< Exodus 33 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fi ìhín yìí sílẹ̀, ìwọ àti àwọn ènìyàn tí o mú gòkè láti Ejibiti wá, kí ẹ sì gòkè lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ti pinnu ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu wí pé, ‘Èmi yóò fi fún irú-ọmọ rẹ.’
OLELO mai la o Iehova ia Mose, o hele, e pii aku, o oe a me na kanaka au i alakai mai nei, mai ka aina o Aigupita mai, a i ka aina a'u i hoohiki ai ia Aberahama, a ia Isaaka, a ia Iakoba, i ka i ana iho, Ke haawi nei au ia na kau poe mamo.
2 Èmi yóò rán angẹli ṣáájú yín, Èmi yóò sì lé àwọn Kenaani, àwọn ará Amori, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde.
A e hoouna aku au i ko'u anela imua ou; a na'u no e kipaku aku i ka Kanaana, i ka Amora, i ka Heta, i ka Pereza, i ka Heva, a i ka Iebusa;
3 Ẹ gòkè lọ sí ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin. Ṣùgbọ́n èmi kò ní lọ pẹ̀lú yín, nítorí ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ̀yin, kí èmi má ba à run yín ní ọ̀nà.”
A i ka aina e kahe ana o ka waiu a me ka mele; no ka mea, aole au e pii aku iwaena ou, no ka mea, he poe kanaka a-i oolea oukou; o hoopau auanei au ia oe ma ke ala.
4 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ọ̀rọ̀ ìparun wọ̀nyí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì ní kùn, ẹnìkankan kò sì le è wọ ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀.
A lohe na kanaka i keia olelo o ka hewa, uwe iho la lakou, aohe kanaka i hookomo i kona kahiko ana.
5 Nítorí Olúwa ti wí fún Mose pé, “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ènìyàn Ọlọ́rùn líle ní ẹ̀yin, bí Èmi bá lè wá sí àárín yín ni ìṣẹ́jú kan, Èmi lè pa yín run. Nísìnsinyìí, bọ́ ohun ọ̀ṣọ́ rẹ kúrò, Èmi yóò sì gbèrò ohun tí Èmi yóò ṣe pẹ̀lú rẹ.’”
No ka mea, ua olelo mai o Iehova ia Mose, E i aku oe i na mamo a Iseraela, He poe kanaka a-i oolea oukou: i ka minute hookahi, e pii aku no au iwaena konu ou, a e hoopau ia oe, Nolaila, e wehe oe i kou kahiko ana mai ou aku la, i ike au i ka mea e hana aku ai ia oe.
6 Bẹ́ẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bọ́ ohun ọ̀ṣọ́ wọn kúrò lára wọn ní òkè Horebu.
A wehe na mamo a Iseraela i ko lakou kahiko ana, ma ka mauna o Horeba.
7 Mose máa ń gbé àgọ́ náà, ó sì pa á sí ìta ibùdó, ó jìnnà díẹ̀ sí ibùdó, ó pè é ni “Àgọ́ àjọ.” Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń béèrè Olúwa yóò lọ sí ibi àgọ́ àjọ náà ní ìta ibùdó.
A lawe ae la o Mose i ka halelewa, a kukulu iho la mawaho o kahi e hoomoana'i, ma kahi mamao aku o ke kahua i hoomoana'i; a kapa ae la oia ia mea, o ka Halelewa o ke anaina kanaka. A o kela mea keia mea i imi ia Iehova, hele aku la ia iwaho i ka halelewa o ke anaina kanaka, ka mea mawaho o kahi i hoomoana'i.
8 Nígbàkígbà tí Mose bá jáde lọ sí ibi àgọ́, gbogbo ènìyàn á dìde, wọ́n á sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn, wọn yóò máa wo Mose títí yóò fi wọ inú àgọ́ náà.
A i ka hele ana aku o Mose i ka halelewa, ala ae la na kanaka a pau iluna, a ku no kela kanaka keia kanaka ma ka puka o kona halelewa, a nana aku la mahope o Mose, a hala ia iloko o ka halelewa.
9 Bí Mose ṣe wọ inú àgọ́ náà, ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀ yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì dúró sí ẹnu ọnà, nígbà tí Olúwa ń sọ̀rọ̀ pẹ̀lú Mose.
A i ko Mose komo ana iloko o ka halelewa, iho mai la ke kia ao, a ku ma ka puka o ka halelewa, a kamailio mai la [o Iehova] me Mose.
10 Nígbàkígbà tí àwọn ènìyàn bá rí i ti ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀ bá dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, gbogbo wọn yóò dìde wọn yóò sì sìn, olúkúlùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀.
A ike ae la na kanaka a pau i ke kia ao e ku ana ma ka puka o ka halelewa, a ku ae la na Kanaka a pau iluna, a hoomana aku la, o kela kanaka keia kanaka ma ka puka o kona halelewa.
11 Olúwa máa ń bá Mose sọ̀rọ̀ lójúkojú, gẹ́gẹ́ bí i pé ènìyàn ń bá ọ̀rẹ́ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nígbà náà ni Mose yóò tún padà lọ sí ibùdó, ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọkùnrin Joṣua ìránṣẹ́ rẹ̀ ọmọ Nuni kò fi àgọ́ sílẹ̀.
A kamailio mai la o Iehova ia Mose, he maka no he maka, e like me ke kamailio ana o ke kanaka me kona hoa. A hoi aku la ia iloko o kahi e hoomoana'i, a me kana kauwa, o Iosua, ke keiki a Nuna, he kanaka opiopio; aka, aole ia i hele iwaho o ka halelewa.
