< Exodus 30 >

1 “Ìwọ yóò sì ṣe pẹpẹ igi kasia kan; máa jó tùràrí lórí rẹ̀.
Сэ фачь апой ун алтар пентру ардеря тэмыий, ши ануме сэ-л фачь дин лемн де салкым.
2 Kí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ṣe déédé, kí ó jẹ́ ìdajì mita ní gígùn, ìdajì mita ní fífẹ̀ àti ìgbọ̀nwọ́ méjì ni gíga rẹ̀—kí ìwo rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Лунӂимя луй сэ фие де ун кот, яр лэцимя, тот де ун кот; сэ фие ын патру колцурь, ши ынэлцимя луй сэ фие де дой коць. Коарнеле алтарулуй сэ фие динтр-о букатэ ку ел.
3 Ìwọ yóò sì bo òkè rẹ̀, gbogbo ìhà rẹ̀ àti ìwo rẹ̀ pẹ̀lú u kìkì wúrà, ìwọ yóò sì ṣe wúrà gbà á yíká.
Сэ-й полеешть ку аур курат атыт партя де сус, кыт ши переций луй де жур ымпрежур ши коарнеле ши сэ-й фачь о кунунэ де аур де жур ымпрежур.
4 Ìwọ yóò sì ṣe òrùka wúrà méjì fún pẹpẹ náà níṣàlẹ̀ ìgbátí méjèèjì ní òdìkejì ìhà rẹ̀—láti gbá àwọn òpó rẹ̀ mú, láti lè máa fi gbé e.
Дедесубтул кунуний, сэ-й фачь доуэ вериӂь де аур, де амындоуэ латуриле, ын челе доуэ унгюрь, пентру пунеря друӂилор каре вор служи ла дучеря луй.
5 Ìwọ yóò sì ṣe òpó igi kasia, ìwọ yóò sì bọ́ wọ́n pẹ̀lú wúrà.
Друӂий сэ-й фачь дин лемн де салкым ши сэ-й полеешть ку аур.
6 Ìwọ yóò gbé pẹpẹ náà sí iwájú aṣọ ìkélé, èyí tí ó wà níwájú àpótí ẹ̀rí níwájú ìtẹ́ àánú èyí tí ó wà lórí àpótí ẹ̀rí níbi ti èmi yóò ti máa bá ọ pàdé.
Сэ ашезь алтарул ын фаца перделей динэунтру, каре есте ынаинтя кивотулуй мэртурией, ын фаца капакулуй испэширий, каре есте дясупра мэртурией ши унде Мэ вой ынтылни ку тине.
7 “Aaroni yóò sì máa jó tùràrí dídùn lórí pẹpẹ náà ní àràárọ̀, nígbà tí ó tún àwọn fìtílà náà ṣe.
Аарон ва арде пе ел тэмые мироситоаре; ва арде тэмые ын фиекаре диминяцэ, кынд ва прегэти канделеле;
8 Aaroni yóò sì tún jó tùràrí nígbà tí ó bá tan fìtílà ní àṣálẹ́, bẹ́ẹ̀ ní tùràrí yóò máa jó títí láé níwájú Olúwa fún àwọn ìran tó ń bọ̀.
ва арде ши сяра кынд ва ашеза канделеле. Астфел се ва арде некурмат дин партя воастрэ тэмые ынаинтя Домнулуй дин ням ын ням.
9 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mú àjèjì tùràrí wá sórí pẹpẹ yìí tàbí ẹbọ sísun kankan tàbí ọrẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ da ẹbọ ohun mímu sórí i rẹ̀.
Сэ ну адучець пе алтар алтфел де тэмые, нич ардере-де-тот, нич жертфэ де мынкаре ши сэ ну турнаць пе ел ничо жертфэ де бэутурэ.
10 Aaroni yóò sì máa ṣe ètùtù sórí àwọn ìwo rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan lọ́dún. Òun yóò sì máa ṣe ètùtù ọdọọdún yìí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ètùtù fún ìran tó ń bọ̀. Mímọ́ jùlọ ni sí Olúwa.”
Нумай о датэ пе фиекаре ан, Аарон ва фаче испэшире пе коарнеле алтарулуй. Испэширя ачаста о ва фаче о датэ пе ан ку сынӂеле добитокулуй адус ка жертфэ пентру испэширя пэкатулуй, принтре урмаший воштри. Ачеста ва фи ун лукру прясфынт ынаинтя Домнулуй.”
11 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mose pé,
Домнул а ворбит луй Мойсе ши а зис:
12 “Nígbà tí ìwọ bá ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti mọ iye wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn gbọdọ̀ mú ìràpadà ọkàn rẹ̀ wá fún Olúwa ní ìgbà tí o bá ka iye wọn. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn kì yóò súnmọ́ wọn, nígbà tí o bá ń ka iye wọn.
