< Exodus 34 >
1 Olúwa sọ fún Mose pé, “E gé òkúta wàláà méjì jáde bí i ti àkọ́kọ́, Èmi yóò sì kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé tó wà lára tí àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fọ́ sára wọn.
Och Herren sade till Mose: Uthugg dig två stentaflor, sådana som de första voro, att jag skrifver de ord deruti, som i första taflomen voro, som du sönderslog.
2 Múra ní òwúrọ̀, kí o sì wá sórí òkè Sinai. Kí o fi ara rẹ hàn mí lórí òkè náà.
Och var redo i morgon, att du bittida stiger upp på Sinai berg, och träder der upp till mig öfverst på berget.
3 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá pẹ̀lú rẹ tàbí kí a rí wọn lórí òkè náà; bẹ́ẹ̀ ni agbo àgùntàn tàbí ọwọ́ ẹran kó má ṣe jẹ níwájú òkè náà.”
Och låt ingen stiga ditupp, med dig, att ingen varder sedder kringom hela berget; och låt ingen får eller fä beta in mot detta berget.
4 Bẹ́ẹ̀ Mose sì gbẹ́ òkúta wàláà méjì bí ti àkọ́kọ́, ó sì gun orí òkè Sinai lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un; Ó sì gbé òkúta wàláà méjèèjì náà sí ọwọ́ rẹ̀.
Och Mose uthögg sig två stentaflor, sådana som de första voro, och stod bittida upp om morgonen, och steg upp på Sinai berg, såsom Herren honom budit hade, och tog de två stentaflor i sina hand.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọsánmọ̀, ó sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pòkìkí orúkọ Olúwa.
Då kom Herren neder uti ett moln. Och han trädde ditfram till honom, och åkallade Herrans Namn.
6 Ó sì kọjá níwájú Mose, ó sì ń ké pé, “Olúwa, Olúwa, Ọlọ́run aláàánú àti olóore-ọ̀fẹ́, Ẹni tí ó lọ́ra láti bínú, tí ó pọ̀ ní ìfẹ́ àti olóòtítọ́,
Och då Herren gick framom för hans ansigte, ropade han: Herre, Herre Gud, barmhertig och nådelig, och långmodig, och af stor nåde, och trofast.
7 Ẹni tí ó ń pa ìfẹ́ mọ́ fún ẹgbẹ̀rún, ó sì ń dáríjì àwọn ẹni búburú, àwọn ti ń ṣọ̀tẹ̀ àti ẹlẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀ kì í fi àwọn ẹlẹ́bi sílẹ̀ láìjìyà; Ó ń fi ìyà jẹ ọmọ àti àwọn ọmọ wọn fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba dé ìran kẹta àti ẹ̀kẹrin.”
Du som bevarar nåde till tusende leder, och förlåter missgerningar, öfverträdelser och synder; och för hvilkom ingen är oskyldig, du som söker fädernas missgerningar på barn och barnabarn, allt intill tredje och fjerde led.
8 Mose foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn.
Och Mose böjde sig hasteliga neder på jordena, och bad till honom,
9 Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojúrere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jì, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”
Och sade: Hafver jag, Herre, funnit nåd för din ögon, så gånge Herren med oss, förty det är ett hårdnackadt folk; att du varder vårom missgerningom och syndom nådelig, och låter oss vara ditt arfgods.
10 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ Èmi yóò ṣe ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀-èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrín wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí Èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó.
Och han sade: Si, jag vill göra ett förbund för allo dino folke, och vill göra undertecken, hvilkas like icke skapade äro i all land, och ibland all folk. Och allt folk, der du ibland äst, skall se Herrans verk; ty förskräckeligit skall det vara, som jag göra skall med dig.
11 Ṣe ohun tí Èmi pàṣẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Amori, àwọn ará Kenaani, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hiti, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde níwájú rẹ.
Håll det som jag bjuder dig i dag; si, jag vill utdrifva för dig de Amoreer, Cananeer, Hetheer, Phereseer, Heveer och Jebuseer.
12 Máa ṣọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ̀ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdẹwò láàrín rẹ.
Tag dig vara, att du icke gör något förbund med landsens inbyggare, der du inkommer; att de icke varda dig till förargelse ibland dig;
13 Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Aṣerah wọn. (Ère òrìṣà wọn.)
Utan deras altare skall du omstörta, och slå sönder deras beläter, och deras lundar hugga ned;
14 Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ Òjòwú, Ọlọ́run owú ni.
Ty du skall icke tillbedja en annan gud; ty Herren heter en nitälskare, derföre att han är en nitälskande Gud;
15 “Máa ṣọ́ra kí ẹ má ṣe bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà dá májẹ̀mú; nígbà tí wọ́n bá ń ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, tí wọ́n sì rú ẹbọ sí wọn, wọn yóò pè yín, ẹ̀yin yóò sì jẹ ẹbọ wọn.
På det att, om du gör något förbund med landsens inbyggare, och när de i horeri löpa efter sina gudar, och offra sina gudar, att de icke bjuda dig, och du äter af deras offer;
16 Nígbà tí ìwọ bá yàn nínú àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ ní ìyàwó, àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí yóò ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, wọn yóò sì mú kí àwọn ọmọkùnrin yín náà ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
Och tager dinom sönom deras döttrar till hustrur, hvilka i horeri löpa efter deras gudar, och komma dina söner ock till att löpa i horeri efter sina gudar.
17 “Ìwọ kò gbọdọ̀ dá ère òrìṣàkórìṣà fún ara rẹ.
Du skall inga gjutna gudar göra dig.
18 “Àjọ àkàrà àìwú ni kí ìwọ máa pamọ́. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò jẹ àkàrà aláìwú, gẹ́gẹ́ bí Èmi ti pa á láṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní ìgbà tí a yàn nínú oṣù Abibu, nítorí ní oṣù náà ni ẹ jáde láti Ejibiti wá.
