< Exodus 34 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé, “E gé òkúta wàláà méjì jáde bí i ti àkọ́kọ́, Èmi yóò sì kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé tó wà lára tí àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fọ́ sára wọn.
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Taie-ți două table de piatră asemenea primelor și voi scrie pe aceste table cuvintele care au fost pe primele table, pe care le-ai spart.
2 Múra ní òwúrọ̀, kí o sì wá sórí òkè Sinai. Kí o fi ara rẹ hàn mí lórí òkè náà.
Și fii gata mâine dimineață și urcă-te dimineață pe muntele Sinai și prezintă-te acolo mie pe vârful muntelui.
3 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá pẹ̀lú rẹ tàbí kí a rí wọn lórí òkè náà; bẹ́ẹ̀ ni agbo àgùntàn tàbí ọwọ́ ẹran kó má ṣe jẹ níwájú òkè náà.”
Și niciun bărbat să nu urce cu tine, să nu fie văzut niciun bărbat pe tot muntele; să nu pască nici turmele nici cirezile înaintea acelui munte.
4 Bẹ́ẹ̀ Mose sì gbẹ́ òkúta wàláà méjì bí ti àkọ́kọ́, ó sì gun orí òkè Sinai lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un; Ó sì gbé òkúta wàláà méjèèjì náà sí ọwọ́ rẹ̀.
Iar el a tăiat două table de piatră asemenea primelor; și Moise s-a sculat dis-de-dimineață și a urcat pe muntele Sinai, așa cum DOMNUL îi poruncise și a luat în mâna sa cele două table din piatră.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọsánmọ̀, ó sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pòkìkí orúkọ Olúwa.
Și DOMNUL a coborât în nor și a stat cu el acolo și a vestit numele DOMNULUI.
6 Ó sì kọjá níwájú Mose, ó sì ń ké pé, “Olúwa, Olúwa, Ọlọ́run aláàánú àti olóore-ọ̀fẹ́, Ẹni tí ó lọ́ra láti bínú, tí ó pọ̀ ní ìfẹ́ àti olóòtítọ́,
Și DOMNUL a trecut pe dinaintea lui și a vestit: DOMNUL, DOMNUL Dumnezeu, milostiv și cu har, îndelung răbdător și abundent în bunătate și adevăr,
7 Ẹni tí ó ń pa ìfẹ́ mọ́ fún ẹgbẹ̀rún, ó sì ń dáríjì àwọn ẹni búburú, àwọn ti ń ṣọ̀tẹ̀ àti ẹlẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀ kì í fi àwọn ẹlẹ́bi sílẹ̀ láìjìyà; Ó ń fi ìyà jẹ ọmọ àti àwọn ọmọ wọn fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba dé ìran kẹta àti ẹ̀kẹrin.”
Păstrând milă pentru mii, iertând nelegiuire și fărădelege și păcat și în niciun fel nu va cruța pe vinovat; pedepsind nelegiuirea părinților peste copii și peste copiii copiilor, până la a treia și a patra generație.
8 Mose foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn.
Și Moise s-a grăbit și și-a plecat capul spre pământ și s-a închinat.
9 Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojúrere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jì, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”
Și a spus: Dacă acum am găsit har înaintea ochilor tăi, Doamne, lasă te rog, ca Domnul meu, să meargă printre noi, pentru că acesta este un popor îndărătnic; și iartă nelegiuirea noastră și păcatul nostru și ia-ne ca moștenirea ta.
10 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ Èmi yóò ṣe ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀-èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrín wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí Èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó.
Iar el a spus: Iată, fac un legământ: înaintea întregului tău popor voi face minuni, așa cum nu s-au mai făcut pe tot pământul, nici în vreo națiune; și tot poporul printre care tu te afli vor vedea lucrarea DOMNULUI; căci este un lucru înfricoșător pe care îl voi face cu tine.
11 Ṣe ohun tí Èmi pàṣẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Amori, àwọn ará Kenaani, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hiti, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde níwájú rẹ.