„Кынд вей сокоти пе копиий луй Исраел ши ле вей фаче нумэрэтоаря, фиекаре дин ей сэ дя Домнулуй ун дар ын бань пентру рэскумпэраря суфлетулуй луй, ка сэ ну фие ловиць де ничо урӂие, ку прилежул ачестей нумэрэторь.
13 Olúkúlùkù ẹrù tí ó bá kọjá lọ sọ́dọ̀ àwọn tí a ti kà yóò san ìdajì ṣékélì, gẹ́gẹ́ bí ṣékélì ibi mímọ́, èyí tí ó wọn ogún gera. Ìdajì ṣékélì yìí ní ọrẹ fún Olúwa.
Ятэ че вор да тоць чей че вор фи куприншь ын нумэрэтоаря ачаста: о жумэтате де сиклу, дупэ сиклул Сфынтулуй Локаш, каре есте де доуэзечь де гере; о жумэтате де сиклу ва фи дарул ридикат пентру Домнул.
14 Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá sínú àwọn tí a kà láti ẹni ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni yóò fi ọrẹ fún Olúwa.
Орьче ом купринс ын нумэрэтоаре, де ла вырста де доуэзечь де ань ын сус, ва плэти дарул ридикат пентру Домнул.
15 Àwọn olówó kì yóò san ju ìdajì ṣékélì lọ, àwọn tálákà kò sì gbọdọ̀ dín ní ìdajì ṣékélì nígbà tí ẹ̀yin bá mú ọrẹ wá fún Olúwa láti ṣe ètùtù fún ọkàn yín.
Богатул сэ ну плэтяскэ май мулт ши сэракул сэ ну плэтяскэ май пуцин де о жумэтате де сиклу ка дар ридикат пентру Домнул, пентру рэскумпэраря суфлетелор.
16 Ìwọ yóò sì gba owó ètùtù náà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ yóò sì fi lélẹ̀ fún ìsìn àgọ́ àjọ. Yóò jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli níwájú Olúwa, láti ṣe ètùtù fún ọkàn yín.”
Сэ ридичь де ла копиий луй Исраел арӂинтул пентру рэскумпэраре ши сэ-л ынтребуинцезь пентру служба кортулуй ынтылнирий; ачаста ва фи пентру копиий луй Исраел о адучере аминте ынаинтя Домнулуй пентру рэскумпэраря суфлетелор лор.”
17 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mose pé,
Домнул а ворбит луй Мойсе ши а зис:
18 “Ìwọ yóò sì ṣe agbada idẹ kan, àti ẹsẹ̀ rẹ̀ idẹ, fún wíwẹ̀. Ìwọ yóò sì gbé e sí àárín àgọ́ àjọ àti pẹpẹ náà, ìwọ yóò sì pọn omi sínú rẹ̀.
„Сэ фачь ун лигян де арамэ, ку пичорул луй де арамэ, пентру спэлат; сэ-л ашезь ынтре кортул ынтылнирий ши алтар ши сэ торнь апэ ын ел,
19 Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wẹ ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn pẹ̀lú omi tí ó wà nínú rẹ̀.
ка сэ-шь спеле ын ел Аарон ши фиий луй мыниле ши пичоареле.
20 Nígbàkígbà tí wọ́n bá wọ inú àgọ́ àjọ, wọ́n yóò wẹ̀ pẹ̀lú omi nítorí kí wọ́n má ba à kú. Bákan náà, nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi pẹpẹ láti ṣe ìsìn, láti mú ẹbọ ti a fi iná sun wá fún Olúwa,
Кынд вор интра ын кортул ынтылнирий, се вор спэла ку апа ачаста, ка сэ ну моарэ, ши се вор спэла ши кынд се вор апропия де алтар, ка сэ факэ служба ши ка сэ адукэ Домнулуй жертфе арсе де фок.
21 wọn yóò sì wẹ ọwọ́ wọn àti ẹsẹ̀ wọn, nítorí kí wọn máa ba à kú. Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà títí láé fún Aaroni àti irú àwọn ọmọ rẹ̀ fún ìrandíran wọn.”
Ышь вор спэла мыниле ши пичоареле ка сэ ну моарэ. Ачаста ва фи о леӂе некурматэ пентру Аарон, пентру фиий луй ши пентру урмаший лор.”
22 Olúwa sọ fún Mose pé,
Домнул а ворбит луй Мойсе ши а зис:
23 “Ìwọ yóò mú ààyò tùràrí olóòórùn sí ọ̀dọ̀ rẹ; ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ṣékélì (kilogiramu mẹ́fà) tí òjìá ṣíṣàn, ìdajì bí ó bá yẹ àádọ́ta lé nígba ṣékélì tí kinamoni dídùn, àti kénì dídùn àádọ́ta lé nígba ṣékélì,
„Я дин челе май буне миродений, чинч суте де сикли де смирнэ фоарте куратэ, жумэтате, адикэ доуэ суте чинчзечь де сикли, де скорцишоарэ мироситоаре, доуэ суте чинчзечь де сикли де трестие мироситоаре,
24 kasia ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ṣékélì gbogbo rẹ̀ ní ìlànà ṣékélì ibi mímọ́ àti hínì òróró olifi kan (lita mẹ́rin).