Osyradt bröds högtid skall du hålla; i sju dagar skall du äta osyradt bröd, såsom jag dig budit hafver, i Abibs månads tid; ty uti Abibs månad äst du utdragen utur Egypten.
19 “Gbogbo àkọ́bí inú kọ̀ọ̀kan tèmi ní i ṣe, pẹ̀lú àkọ́bí gbogbo ohun ọ̀sìn rẹ, bóyá ti màlúù tàbí ti àgùntàn.
Allt det som först öppnar moderlifvet, är mitt; det mankön är, i dinom boskap, det sitt moderlif öppnar, vare sig oxe eller får.
20 Àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni kí ìwọ kí ó fi ọ̀dọ́-àgùntàn rà padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, dá ọrùn rẹ̀. Ra gbogbo àkọ́bí ọkùnrin rẹ padà. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá síwájú mi ní ọwọ́ òfo.
Men åsnans förstföding skall du lösa med ett får; om du icke löser det, så bryt thy halsen sönder. Allt förstfödt af din barn skall du lösa; och att ingen kommer fram för mig med tomma händer.
21 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ keje ìwọ yóò sinmi; kódà ní àkókò ìfúnrúgbìn àti ní àkókò ìkórè ìwọ gbọdọ̀ sinmi.
Sex dagar skall du arbeta; på sjunde dagen skall du hålla upp, både med plöjande och skärande.
22 “Ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ pẹ̀lú àkọ́so èso alikama àti àjọ ìkórè ní òpin ọdún.
Veckohögtid skall du hålla med förstlingen af hveteskördene; och insamlingshögtid, när året ute är.
23 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún, gbogbo àwọn ọkùnrin ni kí ó farahàn níwájú Olúwa Olódùmarè, Ọlọ́run Israẹli.
Tre resor om året skall allt ditt mankön komma fram för den allsmägtiga Herran och Israels Gud.
24 Èmi yóò lé orílẹ̀-èdè jáde níwájú rẹ, Èmi yóò sì mú kí ìpín rẹ fẹ̀, ẹnikẹ́ni kì yóò gba ilẹ̀ rẹ nígbà tí ìwọ bá gòkè lọ ní ìgbà mẹ́ta lọ́dún kọ̀ọ̀kan láti farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
När jag utdrifver Hedningarna för dig, och förvidgar dina landsändar, skall ingen åstunda efter ditt land, den stund du uppgår, tre resor om året, till att hafva dig fram för Herran din Gud.
25 “Má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sí mi pẹ̀lú ohunkóhun tí ó bá ní ìwúkàrà, kí o má sì ṣe jẹ́ kí ẹbọ ìrékọjá kù títí di òwúrọ̀.
Du skall icke offra bloden af mitt offer på syradt bröd; och Påskahögtidenes offer skall icke blifva öfver nattena intill morgonen.
26 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.”
Förstlingen af den första frukten af dinom åker skall du föra in uti Herrans dins Guds hus. Du skall icke koka kidet, den stund det ännu på sins moders mjölk är.
27 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Èmi bá ìwọ àti Israẹli dá májẹ̀mú.”
Och Herren sade till Mose: Skrif dessa orden; ty efter dessa orden hafver jag gjort ett förbund med dig, och med Israel.
28 Mose wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru láìjẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.
Och han var der när Herranom fyratio dagar och fyratio nätter, och åt intet bröd, och drack intet vatten; och han skref på taflorna detta förbund, de tio ord.
29 Nígbà tí Mose sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè Sinai pẹ̀lú wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀, òun kò mọ̀ pé ojú òun ń dán nítorí ó bá Olúwa sọ̀rọ̀.
Då nu Mose gick ned af berget Sinai, hade han de två vittnesbördsens taflor i sine hand, och visste icke, att huden af hans ansigte sken, deraf att han hade talat med honom.
30 Nígbà tí Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí Mose, ojú rẹ̀ ń dán, ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti súnmọ́ ọn.
Och då Aaron och all Israels barn sågo, att hans ansigtes hud sken, fruktade de nalkas honom.
31 Ṣùgbọ́n Mose pè wọn; Aaroni àti gbogbo àwọn olórí àjọ padà wá bá a, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀.
Då kallade Mose dem; och till honom vände sig både Aaron, och alle de öfverste för menighetene. Och han talade med dem.
32 Lẹ́yìn èyí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli súnmọ́ ọn, ó sì fún wọn ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún un lórí òkè Sinai.
Sedan nalkades all Israels barn intill honom; och han böd dem allt det Herren hade talat med honom på Sinai berg.
33 Nígbà tí Mose parí ọ̀rọ̀ sísọ fún wọn. Ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
Och då han talade med dem, lade han ett täckelse på sitt ansigte.
34 Ṣùgbọ́n nígbàkígbà tí Mose bá wà níwájú Olúwa láti bá a sọ̀rọ̀, á ṣí ìbòjú náà títí yóò fi jáde. Nígbà tí ó bá sì jáde, á sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli ohun tí a ti pàṣẹ fún un,
Och när han ingick för Herran till att tala med honom, lade han täckelset af, tilldess han gick åter ut igen; och när han kom ut, och talade med Israels barn det honom budet var;
35 àwọn ọmọ Israẹli sì rí i pé ojú rẹ̀ ń dán. Mose á sì tún fi ìbòjú bo ojú rẹ̀ títí á fi lọ bá Olúwa sọ̀rọ̀.
Så sågo de Israels barn på hans ansigte, huru hans ansigtes hud sken; så drog han åter täckelset öfver ansigtet, tilldess han gick åter in igen till att tala med honom.