< Exodus 32 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Mose pẹ́ kí ó tó sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè wá, wọn péjọ yí Aaroni ká, wọ́n sì wí pé, “Wá, dá òrìṣà tí yóò máa ṣáájú wa fún wa. Bí ó ṣe ti Mose tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá, àwa kò mọ́ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí i.”
Rĩrĩa andũ moonire atĩ Musa nĩaikarire mũno ataikũrũkĩte kuuma kĩrĩma-inĩ, magĩcookanĩrĩra harĩ Harũni makĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka, tũthondekere ngai iria irĩtũtongoragia. Ha ũhoro wa mũndũ ũyũ ũgwĩtwo Musa, ũrĩa watũrutire bũrũri wa Misiri, tũtiũĩ ũrĩa oonete.”
2 Aaroni dá wọn lóhùn pé, “Ẹ bọ́ òrùka wúrà tí ó wà ní etí àwọn ìyàwó yín, tí àwọn ọmọkùnrin yín, àti tí àwọn ọmọbìnrin yín, kí ẹ sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi.”
Harũni akĩmacookeria akĩmeera atĩrĩ, “Rutai icũhĩ cia thahabu iria irĩ matũ ma atumia anyu, na aanake na airĩtu anyu mũndehere.”
3 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ènìyàn bọ́ òrùka etí wọn, wọn sì kó wọn wá fún Aaroni.
Nĩ ũndũ ũcio andũ othe makĩruta icũhĩ cia thahabu icio ciarĩ matũ-inĩ mao magĩcirehere Harũni.
4 Ó sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ó sì fi ṣe ohun ọnà fínfín, ó sì dà á ní àwòrán ẹgbọrọ màlúù. Nígbà náà ni wọn wí pé, “Israẹli, wọ̀nyí ni òrìṣà, ti ó mú un yín jáde wá láti Ejibiti.”
Nake akĩoya indo iria maamũreheire, agĩcitwekia agĩtũmĩra indo cia ũbundi gũcithondeka mũhianano wa njaũ. Nao andũ makiuga atĩrĩ, “Ici nĩcio ngai ciaku, wee Isiraeli, iria ciakũrutire bũrũri wa Misiri.”
5 Nígbà ti Aaroni rí èyí, ó kọ́ pẹpẹ kan níwájú ẹgbọrọ màlúù náà, ó sì kéde pé, “Lọ́la ni àjọyọ̀ sí Olúwa.”
Rĩrĩa Harũni onire ũguo, agĩaka kĩgongona mbere ya njaũ ĩyo, na akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ, “Rũciũ nĩgũgakorwo na gĩathĩ kĩa Jehova.”
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn dìde ní kùtùkùtù ọjọ́ kejì, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n sì mú ẹbọ àlàáfíà wá. Lẹ́yìn náà wọ́n jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde láti ṣeré.
Nĩ ũndũ ũcio mũthenya ũyũ ũngĩ andũ magĩũkĩra rũciinĩ tene, makĩruta magongona ma njino na ma ũiguano. Thuutha ũcio magĩikara thĩ kũrĩa na kũnyua, magĩcooka magĩũkĩra kũina na gwĩkenia.
7 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, nítorí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú gòkè wá láti Ejibiti, wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀.
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ikũrũka, tondũ andũ aku arĩa warutire bũrũri wa Misiri nĩmethũkĩtie.
8 Wọ́n ti yí kánkán kúrò nípa ọ̀nà tí mo ti mo pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì ti dá ère ẹgbọrọ màlúù fún ara wọn. Wọ́n ti foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì ti rú ẹbọ sí i, wọ́n sì ti sọ pé, ‘Israẹli wọ̀nyí ní òrìṣà tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.’”
Nĩmagarũrũkĩte narua magatiga ũrĩa ndaamathĩte, na nĩmethondekeire mũhianano wa gũtwekio ũhaana njaũ. Nĩmaũinamĩrĩire na makaũrutĩra iruta makiugaga atĩrĩ, ‘Ici nĩcio ngai ciaku, wee Isiraeli, iria ciakũrutire bũrũri wa Misiri.’”
