< Exodus 32 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Mose pẹ́ kí ó tó sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè wá, wọn péjọ yí Aaroni ká, wọ́n sì wí pé, “Wá, dá òrìṣà tí yóò máa ṣáájú wa fún wa. Bí ó ṣe ti Mose tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá, àwa kò mọ́ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí i.”
Попорул, вэзынд кэ Мойсе зэбовеште сэ се кобоаре де пе мунте, с-а стрынс ын журул луй Аарон ши й-а зис: „Хайде, фэ-не ун думнезеу каре сэ мяргэ ынаинтя ноастрэ, кэч Мойсе, омул ачела каре не-а скос дин цара Еӂиптулуй, ну штим че с-а фэкут!”
2 Aaroni dá wọn lóhùn pé, “Ẹ bọ́ òrùka wúrà tí ó wà ní etí àwọn ìyàwó yín, tí àwọn ọmọkùnrin yín, àti tí àwọn ọmọbìnrin yín, kí ẹ sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi.”
Аарон ле-а рэспунс: „Скоатець черчеий де аур дин урекиле невестелор, фиилор ши фийчелор воастре ши адучеци-й ла мине.”
3 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ènìyàn bọ́ òrùka etí wọn, wọn sì kó wọn wá fún Aaroni.
Ши тоць шь-ау скос черчеий де аур дин урекь ши й-ау адус луй Аарон.
4 Ó sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ó sì fi ṣe ohun ọnà fínfín, ó sì dà á ní àwòrán ẹgbọrọ màlúù. Nígbà náà ni wọn wí pé, “Israẹli, wọ̀nyí ni òrìṣà, ti ó mú un yín jáde wá láti Ejibiti.”
Ел й-а луат дин мыниле лор, а бэтут аурул ку далта ши а фэкут ун вицел турнат. Ши ей ау зис: „Исраеле, ятэ думнезеул тэу каре те-а скос дин цара Еӂиптулуй!”
5 Nígbà ti Aaroni rí èyí, ó kọ́ pẹpẹ kan níwájú ẹgbọrọ màlúù náà, ó sì kéde pé, “Lọ́la ni àjọyọ̀ sí Olúwa.”
Кынд а вэзут Аарон лукрул ачеста, а зидит ун алтар ынаинтя луй ши а стригат: „Мыне ва фи о сэрбэтоаре ын чинстя Домнулуй!”
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn dìde ní kùtùkùtù ọjọ́ kejì, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n sì mú ẹbọ àlàáfíà wá. Lẹ́yìn náà wọ́n jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde láti ṣeré.
А доуа зи, с-ау скулат дис-де-диминяцэ ши ау адус ардерь-де-тот ши жертфе де мулцумире. Попорул а шезут де а мынкат ши а бэут; апой с-ау скулат сэ жоаче.
7 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, nítorí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú gòkè wá láti Ejibiti, wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀.
Домнул а зис луй Мойсе: „Скоалэ ши кобоарэ-те, кэч попорул тэу, пе каре л-ай скос дин цара Еӂиптулуй, с-а стрикат.
8 Wọ́n ti yí kánkán kúrò nípa ọ̀nà tí mo ti mo pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì ti dá ère ẹgbọrọ màlúù fún ara wọn. Wọ́n ti foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì ti rú ẹbọ sí i, wọ́n sì ti sọ pé, ‘Israẹli wọ̀nyí ní òrìṣà tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.’”
Фоарте курынд с-ау абэтут де ла каля пе каре ле-о порунчисем Еу; шь-ау фэкут ун вицел турнат, с-ау ынкинат пынэ ла пэмынт ынаинтя луй, й-ау адус жертфе ши ау зис: ‘Исраеле, ятэ думнезеул тэу каре те-а скос дин цара Еӂиптулуй!’”
9 Olúwa wí fún Mose pé, “Èmi ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, wọ́n sì jẹ́ ọlọ́rùn líle ènìyàn.
Домнул а зис луй Мойсе: „Вэд кэ попорул ачеста есте ун попор ынкэпэцынат.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí fi mí sílẹ̀, nítorí kí ìbínú mi lè gbóná sí wọn, kí Èmi sì lè pa wọ́n run. Nígbà náà ni Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Акум, ласэ-Мэ; мыния Мя аре сэ се априндэ ымпотрива лор ши-й вой мистуи, дар пе тине те вой фаче стрэмошул унуй ням маре.”
11 Ṣùgbọ́n Mose kígbe fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìbínú rẹ yóò ṣe gbóná sí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú jáde láti Ejibiti wá pẹ̀lú agbára ńlá àti ọwọ́ agbára?
Мойсе с-а ругат Домнулуй Думнезеулуй сэу ши а зис: „Пентру че сэ се априндэ, Доамне, мыния Та ымпотрива попорулуй Тэу, пе каре л-ай скос дин цара Еӂиптулуй ку маре путере ши ку мынэ таре?
