< Exodus 34 >
1 Olúwa sọ fún Mose pé, “E gé òkúta wàláà méjì jáde bí i ti àkọ́kọ́, Èmi yóò sì kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé tó wà lára tí àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fọ́ sára wọn.
Tad Tas Kungs sacīja uz Mozu: izcērt divus akmens galdiņus tā kā tos pirmajus, tad Es uz tiem galdiņiem rakstīšu tos vārdus, kas ir bijuši uz tiem pirmajiem galdiņiem, ko tu esi salauzis.
2 Múra ní òwúrọ̀, kí o sì wá sórí òkè Sinai. Kí o fi ara rẹ hàn mí lórí òkè náà.
Un rītu esi gatavs, ka tu rītu vari kāpt uz Sinaī kalnu, un stājies Manā priekšā tur kalna galā.
3 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá pẹ̀lú rẹ tàbí kí a rí wọn lórí òkè náà; bẹ́ẹ̀ ni agbo àgùntàn tàbí ọwọ́ ẹran kó má ṣe jẹ níwájú òkè náà.”
Un nevienam nebūs kāpt līdz ar tevi augšā, nevienam arī nebūs tapt redzētam pa visu to kalnu, arī nedz sīkus, nedz lielus lopus nebūs ganīt tam kalnam pretī.
4 Bẹ́ẹ̀ Mose sì gbẹ́ òkúta wàláà méjì bí ti àkọ́kọ́, ó sì gun orí òkè Sinai lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un; Ó sì gbé òkúta wàláà méjèèjì náà sí ọwọ́ rẹ̀.
Tad Mozus izcirta divus akmens galdiņus tā kā tos pirmajus un cēlās no rīta agri un kāpa augšam uz Sinaī kalnu, kā Tas Kungs viņam bija pavēlējis; un viņš ņēma savā rokā tos divus akmens galdiņus.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọsánmọ̀, ó sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pòkìkí orúkọ Olúwa.
Tad Tas Kungs nonāca padebesī, un tur piestājās pie viņa un izsauca Tā Kunga vārdu.
6 Ó sì kọjá níwájú Mose, ó sì ń ké pé, “Olúwa, Olúwa, Ọlọ́run aláàánú àti olóore-ọ̀fẹ́, Ẹni tí ó lọ́ra láti bínú, tí ó pọ̀ ní ìfẹ́ àti olóòtítọ́,
Un Tas Kungs gāja viņam garām un izsauca: Tas Kungs, Dievs ir žēlīgs un sirdsmīlīgs Dievs, lēnprātīgs un liels no žēlastības un uzticības,
7 Ẹni tí ó ń pa ìfẹ́ mọ́ fún ẹgbẹ̀rún, ó sì ń dáríjì àwọn ẹni búburú, àwọn ti ń ṣọ̀tẹ̀ àti ẹlẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀ kì í fi àwọn ẹlẹ́bi sílẹ̀ láìjìyà; Ó ń fi ìyà jẹ ọmọ àti àwọn ọmọ wọn fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba dé ìran kẹta àti ẹ̀kẹrin.”
Kas parāda žēlastību daudz tūkstošiem, piedod noziegumus, pārkāpumus un grēkus, bet arī nepamet nesodītus, piemeklēdams tēvu grēkus pie bērniem un bērnu bērniem līdz trešam un ceturtam augumam.
8 Mose foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn.
Un Mozus traucās un metās zemē un pielūdza,
9 Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojúrere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jì, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”
Un sacīja: Kungs, ja esmu atradis žēlastību Tavās acīs, tad lūdzams, ej jel, Kungs, līdz ar mums, jebšu šie ir pārgalvīgi ļaudis, - ka Tu piedod mūsu noziegumus un mūsu grēkus, un pieņem mūs par Savu īpašumu.
10 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ Èmi yóò ṣe ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀-èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrín wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí Èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó.
Tad Viņš sacīja: redzi, Es daru derību: priekš visiem taviem ļaudīm Es darīšu brīnumus, kas nav darīti nekur pa zemes virsu, nedz pie kādām tautām, tā ka visiem ļaudīm, starp kuriem tu esi, būs redzēt Tā Kunga darbu, jo tās būs ļoti bijājamas lietas, ko Es pie tevis darīšu.
11 Ṣe ohun tí Èmi pàṣẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Amori, àwọn ará Kenaani, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hiti, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde níwájú rẹ.
