< Exodus 33 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fi ìhín yìí sílẹ̀, ìwọ àti àwọn ènìyàn tí o mú gòkè láti Ejibiti wá, kí ẹ sì gòkè lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ti pinnu ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu wí pé, ‘Èmi yóò fi fún irú-ọmọ rẹ.’
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Pleacă și urcă de aici, tu și poporul pe care l-ai scos din țara Egiptului, la țara pe care am jurat-o lui Avraam, lui Isaac și lui Iacob, spunând: Seminței tale o voi da,
2 Èmi yóò rán angẹli ṣáájú yín, Èmi yóò sì lé àwọn Kenaani, àwọn ará Amori, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde.
Și voi trimite un înger înaintea ta; și voi alunga pe canaanit, pe amorit, pe hitit și pe perizit, pe hivit și pe iebusit:
3 Ẹ gòkè lọ sí ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin. Ṣùgbọ́n èmi kò ní lọ pẹ̀lú yín, nítorí ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ̀yin, kí èmi má ba à run yín ní ọ̀nà.”
La o țară în care curge lapte și miere, căci nu mă voi urca în mijlocul tău ca nu cumva eu să te mistui pe cale, pentru că tu ești un popor îndărătnic.
4 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ọ̀rọ̀ ìparun wọ̀nyí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì ní kùn, ẹnìkankan kò sì le è wọ ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀.
Și după ce poporul a auzit aceste vești rele, au jelit; și nimeni nu a pus pe el podoabele sale.
5 Nítorí Olúwa ti wí fún Mose pé, “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ènìyàn Ọlọ́rùn líle ní ẹ̀yin, bí Èmi bá lè wá sí àárín yín ni ìṣẹ́jú kan, Èmi lè pa yín run. Nísìnsinyìí, bọ́ ohun ọ̀ṣọ́ rẹ kúrò, Èmi yóò sì gbèrò ohun tí Èmi yóò ṣe pẹ̀lú rẹ.’”
Pentru că DOMNUL i-a spus lui Moise: Spune copiilor lui Israel: Voi sunteți un popor îndărătnic: dintr-odată mă voi urca în mijlocul tău și te voi mistui; de aceea acum scoate podoabele tale de pe tine, ca să știu ce să îți fac.
6 Bẹ́ẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bọ́ ohun ọ̀ṣọ́ wọn kúrò lára wọn ní òkè Horebu.
Și copiii lui Israel și-au scos podoabele lor la muntele Horeb.
7 Mose máa ń gbé àgọ́ náà, ó sì pa á sí ìta ibùdó, ó jìnnà díẹ̀ sí ibùdó, ó pè é ni “Àgọ́ àjọ.” Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń béèrè Olúwa yóò lọ sí ibi àgọ́ àjọ náà ní ìta ibùdó.
Și Moise a luat tabernacolul și l-a ridicat în afara taberei, departe de tabără și l-a chemat Tabernacolul întâlnirii. Și s-a întâmplat că oricine căuta pe DOMNUL ieșea afară la tabernacolul întâlnirii, care era în afara taberei.
8 Nígbàkígbà tí Mose bá jáde lọ sí ibi àgọ́, gbogbo ènìyàn á dìde, wọ́n á sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn, wọn yóò máa wo Mose títí yóò fi wọ inú àgọ́ náà.
Și s-a întâmplat, după ce Moise a ieșit afară la tabernacol, că tot poporul s-a sculat și fiecare bărbat a stat în picioare la ușa cortului său și s-au uitat după Moise, până ce a intrat în tabernacol.
9 Bí Mose ṣe wọ inú àgọ́ náà, ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀ yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì dúró sí ẹnu ọnà, nígbà tí Olúwa ń sọ̀rọ̀ pẹ̀lú Mose.
Și s-a întâmplat că, pe când Moise a intrat în tabernacol, coloana de nor a coborât și a stat la ușa tabernacolului și DOMNUL a vorbit cu Moise.
10 Nígbàkígbà tí àwọn ènìyàn bá rí i ti ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀ bá dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, gbogbo wọn yóò dìde wọn yóò sì sìn, olúkúlùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀.
Și tot poporul a văzut coloana de nor stând la ușa tabernacolului; și tot poporul s-a ridicat și s-a închinat, fiecare bărbat în ușa cortului său.
11 Olúwa máa ń bá Mose sọ̀rọ̀ lójúkojú, gẹ́gẹ́ bí i pé ènìyàn ń bá ọ̀rẹ́ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nígbà náà ni Mose yóò tún padà lọ sí ibùdó, ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọkùnrin Joṣua ìránṣẹ́ rẹ̀ ọmọ Nuni kò fi àgọ́ sílẹ̀.
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise față în față, așa cum un bărbat vorbește prietenului său. Și el s-a întors din nou în tabără; dar servitorul său, Iosua, fiul lui Nun, un tânăr, nu s-a depărtat de tabernacol.