12 Mose sọ fún Olúwa pé, “Ìwọ ti ń sọ fún mi, ‘Darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,’ ṣùgbọ́n ìwọ kò jẹ́ kí ń mọ ẹni tí ìwọ yóò rán pẹ̀lú mi. Ìwọ ti wí pé, ‘Èmi mọ̀ ọ́n nípa orúkọ, ìwọ sì ti rí ojúrere mi pẹ̀lú.’
I aku la o Mose ia Iehova, E nana hoi, ke olelo mai nei oe ia'u, E kai mai oe i keia poe kanaka; aole nae oe i hoike mai ia'u i ka mea au e hoouna pu ai me au. Aka, na olelo mai no, Ua ike no wau ia oe ma ka inoa, a e loaa ia oe ka lokomaikaiia i ko'u mau maka.
13 Bí ìwọ bá ní inú dídùn pẹ̀lú mi, kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, kí èmi kí ó lè mọ̀ ọ́n, kí n sì le máa wá ojúrere rẹ pẹ̀lú. Rántí wí pé orílẹ̀-èdè yìí ènìyàn rẹ ni.”
Nolaila, ke nonoi aku nei au ia oe, ina i loaa ia'u ka lokomaikaiia i kou mau maka, e hoike mai oe ia'u i kou aoao, i ike aku au ia oe, i loaa ia'u ka lokomaikaiia i kou mau maka: a e hoomanao hoi, o kou aupuni no keia poe kanaka.
14 Olúwa dáhùn wí pé, “Ojú mi yóò máa bá ọ lọ, Èmi yóò sì fún ọ ní ìsinmi.”
I mai la keia, E hele pa ne ko'u maka, a na'u no oe e hoomaha aku.
15 Nígbà náà ni, Mose wí fún un pé, “Bí ojú rẹ kò bá bá wa lọ, má ṣe rán wa gòkè láti ìhín lọ.
I aka la keia, I ole e hele pu kou maka, mai lawe aku oe ia makou.
16 Báwo ni ẹnikẹ́ni yóò ṣe mọ̀ pé inú rẹ dùn pẹ̀lú mi àti pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ àyàfi ti o bá bá wa lọ? Kí ni yóò lè yà mí àti àwọn ènìyàn rẹ kúrò lára gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé?”
Mahea la e ikeia'i ua loaa ia'u a me kou poe kanaka ka lokomaikaiia i kou maka? Aole anei ma kou hele pu ana me makou? A pela makou e hookaawaleia'i, owau a me ko'u poe kanaka, mai na kanaka e aka a pau loa e noho ana maluna o ka honua.
17 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi yóò ṣe ohun gbogbo tí ìwọ ti béèrè, nítorí inú mi dún sí o, Èmi sì mọ̀ ọ́n nípa orúkọ rẹ̀.”
Olelo mai la o Iehova, ia Mose, E hana no hoi au i keia mea au i olelo mai ai; no ka mea, ua loaa ia oe ka lokomaikaiia i ko'u maka, a ua ike aka au ia oe ma ka inoa.
18 Mose sì wí pé, “Nísinsin yìí fi ògo rẹ hàn mí.”
A i aku la keia, Ke nonoi aku nei au ia oe, e hoike mai oe i kou nani ia'u.
19 Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò sì mú gbogbo ìre mí kọjá níwájú rẹ, Èmi yóò sì pòkìkí orúkọ Olúwa níwájú rẹ. Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí Èmi yóò ṣàánú fún, Èmi yóò sì ṣoore-ọ̀fẹ́ fún ẹni tí Èmi yóò ṣoore-ọ̀fẹ́ fún.
Olelo mai la ia, E hoohele au i ko'u maikai a pau imua o kou maka, a e hea aku au i ka inoa o Iehova imua o kou maka; a e lokomaikai aka au i ka mea a'u e manao ai e lokomaikai aku, a e aloha aku au i ka mea a'u e manao ai e aloha aka.
20 Ṣùgbọ́n,” ó wí pé, “Ìwọ kò le è rí ojú mi, nítorí kò sí ènìyàn kan tí ń rí mi, tí ó lè yè.”
A i mai la ia, Aole hiki ia oe ke ike mai i ko'u maka; no ka mea, aohe kanaka e ike mai ia'u, a ola.
21 Olúwa sì wí pé, “Ibìkan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀dọ̀ mi, níbi tí o ti lè dúró lórí àpáta.
A i mai la o Iehova, Aia kahi e kokoke ana ia'u, a e ku no oe maluna o ka pohaku.
22 Nígbà tí ògo mi bá kọjá, Èmi yóò gbé ọ sínú pàlàpálá àpáta, Èmi yóò sì bò ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ mi títí Èmi yóò fi rékọjá.
A i ka wa e hele ae ko'u nani, e hookomo no wau ia oe iloko o ka mauae o ka pohaku, a e uhi aku au ia oe i ko'u lima, ia'u e hele ana'e.
23 Nígbà tí Èmi yóò mú ọwọ́ mi kúrò, ìwọ yóò sì rí ẹ̀yìn mi; ṣùgbọ́n ojú mi ni o kò ní rí.”
A e lawe aku au i ko'u lima, a e ike mai oe i ko'u kua; aka, aole e ikeia ko'u maka.

< Exodus 33 >