< Exodus 32 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Mose pẹ́ kí ó tó sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè wá, wọn péjọ yí Aaroni ká, wọ́n sì wí pé, “Wá, dá òrìṣà tí yóò máa ṣáájú wa fún wa. Bí ó ṣe ti Mose tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá, àwa kò mọ́ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí i.”
Mae hoiah Mosi angzo tathuk ai boeh, tito kaminawk mah panoek o naah, kaminawk loe Aaron khaeah amkhueng o moe, anih khaeah, Angthawk ah; kaicae hmaa ah caeh hanah sithawnawk to na sah pae ah; Izip prae thung hoi kaicae zaehoikung Mosi loe, kawbang maw oh ving boeh, tito a panoek o ai boeh, tiah a naa o.
2 Aaroni dá wọn lóhùn pé, “Ẹ bọ́ òrùka wúrà tí ó wà ní etí àwọn ìyàwó yín, tí àwọn ọmọkùnrin yín, àti tí àwọn ọmọbìnrin yín, kí ẹ sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi.”
Aaron mah nihcae khaeah, Na zunawk, na capanawk hoi na canunawk ih sui naa tangkraengnawk to angkhring oh loe, kai khaeah na sin oh, tiah a naa.
3 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ènìyàn bọ́ òrùka etí wọn, wọn sì kó wọn wá fún Aaroni.
To pongah kaminawk boih mah angmacae ih sui naa tangkraeng to angkring o moe, Aaron khaeah sin pae o.
4 Ó sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ó sì fi ṣe ohun ọnà fínfín, ó sì dà á ní àwòrán ẹgbọrọ màlúù. Nígbà náà ni wọn wí pé, “Israẹli, wọ̀nyí ni òrìṣà, ti ó mú un yín jáde wá láti Ejibiti.”
Nihcae mah paek o ih hmuennawk to anih mah talawk boih moe, a sak pae pacoengah maitaw caa ih krang to a soi pae; Aw Israel, hae sithaw loe Izip prae thung hoiah nangcae zaehoikung sithawnawk boeh ni, tiah a naa.
5 Nígbà ti Aaroni rí èyí, ó kọ́ pẹpẹ kan níwájú ẹgbọrọ màlúù náà, ó sì kéde pé, “Lọ́la ni àjọyọ̀ sí Olúwa.”
Aaron mah to hmuen to hnuk naah, maitaw caa hmaa ah hmaicam maeto sak moe, Khawnbang loe Angraeng hanah poih sakhaih niah om tih, tiah kaminawk khaeah taphongsak.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn dìde ní kùtùkùtù ọjọ́ kejì, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n sì mú ẹbọ àlàáfíà wá. Lẹ́yìn náà wọ́n jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde láti ṣeré.
To pongah kaminawk loe khawnbang khawnthaw ah angthawk o moe, hmai angbawnhaih hoi angdaeh angbawnhaih to sak o; caak naek hanah anghnut o moe, hnawh hanah angthawk o.
7 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, nítorí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú gòkè wá láti Ejibiti, wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀.
To naah Angraeng mah Mosi khaeah, Caeh tathuk ah, Izip prae thung hoiah na hoih ih kaminawk loe, amro o boih boeh;
8 Wọ́n ti yí kánkán kúrò nípa ọ̀nà tí mo ti mo pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì ti dá ère ẹgbọrọ màlúù fún ara wọn. Wọ́n ti foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì ti rú ẹbọ sí i, wọ́n sì ti sọ pé, ‘Israẹli wọ̀nyí ní òrìṣà tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.’”
nihcae han ka thuih pae ih loklam to karangah angqoi o taak moe, angmacae han maitaw caa krang to a sak o boeh; to krang to bok o moe, angbawnhaih to a sak o pacoengah, Aw Israel kaminawk, hae sithaw loe Izip prae thung hoi nangcae zaehoikung sithaw ah ni oh o boeh, tiah a thuih o, tiah a naa.
