< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Мойсе пэштя турма сокрулуй сэу, Иетро, преотул Мадианулуй. Одатэ, а мынат турма пынэ динколо де пустиу ши а ажунс ла мунтеле луй Думнезеу, ла Хореб.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
Ынӂерул Домнулуй и С-а арэтат ынтр-о флакэрэ де фок, каре ешя дин мижлокул унуй руг. Мойсе с-а уйтат ши ятэ кэ ругул ера тот ун фок ши ругул ну се мистуя делок.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Мойсе а зис: „Ам сэ мэ ынторк сэ вэд че есте ачастэ ведение минунатэ ши пентру че ну се мистуе ругул.”
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Домнул а вэзут кэ ел се ынтоарче сэ вадэ ши Думнезеу л-а кемат дин мижлокул ругулуй ши а зис: „Мойсе! Мойсе!” Ел а рэспунс: „Ятэ-мэ!”
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Думнезеу а зис: „Ну те апропия де локул ачеста; скоате-ць ынкэлцэминтя дин пичоаре, кэч локул пе каре калчь есте ун пэмынт сфынт.”
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Ши а адэугат: „Еу сунт Думнезеул татэлуй тэу, Думнезеул луй Авраам, Думнезеул луй Исаак ши Думнезеул луй Иаков.” Мойсе шь-а аскунс фаца, кэч се темя сэ-Л привяскэ пе Думнезеу.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
Домнул а зис: „Ам вэзут асуприря попорулуй Меу, каре есте ын Еӂипт, ши ам аузит стригэтеле пе каре ле скоате дин причина асуприторилор луй, кэч ый куноск дурериле.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
М-ам коборыт ка сэ-л избэвеск дин мына еӂиптенилор ши сэ-л скот дин цара ачаста ши сэ-л дук ынтр-о царэ бунэ ши ынтинсэ, ынтр-о царэ унде курӂе лапте ши мьере, ши ануме ын локуриле пе каре ле локуеск канааниций, хетиций, амориций, ферезиций, хевиций ши иебусиций.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Ятэ кэ стригэтеле исраелицилор ау ажунс пынэ ла Мине ши ам вэзут кинул ку каре ый кинуеск еӂиптений.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Акум, вино, Еу те вой тримите ла Фараон ши вей скоате дин Еӂипт пе попорул Меу, пе копиий луй Исраел.”
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Мойсе а зис луй Думнезеу: „Чине сунт еу, ка сэ мэ дук ла Фараон ши сэ скот дин Еӂипт пе копиий луй Исраел?”
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Думнезеу а зис: „Еу вой фи негрешит ку тине, ши ятэ каре ва фи пентру тине семнул кэ Еу те-ам тримис: дупэ че вей скоате пе попор дин Еӂипт, вець служи луй Думнезеу пе мунтеле ачеста.”
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Мойсе а зис луй Думнезеу: „Ятэ, кынд мэ вой дуче ла копиий луй Исраел ши ле вой спуне: ‘Думнезеул пэринцилор воштри м-а тримис ла вой’ ши мэ вор ынтреба: ‘Каре есте Нумеле Луй?’, че ле вой рэспунде?”
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Думнезеу а зис луй Мойсе: „Еу сунт Чел че сунт.” Ши а адэугат: „Вей рэспунде копиилор луй Исраел астфел: ‘Чел че Се нумеште «Еу сунт» м-а тримис ла вой.’”
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
Думнезеу а май зис луй Мойсе: „Аша сэ ворбешть копиилор луй Исраел: ‘Домнул Думнезеул пэринцилор воштри, Думнезеул луй Авраам, Думнезеул луй Исаак ши Думнезеул луй Иаков, м-а тримис ла вой. Ачеста есте Нумеле Меу пентру вешничие, ачеста есте Нумеле Меу дин ням ын ням.’
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Ду-те, стрынӂе пе бэтрыний луй Исраел ши спуне-ле: ‘Ми с-а арэтат Домнул Думнезеул пэринцилор воштри, Думнезеул луй Авраам, луй Исаак ши луй Иаков. Ел а зис: «В-ам вэзут ши ам вэзут че ви се фаче ын Еӂипт
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
ши ам зис: Вэ вой скоате дин суферинца Еӂиптулуй ши вэ вой дуче ын цара канааницилор, хетицилор, аморицилор, ферезицилор, хевицилор ши иебусицилор, ынтр-о царэ унде курӂе лапте ши мьере.»’
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Ей вор аскулта де гласул тэу ши те вей дуче, ту ши бэтрыний луй Исраел, ла ымпэратул Еӂиптулуй ши ый вець спуне: ‘Домнул Думнезеул евреилор С-а ынтылнит ку ной. Дэ-не вое сэ мерӂем кале де трей зиле ын пустиу, ка сэ адучем жертфе Домнулуй Думнезеулуй ностру.’
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Штиу кэ ымпэратул Еӂиптулуй н-аре сэ вэ ласе сэ плекаць декыт силит де о мынэ путерникэ.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Еу Ымь вой ынтинде мына ши вой лови Еӂиптул ку тот фелул де минунь, пе каре ле вой фаче ын мижлокул луй. Дупэ ачея, аре сэ вэ ласе сэ плекаць.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
Вой фаче кяр ка попорул ачеста сэ капете тречере ынаинтя еӂиптенилор, ши, кынд вець плека, ну вець плека ку мыниле гоале.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Фиекаре фемее ва чере де ла вечина ей ши де ла чя каре локуеште ын каса ей васе де арӂинт, васе де аур ши хайне пе каре ле вець пуне пе фиий ши фийчеле воастре. Ши вець жефуи астфел пе еӂиптень.”

< Exodus 3 >