< Exodus 31 >

1 Olúwa wí fún Mose pé,
And YHWH speaks to Moses, saying,
2 “Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
“See, I have called by name Bezaleel, son of Uri, son of Hur, of the tribe of Judah,
3 Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
and I fill him [with] the Spirit of God, in wisdom, and in understanding, and in knowledge, and in all work,
4 Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
to devise inventions to work in gold, and in silver, and in bronze,
5 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
and in a carving of stone for settings, and in a carving of wood to work in all work.
6 Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
And I, behold, have given with him Aholiab, son of Ahisamach, of the tribe of Dan, and I have given wisdom in the heart of every wise-hearted one, and they have made all that which I have commanded you.
7 “àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
The Tent of Meeting, and the Ark of Testimony, and the propitiatory covering which [is] on it, and all the vessels of the tent,
8 tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
and the table and its vessels, and the pure lampstand and all its vessels, and the altar of the incense,
9 pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
and the altar of the burnt-offering and all its vessels, and the laver and its base,
10 àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
and the colored garments, and the holy garments for Aaron the priest, and the garments of his sons, for acting as priests in;
11 òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
and the anointing oil, and the incense of the spices for the holy place; according to all that I have commanded you—they do.”
12 Olúwa wí fún Mose pé,
And YHWH speaks to Moses, saying,
13 “Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
“And you, speak to the sons of Israel, saying, Surely you keep My Sabbaths, for it [is] a sign between Me and you throughout your generations, to know that I, YHWH, am sanctifying you;
14 “‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
and you have kept the Sabbath, for it [is] holy to you, he who is defiling it is certainly put to death—for any who does work in it—that person has even been cut off from the midst of his people.
15 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
[For] six days work is done, and in the seventh day [is] a Sabbath of holy rest to YHWH; any who does work in the Sabbath day is certainly put to death,
16 Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
and the sons of Israel have observed the Sabbath; to keep the Sabbath throughout their generations [is] a perpetual covenant—
17 Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
it [is] a sign between Me and the sons of Israel for all time; for [in] six days YHWH made the heavens and the earth, and in the seventh day He has ceased and is refreshed.”
18 Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.
And He gives to Moses, when He finishes speaking with him in Mount Sinai, two tablets of the Testimony, tablets of stone, written by the finger of God.

< Exodus 31 >