9 Olúwa wí fún Mose pé, “Èmi ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, wọ́n sì jẹ́ ọlọ́rùn líle ènìyàn.
Angraeng mah Mosi khaeah, Hae kaminawk hae ka hnuk boeh; nihcae loe palungthah kami ah oh o;
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí fi mí sílẹ̀, nítorí kí ìbínú mi lè gbóná sí wọn, kí Èmi sì lè pa wọ́n run. Nígbà náà ni Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.”
to pongah kaimah bueng na caehtaak ah; hmai baktih kamngaeh palungphuihaih hoiah nihcae to ka kanghsak moe, kam rosak boih han; to pacoengah nang hae kalen parai acaeng ah kang sak han, tiah a naa.
11 Ṣùgbọ́n Mose kígbe fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìbínú rẹ yóò ṣe gbóná sí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú jáde láti Ejibiti wá pẹ̀lú agbára ńlá àti ọwọ́ agbára?
Toe Mosi mah angmah ih Angraeng Sithaw khaeah, Angraeng, tipongah na sak thaihaih, na ban thacakhaih hoiah Izip prae thung hoi na zaehhoih ih nangmah ih kaminawk to palungphuihaih hoiah nam rosak boih han loe?
12 Èéṣe tí àwọn ará Ejibiti yóò ṣe wí pé, ‘Nítorí ibi ni ó ṣe mọ̀ ọ́n mọ̀ mú wọn jáde, láti pa wọ́n ní orí òkè àti láti gbá wọn kúrò lórí ayé’? Yípadà kúrò nínú ìbínú rẹ tí ó múná, yí ọkàn padà, kí o má sì ṣe mú ìparun wá sórí àwọn ènìyàn rẹ.
Tipongah Izip kaminawk mah, Sithaw loe kasae poekhaih tawnh, to pongah ni nihcae to mae nuiah hum moe, long pum hoiah tamit boih hanah, a caeh haih, tiah thuih han koi ah oh ving loe? Hmai baktih kamngaeh palungphuihaih to dipsak ah loe, nangmah ih kaminawk nuiah sak han ih kasae poekhaih to dawnpakhuem raeh.
13 Rántí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, ẹni tí ìwọ búra fún fúnra rẹ̀, ‘Tí o wí fún wọn pé, Èmi yóò mú irú-ọmọ rẹ pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, Èmi yóò sì fún irú-ọmọ rẹ ní gbogbo ilẹ̀ tí mo ti pinnu fún wọn, yóò sì jẹ́ ogún ìní wọn láéláé.’”
Na tamna Abraham, Issak hoi Israel khaeah, Na caanawk loe van ih cakaeh zetto kang pungsak moe, dungzan ah qawk na toep o thai hanah, long nuiah kaom hmuennawk boih kang paek han, tiah na thuih ih lok to pahnet hmah raeh, tiah a naa.
14 Nígbà náà ni Olúwa dáwọ́ ìbínú rẹ̀ dúró, kò sì mú ìparun náà tí ó sọ wá sórí àwọn ènìyàn rẹ̀ mọ́.
To naah Angraeng mah angmah ih kaminawk nuiah kasae sak han poekhaih to dawnpakhuem let.
15 Mose sì yípadà, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà pẹ̀lú òkúta wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀. Wọ́n kọ ìwé síhà méjèèjì, iwájú àti ẹ̀yin.
Mosi loe a ban ah hnukung thlung kangphaek hnetto sin moe, mae nui hoiah anghum tathuk; thlung kangphaek hnetto pongah, ahnuk ahmaa ca to tarik.
16 Iṣẹ́ Ọlọ́run sì ni wàláà náà; ìkọ̀wé náà jẹ́ ìkọ̀wé Ọlọ́run, a fín in sára àwọn òkúta wàláà náà.
To thlung kangphaek hnetto loe, Sithaw mah sak ih thlung kangphaek ah oh moe, Sithaw mah ni ca doeh tarik.