12 Mose sọ fún Olúwa pé, “Ìwọ ti ń sọ fún mi, ‘Darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,’ ṣùgbọ́n ìwọ kò jẹ́ kí ń mọ ẹni tí ìwọ yóò rán pẹ̀lú mi. Ìwọ ti wí pé, ‘Èmi mọ̀ ọ́n nípa orúkọ, ìwọ sì ti rí ojúrere mi pẹ̀lú.’
Și Moise a spus DOMNULUI: Vezi, îmi spui: Adu acest popor; și nu mă lași să știu pe cine vei trimite cu mine. Totuși ai spus: Te cunosc pe nume și de asemenea ai găsit har înaintea ochilor mei.
13 Bí ìwọ bá ní inú dídùn pẹ̀lú mi, kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, kí èmi kí ó lè mọ̀ ọ́n, kí n sì le máa wá ojúrere rẹ pẹ̀lú. Rántí wí pé orílẹ̀-èdè yìí ènìyàn rẹ ni.”
Și acum, te rog, dacă am găsit har înaintea ochilor tăi, arată-mi acum calea ta, ca să te cunosc, ca să găsesc har înaintea ochilor tăi; și ai în vedere că această națiune este poporul tău.
14 Olúwa dáhùn wí pé, “Ojú mi yóò máa bá ọ lọ, Èmi yóò sì fún ọ ní ìsinmi.”
Și a spus: Prezența mea va merge cu tine și îți voi da odihnă.
15 Nígbà náà ni, Mose wí fún un pé, “Bí ojú rẹ kò bá bá wa lọ, má ṣe rán wa gòkè láti ìhín lọ.
Iar el i-a spus: Dacă prezența ta nu merge cu mine, nu ne urca de aici.
16 Báwo ni ẹnikẹ́ni yóò ṣe mọ̀ pé inú rẹ dùn pẹ̀lú mi àti pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ àyàfi ti o bá bá wa lọ? Kí ni yóò lè yà mí àti àwọn ènìyàn rẹ kúrò lára gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé?”
Căci în ce va fi cunoscut aici că eu și poporul tău am găsit har înaintea ochilor tăi? Nu este în aceea că mergi cu noi? Astfel vom fi separați, eu și poporul tău, dintre toate popoarele care sunt pe fața pământului.
17 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi yóò ṣe ohun gbogbo tí ìwọ ti béèrè, nítorí inú mi dún sí o, Èmi sì mọ̀ ọ́n nípa orúkọ rẹ̀.”
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Voi face și lucrul acesta pe care l-ai vorbit, pentru că ai găsit har înaintea ochilor mei și te cunosc pe nume.
18 Mose sì wí pé, “Nísinsin yìí fi ògo rẹ hàn mí.”
Iar el a spus: Te implor, arată-mi gloria ta.
19 Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò sì mú gbogbo ìre mí kọjá níwájú rẹ, Èmi yóò sì pòkìkí orúkọ Olúwa níwájú rẹ. Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí Èmi yóò ṣàánú fún, Èmi yóò sì ṣoore-ọ̀fẹ́ fún ẹni tí Èmi yóò ṣoore-ọ̀fẹ́ fún.
Iar el a spus: Voi face ca toată bunătatea mea să treacă pe dinaintea ta și voi vesti numele DOMNULUI înaintea ta; și voi avea har fața de cine voi avea har și voi arăta milă cui voi arăta milă.
20 Ṣùgbọ́n,” ó wí pé, “Ìwọ kò le è rí ojú mi, nítorí kò sí ènìyàn kan tí ń rí mi, tí ó lè yè.”
Și a mai spus: Nu poți vedea fața mea, căci niciun om nu mă va vedea și după aceea să trăiască.
21 Olúwa sì wí pé, “Ibìkan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀dọ̀ mi, níbi tí o ti lè dúró lórí àpáta.
Și DOMNUL a spus: Iată, este un loc lângă mine și stai în picioare pe stâncă;
22 Nígbà tí ògo mi bá kọjá, Èmi yóò gbé ọ sínú pàlàpálá àpáta, Èmi yóò sì bò ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ mi títí Èmi yóò fi rékọjá.
Și se va întâmpla, în timp ce gloria mea trece pe lângă tine, că te voi pune într-o crăpătură a stâncii și te voi acoperi cu mâna mea în timp ce trec pe lângă tine;
23 Nígbà tí Èmi yóò mú ọwọ́ mi kúrò, ìwọ yóò sì rí ẹ̀yìn mi; ṣùgbọ́n ojú mi ni o kò ní rí.”
Și îmi voi retrage mâna și vei vedea părțile mele din spate, dar fața mea nu se va vedea.

< Exodus 33 >