< Exodus 34 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé, “E gé òkúta wàláà méjì jáde bí i ti àkọ́kọ́, Èmi yóò sì kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé tó wà lára tí àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fọ́ sára wọn.
خداوند به موسی فرمود: «دو لوح سنگی مثل لوحهای اول که شکستی تهیه کن تا دوباره ده فرمان را روی آنها بنویسم.
2 Múra ní òwúrọ̀, kí o sì wá sórí òkè Sinai. Kí o fi ara rẹ hàn mí lórí òkè náà.
فردا صبح حاضر شو و از کوه سینا بالا بیا و بر قلهٔ کوه در حضور من بایست.
3 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá pẹ̀lú rẹ tàbí kí a rí wọn lórí òkè náà; bẹ́ẹ̀ ni agbo àgùntàn tàbí ọwọ́ ẹran kó má ṣe jẹ níwájú òkè náà.”
هیچ‌کس با تو بالا نیاید و کسی هم در هیچ نقطهٔ کوه دیده نشود. حتی گله و رمه نیز نزدیک کوه چرا نکنند.»
4 Bẹ́ẹ̀ Mose sì gbẹ́ òkúta wàláà méjì bí ti àkọ́kọ́, ó sì gun orí òkè Sinai lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un; Ó sì gbé òkúta wàláà méjèèjì náà sí ọwọ́ rẹ̀.
موسی همان‌طور که خداوند فرموده بود، صبح زود برخاست و دو لوح سنگی مثل لوحهای قبلی تراشید و آنها را به دست گرفته، از کوه سینا بالا رفت.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọsánmọ̀, ó sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pòkìkí orúkọ Olúwa.
آنگاه خداوند در ابر فرود آمد و آنجا با موسی ایستاد؛ و نام خود، یهوه را ندا کرد.
6 Ó sì kọjá níwájú Mose, ó sì ń ké pé, “Olúwa, Olúwa, Ọlọ́run aláàánú àti olóore-ọ̀fẹ́, Ẹni tí ó lọ́ra láti bínú, tí ó pọ̀ ní ìfẹ́ àti olóòtítọ́,
خداوند از برابر موسی گذشت و چنین ندا کرد: «یهوه! خداوند! خدای رحیم و مهربان، خدای دیرخشم و پراحسان؛ خدای امین که
7 Ẹni tí ó ń pa ìfẹ́ mọ́ fún ẹgbẹ̀rún, ó sì ń dáríjì àwọn ẹni búburú, àwọn ti ń ṣọ̀tẹ̀ àti ẹlẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀ kì í fi àwọn ẹlẹ́bi sílẹ̀ láìjìyà; Ó ń fi ìyà jẹ ọmọ àti àwọn ọmọ wọn fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba dé ìran kẹta àti ẹ̀kẹrin.”
به هزاران نفر رحمت می‌کنم و خطا و عصیان و گناه را می‌بخشم؛ ولی گناه را هرگز بی‌سزا نمی‌گذارم. انتقام گناه پدران را از فرزندان آنها تا نسل سوم و چهارم می‌گیرم.»
8 Mose foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn.
موسی در حضور خداوند به خاک افتاد و او را پرستش کرده،
9 Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojúrere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jì, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”
گفت: «خداوندا، اگر واقعا مورد لطف تو قرار گرفته‌ام، استدعا می‌کنم که تو نیز همراه ما باشی. می‌دانم که این قوم سرکشند، ولی از سر تقصیرها و گناهان ما بگذر و بار دیگر ما را مثل قوم خاص خود بپذیر.»
10 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ Èmi yóò ṣe ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀-èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrín wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí Èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó.
خداوند فرمود: «اینک با تو عهد می‌بندم و در نظر تمامی قوم کارهای عجیب می‌کنم کارهای عجیبی که نظیر آن در هیچ جای دنیا دیده نشده است. تمام بنی‌اسرائیل قدرت مهیب مرا که به‌وسیلۀ تو به آنها نشان می‌دهم، خواهند دید.
11 Ṣe ohun tí Èmi pàṣẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Amori, àwọn ará Kenaani, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hiti, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde níwájú rẹ.
آنچه را که امروز به شما امر می‌کنم، اطاعت کنید. من قبایل اموری، کنعانی، حیتی، فرزی، حوی و یبوسی را از سر راه شما برمی‌دارم.