17 Nígbà tí Joṣua gbọ́ ariwo àwọn ènìyàn tí wọ́n ń kígbe, ó sọ fún Mose pé, “Ariwo ogun wà nínú àgọ́.”
Kaminawk hanghaih lok to Joshua mah thaih naah, Mosi khaeah, ataihaih ahmuen ah misatukhaih lok to ka thaih, tiah a naa.
18 Mose dáhùn pé, “Kì í ṣe ariwo fún ìṣẹ́gun, kì í ṣe ariwo fún aṣẹ́gun; ohùn àwọn tí ń kọrin ni mo gbọ́.”
Mosi mah, To hanghaih lok loe misa pazawhaih lok na ai ni, misa sunghaih lok doeh na ai ah, laasakhaih lok ni ka thaih, tiah a naa.
19 Nígbà tí Mose dé àgọ́, ó sì rí ẹgbọrọ màlúù náà àti ijó, ìbínú rẹ gbóná, ó sì sọ wàláà ọwọ́ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ ní ìsàlẹ̀ òkè náà.
Ataihaih ahmuen taengah phak naah, Mosi mah maitaw caa hoi nawnto hnawh kaminawk to hnuk; hmai kamngaeh baktiah palung to phui pongah, a ban ih thlung kangphaek to a vah; mae tlim ah a vah phaeng.
20 Ó sì gbé ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n ṣe, ó sì fi iná jó wọn; ó sì lọ̀ wọ́n kúnná, ó dà á sínú omi, ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli mu ún.
Nihcae mah sak o ih maitaw caa to a lak moe, hmai thungah a vah pae; kadip puengah naep pae pacoengah, tui pongah phuih moe, Israel kaminawk to a naeksak.
21 Mose sọ fún Aaroni pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe sí ọ, tí ìwọ ṣe mú wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá yìí?”
Aaron khaeah, Hae tiah kalen zaehaih to sak hanah, nihcae mah na nuiah tih hmuen maw a sak o? tiah a naa.
22 Aaroni dáhùn wí pé, “Má ṣe bínú olúwa mi. Ìwọ mọ bí àwọn ènìyàn yìí ṣe burú tó.
Aaron mah, Ka angraeng, palungphuisak hmah; hae kaminawk loe kasae poekhaih a tawnh o, tito na panoek, tiah a naa.
23 Wọ́n sọ fún mi pé, ‘Ṣe òrìṣà fún wa, tí yóò máa ṣáájú wa. Bí ó ṣe ti Mose ẹni tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá àwa kò mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.’
Kai khaeah, Kaicae hmabang ah ka caeh o thai hanah, sithawnawk to na sah paeh, Izip prae thung hoi kaicae zaehoikung Mosi loe, kawbang maw oh boeh, tito a panoek o ai boeh, tiah a thuih o.
24 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní òrùka wúrà, kí ó bọ́ ọ wá.’ Nígbà náà ni wọ́n fún mi ní wúrà, mo sì jù ú sínú iná, a sì fi ṣe ẹgbọrọ màlúù yìí!”
To pongah kai mah nihcae khaeah, Sui tawn kaminawk boih sui to angkhring oh loe, kai khaeah na paek oh, tiah ka naa. To naah nihcae mah sui to angkhring o moe, ang paek o; kai mah hmai thungah ka vah naah, maitaw caa ah angcoeng, tiah a naa.
25 Mose rí pé àwọn ènìyàn náà kò ṣe ṣàkóso àti pé Aaroni ti sọ wọ́n di aláìlákóṣo láàrín àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
(Aaron mah kaminawk to khen laek ai boeh pongah, a misanawk hmaa ah bangkrai ah ohsak), tito Mosi mah hnuk naah,
26 Bẹ́ẹ̀ ni Mose dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà fún Olúwa, kí ó wá sí ọ̀dọ̀ mi.” Gbogbo àwọn ará Lefi sì péjọ yí i ká.
to pongah Mosi loe ataihaih khongkha ah angdoet moe, Angraeng bangah angdoe kaminawk boih, kai khaeah angzo oh, tiah a naa. To naah Levi caanawk boih anih taengah amkhueng o.