чинч суте де сикли де касия, дупэ сиклул Сфынтулуй Локаш, ши ун хин де унтделемн де мэслине.
25 Ṣe ìwọ̀nyí ní òróró mímọ́ ìkunra, tí a pò gẹ́gẹ́ bí olùṣe òórùn dídùn tì í ṣe. Yóò jẹ òróró mímọ́ ìtasórí.
Ку еле сэ фачь ун унтделемн пентру унӂеря сфынтэ, о аместекэтурэ мироситоаре, фэкутэ дупэ мештешугул фэкэторулуй де мир; ачеста ва фи унтделемнул пентру унӂеря сфынтэ.
26 Ìwọ yóò sì lò ó láti ya àgọ́ sí mímọ́ àti àpótí ẹ̀rí náà,
Ку ел сэ унӂь кортул ынтылнирий ши кивотул мэртурией,
27 tábìlì àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà àti ohun èlò rẹ̀, àti pẹpẹ tùràrí,
маса ши тоате унелтеле ей, сфешникул ши унелтеле луй, алтарул тэмыерий,
28 pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, àti agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
алтарул ардерилор-де-тот, ку тоате унелтеле луй, ши лигянул ку пичорул луй.
29 Ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, nítorí kí wọn lè jẹ́ mímọ́ jùlọ, àti ohunkóhun tí ó bá fi ọwọ́ kàn wọn yóò di mímọ́.
Сэ сфинцешть ачесте лукрурь, ши еле вор фи прясфинте; орьчине се ва атинӂе де еле ва фи сфинцит.
30 “Ìwọ yóò sì ta òróró sí orí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, nítorí kí wọn lè sìn mí bí àlùfáà.
Сэ унӂь, де асеменя, пе Аарон ши пе фиий луй ши сэ-й сфинцешть, ка сэ фие ын служба Мя ка преоць.
31 Ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Èyí ni yóò ṣe òróró mímọ́ ìtasórí mi fún ìrandíran tó ń bọ̀.
Сэ ворбешть копиилор луй Исраел ши сэ ле спуй: ‘Ачеста Ымь ва фи унтделемнул пентру унӂеря сфынтэ, принтре урмаший воштри.
32 Má ṣe dà á sí ara ènìyàn kí o má sì ṣe ṣe òróró kankan ni irú rẹ̀. Mímọ́ ni, ẹ̀yin sì gbọdọ̀ kà á sí mímọ́.
Сэ ну се унгэ ку ел трупул ничунуй ом ши сэ ну фачець ун алт унтделемн ка ел дупэ ачеяшь ынтокмире; ел есте сфынт, ши вой сэ-л привиць ка сфынт.
33 Ẹnikẹ́ni tí ó bá po irú rẹ̀, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá fi sára àlejò yàtọ̀ sí àlùfáà, a ó gé e kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.’”
Орьчине ва фаче ун унтделемн ка ел сау ва унӂе ку ел пе алтул ва фи нимичит дин попорул луй.’”
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú tùràrí olóòórùn dídùn sọ́dọ̀ rẹ, onika, àti galibanumu àti kìkì tùràrí dáradára, òsùwọ̀n kan fún gbogbo rẹ,
Домнул а зис луй Мойсе: „Я миродений, стакте, ониче мироситоаре, халван ши тэмые куратэ ын ачеяшь мэсурэ.
35 ṣe tùràrí olóòórùn dídùn tí a pò, iṣẹ́ àwọn olóòórùn, tí ó ní iyọ̀, ó dára, ó sì jẹ́ mímọ́.
Ку еле сэ фачь тэмые, о аместекэтурэ мироситоаре, алкэтуитэ дупэ мештешугул фэкэторулуй де мир; сэ фие сэратэ, куратэ ши сфынтэ.
36 Ìwọ yóò sì lọ díẹ̀ nínú rẹ̀ kúnná, ìwọ yóò sì gbé e síwájú ẹ̀rí ní àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti pàdé yín. Yóò sì jẹ́ mímọ́ jùlọ fún yín.
С-о писезь мэрунт ши с-о пуй ынаинтя мэртурией, ын кортул ынтылнирий, унде Мэ вой ынтылни ку тине. Ачеста ва фи пентру вой ун лукру прясфынт.
37 Ẹ má ṣe ṣe tùràrí kankan ní irú èyí fúnra yín; ẹ kà á ní mímọ́ sí Olúwa.
Тэмые ка ачаста, ын ачеяшь ынтокмире, сэ ну вэ фачець, чи с-о привиць ка сфынтэ ши пэстратэ пентру Домнул.
38 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe irú rẹ̀ láti máa gbádùn òórùn rẹ̀, òun ni a ó gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.”
Орьчине ва фаче тэмые ка еа ка с-о мироасе ва фи нимичит дин попорул луй.”

< Exodus 30 >