Ține ceea ce îți poruncesc în această zi; iată, alung dinaintea ta pe amorit și pe canaanit și pe hitit și pe perizit și pe hivit și pe iebusit.
12 Máa ṣọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ̀ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdẹwò láàrín rẹ.
Ia seama la tine însuți, ca nu cumva să faci legământ cu locuitorii țării în care mergi, ca nu cumva să fie o cursă în mijlocul tău;
13 Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Aṣerah wọn. (Ère òrìṣà wọn.)
Ci să distrugeți altarele lor, să spargeți idolii lor și să le tăiați dumbrăvile,
14 Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ Òjòwú, Ọlọ́run owú ni.
Pentru că nu te vei închina niciunui alt dumnezeu, pentru că DOMNUL, a cărui nume este Gelos, este un Dumnezeu gelos;
15 “Máa ṣọ́ra kí ẹ má ṣe bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà dá májẹ̀mú; nígbà tí wọ́n bá ń ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, tí wọ́n sì rú ẹbọ sí wọn, wọn yóò pè yín, ẹ̀yin yóò sì jẹ ẹbọ wọn.
Nu cumva să faci legământ cu locuitorii țării și ei să curvească după dumnezeii lor și să aducă sacrificiu dumnezeilor lor și vreunul să te cheme și să mănânci din sacrificiul lui;
16 Nígbà tí ìwọ bá yàn nínú àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ ní ìyàwó, àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí yóò ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, wọn yóò sì mú kí àwọn ọmọkùnrin yín náà ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
Și să iei dintre fiicele lor pentru fiii tăi și fiicele lor să curvească după dumnezeii lor și să facă pe fiii tăi să curvească după dumnezeii lor.
17 “Ìwọ kò gbọdọ̀ dá ère òrìṣàkórìṣà fún ara rẹ.
Să nu îți faci dumnezei turnați.
18 “Àjọ àkàrà àìwú ni kí ìwọ máa pamọ́. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò jẹ àkàrà aláìwú, gẹ́gẹ́ bí Èmi ti pa á láṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní ìgbà tí a yàn nínú oṣù Abibu, nítorí ní oṣù náà ni ẹ jáde láti Ejibiti wá.
Ține sărbătoarea azimelor. Mănâncă șapte zile azimă cum ți-am poruncit, în timpul lunii Abib, pentru că în luna Abib ai ieșit din Egipt.
19 “Gbogbo àkọ́bí inú kọ̀ọ̀kan tèmi ní i ṣe, pẹ̀lú àkọ́bí gbogbo ohun ọ̀sìn rẹ, bóyá ti màlúù tàbí ti àgùntàn.
Tot ce deschide pântecele este al meu; și fiecare întâi născut între vitele tale, fie bou sau oaie.
20 Àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni kí ìwọ kí ó fi ọ̀dọ́-àgùntàn rà padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, dá ọrùn rẹ̀. Ra gbogbo àkọ́bí ọkùnrin rẹ padà. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá síwájú mi ní ọwọ́ òfo.
Dar să răscumperi pe întâiul născut al măgăriței cu un miel; și dacă nu îl răscumperi, atunci să îi frângi gâtul. Să răscumperi pe tot întâiul născut dintre fiii tăi. Și niciunul să nu se arate înaintea mea cu mâna goală.
21 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ keje ìwọ yóò sinmi; kódà ní àkókò ìfúnrúgbìn àti ní àkókò ìkórè ìwọ gbọdọ̀ sinmi.
Să lucrezi șase zile, dar să te odihnești în a șaptea zi; să te odihnești în timpul aratului și al secerișului.
22 “Ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ pẹ̀lú àkọ́so èso alikama àti àjọ ìkórè ní òpin ọdún.
Și să ții sărbătoarea săptămânilor, ale primelor roade ale secerișului grâului și sărbătoarea recoltei la sfârșitul anului.
23 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún, gbogbo àwọn ọkùnrin ni kí ó farahàn níwájú Olúwa Olódùmarè, Ọlọ́run Israẹli.
De trei ori într-un an toți copiii tăi de parte bărbătească să se arate înaintea Domnului DUMNEZEU, Dumnezeul lui Israel.
