< Exodus 3 >
1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Men Mose vaktade sins svärs Jethro får, Prestens i Midian; och han dref fåren bak in i öknena, och kom till Guds berg Horeb.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
Och Herrans Ängel syntes honom uti en brinnande låga utu buskanom. Och han såg, att busken brann af elden, och vardt dock icke förtärd.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Och sade: Jag vill gå dit, och bese denna stora synena, hvi busken icke uppbrinner.
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Då Herren såg, att han gick åstad till att se, kallade Gud honom utu buskanom, och sade: Mose, Mose. Han svarade: Här är jag.
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Han sade: Träd icke hit, drag dina skor af dina fötter; ty rummet, der du står uppå, är ett heligt land.
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Och han sade ytterligare: Jag är dins faders Gud, Abrahams Gud, Isaacs Gud och Jacobs Gud. Och Mose skylde sitt ansigte; ty han fruktade se uppå Gud.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
Och Herren sade: Jag hafver sett mins folks jämmer uti Egypten, och jag hafver hört deras rop öfver dem, som drifva dem; jag hafver förnummit deras vedermödo;
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
Och är nederstigen till att frälsa dem utu de Egyptiers våld; och föra dem utu det landet, in uti ett godt och vidt land, som flytandes är med mjölk och hannog, såsom är på den platsen, som de Cananeer, Hetheer, Amoreer, Phereseer, Heveer och Jebuseer bo.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Så efter nu Israels barnas rop är kommet före mig, och jag dertill hafver skådat deras tvång, der de Egyptier dem med betvinga;
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Så gack nu, jag vill sända dig till Pharao, att du skall föra mitt folk Israels barn utur Egypten.
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Mose sade till Gud: Ho är jag, att jag gå skulle till Pharao, och föra Israels barn utur Egypten?
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Han sade: Jag vill vara med dig, och detta skall vara dig för ett tecken, att jag hafver sändt dig; då du hafver fört mitt folk utur Egypten, skolen I offra Gudi på desso bergena.
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Mose sade till Gud: Si, när jag kommer till Israels barn, och säger till dem: Edra fäders Gud hafver sändt mig till eder; och de säga till mig: Hvad är hans namn? hvad skall jag säga dem?
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Sade Gud till Mose: Jag skall vara den jag vara skall; och sade: Så skall du säga till Israels barn: Jag skall varat, han hafver sändt mig till eder.
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
Och Gud sade ytterligare till Mose: Så skall du säga till Israels barn: Herren, edra fäders Gud, Abrahams Gud, Isaacs Gud och Jacobs Gud, hafver sändt mig till eder: Detta Namnet är mig evinnerliga; det skall vara min åminnelse ifrå barn och till barnabarn.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Derföre gack åstad, och församla de äldsta af Israel, och säg till dem: Herren, edra fäders Gud, hafver synts mig, Abrahams Gud, Isaacs Gud och Jacobs Gud, och sagt: Jag hafver sökt eder, och sett hvad eder vederfaret är uti Egypten;
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
Och hafver sagt: Jag skall föra eder utu den Egyptiska jämmeren in uti de Cananeers, Hetheers, Amoreers, Phereseers, Heveers och Jebuseers land, uti det land, der mjölk och hannog uti flyter.
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Och då de höra dina röst, skall du och de äldste af Israel gå in till Konungen i Egypten, och säga till honom: Herren, de Ebreers Gud, hafver kallat oss. Så låt oss nu gå tre dagsresor in uti öknena, till att offra Herranom vårom Gud.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Men jag vet, att Konungen i Egypten icke skall låta eder fara, utan genom stark under.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Ty jag skall uträcka mina hand, och slå Egypten med allahanda under, som jag derinne göra skall; sedan skall han låta fara eder.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
Och jag vill gifva desso folkena nåde för de Egyptier, att när I utfaren, skolen I icke utgå med tomma händer;
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Utan hvar och en qvinna skall bedas af hennes grannqvinno och värdinno silfver och gyldene tyg, och kläder; dem skolen I lägga på edra söner och döttrar, och blotta de Egyptier.