9 Olúwa wí fún Mose pé, “Èmi ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, wọ́n sì jẹ́ ọlọ́rùn líle ènìyàn.
Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Nĩnyonete andũ aya, nĩ andũ momĩtie ngingo.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí fi mí sílẹ̀, nítorí kí ìbínú mi lè gbóná sí wọn, kí Èmi sì lè pa wọ́n run. Nígbà náà ni Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Rĩu tigana na niĩ nĩgeetha marakara makwa mamarĩrĩmbũkĩre, nĩgeetha ndĩmaniine. Nĩngacooka ngũtue rũrĩrĩ rũnene.”
11 Ṣùgbọ́n Mose kígbe fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìbínú rẹ yóò ṣe gbóná sí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú jáde láti Ejibiti wá pẹ̀lú agbára ńlá àti ọwọ́ agbára?
No Musa agĩthaitha Jehova Ngai wake, akĩmwĩra atĩrĩ, “Wee Jehova, ũngĩcinwo nĩ marakara ũũkĩrĩre andũ aku nĩkĩ, o arĩa warutire kuuma bũrũri wa Misiri na guoko gwaku kũrĩ ũhoti na ũkĩmaruta kuo na hinya mũnene?
12 Èéṣe tí àwọn ará Ejibiti yóò ṣe wí pé, ‘Nítorí ibi ni ó ṣe mọ̀ ọ́n mọ̀ mú wọn jáde, láti pa wọ́n ní orí òkè àti láti gbá wọn kúrò lórí ayé’? Yípadà kúrò nínú ìbínú rẹ tí ó múná, yí ọkàn padà, kí o má sì ṣe mú ìparun wá sórí àwọn ènìyàn rẹ.
Nĩ kĩĩ kĩngĩtũma andũ a Misiri moige atĩrĩ, ‘Aamarutire bũrũri wa Misiri arĩ na muoroto wa kũmeka ũũru amooragĩre irĩma-inĩ, na amaniine mathire gũkũ thĩ’? Tiga kũrakara mũno; wĩricũkwo ndũkarehere andũ aku mwanangĩko.
13 Rántí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, ẹni tí ìwọ búra fún fúnra rẹ̀, ‘Tí o wí fún wọn pé, Èmi yóò mú irú-ọmọ rẹ pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, Èmi yóò sì fún irú-ọmọ rẹ ní gbogbo ilẹ̀ tí mo ti pinnu fún wọn, yóò sì jẹ́ ogún ìní wọn láéláé.’”
Ririkana ndungata ciaku Iburahĩmu, na Isaaka, na Isiraeli, arĩa wee wehĩtire kũrĩ o na mwĩhĩtwa ũkĩĩgwetaga, ũkiuga atĩrĩ: ‘Nĩngatũma njiaro ciaku cingĩhe ta njata cia matu-inĩ, na nĩngaahe njiaro ciaku bũrũri ũyũ wothe ũrĩa ndaamerĩire, naguo ũgaatuĩka igai rĩao nginya tene.’”
14 Nígbà náà ni Olúwa dáwọ́ ìbínú rẹ̀ dúró, kò sì mú ìparun náà tí ó sọ wá sórí àwọn ènìyàn rẹ̀ mọ́.
Hĩndĩ ĩyo Jehova akĩĩricũkwo, na ndaigana kũrehere andũ ake mwanangĩko ũrĩa oigĩte atĩ nĩekũmarehera.
15 Mose sì yípadà, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà pẹ̀lú òkúta wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀. Wọ́n kọ ìwé síhà méjèèjì, iwájú àti ẹ̀yin.
Musa akĩhũndũka, agĩikũrũka kuuma kĩrĩma igũrũ akuuĩte ihengere icio igĩrĩ cia Ũira na moko make. Ciarĩ nyandĩke mĩena yeerĩ, mbere na thuutha.
16 Iṣẹ́ Ọlọ́run sì ni wàláà náà; ìkọ̀wé náà jẹ́ ìkọ̀wé Ọlọ́run, a fín in sára àwọn òkúta wàláà náà.
Ihengere icio ciarĩ wĩra wa Ngai; maandĩko macio maarĩ maandĩko ma Ngai makururĩtwo ihengere-inĩ icio.
17 Nígbà tí Joṣua gbọ́ ariwo àwọn ènìyàn tí wọ́n ń kígbe, ó sọ fún Mose pé, “Ariwo ogun wà nínú àgọ́.”
Rĩrĩa Joshua aiguire inegene rĩa andũ makiugĩrĩria akĩĩra Musa atĩrĩ, “Kũrĩ mbugĩrĩrio ya mbaara kambĩ-inĩ.”
