< Exodus 31 >
És szólt az Örökkévaló Mózeshez, mondván:
2 “Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
Lásd, név szerint szólítottam Becálélt, Uri fiái, Chúr fiát, Júda törzséből;
3 Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
és betöltöttem őt Isten szellemével, bölcsességgel, értelemmel és ismerettel minden munkában,
4 Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
hogy kigondoljon terveket, hogy elkészítse aranyban, ezüstben és rézben,
5 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
és kőmetszésben foglalásra és fafaragásban, hogy elkészítse mindenféle munkával.
6 Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
És én íme adtam mellé Oholiovot, Áchiszómoch fiát, Dán törzséből és minden bölcsnek a szívébe adtam bölcsességet, hogy elkészítsék mindazt, amit neked parancsoltam.
7 “àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
A gyülekezés sátorát és a ládát a bizonyság számára és a födelet, mely rá való és a sátor minden edényét;
8 tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
az asztalt és edényeit, a tiszta arany lámpás és minden edényeit és a füstölőszer oltárát;
9 pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
az égőáldozat oltárát és minden edényeit, a medencét és talapzatát;
10 àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
és a szolgálati ruhákat és a szent ruhákat Áronnak, a papnak és fiainak ruháit papi szolgálatra;
11 òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
a kenetolajat és a fűszeres füstölőszert a szentségnek, egészen úgy, amint neked parancsoltam, készítsék:
És szólt az Örökkévaló Mózeshez, mondván:
13 “Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
Te pedig szólj Izrael fiaihoz, mondván: Bizony szombataimat őrizzétek meg, mert jel az köztem és köztetek, nemzedékeiteken át, hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Örökkévaló, aki megszentellek benneteket.
14 “‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
Azért őrizzétek meg a szombatot, mert szent az nektek; aki megszentségteleníti, ölessék meg, mert bárki munkát végez azon, irtassék ki az a személy az ő népe köréből.
15 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
Hat napon át végeztessék munka, de a hetedik napon szombati nyugalom legyen, szent az Örökkévalónak; bárki munkát végez a szombat napján, ölessék meg,
16 Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
És őrizzék meg Izrael fiai a szombatot, hogy megtartsák a szombatot nemzedékeiken át, örök szövetségül.
17 Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
Közöttem és Izrael fiai között jel az örökre; mert hat napon alkotta az Örökkévaló az eget és a földet, a hetedik napon pedig megnyugodott és pihent.
18 Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.
És odaadta Mózesnek, amint végzett azzal, hogy beszéljen vele, a Szináj hegyén, a bizonyság két tábláját, kőtáblákat, írva Isten ujjával.