12 Èéṣe tí àwọn ará Ejibiti yóò ṣe wí pé, ‘Nítorí ibi ni ó ṣe mọ̀ ọ́n mọ̀ mú wọn jáde, láti pa wọ́n ní orí òkè àti láti gbá wọn kúrò lórí ayé’? Yípadà kúrò nínú ìbínú rẹ tí ó múná, yí ọkàn padà, kí o má sì ṣe mú ìparun wá sórí àwọn ènìyàn rẹ.
Пентру че сэ зикэ еӂиптений: ‘Спре ненорочиря лор й-а скос, ка сэ-й омоаре прин мунць ши ка сэ-й штяргэ де пе фаца пэмынтулуй’? Ынтоарче-Те дин юцяла мынией Тале ши ласэ-Те де рэул ачеста пе каре врей сэ-л фачь попорулуй Тэу.
13 Rántí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, ẹni tí ìwọ búra fún fúnra rẹ̀, ‘Tí o wí fún wọn pé, Èmi yóò mú irú-ọmọ rẹ pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, Èmi yóò sì fún irú-ọmọ rẹ ní gbogbo ilẹ̀ tí mo ti pinnu fún wọn, yóò sì jẹ́ ogún ìní wọn láéláé.’”
Аду-ць аминте де Авраам, де Исаак ши де Исраел, робий Тэй, кэрора ле-ай спус, журынду-Те пе Тине Ынсуць: ‘Вой ынмулци сэмынца воастрэ ка стелеле черулуй, вой да урмашилор воштри тоатэ цара ачаста де каре ам ворбит, ши ей о вор стэпыни ын вяк.’”
14 Nígbà náà ni Olúwa dáwọ́ ìbínú rẹ̀ dúró, kò sì mú ìparun náà tí ó sọ wá sórí àwọn ènìyàn rẹ̀ mọ́.
Ши Домнул С-а лэсат де рэул пе каре спусесе кэ вря сэ-л факэ попорулуй Сэу.
15 Mose sì yípadà, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà pẹ̀lú òkúta wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀. Wọ́n kọ ìwé síhà méjèèjì, iwájú àti ẹ̀yin.
Мойсе с-а ынторс ши с-а коборыт де пе мунте ку челе доуэ табле але мэртурией ын мынэ. Таблеле ерау скрисе пе амындоуэ пэрциле, пе о парте ши пе алта.
16 Iṣẹ́ Ọlọ́run sì ni wàláà náà; ìkọ̀wé náà jẹ́ ìkọ̀wé Ọlọ́run, a fín in sára àwọn òkúta wàláà náà.
Таблеле ерау лукраря луй Думнезеу ши скрисул ера скрисул луй Думнезеу, сэпат пе табле.
17 Nígbà tí Joṣua gbọ́ ariwo àwọn ènìyàn tí wọ́n ń kígbe, ó sọ fún Mose pé, “Ariwo ogun wà nínú àgọ́.”
Иосуа а аузит гласул попорулуй, каре скотя стригэте, ши а зис луй Мойсе: „Ын табэрэ есте ун стригэт де рэзбой!”
18 Mose dáhùn pé, “Kì í ṣe ariwo fún ìṣẹ́gun, kì í ṣe ariwo fún aṣẹ́gun; ohùn àwọn tí ń kọrin ni mo gbọ́.”
Мойсе а рэспунс: „Стригэтул ачеста ну-й нич стригэт де бируиторь, нич стригэт де бируиць; че ауд еу есте гласул унор оамень каре кынтэ!”
19 Nígbà tí Mose dé àgọ́, ó sì rí ẹgbọrọ màlúù náà àti ijó, ìbínú rẹ gbóná, ó sì sọ wàláà ọwọ́ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ ní ìsàlẹ̀ òkè náà.
Ши, пе кынд се апропия де табэрэ, а вэзут вицелул ши жокуриле. Мойсе с-а апринс де мыние, а арункат таблеле дин мынэ ши ле-а сфэрымат де пичорул мунтелуй.
20 Ó sì gbé ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n ṣe, ó sì fi iná jó wọn; ó sì lọ̀ wọ́n kúnná, ó dà á sínú omi, ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli mu ún.
А луат вицелул пе каре-л фэкусерэ ей ши л-а арс ын фок; л-а префэкут ын ченушэ, а пресэрат ченуша пе фаца апей ши а дат-о копиилор луй Исраел с-о бя.
21 Mose sọ fún Aaroni pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe sí ọ, tí ìwọ ṣe mú wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá yìí?”
Мойсе а зис луй Аарон: „Че ць-а фэкут попорул ачеста, де ай адус асупра луй ун пэкат атыт де маре?”
22 Aaroni dáhùn wí pé, “Má ṣe bínú olúwa mi. Ìwọ mọ bí àwọn ènìyàn yìí ṣe burú tó.
Аарон а рэспунс: „Сэ ну се априндэ де мыние домнул меу! Ту сингур штий кэ попорул ачеста есте порнит ла рэу.
23 Wọ́n sọ fún mi pé, ‘Ṣe òrìṣà fún wa, tí yóò máa ṣáájú wa. Bí ó ṣe ti Mose ẹni tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá àwa kò mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.’
