< Exodus 32 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Mose pẹ́ kí ó tó sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè wá, wọn péjọ yí Aaroni ká, wọ́n sì wí pé, “Wá, dá òrìṣà tí yóò máa ṣáájú wa fún wa. Bí ó ṣe ti Mose tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá, àwa kò mọ́ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí i.”
І побачив наро́д, що загаявся Мойсей зійти з гори. І зібрався наро́д проти Аарона, та й сказали до нього: „Устань, зроби нам богі́в, що бу́дуть ходити перед нами, бо той Мойсей, муж, що вивів був нас із єгипетського кра́ю, — ми не знаємо, що сталось йому“.
2 Aaroni dá wọn lóhùn pé, “Ẹ bọ́ òrùka wúrà tí ó wà ní etí àwọn ìyàwó yín, tí àwọn ọmọkùnrin yín, àti tí àwọn ọmọbìnrin yín, kí ẹ sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi.”
І сказав їм Аарон „Поздіймайте золоті сере́жки, що в ушах ваших жінок, ваших синів та дочо́к ваших, і поприносьте до мене“.
3 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ènìyàn bọ́ òrùka etí wọn, wọn sì kó wọn wá fún Aaroni.
І ввесь наро́д поздіймав з себе золоті сережки, що в їхніх ушах, та й позно́сили до Аарона.
4 Ó sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ó sì fi ṣe ohun ọnà fínfín, ó sì dà á ní àwòrán ẹgbọrọ màlúù. Nígbà náà ni wọn wí pé, “Israẹli, wọ̀nyí ni òrìṣà, ti ó mú un yín jáde wá láti Ejibiti.”
І взяв він це з їхньої руки, і вформував його в глині, і зробив із нього лите теля. А вони сказали: „Оце твої боги, Ізраїлю, що вивели тебе з єгипетського кра́ю!“
5 Nígbà ti Aaroni rí èyí, ó kọ́ pẹpẹ kan níwájú ẹgbọrọ màlúù náà, ó sì kéde pé, “Lọ́la ni àjọyọ̀ sí Olúwa.”
І побачив це Аарон, і збудував жертівника перед ним. І кликнув Аарон та й сказав: „Завтра свято для Господа!“
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn dìde ní kùtùkùtù ọjọ́ kejì, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n sì mú ẹbọ àlàáfíà wá. Lẹ́yìn náà wọ́n jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde láti ṣeré.
І повставали вони взавтра ра́но вранці, і принесли цілопа́лення, і привели́ мирну жертву. І засів наро́д до їди́ та до пиття́, і встали ба́витися.
7 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, nítorí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú gòkè wá láti Ejibiti, wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀.
А Господь промовляв до Мойсея: „Іди, зійди, бо зіпсувся наро́д твій, якого ти вивів із єгипетського краю.
8 Wọ́n ti yí kánkán kúrò nípa ọ̀nà tí mo ti mo pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì ti dá ère ẹgbọrọ màlúù fún ara wọn. Wọ́n ti foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì ti rú ẹbọ sí i, wọ́n sì ti sọ pé, ‘Israẹli wọ̀nyí ní òrìṣà tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.’”
Зійшли вони скоро з дороги, що наказав був Я їм, — зробили собі лите теля, і поклонились йому, і склали йому́ жертви, та й сказали: Оце твої боги, Ізраїлю, що вивели тебе з єгипетського краю!“
9 Olúwa wí fún Mose pé, “Èmi ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, wọ́n sì jẹ́ ọlọ́rùn líle ènìyàn.
І промовив Господь до Мойсея: „Я бачив наро́д той, і ось наро́д — твердошиїй він!
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí fi mí sílẹ̀, nítorí kí ìbínú mi lè gbóná sí wọn, kí Èmi sì lè pa wọ́n run. Nígbà náà ni Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.”
А тепер залиши Мене, — і розпа́литься гнів Мій на них, і Я ви́нищу їх, а тебе зроблю́ великим наро́дом“.
11 Ṣùgbọ́n Mose kígbe fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìbínú rẹ yóò ṣe gbóná sí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú jáde láti Ejibiti wá pẹ̀lú agbára ńlá àti ọwọ́ agbára?
І Мойсей став благати лице Господа, Бога свого, та й сказав: „На́що, Господи, розпа́люється гнів Твій на народ Твій, якого Ти випровадив з єгипетського кра́ю силою великою та міцно́ю рукою?