18 Mose dáhùn pé, “Kì í ṣe ariwo fún ìṣẹ́gun, kì í ṣe ariwo fún aṣẹ́gun; ohùn àwọn tí ń kọrin ni mo gbọ́.”
Musa akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ti mĩgambo ya ũhootani, na ti mĩgambo ya kũhootwo; nĩ mĩgambo ya kũina ndĩraigua.”
19 Nígbà tí Mose dé àgọ́, ó sì rí ẹgbọrọ màlúù náà àti ijó, ìbínú rẹ gbóná, ó sì sọ wàláà ọwọ́ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ ní ìsàlẹ̀ òkè náà.
Rĩrĩa Musa akuhĩrĩirie kambĩ, na akĩona njaũ na ndũrũhĩ ĩrĩa yarĩ kũndũ kũu, agĩcinwo nĩ marakara, nake agĩikia ihengere icio thĩ, ikiunĩkanga icunjĩ o hau magũrũ-inĩ ma kĩrĩma.
20 Ó sì gbé ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n ṣe, ó sì fi iná jó wọn; ó sì lọ̀ wọ́n kúnná, ó dà á sínú omi, ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli mu ún.
Nake akĩnyiita njaũ ĩyo maathondekete, akĩmĩcina na mwaki, agĩcooka akĩmĩthĩa, ĩgĩtuĩka mũtu, akĩũikia maaĩ-inĩ na agĩatha andũ a Isiraeli manyue maaĩ macio.
21 Mose sọ fún Aaroni pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe sí ọ, tí ìwọ ṣe mú wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá yìí?”
Nake Musa akĩũria Harũni atĩrĩ, “Andũ aya maragwĩkire atĩa nĩgeetha ũmatoonyie mehia-inĩ manene ũũ?”
22 Aaroni dáhùn wí pé, “Má ṣe bínú olúwa mi. Ìwọ mọ bí àwọn ènìyàn yìí ṣe burú tó.
Nake Harũni akĩmũcookeria, akĩmwĩra atĩrĩ, “Tiga kũrakara, mwathi wakwa; wee nĩũũĩ ũrĩa andũ aya mendete gwĩka ũũru.
23 Wọ́n sọ fún mi pé, ‘Ṣe òrìṣà fún wa, tí yóò máa ṣáájú wa. Bí ó ṣe ti Mose ẹni tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá àwa kò mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.’
Maanjĩĩrire atĩrĩ, ‘Tũthondekere ngai iria irĩtũtongoragia. Ha ũhoro wa mũndũ ũyũ ũgwĩtwo Musa, ũrĩa watũrutire bũrũri wa Misiri-rĩ, tũtiũĩ ũrĩa oonire.’
24 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní òrùka wúrà, kí ó bọ́ ọ wá.’ Nígbà náà ni wọ́n fún mi ní wúrà, mo sì jù ú sínú iná, a sì fi ṣe ẹgbọrọ màlúù yìí!”
Nĩ ũndũ ũcio ngĩmeera atĩrĩ, ‘Ũrĩa wothe ũrĩ na mathaga ma thahabu, nĩarute.’ Nao makĩĩnengera indo icio cia thahabu, ngĩciikia riiko, nacio ikiuma njaũ ĩno!”
25 Mose rí pé àwọn ènìyàn náà kò ṣe ṣàkóso àti pé Aaroni ti sọ wọ́n di aláìlákóṣo láàrín àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
Musa akĩona atĩ andũ nĩmakararĩtie, na atĩ Harũni nĩamarekereirie meke ũrĩa mekwenda, nginya magaatuĩka andũ a gũthekagĩrĩrwo nĩ thũ ciao.
26 Bẹ́ẹ̀ ni Mose dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà fún Olúwa, kí ó wá sí ọ̀dọ̀ mi.” Gbogbo àwọn ará Lefi sì péjọ yí i ká.
Nĩ ũndũ ũcio akĩrũgama itoonyero-inĩ rĩa kambĩ, akiuga atĩrĩ, “Ũrĩa wothe ũrĩ mwena wa Jehova-rĩ, nĩoke haha.” Nao Alawii othe makĩrũgama mwena wake.