Ей мь-ау зис: ‘Фэ-не ун думнезеу каре сэ мяргэ ынаинтя ноастрэ; кэч Мойсе, омул ачела каре не-а скос дин цара Еӂиптулуй, ну штим че с-а фэкут!’
24 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní òrùka wúrà, kí ó bọ́ ọ wá.’ Nígbà náà ni wọ́n fún mi ní wúrà, mo sì jù ú sínú iná, a sì fi ṣe ẹgbọrọ màlúù yìí!”
Еу ле-ам зис: ‘Чине аре аур сэ-л скоатэ!’ Ши ми л-ау дат; л-ам арункат ын фок ши дин ел а ешит вицелул ачеста.”
25 Mose rí pé àwọn ènìyàn náà kò ṣe ṣàkóso àti pé Aaroni ti sọ wọ́n di aláìlákóṣo láàrín àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
Мойсе а вэзут кэ попорул ера фэрэ фрыу, кэч Аарон ыл фэкусе сэ фие фэрэ фрыу, спре батжокура врэжмашилор сэй;
26 Bẹ́ẹ̀ ni Mose dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà fún Olúwa, kí ó wá sí ọ̀dọ̀ mi.” Gbogbo àwọn ará Lefi sì péjọ yí i ká.
с-а ашезат ла уша таберей ши а зис: „Чине есте пентру Домнул сэ винэ ла мине!” Ши тоць копиий луй Леви с-ау стрынс ла ел.
27 Nígbà náà ni ó sọ fún wọn pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wí pé, ‘Kí olúkúlùkù ọkùnrin kí ó kọ idà rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Ẹ lọ padà, kí ẹ jà láti àgọ́ kan dé òmíràn, olúkúlùkù kí ó pa arákùnrin rẹ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ àti aládùúgbò rẹ.’”
Ел ле-а зис: „Аша ворбеште Домнул Думнезеул луй Исраел: ‘Фиекаре дин вой сэ се ынчингэ ку сабия; мерӂець ши стрэбатець табэра де ла о поартэ ла алта ши фиекаре сэ омоаре пе фрателе, пе приетенул ши пе руда са.’”
28 Àwọn ará Lefi ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ṣe pàṣẹ, àti ní ọjọ́ náà àwọn tí ó kú tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ènìyàn.
Копиий луй Леви ау фэкут дупэ порунка луй Мойсе ши апроапе трей мий де оамень ау перит ын зиуа ачея дин попор.
29 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ẹ ti ya ara yín sọ́tọ̀ fún Olúwa lónìí, nítorí ìwọ ti dìde sí àwọn ọmọ rẹ àti arákùnrin rẹ, ó sì ti bùkún fún ọ lónìí.”
Мойсе а зис: „Предаци-вэ азь ын служба Домнулуй, кяр ку жертфа фиулуй ши фрателуй востру, пентру ка бинекувынтаря Луй сэ винэ астэзь песте вой!”
30 Ní ọjọ́ kejì Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ̀yin ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi yóò gòkè lọ bá Olúwa; bóyá èmi lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
А доуа зи, Мойсе а зис попорулуй: „Аць фэкут ун пэкат фоарте маре. Ам сэ мэ суй акум ла Домнул: поате кэ вой кэпэта ертаре пентру пэкатул востру.”
31 Bẹ́ẹ̀ ni Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Yé, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tí àwọn ènìyàn ti dá yìí! Wọ́n ti ṣe òrìṣà wúrà fún ara wọn.
Мойсе с-а ынторс ла Домнул ши а зис: „Ах, попорул ачеста а фэкут ун пэкат фоарте маре! Шь-ау фэкут ун думнезеу де аур.
32 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n ṣùgbọ́n tí kò bá sì ṣe bẹ́ẹ̀, pa orúkọ mi rẹ́ kúrò nínú ìwé tí ìwọ ti kọ.”
Яртэ-ле акум пэкатул! Дакэ ну, атунч штерӂе-мэ дин картя Та пе каре ай скрис-о!”
33 Olúwa dá Mose lóhùn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi, Èmi yóò pa á rẹ́ kúrò nínú ìwé mi.
Домнул а зис луй Мойсе: „Пе чел че а пэкэтуит ымпотрива Мя, пе ачела ыл вой штерӂе дин картя Мя.
34 Ǹjẹ́ nísinsin yìí lọ, máa darí àwọn ènìyàn yìí lọ sí ibi ti mo sọ, angẹli mi yóò sì máa lọ ṣáájú yín. Ìgbà ń bọ̀ fún mi tì Èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò, Èmi yóò fi yà jẹ wọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
Ду-те дар ши ду попорул унде ць-ам спус. Ятэ, Ынӂерул Меу ва мерӂе ынаинтя та, дар ын зиуа рэзбунэрий Меле, ый вой педепси пентру пэкатул лор!”
35 Olúwa sì yọ àwọn ènìyàn náà lẹ́nu, pẹ̀lú ààrùn nítorí ohun tí wọ́n ṣe ní ti ẹgbọrọ màlúù tí Aaroni ṣe.
Домнул а ловит ку урӂие попорул, пентру кэ фэкусе вицелул фэурит де Аарон.

< Exodus 32 >