< Exodus 35 >

1 Mose pe gbogbo ìjọ Israẹli ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ohun ti Olúwa ti pàṣẹ fún un yín láti ṣe.
And Moses gathered together all the congregation of the children of Israel, and said unto them, These are the things which the Lord hath commanded, that ye should do them.
2 Fún ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje yóò jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún yín, ọjọ́ ìsinmi ni sí Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ni ọjọ́ náà ní a ó pa.
Six days shall work be done, but on the seventh day there shall be to you a holy day, a sabbath of rest to the Lord: whosoever doth work thereon shall be put to death.
3 Ẹ má ṣe dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”
Ye shall not kindle any fire throughout your habitations upon the sabbath day.
4 Mose sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ.
And Moses said unto all the congregation of the children of Israel, as followeth, This is the thing which the Lord hath commanded, saying,
5 Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti: “wúrà, fàdákà àti idẹ;
Take ye from among you an offering unto the Lord; whosoever is of a willing heart, let him bring it, an offering of the Lord: Gold, and silver, and copper,
6 aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára; àti irun ewúrẹ́;
And blue, and purple, and scarlet yarn, and linen thread, and goats' hair,
7 awọ àgbò tí a kùn ní pupa àti awọ màlúù; odò igi kasia;
And rams' skills dyed red, and badgers' skins, and shittim wood,
8 òróró olifi fún títan iná; olóòórùn fún òróró ìtasórí, àti fún tùràrí dídùn;
And oil for the lighting, and spices, for the anointing oil, and for the incense of spices,
9 òkúta óníkìsì àti òkúta tí a tò sí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
And onyx stones, and stones for setting, for the ephod, and for the breastplate.
10 “Gbogbo ẹni tí ó ní ọgbọ́n láàrín yín, kí ó wa, kí ó sì wá ṣe gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ:
And all the wise-hearted among you shall come, and make all that which the Lord hath commanded:
11 “àgọ́ náà pẹ̀lú àgọ́ rẹ àti ìbòrí rẹ̀, kọ́kọ́rọ́ rẹ̀, pákó rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, ọ̀wọ́n rẹ̀ àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀;
The tabernacle, its tent, and its covering, its hooks, and its boards, its bars, its pillars, and its sockets;
12 Àpótí náà pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀, ìbò àánú àti aṣọ títa náà tí ó síji bò ó.
The ark, and its staves, [with] the mercy-seat, and the vail of the separation;
13 Tábìlì náà pẹ̀lú òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀ àti àkàrà ìfihàn náà.
The table, and its staves, and all its vessels, and the showbread;
14 Ọ̀pá fìtílà tí ó wà fún títanná pẹ̀lú ohun èlò rẹ̀, fìtílà àti òróró fún títanná.
And the candlestick for the lighting, and its vessel, and its lamps, with the oil for the lighting;
15 Pẹpẹ tùràrí náà pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀, òróró ìtasórí àti tùràrí dídùn; aṣọ títa fún ọ̀nà ìlẹ̀kùn ní ẹnu-ọ̀nà sí àgọ́ náà.
And the altar of incense, and its staves, and the anointing oil, and the incense of spices, and the hanging for the door at the entrance of the tabernacle;
16 Pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú ojú ààrò idẹ rẹ̀, òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀; agbada idẹ pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
The altar of burnt-offering, with its grating of copper, its staves, and all its vessels, the laver and its foot;
17 Aṣọ títa ti àgbàlá pẹ̀lú, ọ̀wọ́n àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀ àti aṣọ títa fún ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà.
The hangings of the court, its pillars, and its sockets, and the hanging for the door of the court;
18 Èèkàn àgọ́ náà fún àgọ́ náà àti fún àgbàlá àti okùn wọn.
The pins of the tabernacle, and the pins of the court, and their cords;
19 Aṣọ híhun láti ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́ aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n sìn bí àlùfáà.”
The cloths of service, to do service therewith in the holy place, the holy garments for Aaron the priest, and the garments of his sons, to minister in as priests.
20 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì kúrò níwájú Mose,
And all the congregation of the children of Israel departed from the presence of Moses.
21 olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ àti ẹni tí ọkàn rẹ̀ gbé sókè wá, wọ́n sì mú ọrẹ fún Olúwa, fún iṣẹ́ àgọ́ àjọ, fún gbogbo ìsìn rẹ̀ àti fún aṣọ mímọ́ náà.
And they came, every man whose heart stirred him up; and every one whom his spirit made willing, brought the Lord's offering for the work of the tabernacle of the congregation, and for all its service, and for the holy garments.
