< Exodus 34 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé, “E gé òkúta wàláà méjì jáde bí i ti àkọ́kọ́, Èmi yóò sì kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé tó wà lára tí àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fọ́ sára wọn.
I rzekł Pan do Mojżesza: Wyciesz sobie dwie tablice kamienne, podobne pierwszym, a napiszę na tychże tablicach słowa, które były na tablicach pierwszych, któreś stłukł.
2 Múra ní òwúrọ̀, kí o sì wá sórí òkè Sinai. Kí o fi ara rẹ hàn mí lórí òkè náà.
A bądź gotów rano, że wstąpisz jutro na górę Synaj, i staniesz przede mną na wierzchu tej góry.
3 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá pẹ̀lú rẹ tàbí kí a rí wọn lórí òkè náà; bẹ́ẹ̀ ni agbo àgùntàn tàbí ọwọ́ ẹran kó má ṣe jẹ níwájú òkè náà.”
Ale żaden niech nie wstępuje z tobą, a nikt też niech nie będzie widziany po wszystkiej górze; ani owce, ani woły, niech się nie pasą przeciwko tej górze.
4 Bẹ́ẹ̀ Mose sì gbẹ́ òkúta wàláà méjì bí ti àkọ́kọ́, ó sì gun orí òkè Sinai lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un; Ó sì gbé òkúta wàláà méjèèjì náà sí ọwọ́ rẹ̀.
Tedy wyciosał Mojżesz dwie tablice kamienne, podobne pierwszym; i wstawszy rano, wstąpił na górę Synaj, jako mu rozkazał Pan, wziąwszy w ręce swe dwie tablice kamienne.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọsánmọ̀, ó sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pòkìkí orúkọ Olúwa.
I zstąpił Pan w obłoku, i stanął tam z nim, i zawołał imieniem Pan.
6 Ó sì kọjá níwájú Mose, ó sì ń ké pé, “Olúwa, Olúwa, Ọlọ́run aláàánú àti olóore-ọ̀fẹ́, Ẹni tí ó lọ́ra láti bínú, tí ó pọ̀ ní ìfẹ́ àti olóòtítọ́,
Bo przechodząc Pan przed twarzą jego, wołał: Pan, Pan, Bóg miłosierny i litościwy, nie rychły do gniewu, a obfity w miłosierdziu i w prawdzie;
7 Ẹni tí ó ń pa ìfẹ́ mọ́ fún ẹgbẹ̀rún, ó sì ń dáríjì àwọn ẹni búburú, àwọn ti ń ṣọ̀tẹ̀ àti ẹlẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀ kì í fi àwọn ẹlẹ́bi sílẹ̀ láìjìyà; Ó ń fi ìyà jẹ ọmọ àti àwọn ọmọ wọn fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba dé ìran kẹta àti ẹ̀kẹrin.”
Zachowujący miłosierdzie nad tysiącami, gładzący nieprawość i przestępstwo i grzech, nie usprawiedliwiający winnego, nawiedzając nieprawość ojcowską w synach i w synach synów ich do trzeciego i do czwartego pokolenia.
8 Mose foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn.
Pospieszywszy się tedy Mojżesz nachylił się ku ziemi i pokłonił się,
9 Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojúrere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jì, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”
I rzekł; Jeźlim teraz znalazł łaskę w oczach twoich, Panie, niech idzie proszę Pan w pośrodku nas, lud bowiem ten twardego karku jest, a odpuść nieprawości nasze, i grzech nasz, a miej nas za dziedzictwo.
10 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ Èmi yóò ṣe ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀-èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrín wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí Èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó.
Który odpowiedział: Oto, Ja postanowię przymierze; przed wszystkim ludem twoim czynić będę cuda, które nie były czynione po wszystkiej ziemi i we wszystkich narodziech; i obaczy wszystek lud, między którymeś ty, sprawę Pańską; bo straszne będzie to, co Ja uczynię z tobą.
11 Ṣe ohun tí Èmi pàṣẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Amori, àwọn ará Kenaani, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hiti, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde níwájú rẹ.