27 Nígbà náà ni ó sọ fún wọn pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wí pé, ‘Kí olúkúlùkù ọkùnrin kí ó kọ idà rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Ẹ lọ padà, kí ẹ jà láti àgọ́ kan dé òmíràn, olúkúlùkù kí ó pa arákùnrin rẹ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ àti aládùúgbò rẹ.’”
Nake akĩmeera atĩrĩ, “Jehova Ngai wa Isiraeli ekuuga atĩrĩ, ‘O mũndũ nĩeyohe rũhiũ rwa njora njohero. Hungurai kambĩ ĩno kuuma mwena ũmwe nginya ũrĩa ũngĩ, o mũndũ nĩoorage mũrũ wa nyina na oorage mũratawe na mũndũ wa itũũra rĩake.’”
28 Àwọn ará Lefi ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ṣe pàṣẹ, àti ní ọjọ́ náà àwọn tí ó kú tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ènìyàn.
Alawii magĩĩka ta ũrĩa maathirwo nĩ Musa, na mũthenya ũcio gũkĩũragwo andũ ta 3,000.
29 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ẹ ti ya ara yín sọ́tọ̀ fún Olúwa lónìí, nítorí ìwọ ti dìde sí àwọn ọmọ rẹ àti arákùnrin rẹ, ó sì ti bùkún fún ọ lónìí.”
Nake Musa akiuga atĩrĩ, “Nĩmwarĩkia kwamũrĩrwo Jehova ũmũthĩ, nĩgũkorwo nĩmwareganire na ariũ anyu na mũkĩregana na arĩa mũciaranĩirwo nao, na Jehova nĩamũrathima ũmũthĩ.”
30 Ní ọjọ́ kejì Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ̀yin ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi yóò gòkè lọ bá Olúwa; bóyá èmi lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
Mũthenya ũyũ ũngĩ Musa akĩĩra andũ atĩrĩ, “Nĩmwĩhĩtie mũno. No rĩu, nĩngwambata kũrĩ Jehova; hihi no kũhoteke ndĩmũrutĩre horohio nĩ ũndũ wa rĩhia rĩanyu.”
31 Bẹ́ẹ̀ ni Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Yé, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tí àwọn ènìyàn ti dá yìí! Wọ́n ti ṣe òrìṣà wúrà fún ara wọn.
Nĩ ũndũ ũcio Musa agĩcooka kũrĩ Jehova, akĩmwĩra atĩrĩ, “Hĩ, kaĩ andũ aya nĩmekĩte rĩhia inene-ĩ! Nĩmethondekeire ngai cia thahabu.
32 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n ṣùgbọ́n tí kò bá sì ṣe bẹ́ẹ̀, pa orúkọ mi rẹ́ kúrò nínú ìwé tí ìwọ ti kọ.”
No rĩu-rĩ, ndagũthaitha marekere mehia mao; angĩkorwo ndũkũmarekera, o na niĩ tharia ibuku-inĩ rĩrĩa wandĩkĩte andũ aku.”
33 Olúwa dá Mose lóhùn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi, Èmi yóò pa á rẹ́ kúrò nínú ìwé mi.
Nake Jehova agĩcookeria Musa atĩrĩ, “Ũrĩa wothe ũnjĩhĩirie, nĩngamũtharia ibuku-inĩ rĩakwa.
34 Ǹjẹ́ nísinsin yìí lọ, máa darí àwọn ènìyàn yìí lọ sí ibi ti mo sọ, angẹli mi yóò sì máa lọ ṣáájú yín. Ìgbà ń bọ̀ fún mi tì Èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò, Èmi yóò fi yà jẹ wọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
Rĩu gĩthiĩ, ũtongorie andũ acio mathiĩ bũrũri ũrĩa ndaaririe ũhoro waguo, nake mũraika wakwa nĩakamũtongoria. Na rĩrĩ, hĩndĩ ya kũmaherithia yakinya-rĩ, no ngaamaherithia nĩ ũndũ wa mehia mao.”
35 Olúwa sì yọ àwọn ènìyàn náà lẹ́nu, pẹ̀lú ààrùn nítorí ohun tí wọ́n ṣe ní ti ẹgbọrọ màlúù tí Aaroni ṣe.
Nake Jehova akĩhũũra andũ acio na mũthiro nĩ tondũ wa ũrĩa meekire na njaũ ĩyo yathondeketwo nĩ Harũni.

< Exodus 32 >