12 Èéṣe tí àwọn ará Ejibiti yóò ṣe wí pé, ‘Nítorí ibi ni ó ṣe mọ̀ ọ́n mọ̀ mú wọn jáde, láti pa wọ́n ní orí òkè àti láti gbá wọn kúrò lórí ayé’? Yípadà kúrò nínú ìbínú rẹ tí ó múná, yí ọkàn padà, kí o má sì ṣe mú ìparun wá sórí àwọn ènìyàn rẹ.
На́що будуть казати єги́птяни, говорячи: На зле ти їх вивів, щоб їх повбивати в гора́х, та щоб винищити їх з пове́рхні землі?. Вернися з ро́зпалу гніву Свого, та й відверни́ зло від Свого́ наро́ду!
13 Rántí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, ẹni tí ìwọ búra fún fúnra rẹ̀, ‘Tí o wí fún wọn pé, Èmi yóò mú irú-ọmọ rẹ pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, Èmi yóò sì fún irú-ọmọ rẹ ní gbogbo ilẹ̀ tí mo ti pinnu fún wọn, yóò sì jẹ́ ogún ìní wọn láéláé.’”
Згадай про Авраама, Ісака та Ізраїля, рабів Своїх, що Ти їм присягався був Собою, та говорив їм: „Помно́жу ваших наща́дків, немов зорі небесні, і всю оту землю, що про неї казав, дам вашим наща́дкам, — і вони пося́дуть навіки“.
14 Nígbà náà ni Olúwa dáwọ́ ìbínú rẹ̀ dúró, kò sì mú ìparun náà tí ó sọ wá sórí àwọn ènìyàn rẹ̀ mọ́.
І відверну́в Господь зло, про яке говорив, щоб зробити Своєму народо́ві.
15 Mose sì yípadà, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà pẹ̀lú òkúta wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀. Wọ́n kọ ìwé síhà méjèèjì, iwájú àti ẹ̀yin.
І повернувся, і зійшов Мойсей із гори, — а в руці його дві табли́ці свідо́цтва, писані з обох їхніх сторін, — звідси й звідти вони були́ писані.
16 Iṣẹ́ Ọlọ́run sì ni wàláà náà; ìkọ̀wé náà jẹ́ ìkọ̀wé Ọlọ́run, a fín in sára àwọn òkúta wàláà náà.
А табли́ці — Божа робота вони, а письмо — Боже письмо воно, ви́різьблене на табли́цях.
17 Nígbà tí Joṣua gbọ́ ariwo àwọn ènìyàn tí wọ́n ń kígbe, ó sọ fún Mose pé, “Ariwo ogun wà nínú àgọ́.”
І почув Ісус голос наро́ду, як кричав він, та й сказав до Мойсея: „Крик бо́ю в табо́рі!“
18 Mose dáhùn pé, “Kì í ṣe ariwo fún ìṣẹ́gun, kì í ṣe ariwo fún aṣẹ́gun; ohùn àwọn tí ń kọrin ni mo gbọ́.”
А той відказав: „Це не крик сили перемо́жців і не крик слабости переможених, — я чую голос співу!“
19 Nígbà tí Mose dé àgọ́, ó sì rí ẹgbọrọ màlúù náà àti ijó, ìbínú rẹ gbóná, ó sì sọ wàláà ọwọ́ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ ní ìsàlẹ̀ òkè náà.
І сталося, коли він набли́зився до табо́ру, то побачив теля те та та́нці... І розпали́вся гнів Мойсеїв, і він кинув табли́ці із рук свої́х, — та й розторо́щив їх під горою!.
20 Ó sì gbé ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n ṣe, ó sì fi iná jó wọn; ó sì lọ̀ wọ́n kúnná, ó dà á sínú omi, ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli mu ún.
І схопи́в він теля, що зробили вони, та й спалив на огні, та змолов, аж став порох І розси́пав на поверхні води, і напоїв тим синів Ізра́їлевих.
21 Mose sọ fún Aaroni pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe sí ọ, tí ìwọ ṣe mú wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá yìí?”
І сказав Мойсей Ааронові: „Що́ вчинив тобі наро́д цей, що ти гріх великий навів на нього?“
22 Aaroni dáhùn wí pé, “Má ṣe bínú olúwa mi. Ìwọ mọ bí àwọn ènìyàn yìí ṣe burú tó.
А Аарон відказав: „Нехай не запа́литься гнів мого пана! Ти знаєш наро́д цей, що він у злому.
23 Wọ́n sọ fún mi pé, ‘Ṣe òrìṣà fún wa, tí yóò máa ṣáájú wa. Bí ó ṣe ti Mose ẹni tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá àwa kò mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.’