Strzeżże tego, co Ja rozkazuję tobie: Oto, Ja wypędzę przed obliczem twojem Amorejczyka, i Chananejczyka, i Hetejczyka, i Ferezejczyka, i Hewejczyka, i Jebuzejczyka.
12 Máa ṣọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ̀ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdẹwò láàrín rẹ.
Strzeżże się, abyś snać nie stanowił przymierza z obywatelami ziemi onej, do której ty wnijdziesz, żebyć to nie było sidłem pośrodku ciebie.
13 Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Aṣerah wọn. (Ère òrìṣà wọn.)
Przetoż ołtarze ich zburzycie, bałwany ich połamiecie, i gaje ich święcone wyrąbiecie.
14 Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ Òjòwú, Ọlọ́run owú ni.
Nie będziesz się kłaniał bogu innemu, przeto że Pan jest, zawistny imię jego, Bóg zawistny jest;
15 “Máa ṣọ́ra kí ẹ má ṣe bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà dá májẹ̀mú; nígbà tí wọ́n bá ń ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, tí wọ́n sì rú ẹbọ sí wọn, wọn yóò pè yín, ẹ̀yin yóò sì jẹ ẹbọ wọn.
By snać, uczyniwszy przymierze z obywatelami tej ziemi, gdyby oni cudzołożyli z bogami swymi, i ofiarowali bogom swym, ciebie nie wezwali, a jadłbyś z ofiar ich:
16 Nígbà tí ìwọ bá yàn nínú àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ ní ìyàwó, àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí yóò ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, wọn yóò sì mú kí àwọn ọmọkùnrin yín náà ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
I brałbyś z córek ich żony synom swym, i cudzołożyłyby córki ich z bogi swymi, a przywiodłyby syny twoje do wszeteczeństwa z bogi swymi.
17 “Ìwọ kò gbọdọ̀ dá ère òrìṣàkórìṣà fún ara rẹ.
Bogów odlewanych nie czyń sobie.
18 “Àjọ àkàrà àìwú ni kí ìwọ máa pamọ́. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò jẹ àkàrà aláìwú, gẹ́gẹ́ bí Èmi ti pa á láṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní ìgbà tí a yàn nínú oṣù Abibu, nítorí ní oṣù náà ni ẹ jáde láti Ejibiti wá.
Święto przaśników zachowywać będziesz; przez siedem dni jeść będziesz przaśniki, jakom ci rozkazał, czasu miesiąca Abib; albowiem tegoż miesiąca Abib wyszedłeś z Egiptu.
19 “Gbogbo àkọ́bí inú kọ̀ọ̀kan tèmi ní i ṣe, pẹ̀lú àkọ́bí gbogbo ohun ọ̀sìn rẹ, bóyá ti màlúù tàbí ti àgùntàn.
Wszystko, co otwiera żywot, moje jest; i wszystko z dobytku twego cokolwiek samcem jest, pierworodne i z owiec, i z wołów;
20 Àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni kí ìwọ kí ó fi ọ̀dọ́-àgùntàn rà padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, dá ọrùn rẹ̀. Ra gbogbo àkọ́bí ọkùnrin rẹ padà. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá síwájú mi ní ọwọ́ òfo.
Ale pierworodne oślę odkupisz owcą; a jeźlibyś go nie odkupił, złamiesz mu szyję. Każdego pierworodnego z synów twych odkupisz, i nie ukażą się przed twarz moję próżni.
21 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ keje ìwọ yóò sinmi; kódà ní àkókò ìfúnrúgbìn àti ní àkókò ìkórè ìwọ gbọdọ̀ sinmi.
Sześć dni robić będziesz, a dnia siódmego odpoczniesz; czasu orania i czasu żniwa odpoczniesz.
22 “Ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ pẹ̀lú àkọ́so èso alikama àti àjọ ìkórè ní òpin ọdún.
Święto Tygodni uczynisz też sobie, w pierwiastki żniwa pszenicznego, i święto zbierania na skończeniu roku.
23 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún, gbogbo àwọn ọkùnrin ni kí ó farahàn níwájú Olúwa Olódùmarè, Ọlọ́run Israẹli.
Trzy kroć do roku ukaże się każdy mężczyzna twój przed obliczem Panującego Pana, Boga Izraelskiego.