24 Èmi yóò lé orílẹ̀-èdè jáde níwájú rẹ, Èmi yóò sì mú kí ìpín rẹ fẹ̀, ẹnikẹ́ni kì yóò gba ilẹ̀ rẹ nígbà tí ìwọ bá gòkè lọ ní ìgbà mẹ́ta lọ́dún kọ̀ọ̀kan láti farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Pentru că voi arunca afară națiunile dinaintea ta și voi lărgi hotarele tale; niciun om nu va dori țara ta, când te vei urca să te arăți înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău, de trei ori într-un an.
25 “Má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sí mi pẹ̀lú ohunkóhun tí ó bá ní ìwúkàrà, kí o má sì ṣe jẹ́ kí ẹbọ ìrékọjá kù títí di òwúrọ̀.
Să nu oferi sângele sacrificiului meu cu dospeală; nici să nu fie lăsat sacrificiul sărbătorii paștelui până dimineața.
26 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.”
Să aduci primul dintre primele roade ale pământului tău la casa DOMNULUI Dumnezeul tău. Să nu fierbi un ied în laptele mamei sale.
27 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Èmi bá ìwọ àti Israẹli dá májẹ̀mú.”
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Scrie-ți aceste cuvinte; căci după tonul acestor cuvinte am făcut un legământ cu tine și cu Israel.
28 Mose wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru láìjẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.
Iar el a fost acolo cu DOMNUL patruzeci de zile și patruzeci de nopți; nici nu a mâncat pâine, nici nu a băut apă. Și el a scris pe table cuvintele legământului, cele zece porunci.
29 Nígbà tí Mose sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè Sinai pẹ̀lú wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀, òun kò mọ̀ pé ojú òun ń dán nítorí ó bá Olúwa sọ̀rọ̀.
Și s-a întâmplat, când a coborât Moise de pe Muntele Sinai, și cele două table ale mărturiei erau în mâna lui Moise când a coborât de pe munte, că Moise nu știa că pielea feței sale strălucea cât timp a vorbit cu el.
30 Nígbà tí Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí Mose, ojú rẹ̀ ń dán, ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti súnmọ́ ọn.
Și când Aaron și toți copiii lui Israel au văzut pe Moise, iată, pielea feței sale strălucea; și s-au temut să se apropie de el.
31 Ṣùgbọ́n Mose pè wọn; Aaroni àti gbogbo àwọn olórí àjọ padà wá bá a, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀.
Și Moise i-a chemat; și Aaron și toți conducătorii adunării s-au întors la el; și Moise a vorbit cu ei.
32 Lẹ́yìn èyí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli súnmọ́ ọn, ó sì fún wọn ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún un lórí òkè Sinai.
Și după aceea toți copiii lui Israel s-au apropiat, și le-a dat în poruncă tot ceea ce DOMNUL vorbise cu el în muntele Sinai.
33 Nígbà tí Mose parí ọ̀rọ̀ sísọ fún wọn. Ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
Și când Moise a încetat să vorbească cu ei și-a pus un văl pe față.
34 Ṣùgbọ́n nígbàkígbà tí Mose bá wà níwájú Olúwa láti bá a sọ̀rọ̀, á ṣí ìbòjú náà títí yóò fi jáde. Nígbà tí ó bá sì jáde, á sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli ohun tí a ti pàṣẹ fún un,
Dar când Moise a intrat înaintea DOMNULUI ca să vorbească cu el, el a scos vălul, până când a ieșit. Și a ieșit și le-a spus copiilor lui Israel ceea ce i-a fost poruncit.
35 àwọn ọmọ Israẹli sì rí i pé ojú rẹ̀ ń dán. Mose á sì tún fi ìbòjú bo ojú rẹ̀ títí á fi lọ bá Olúwa sọ̀rọ̀.
Și copiii lui Israel au văzut fața lui Moise, că pielea feței lui Moise strălucea; și Moise a pus vălul peste fața sa din nou, până când a intrat să vorbească cu el.

< Exodus 34 >