< Exodus 31 >
Og Herren talede til Mose og sagde:
2 “Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
Se, jeg har kaldet Bezaleel, en Søn af Uri, som var en Søn af Hur, af Juda Stamme, ved Navn.
3 Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
Og jeg har opfyldt ham med Guds Aand, med Visdom og med Forstand og med Kundskab, og det i alle Haande Gerning,
4 Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
til at udtænke Kunstværker, til at arbejde i Guld og i Sølv og i Kobber
5 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
og til at udskære Stene, til at indfatte, og til at udskære Træ, til at gøre alle Haande Gerning.
6 Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
Og jeg, se, jeg har medgivet ham Oholiab, Ahisamaks Søn af Dans Stamme, og i hvers Hjerte, som er forstandig, har jeg givet Visdom; og de skulle gøre alt det, som jeg har befalet dig:
7 “àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
Nemlig Forsamlingens Paulun og Vidnesbyrdets Ark og Naadestolen, som er derpaa, og alt Redskab til Paulunet,
8 tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
og Bordet med dets Redskab og den rene Lysestage med alt dens Redskab og Røgelsealteret
9 pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
og Brændofferets Alter med alt dets Redskab og Kedelen med dens Fod
10 àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
og Tjenestens Klæder og Arons, Præstens, hellige Klæder og hans Sønners Klæder til at gøre Præstetjeneste udi
11 òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
og Salveolien og Røgelsen af vellugtende Urter til Helligdommen; efter alt det, som jeg har befalet dig, skulle de gøre det.
Og Herren talede til Mose og sagde:
13 “Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
Og du, tal til Israels Børn og sig: I skulle visselig holde mine Sabbater; thi det er et Tegn imellem mig og imellem eder hos eders Efterkommere, at I skulle vide, at jeg er Herren, som helliger eder.
14 “‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
Derfor skulle I holde Sabbaten, thi den skal være eder hellig; den der vanhelliger den, skal visselig dødes; thi hver som gør Arbejde paa den, den Sjæl skal udryddes af sit Folks Midte.
15 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
Seks Dage skal al Gerning gøres, men paa den syvende Dag er Sabbatshvile, en Hellighed for Herren; hver den, som gør Arbejde paa Sabbatsdagen, skal visselig dødes.
16 Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
Derfor skulle Israels Børn tage Vare paa Sabbaten, saa at de holde Sabbaten, hos deres Efterkommere til en evig Pagt.
17 Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
Den er et evigt Tegn imellem mig og imellem Israels Børn; thi i seks Dage gjorde Herren Himmelen og Jorden, og paa den syvende Dag hvilede han og vederkvægede sig.
18 Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.
Og han gav Mose, der han havde endt at tale med ham paa Sinai Bjerg, to Vidnesbyrdets Tavler, Stentavler, skrevne med Guds Finger.