27 Nígbà náà ni ó sọ fún wọn pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wí pé, ‘Kí olúkúlùkù ọkùnrin kí ó kọ idà rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Ẹ lọ padà, kí ẹ jà láti àgọ́ kan dé òmíràn, olúkúlùkù kí ó pa arákùnrin rẹ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ àti aládùúgbò rẹ.’”
To pacoengah Mosi mah nihcae khaeah, Israel Angraeng Sithaw mah, Kami boih mah sumsen to avak nasoe; ataihaih ahmuen ih khongkha maeto hoi maeto boenghaih khoek to caeh nasoe loe, kami boih mah angmah ih nawkamya, angmah ih ampuinawk hoi angmah imtaeng kami to hum nasoe, tiah a thuih, tiah a naa.
28 Àwọn ará Lefi ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ṣe pàṣẹ, àti ní ọjọ́ náà àwọn tí ó kú tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ènìyàn.
Mosi mah thuih ih lok baktih toengah, Levinawk mah sak o; to na niah kami sang thumto duek o.
29 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ẹ ti ya ara yín sọ́tọ̀ fún Olúwa lónìí, nítorí ìwọ ti dìde sí àwọn ọmọ rẹ àti arákùnrin rẹ, ó sì ti bùkún fún ọ lónìí.”
To pacoengah Mosi mah, Angraeng mah vai hniah tahamhoihaih paek hanah, kami boih angmah ih capa hoi angmah ih nawkamya humhaih rang hoiah, vaihniah nangmah hoi nangmah to Angraeng khaeah nang paek o boeh, tiah a naa.
30 Ní ọjọ́ kejì Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ̀yin ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi yóò gòkè lọ bá Olúwa; bóyá èmi lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
Khawnbang ah Mosi mah kaminawk khaeah, Kalen parai zaehaih to na sak o boeh; toe vaihi Angraeng khaeah ka caeh tahang moe, nangcae zae loihaih to ka sak thai thung ka sak han, tiah a naa.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Yé, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tí àwọn ènìyàn ti dá yìí! Wọ́n ti ṣe òrìṣà wúrà fún ara wọn.
To pongah Mosi loe Angraeng khaeah caeh let, Aw, hae kaminawk loe kalen parai zaehaih to a sak o moeng boeh! Sui to angmacae hanah sithaw ah a sak o boeh.
32 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n ṣùgbọ́n tí kò bá sì ṣe bẹ́ẹ̀, pa orúkọ mi rẹ́ kúrò nínú ìwé tí ìwọ ti kọ.”
Toe vaihiah nihcae zaehaih to tahmen raeh; a zae o haih na tahmen ai nahaeloe, na tarik ih cabu thung hoiah kai ih ahmin to phrae ving halat ah, tiah a naa.
33 Olúwa dá Mose lóhùn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi, Èmi yóò pa á rẹ́ kúrò nínú ìwé mi.
Angraeng mah Mosi khaeah, Ka hmaa ah zaehaih sah kami loe, anih ih ahmin to ka cabu thung hoiah ka phraek han.
34 Ǹjẹ́ nísinsin yìí lọ, máa darí àwọn ènìyàn yìí lọ sí ibi ti mo sọ, angẹli mi yóò sì máa lọ ṣáájú yín. Ìgbà ń bọ̀ fún mi tì Èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò, Èmi yóò fi yà jẹ wọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
Vaihi caeh ah loe, kang thuih ih ahmuen ah kaminawk to caeh haih ah; khenah, kai ih van kami to na hmaa ah caeh tih; nihcae thuitaekhaih atue to phak naah, a zae o haih pongah nihcae to ka thuitaek han, tiah a naa.
35 Olúwa sì yọ àwọn ènìyàn náà lẹ́nu, pẹ̀lú ààrùn nítorí ohun tí wọ́n ṣe ní ti ẹgbọrọ màlúù tí Aaroni ṣe.
Aaron mah sak pae ih maitaw caa pongah, Angraeng mah kaminawk to nathaih hoiah thuitaek.

< Exodus 32 >