< Exodus 31 >
I mluvil Hospodin k Mojžíšovi, řka:
2 “Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
Hle, povolal jsem ze jména Bezeleele, syna Uri, syna Hur, z pokolení Judova.
3 Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
A naplnil jsem ho duchem Božím, moudrostí a rozumností, i uměním všelijakého řemesla,
4 Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
Aby vtipně smysliti uměl, což by koli řemeslně uděláno býti mohlo z zlata a z stříbra i z mědi.
5 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
I v řezání kamení drahého k vsazování, i v umělém vysazování na dřevě aby dělal všelijaké dílo.
6 Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
A aj, já přidal jsem jemu Aholiaba, syna Achisamechova, z pokolení Dan. A v srdci každého vtipného složil jsem moudrost, aby spravili vše, což jsem přikázal tobě:
7 “àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
Stánek úmluvy a truhlu svědectví, a slitovnici, kteráž má býti na ní, i všelijaké nádobí stánku;
8 tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
Stůl také a nádoby k němu, i svícen čistý se všemi nádobami jeho, a oltář pro kadění;
9 pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
Též oltář k zápalům se všemi nádobami jeho, a umyvadlo s podstavkem jeho;
10 àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
I roucha k službě, i roucha svatá Aronovi knězi, i roucha synů jeho, aby mi úřad kněžský konali;
11 òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
I olej pomazání a kadidlo vonné do svatyně. Všecko tak, jakž jsem přikázal tobě, udělají.
Mluvil také Hospodin k Mojžíšovi, řka:
13 “Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
Ty pak mluv k synům Izraelským a rci: A však sobot mých ostříhati budete. Nebo to znamením jest mezi mnou a vámi po rodech vašich, aby známo bylo, že já jsem Hospodin, kterýž vás posvěcuji.
14 “‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
Protož ostříhati budete soboty, nebo svatá jest vám. Kdož by ji poškvrnil, smrtí umře; a kdo by koli dělal v ní dílo, vyhlazena bude ta duše z prostředku lidu svého.
15 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
Šest dní děláno bude dílo, ale v den sedmý sobota odpočinutí jest, svatost Hospodinu. Každý, kdož by dělal dílo v den sobotní, smrtí umře.
16 Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
Protož ostříhati budou synové Izraelští soboty, tak aby světili sobotu po rodech svých smlouvou věčnou.
17 Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
Mezi mnou a syny Izraelskými za znamení jest na věčnost; nebo šest dní činil Hospodin nebe i zemi, v den pak sedmý přestal a odpočinul.
18 Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.
I dal Pán Mojžíšovi po dokonání těchto řečí s ním na hoře Sinai dvě dsky svědectví, dsky kamenné, psané prstem Božím.