22 Gbogbo àwọn tí ó fẹ́, ọkùnrin àti obìnrin, wọ́n wá wọ́n sì mú onírúurú ìlẹ̀kẹ̀ wúrà: òrùka etí, òrùka àti ọ̀ṣọ́. Gbogbo wọn mú wúrà gẹ́gẹ́ bí ọrẹ wá fún Olúwa.
And they came, the men with the women; whoever was willing-hearted, brought bracelets, and earrings, and finger-rings, and tablets, all kinds of ornaments of gold, and every man that offered an offering of gold unto the Lord.
23 Olúkúlùkù ẹni tí ó ni aṣọ aláró elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára, tàbí irun ewúrẹ́, awọ àgbò tí a rì ní pupa tàbí awọ màlúù odò, kí ó mú wọn wá.
And every man, with whom was found blue, and purple, and scarlet yarn, and linen thread, and goats' hair, and rams' skins dyed red, and badgers' skins, brought them.
24 Àwọn tí ó mú ọrẹ fàdákà tàbí idẹ wá, mú ọrẹ wá fún Olúwa, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ní igi ṣittimu fún ipa kankan nínú iṣẹ́ mú un wá.
Every one that did offer an offering of silver and copper brought it as the Lord's offering; and every one with whom was found shittim wood for any work of the service, brought it.
25 Gbogbo àwọn obìnrin tí ó ní ọgbọ́n ríran owú pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀, kí ó mú èyí ti ó ti ran wá ti aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó tàbí ti ọ̀gbọ̀ dáradára.
And all the women that were wise-hearted spun with their hands, and they brought that which they had spun, of the blue, and of the purple, and of the scarlet yarn, and of the linen thread.
26 Gbogbo àwọn obìnrin tí ó fẹ́, tí ó sì ní ọgbọ́n ń ran òwú irun ewúrẹ́.
And all the women whose heart stirred them up in wisdom spun the goats' hair.
27 Àwọn olórí mú òkúta óníkìsì wá láti tò ó lórí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
And the princes brought the onyx stones, and the stones for setting, for the ephod, and for the breastplate;
28 Wọ́n sì tún mú olóòórùn àti òróró olifi wá fún títanná àti fún òróró ìtasórí àti fún tùràrí dídùn.
And the spice and the oil, for lighting, and for the anointing oil, and for the incense of spices.
29 Gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli ọkùnrin àti obìnrin ẹni tí ó fẹ́ mú ọrẹ àtinúwá fún Olúwa fún gbogbo iṣẹ́ tí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn láti ṣe nípasẹ̀ Mose.
Every man and woman, whose heart made them willing to bring for all manner of work, which the Lord had commanded to be made, by the hand of Moses, even that brought the children of Israel as a free-will offering unto the Lord.
30 Nígbà náà ni Mose wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Wò ó, Olúwa ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
And Moses said unto the children of Israel, See, the Lord hath called by name Bezalel the son of Uri, the son of Chur, of the tribe of Judah;
31 Ó sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un, pẹ̀lú ọgbọ́n, òye, ìmọ̀ àti gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
And he hath filled him with the spirit of God, in wisdom, in understanding, and in knowledge, and in all manner of workmanship;
32 Láti máa ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ,
And to devise works of art, to work in gold, and in silver, and in copper,
33 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò ó, láti fún igi àti láti ṣiṣẹ́ ni gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
And in the cutting of stones, to set them, and in the carving of wood, to make any manner of work of art.
34 Ó sì fún òun àti Oholiabu ọmọ Ahisamaki ti ẹ̀yà Dani, ni agbára láti kọ́ àwọn tókù.
And to teach hath he put in his heart, both to him, and to Aholiab, the son of Achissamach, of the tribe of Dan.
35 Ó sì fi ọgbọ́n kún wọn láti ṣe gbogbo onírúurú iṣẹ́, ti oníṣọ̀nà, ti ayàwòrán, ti aránsọ, ti aláṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ní ọ̀gbọ̀ dáradára àti ti ahunṣọ, gbogbo èyí tí ọ̀gá oníṣẹ́-ọnà àti ayàwòrán ń ṣe.
He hath filled them with wisdom of heart, to execute all manner of work, of the engraver, and of the designing weaver, and of the embroiderer, in blue, and in purple, in scarlet yarn, and in linen thread, and of the weaver, of those that do every species of work, and of those that devise works of art.

< Exodus 35 >