12 Máa ṣọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ̀ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdẹwò láàrín rẹ.
مواظب باشید هرگز با آن قبایل پیمان دوستی نبندید، مبادا شما را به راههای گمراه کننده بکشانند.
13 Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Aṣerah wọn. (Ère òrìṣà wọn.)
بلکه باید بتها، مجسمه‌های شرم‌آور و مذبحهای آنها را ویران کنید.
14 Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ Òjòwú, Ọlọ́run owú ni.
نباید خدای دیگری را عبادت نمایید، زیرا یهوه خدای غیوری است و پرستش خدای غیر را تحمل نمی‌کند.
15 “Máa ṣọ́ra kí ẹ má ṣe bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà dá májẹ̀mú; nígbà tí wọ́n bá ń ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, tí wọ́n sì rú ẹbọ sí wọn, wọn yóò pè yín, ẹ̀yin yóò sì jẹ ẹbọ wọn.
«هرگز نباید با ساکنان آنجا پیمان دوستی ببندید؛ چون آنها به جای پرستش من، بتها را می‌پرستند و برای آنها قربانی می‌کنند. اگر با ایشان دوست شوید شما را به خوردن خوراک قربانی خود خواهند کشانید.
16 Nígbà tí ìwọ bá yàn nínú àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ ní ìyàwó, àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí yóò ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, wọn yóò sì mú kí àwọn ọmọkùnrin yín náà ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
شما دختران بت‌پرست آنها را برای پسران خود خواهید گرفت و در نتیجه پسران شما هم از خدا برگشته بتهای زنان خود را خواهند پرستید.
17 “Ìwọ kò gbọdọ̀ dá ère òrìṣàkórìṣà fún ara rẹ.
«برای خود هرگز بت نسازید.
18 “Àjọ àkàrà àìwú ni kí ìwọ máa pamọ́. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò jẹ àkàrà aláìwú, gẹ́gẹ́ bí Èmi ti pa á láṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní ìgbà tí a yàn nínú oṣù Abibu, nítorí ní oṣù náà ni ẹ jáde láti Ejibiti wá.
«عید فطیر را هر سال جشن بگیرید. همان‌طور که به شما دستور دادم، هفت روز نانِ بی‌خمیرمایه بخورید. این جشن را در وقت مقرر، در ماه ابیب برگزار کنید، چون در همین ماه بود که از بندگی مصری‌ها آزاد شدید.
19 “Gbogbo àkọ́bí inú kọ̀ọ̀kan tèmi ní i ṣe, pẹ̀lú àkọ́bí gbogbo ohun ọ̀sìn rẹ, bóyá ti màlúù tàbí ti àgùntàn.
«تمام نخست‌زاده‌های نر گاو و گوسفند و بز شما به من تعلق دارند.
20 Àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni kí ìwọ kí ó fi ọ̀dọ́-àgùntàn rà padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, dá ọrùn rẹ̀. Ra gbogbo àkọ́bí ọkùnrin rẹ padà. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá síwájú mi ní ọwọ́ òfo.
در برابر نخست‌زادهٔ نر الاغ، یک بره به من تقدیم کنید و اگر نخواستید این کار را بکنید گردن الاغ را بشکنید. ولی برای تمام پسران ارشد خود حتماً باید فدیه دهید. «هیچ‌کس نباید با دست خالی به حضور من حاضر شود.
21 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ keje ìwọ yóò sinmi; kódà ní àkókò ìfúnrúgbìn àti ní àkókò ìkórè ìwọ gbọdọ̀ sinmi.
«فقط شش روز کار کنید و در روز هفتم استراحت نمایید، حتی در فصل شخم و فصل درو.
22 “Ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ pẹ̀lú àkọ́so èso alikama àti àjọ ìkórè ní òpin ọdún.
«عید هفته‌ها را که همان عید نوبر محصول گندم است، برگزار کن و همچنین عید جمع‌آوری را به هنگام تحویل سال.
23 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún, gbogbo àwọn ọkùnrin ni kí ó farahàn níwájú Olúwa Olódùmarè, Ọlọ́run Israẹli.
«سالی سه بار تمام مردان و پسران قوم اسرائیل باید برای عبادت به حضور خداوند، خدای اسرائیل بیایند.
