gĩa gĩcango, na mĩtĩ yakĩo, na indo ciakĩo ciothe; na kĩraĩ gĩa gĩcango na kĩgũrũ gĩakĩo;
17 Aṣọ títa ti àgbàlá pẹ̀lú, ọ̀wọ́n àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀ àti aṣọ títa fún ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà.
na itambaya cia gũcuurio cia itoonyero rĩa nja hamwe na itugĩ na itina ciacio na gĩtambaya gĩa gũcuurio gĩa itoonyero rĩa kuuma nja ya hema
18 Èèkàn àgọ́ náà fún àgọ́ náà àti fún àgbàlá àti okùn wọn.
na higĩ cia hema ĩrĩa nyamũre, na cia nja yayo, na mĩkanda yayo;
19 Aṣọ híhun láti ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́ aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n sìn bí àlùfáà.”
na nguo ndume cia kwĩhumbagwo mũndũ agĩtungata arĩ handũ-harĩa-haamũre; nĩcio nguo iria nyamũre cia Harũni ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai o na cia ariũ ake rĩrĩa megũtungata marĩ athĩnjĩri-Ngai.”
20 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì kúrò níwájú Mose,
Naguo mũingĩ wothe wa andũ a Isiraeli ũkĩehera harĩ Musa,
21 olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ àti ẹni tí ọkàn rẹ̀ gbé sókè wá, wọ́n sì mú ọrẹ fún Olúwa, fún iṣẹ́ àgọ́ àjọ, fún gbogbo ìsìn rẹ̀ àti fún aṣọ mímọ́ náà.
na mũndũ o wothe ũrĩa weyendeire na ngoro yake yahĩĩahĩaga, nĩokire na akĩrehera Jehova kĩndũ gĩa kũmũrutĩra nĩ ũndũ wa wĩra wa hema-ya-Gũtũnganwo na mawĩra mayo mothe, o na nĩ ũndũ wa nguo iria nyamũre.
22 Gbogbo àwọn tí ó fẹ́, ọkùnrin àti obìnrin, wọ́n wá wọ́n sì mú onírúurú ìlẹ̀kẹ̀ wúrà: òrùka etí, òrùka àti ọ̀ṣọ́. Gbogbo wọn mú wúrà gẹ́gẹ́ bí ọrẹ wá fún Olúwa.
Arĩa maiguire metĩkĩra ũhoro ũcio, arũme na andũ-a-nja o ũndũ ũmwe, nĩmookire na makĩrehe mathaga ma thahabu ma mĩthemba yothe: namo nĩ mbini ngʼemie cia gwĩkĩrwo nguo-inĩ, na icũhĩ cia matũ, na icũhĩ cia ciara na mathaga mangĩ. Othe nĩmarehire thahabu yao ĩtuĩke iruta rĩa gũthũngũthio harĩ Jehova.
23 Olúkúlùkù ẹni tí ó ni aṣọ aláró elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára, tàbí irun ewúrẹ́, awọ àgbò tí a rì ní pupa tàbí awọ màlúù odò, kí ó mú wọn wá.
Ũrĩa wothe warĩ na ndigi cia rangi wa bururu, kana cia rangi wa ndathi, kana cia rangi mũtune ta gakarakũ, kana gatani ĩrĩa njega, kana guoya wa mbũri, kana njũa cia ndũrũme itoboketio rangi-inĩ mũtune igatunĩha, kana njũa cia pomboo, nĩacireehire.
24 Àwọn tí ó mú ọrẹ fàdákà tàbí idẹ wá, mú ọrẹ wá fún Olúwa, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ní igi ṣittimu fún ipa kankan nínú iṣẹ́ mú un wá.
Andũ arĩa maarehire iruta rĩa betha kana rĩa gĩcango, maarĩrehire rĩrĩ iruta harĩ Jehova, na ũrĩa wothe warĩ na mbaũ cia mũgaa nĩ ũndũ wa wĩra ũcio nĩacireehire.
25 Gbogbo àwọn obìnrin tí ó ní ọgbọ́n ríran owú pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀, kí ó mú èyí ti ó ti ran wá ti aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó tàbí ti ọ̀gbọ̀ dáradára.
