< Exodus 31 >

1 Olúwa wí fún Mose pé,
Et l'Éternel adressa ces paroles à Moïse:
2 “Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
Vois, j'ai appelé nommément Betsaléel, fils de Ouri, fils de Hur, de la tribu de Juda,
3 Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
et je le remplis de l'esprit de Dieu, de sens, d'intelligence, d'entente et d'industrie en tout genre,
4 Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
pour concevoir des idées, pour travailler l'or et l'argent et l'airain,
5 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
pour graver les pierres à enchâsser, pour ouvrager le bois et exécuter toutes sortes de travaux.
6 Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
Et voici, je lui ai adjoint Oholiab, fils d'Ahisamach, de la tribu de Dan, et j'ai mis de l'intelligence dans l'esprit de tous ceux qui ont un esprit intelligent, afin qu'ils exécutent tout ce que je t'ai prescrit,
7 “àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
la Tente du Rendez-vous et l'Arche du Témoignage et le Propitiatoire qui la couvre et tous les meubles de la tente,
8 tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
et la Table et ses ustensiles et le Candélabre d'or pur et tout son attirail, et l'Autel aux parfums
9 pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
et l'Autel des holocaustes et tous ses ustensiles, et le Bassin et son support, et les tissus de mailles,
10 àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
et les Vêtements sacrés du prêtre Aaron et les habits de ses fils pour l'usage du sacerdoce,
11 òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
et l'Huile de l'onction et l'Encens d'aromates pour l'usage du Sanctuaire: qu'ils se conforment dans l'exécution à tous les ordres que je t'ai donnés.
12 Olúwa wí fún Mose pé,
Et l'Éternel s'adressa à Moïse en ces mots:
13 “Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
Adresse ces paroles aux enfants d'Israël: Observez bien mes sabbats; car ils serviront de signe entre moi et vous dans vos âges futurs pour vous faire comprendre que c'est moi, l'Éternel, qui vous ai consacrés.
14 “‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
Observez donc le jour du repos, car il est sacré pour vous; qui le profanera sera mis à mort; toute personne qui l'emploiera à une affaire sera extirpée du milieu de son peuple.
15 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
Six jours l'on vaquera à ses affaires, mais au septième c'est jour de repos consacré à l'Éternel; quiconque fera une affaire le septième jour sera mis à mort.
16 Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
Ainsi les enfants d'Israël garderont le sabbat en observant le jour du repos dans leurs âges futurs comme une institution éternelle.
17 Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
Ce sera éternellement un signe entre moi et les enfants d'Israël; car en six jours l'Éternel a fait les cieux et la terre, et le septième jour Il s'est reposé et a repris haleine.
18 Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.
Et quand Il eut achevé de parler avec Moïse sur le mont de Sinaï, Il lui remit les Deux Tables du Témoignage, tables de pierre écrites du doigt de Dieu.

< Exodus 31 >