24 Èmi yóò lé orílẹ̀-èdè jáde níwájú rẹ, Èmi yóò sì mú kí ìpín rẹ fẹ̀, ẹnikẹ́ni kì yóò gba ilẹ̀ rẹ nígbà tí ìwọ bá gòkè lọ ní ìgbà mẹ́ta lọ́dún kọ̀ọ̀kan láti farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
در این سه مرتبه‌ای که به حضور یهوه خدایتان می‌آیید، کسی دست طمع به سوی سرزمین شما دراز نخواهد کرد، زیرا تمام قبایل بیگانه را از میان شما بیرون می‌رانم و حدود سرزمین شما را وسیع می‌گردانم.
25 “Má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sí mi pẹ̀lú ohunkóhun tí ó bá ní ìwúkàrà, kí o má sì ṣe jẹ́ kí ẹbọ ìrékọjá kù títí di òwúrọ̀.
«خون قربانی را هرگز همراه با نان خمیرمایه‌دار به حضور من تقدیم نکنید و از گوشت برهٔ عید پِسَح تا صبح چیزی باقی نگذارید.
26 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.”
«بهترین نوبر هر محصولی را که درو می‌کنید، به خانهٔ یهوه خدایتان بیاورید. «بزغاله را در شیر مادرش نپزید.»
27 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Èmi bá ìwọ àti Israẹli dá májẹ̀mú.”
خداوند به موسی فرمود: «این قوانین را بنویس، چون عهد خود را بر اساس این قوانین با تو و با قوم اسرائیل بسته‌ام.»
28 Mose wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru láìjẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.
موسی چهل شبانه روز بالای کوه در حضور خداوند بود. در آن مدت نه چیزی خورد و نه چیزی آشامید. در آن روزها بود که خداوند ده فرمان را روی دو لوح سنگی نوشت.
29 Nígbà tí Mose sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè Sinai pẹ̀lú wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀, òun kò mọ̀ pé ojú òun ń dán nítorí ó bá Olúwa sọ̀rọ̀.
وقتی موسی با دو لوح سنگی که بر آن مُفاد عهد نوشته شده بود، از کوه سینا فرود آمد، خبر نداشت که چهره‌اش بر اثر گفتگو با خدا می‌درخشید.
30 Nígbà tí Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí Mose, ojú rẹ̀ ń dán, ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti súnmọ́ ọn.
پس وقتی هارون و بنی‌اسرائیل موسی را با آن صورت نورانی دیدند، ترسیدند به او نزدیک شوند.
31 Ṣùgbọ́n Mose pè wọn; Aaroni àti gbogbo àwọn olórí àjọ padà wá bá a, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀.
ولی موسی ایشان را به نزد خود خواند. آنگاه هارون و بزرگان قوم نزد او آمدند و موسی با ایشان سخن گفت.
32 Lẹ́yìn èyí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli súnmọ́ ọn, ó sì fún wọn ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún un lórí òkè Sinai.
سپس تمام مردم نزد او آمدند و موسی دستورهایی را که خداوند در بالای کوه به او داده بود، به ایشان بازگفت.
33 Nígbà tí Mose parí ọ̀rọ̀ sísọ fún wọn. Ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
موسی پس از آنکه سخنانش تمام شد، نقابی بر صورت خود کشید.
34 Ṣùgbọ́n nígbàkígbà tí Mose bá wà níwájú Olúwa láti bá a sọ̀rọ̀, á ṣí ìbòjú náà títí yóò fi jáde. Nígbà tí ó bá sì jáde, á sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli ohun tí a ti pàṣẹ fún un,
هر وقت موسی به خیمهٔ ملاقات می‌رفت تا با خداوند گفتگو کند، نقاب را از صورتش بر می‌داشت. وقتی از خیمه بیرون می‌آمد هر چه از خداوند شنیده بود برای قوم بازگو می‌کرد،
35 àwọn ọmọ Israẹli sì rí i pé ojú rẹ̀ ń dán. Mose á sì tún fi ìbòjú bo ojú rẹ̀ títí á fi lọ bá Olúwa sọ̀rọ̀.
و مردم صورت او را که می‌درخشید، می‌دیدند. سپس او نقاب را دوباره به صورت خود می‌کشید و نقاب بر صورت او بود تا وقتی که باز برای گفتگو با خداوند به خیمهٔ عبادت داخل می‌شد.

< Exodus 34 >