Ņem vērā, ko Es tev šodien pavēlu: redzi, Es izdzīšu tavā priekšā Amoriešus un Kanaāniešus un Hetiešus un Fereziešus un Hiviešus un Jebusiešus,
12 Máa ṣọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ̀ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdẹwò láàrín rẹ.
Sargies, ka tu nedari derību ar tās zemes iedzīvotājiem, pie kuriem tu nāksi, ka tie nekļūst tavā starpā par slazda valgu.
13 Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Aṣerah wọn. (Ère òrìṣà wọn.)
Bet jums būs izpostīt viņu altārus un jums būs salauzīt viņu uzceltos stabus un nocirst viņu elku kokus.
14 Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ Òjòwú, Ọlọ́run owú ni.
Jo tev nebūs pielūgt nekādu citu dievu, - jo Tas Kungs: dusmotājs ir Viņa vārds, Viņš ir dusmīgs Dievs,
15 “Máa ṣọ́ra kí ẹ má ṣe bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà dá májẹ̀mú; nígbà tí wọ́n bá ń ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, tí wọ́n sì rú ẹbọ sí wọn, wọn yóò pè yín, ẹ̀yin yóò sì jẹ ẹbọ wọn.
Ka tu nedari nekādu derību ar tās zemes iedzīvotājiem, un kad tie saviem dieviem mauko pakaļ un nes upurus saviem dieviem, ka tie tevi neaicina, un tu neēdi no viņu upuriem,
16 Nígbà tí ìwọ bá yàn nínú àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ ní ìyàwó, àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí yóò ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, wọn yóò sì mú kí àwọn ọmọkùnrin yín náà ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
Un ka tu saviem dēliem neņem no viņu meitām, un viņu meitas saviem dieviem nemauko pakaļ un nedara arī tavus dēlus pakaļ maukojam viņu dieviem.
17 “Ìwọ kò gbọdọ̀ dá ère òrìṣàkórìṣà fún ara rẹ.
Tev nebūs sev taisīt lietus dievus.
18 “Àjọ àkàrà àìwú ni kí ìwọ máa pamọ́. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò jẹ àkàrà aláìwú, gẹ́gẹ́ bí Èmi ti pa á láṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní ìgbà tí a yàn nínú oṣù Abibu, nítorí ní oṣù náà ni ẹ jáde láti Ejibiti wá.
Tev būs turēt neraudzētās maizes svētkus; septiņas dienas tev būs ēst neraudzētu maizi, kā Es tev esmu pavēlējis, noliktā laikā Abiba mēnesī; jo Abiba mēnesī tu esi izgājis no Ēģiptes zemes.
19 “Gbogbo àkọ́bí inú kọ̀ọ̀kan tèmi ní i ṣe, pẹ̀lú àkọ́bí gbogbo ohun ọ̀sìn rẹ, bóyá ti màlúù tàbí ti àgùntàn.
Viss, kas māti atplēš, Man pieder, un visi tavi lopi, kas no tēviņu kārtas piedzimst, māti atplēsdami, lai lieli, lai sīki.
20 Àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni kí ìwọ kí ó fi ọ̀dọ́-àgùntàn rà padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, dá ọrùn rẹ̀. Ra gbogbo àkọ́bí ọkùnrin rẹ padà. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá síwájú mi ní ọwọ́ òfo.
Bet ēzeli, kas ēzeļa māti atplēš, tev būs izpirkt ar avi; bet ja tu to neizpirksi, tad lauz viņam kaklu. Visus pirmdzimušos no taviem dēliem tev būs izpirkt, un priekš Mana vaiga jums nebūs rādīties tukšiem.
21 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ keje ìwọ yóò sinmi; kódà ní àkókò ìfúnrúgbìn àti ní àkókò ìkórè ìwọ gbọdọ̀ sinmi.
Sešas dienas tev būs strādāt, bet septītā dienā dusēt, arī aramā un pļaujamā laikā tev būs dusēt.
22 “Ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ pẹ̀lú àkọ́so èso alikama àti àjọ ìkórè ní òpin ọdún.
Nedēļu svētkus arīdzan tev būs turēt ar kviešu pļaujas pirmajiem augļiem un pļaušanas svētkus, kad gads pagalam.
23 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún, gbogbo àwọn ọkùnrin ni kí ó farahàn níwájú Olúwa Olódùmarè, Ọlọ́run Israẹli.
