< Exodus 31 >

1 Olúwa wí fún Mose pé,
I korero ano a Ihowa ki a Mohi, i mea,
2 “Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
Titiro, kua whakahuatia nei e ahau te ingoa o Petareere, tama a Uri, ko ia nei he tama na Huru, no te iwi o Hura:
3 Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
Kua whakakiia ano ia e ahau ki te wairua o te Atua, ki te ngakau tupato, ki te whakaaro, ki te mohio, ki nga mahi katoa hoki,
4 Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
Hei whakaaro ki nga mahi a te tohunga, hei mahi i te koura, i te hiriwa, i te parahi,
5 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
Mo te whakairo kohatu hoki, mo te whakanoho hoki, mo te whakairo rakau, mo te mahi ano hoki i nga mahi katoa.
6 Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
Na, tenei ano te hoatu nei e ahau hei hoa mona a Ahoriapa tama a Ahihamaka, no te iwi o Rana: kua whakanohoia ano e ahau he mahara ki nga ngakau o te hunga ngakau mahara katoa, hei hanga i nga mea katoa i whakahaua atu nei e ahau ki a koe;
7 “àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
I te tapenakara o te whakaminenga, i te aaka o te whakaaturanga, i tona taupoki, i nga mea katoa o te tapenakara,
8 tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
I te tepu, i ona mea, i te turanga parakore o nga rama, i ona mea katoa, i te aata mo te whakakakara,
9 pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
I te aata mo te tahunga tinana, i ona mea katoa, i te takotoranga wai raua ko tona turanga.
10 àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
I nga kakahu mo te mahi minita, i nga kakahu tapu mo Arona, mo te tohunga, i nga kakahu mo ana tama, mo te mahi tohunga,
11 òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
I te hinu whakawahi, i te whakakakara reka mo te wahi tapu: kia rite ta ratou e mea ai ki nga mea katoa i whakahaua atu e ahau ki a koe.
12 Olúwa wí fún Mose pé,
I korero ano a Ihowa ki a Mohi, i mea,
13 “Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
Korero ano ki nga tama a Iharaira, mea atu, Me whakarite ano e koutou aku hapati: hei tohu hoki ki waenganui oku, o koutou, i o koutou whakatupuranga: kia mohio ai ko ahau, ko Ihowa, te whakatapu nei i a koutou.
14 “‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
Na me whakarite te hapati; he tapu hoki tena ki a koutou: he mate kau mo te tangata e whakanoa ana i taua ra: ko te tangata hoki e mahi ana i tetahi mahi i reira, ina, ka hatepea atu taua wairua i roto i tona iwi.
15 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
E ono nga ra e mahia ai te mahi; kei te whitu ia o nga ra te hapati okiokinga, he tapu ki a Ihowa: ko te tangata e mahi ana i tetahi mahi i te ra hapati he mate kau mona.
16 Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
Mo reira me mahara nga tama a Iharaira ki te hapati, kia whakaritea te hapati i o ratou whakatupuranga: kia mau tonu tenei kawenata.
17 Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
He tohu tena ra ki waenganui oku, o nga tama a Iharaira, ake ake: e ono hoki nga ra i hanga ai e Ihowa te rangi me te whenua, a i te whitu o nga ra ka okioki, a ta ana tona manawa.
18 Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.
I homai ano e ia ki a Mohi, i te mutunga o tana korero ki a ia i runga i Maunga Hinai, e rua nga papa whakaaturanga, he papa kohatu, he mea tuhituhi na te ringa o te Atua.

< Exodus 31 >