І вони сказали мені: Зроби нам богів, що будуть ходити перед нами, бо той Мойсей, муж, що вивів нас із єгипетського кра́ю, — ми не знаємо, що сталось йому.
24 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní òrùka wúrà, kí ó bọ́ ọ wá.’ Nígbà náà ni wọ́n fún mi ní wúrà, mo sì jù ú sínú iná, a sì fi ṣe ẹgbọrọ màlúù yìí!”
І сказав я до них: Хто має золото, — поздіймайте з себе. І дали вони мені, а я кинув його в огонь, — і вийшло те теля“.
25 Mose rí pé àwọn ènìyàn náà kò ṣe ṣàkóso àti pé Aaroni ti sọ wọ́n di aláìlákóṣo láàrín àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
І побачив Мойсей народ, що незагну́зданий він, бо Аарон розгнузда́в його на га́ньбу поміж їхніми ворогами.
26 Bẹ́ẹ̀ ni Mose dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà fún Olúwa, kí ó wá sí ọ̀dọ̀ mi.” Gbogbo àwọn ará Lefi sì péjọ yí i ká.
І став Мойсей у брамі табо́ру й сказав: „Хто за Господа — до мене!“І зібралися до нього всі Левіїні сини.
27 Nígbà náà ni ó sọ fún wọn pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wí pé, ‘Kí olúkúlùkù ọkùnrin kí ó kọ idà rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Ẹ lọ padà, kí ẹ jà láti àgọ́ kan dé òmíràn, olúkúlùkù kí ó pa arákùnrin rẹ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ àti aládùúgbò rẹ.’”
І сказав він до них: „Так сказав Господь, Бог Ізраїлів: Припаші́ть кожен меча свого́ на стегно́ своє, перейдіть, і верніться від брами до брами в табо́рі, — і повбивайте кожен брата свого, і кожен приятеля свого, і кожен бли́жнього свого́“.
28 Àwọn ará Lefi ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ṣe pàṣẹ, àti ní ọjọ́ náà àwọn tí ó kú tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ènìyàn.
І зробили Левіїні сини за словом Мойсеєвим. І впало з наро́ду того дня близько трьох тисяч чоловіка.
29 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ẹ ti ya ara yín sọ́tọ̀ fún Olúwa lónìí, nítorí ìwọ ti dìde sí àwọn ọmọ rẹ àti arákùnrin rẹ, ó sì ti bùkún fún ọ lónìí.”
І сказав Мойсей: „Освятіть сьогодні себе для Господа, бо кожен мстився на сині своїм та на браті своїм, і щоб сьогодні Він дав вам благослове́ння“.
30 Ní ọjọ́ kejì Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ̀yin ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi yóò gòkè lọ bá Olúwa; bóyá èmi lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
І сталося назавтра, і сказав Мойсей до народу: „Ви згрішили великим гріхом, а тепер зійду́ я до Господа, — може складу́ оку́плення за ваш гріх“.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Yé, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tí àwọn ènìyàn ti dá yìí! Wọ́n ti ṣe òrìṣà wúrà fún ara wọn.
І вернувся Мойсей до Господа та й сказав: „О, згрішив цей наро́д великим гріхом, — вони зробили собі золотих богі́в!
32 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n ṣùgbọ́n tí kò bá sì ṣe bẹ́ẹ̀, pa orúkọ mi rẹ́ kúrò nínú ìwé tí ìwọ ti kọ.”
А тепер, коли б Ти пробачив їм їхній гріх! А як ні, — витри мене з книги Своєї, яку Ти написав“.
33 Olúwa dá Mose lóhùn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi, Èmi yóò pa á rẹ́ kúrò nínú ìwé mi.
І промовив Господь до Мойсея: „Хто згрішив Мені, того витру із книги Своєї.
34 Ǹjẹ́ nísinsin yìí lọ, máa darí àwọn ènìyàn yìí lọ sí ibi ti mo sọ, angẹli mi yóò sì máa lọ ṣáájú yín. Ìgbà ń bọ̀ fún mi tì Èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò, Èmi yóò fi yà jẹ wọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
А тепер іди, провадь цей народ туди, куди казав Я тобі. Ось Мій Ангол піде перед лицем твоїм. А в день кари Моєї — покараю їх за їхній гріх!
35 Olúwa sì yọ àwọn ènìyàn náà lẹ́nu, pẹ̀lú ààrùn nítorí ohun tí wọ́n ṣe ní ti ẹgbọrọ màlúù tí Aaroni ṣe.
І Господь ударив той народ за те, що вони зробили теля, яке Аарон учинив був.

< Exodus 32 >