Mũndũ-wa-nja o wothe warĩ mũũgĩ wĩra-inĩ wa kuogotha ndigi na moko make, akĩrehe kĩrĩa ogothete, ndigi cia rangi wa bururu, kana cia rangi wa ndathi, kana cia rangi mũtune ta gakarakũ, kana gatani ĩrĩa njega.
26 Gbogbo àwọn obìnrin tí ó fẹ́, tí ó sì ní ọgbọ́n ń ran òwú irun ewúrẹ́.
Nao andũ-a-nja othe arĩa meyendeire na nĩ maarĩ na ũũgĩ ũcio, nĩmoogothire ndigi cia guoya wa mbũri.
27 Àwọn olórí mú òkúta óníkìsì wá láti tò ó lórí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
Atongoria marehire tũhiga twa onigithi na tũhiga tũngĩ twa goro tũtumĩrĩrwo nguo-inĩ ya ebodi na gakuo ga gĩthũri.
28 Wọ́n sì tún mú olóòórùn àti òróró olifi wá fún títanná àti fún òróró ìtasórí àti fún tùràrí dídùn.
Nĩmacookire makĩrehe mahuti manungi wega, na maguta ma mĩtamaiyũ ma gwakia tawa, na maguta ma gũitanĩrĩrio o na ma gũthondeka ũbumba ũrĩa mũnungi wega.
29 Gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli ọkùnrin àti obìnrin ẹni tí ó fẹ́ mú ọrẹ àtinúwá fún Olúwa fún gbogbo iṣẹ́ tí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn láti ṣe nípasẹ̀ Mose.
Andũ a Isiraeli othe, arũme na andũ-a-nja arĩa meyendeire, nĩmareheire Jehova maruta ma kwĩyendera nĩ ũndũ wa wĩra ũrĩa Jehova aamaathĩte na kanua ka Musa marute.
30 Nígbà náà ni Mose wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Wò ó, Olúwa ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
Ningĩ Musa akĩĩra andũ a Isiraeli atĩrĩ, “Onei, Jehova nĩathuurĩte Bezaleli mũrũ wa Uri ũrĩa mũriũ wa Huri, wa mũhĩrĩga wa Juda,
31 Ó sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un, pẹ̀lú ọgbọ́n, òye, ìmọ̀ àti gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
na nĩamũiyũrĩtie na Roho wa Ngai, na ũũgĩ, na ũhoti, na ũmenyo wa mawĩra mothe ma ũbundi
32 Láti máa ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ,
nĩgeetha athugunde mĩcoro ya ũũgĩ ya indo-inĩ cia thahabu, na betha, na gĩcango,
33 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò ó, láti fún igi àti láti ṣiṣẹ́ ni gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
na gwacũhia tũhiga twa goro twa gũthecererwo indo-inĩ, na kũruta wĩra wa gũkaaya mbaũ, na kũruta mawĩra ma mĩcoro ma mĩthemba yothe ya ũbundi.
34 Ó sì fún òun àti Oholiabu ọmọ Ahisamaki ti ẹ̀yà Dani, ni agbára láti kọ́ àwọn tókù.
Na eerĩ, we marĩ na Oholiabu mũrũ wa Ahisamaku wa mũhĩrĩga wa Dani, nĩamaheete ũhoti wa kũruta andũ arĩa angĩ.
35 Ó sì fi ọgbọ́n kún wọn láti ṣe gbogbo onírúurú iṣẹ́, ti oníṣọ̀nà, ti ayàwòrán, ti aránsọ, ti aláṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ní ọ̀gbọ̀ dáradára àti ti ahunṣọ, gbogbo èyí tí ọ̀gá oníṣẹ́-ọnà àti ayàwòrán ń ṣe.
Nĩamaiyũrĩtie na ũũgĩ wa kũruta mawĩra mothe, marĩ mabundi, na acori, na agemia na ndigi cia rangi wa bururu, na cia rangi wa ndathi, na cia rangi mũtune ta gakarakũ, na gatani ĩrĩa njega, o na atumi: othe marĩ mabundi moogĩ, na acori oogĩ.

< Exodus 35 >