Trīs reiz gadskārtā visiem, kas jūsu starpā ir vīrieši, būs rādīties Tā Kunga Dieva, Israēla Dieva priekšā.
24 Èmi yóò lé orílẹ̀-èdè jáde níwájú rẹ, Èmi yóò sì mú kí ìpín rẹ fẹ̀, ẹnikẹ́ni kì yóò gba ilẹ̀ rẹ nígbà tí ìwọ bá gòkè lọ ní ìgbà mẹ́ta lọ́dún kọ̀ọ̀kan láti farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Kad Es tos pagānus izdzīšu tavā priekšā, un izpletīšu tavas robežas, tad neviens tavu zemi neiekāros, kamēr tu iesi rādīties Tā Kunga, sava Dieva priekšā, trīs reiz gadskārtā.
25 “Má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sí mi pẹ̀lú ohunkóhun tí ó bá ní ìwúkàrà, kí o má sì ṣe jẹ́ kí ẹbọ ìrékọjá kù títí di òwúrọ̀.
Tev nebūs upurēt Mana upura asinis ar raudzētu maizi, un Pasa svētku upurim nebūs palikt cauru nakti līdz rītam.
26 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.”
Tos pirmajus no tavas zemes pirmajiem augļiem tev būs nest Tā Kunga tava Dieva, namā; āzīti tev nebūs vārīt viņa mātes pienā.
27 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Èmi bá ìwọ àti Israẹli dá májẹ̀mú.”
Un Tas Kungs sacīja uz Mozu: “Raksti šos vārdus, jo pēc šiem vārdiem Es esmu darījis derību ar tevi un ar Israēli.”
28 Mose wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru láìjẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.
Un viņš tur bija pie Tā Kunga četrdesmit dienas un četrdesmit naktis; viņš neēda maizes un nedzēra ūdens, un rakstīja uz tiem galdiņiem tos derības vārdus, tos desmit vārdus.
29 Nígbà tí Mose sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè Sinai pẹ̀lú wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀, òun kò mọ̀ pé ojú òun ń dán nítorí ó bá Olúwa sọ̀rọ̀.
Un notikās, kad Mozus nokāpa no Sinaī kalna un tie divi liecības galdiņi bija Mozus rokā, tad no tā kalna nokāpjot Mozus nezināja, ka viņa vaiga āda spīdēja, tādēļ ka tas ar Viņu bija runājis.
30 Nígbà tí Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí Mose, ojú rẹ̀ ń dán, ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti súnmọ́ ọn.
Kad nu Ārons un visi Israēla bērni Mozu uzlūkoja, redzi, tad viņa vaiga āda spīdēja, tāpēc tie bijās nākt tuvu pie viņa.
31 Ṣùgbọ́n Mose pè wọn; Aaroni àti gbogbo àwọn olórí àjọ padà wá bá a, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀.
Tad Mozus tos sauca un Ārons un visi draudzes virsnieki griezās pie viņa un Mozus uz tiem runāja.
32 Lẹ́yìn èyí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli súnmọ́ ọn, ó sì fún wọn ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún un lórí òkè Sinai.
Pēc tam visi Israēla bērni piegāja, un viņš tiem visu pavēlēja, ko Tas Kungs ar viņu bija runājis Sinaī kalnā.
33 Nígbà tí Mose parí ọ̀rọ̀ sísọ fún wọn. Ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
Un kad Mozus beidza ar tiem runāt, tad viņš lika apsegu uz savu vaigu.
34 Ṣùgbọ́n nígbàkígbà tí Mose bá wà níwájú Olúwa láti bá a sọ̀rọ̀, á ṣí ìbòjú náà títí yóò fi jáde. Nígbà tí ó bá sì jáde, á sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli ohun tí a ti pàṣẹ fún un,
Bet kad Mozus priekš Tā Kunga nāca ar Viņu runāt, tad tas noņēma to apsegu, tiekams tas izgāja, un kad tas bija izgājis, tad tas runāja uz Israēla bērniem, kas tam bija pavēlēts.
35 àwọn ọmọ Israẹli sì rí i pé ojú rẹ̀ ń dán. Mose á sì tún fi ìbòjú bo ojú rẹ̀ títí á fi lọ bá Olúwa sọ̀rọ̀.
Un Israēla bērni redzēja Mozus vaigu, ka Mozus vaiga āda spīdēja, un tad Mozus to apsegu atkal uzlika uz savu vaigu, tiekams tas iegāja ar Viņu runāt.