24 Èmi yóò lé orílẹ̀-èdè jáde níwájú rẹ, Èmi yóò sì mú kí ìpín rẹ fẹ̀, ẹnikẹ́ni kì yóò gba ilẹ̀ rẹ nígbà tí ìwọ bá gòkè lọ ní ìgbà mẹ́ta lọ́dún kọ̀ọ̀kan láti farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Albowiem wypędzę narody przed tobą, a rozszerzę granice twoje; i nie będzie pożądał nikt ziemi twojej, gdy pójdziesz, abyś się ukazał przed obliczem Pana Boga twego trzy kroć do roku.
25 “Má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sí mi pẹ̀lú ohunkóhun tí ó bá ní ìwúkàrà, kí o má sì ṣe jẹ́ kí ẹbọ ìrékọjá kù títí di òwúrọ̀.
Nie będziesz ofiarował przy kwasie krwi ofiary mojej, i nie zostanie nic do jutra z ofiary obchodu święta przejścia.
26 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.”
Pierwiastki pierwszych urodzajów ziemi twej przyniesiesz w dom Pana Boga twego. Nie będziesz warzył koźlęcia w mleku matki jego.
27 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Èmi bá ìwọ àti Israẹli dá májẹ̀mú.”
Zatem rzekł Pan do Mojżesza: Napisz sobie te słowa, bo według słów tych postanowiłem z tobą przymierze, i z Izraelem.
28 Mose wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru láìjẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.
I był tam z Panem czterdzieści dni i czterdzieści nocy; chleba nie jadł, i wody nie pił; i napisał Pan na tablicach słowa przymierza, dziesięć słów.
29 Nígbà tí Mose sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè Sinai pẹ̀lú wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀, òun kò mọ̀ pé ojú òun ń dán nítorí ó bá Olúwa sọ̀rọ̀.
I stało się, gdy zstępował Mojżesz z góry Synaj, a dwie tablice świadectwa miał w ręku Mojżesz, gdy zstępował z góry, że nie wiedział Mojżesz, iżby się lśniła skóra twarzy jego, gdy Pan mówił z nim.
30 Nígbà tí Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí Mose, ojú rẹ̀ ń dán, ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti súnmọ́ ọn.
I ujrzeli Aaron, i wszyscy synowie Izraelscy Mojżesza, a oto lśniła się skóra twarzy jego, i bali się przystąpić do niego.
31 Ṣùgbọ́n Mose pè wọn; Aaroni àti gbogbo àwọn olórí àjọ padà wá bá a, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀.
Ale zawołał na nich Mojżesz, i nawrócili się ku niemu Aaron, i wszystkie książęta zgromadzenia, i mówił Mojżesz do nich.
32 Lẹ́yìn èyí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli súnmọ́ ọn, ó sì fún wọn ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún un lórí òkè Sinai.
Potem też przyszli wszyscy synowie Izraelscy, którym przykazał wszystko, co mówił Pan z nim na górze SYnaj.
33 Nígbà tí Mose parí ọ̀rọ̀ sísọ fún wọn. Ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
A póki Mojżesz mówił z nimi, miewał na twarzy swojej zasłonę;
34 Ṣùgbọ́n nígbàkígbà tí Mose bá wà níwájú Olúwa láti bá a sọ̀rọ̀, á ṣí ìbòjú náà títí yóò fi jáde. Nígbà tí ó bá sì jáde, á sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli ohun tí a ti pàṣẹ fún un,
Ale gdy wchadzał Mojżesz przed twarz Pańską, aby rozmawiał z nim, odejmował zasłonę, póki nie wyszedł; a wyszedłszy, mówił do synów Izraelskich, co mu było rozkazano.
35 àwọn ọmọ Israẹli sì rí i pé ojú rẹ̀ ń dán. Mose á sì tún fi ìbòjú bo ojú rẹ̀ títí á fi lọ bá Olúwa sọ̀rọ̀.
Widzieli tedy synowie Izraelscy twarz Mojżeszową, że się lśniła skóra twarzy Mojżeszowej; i kładł zaś Mojżesz zasłonę na twarz swoję, póki nie wszedł aby mówił z nim.

< Exodus 34 >