< Exodus 3 >
1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Agora Moisés estava mantendo o rebanho de Jetro, seu sogro, o sacerdote de Midian, e conduziu o rebanho para o fundo do deserto, e veio para a montanha de Deus, para Horebe.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
O anjo de Javé apareceu-lhe em uma chama de fogo do meio de um arbusto. Ele olhou, e eis que o arbusto ardeu com fogo, e o arbusto não foi consumido.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Moisés disse: “Eu vou agora, e verei esta grande visão, porque o arbusto não está queimado”.
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Quando Javé viu que ele veio ver, Deus o chamou do meio do mato e disse: “Moisés! Moisés!”. Ele disse: “Aqui estou eu”.
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Ele disse: “Não chegue perto. Tire suas sandálias, pois o lugar em que você está de pé é terra sagrada”.
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Moreover ele disse: “Eu sou o Deus de seu pai, o Deus de Abraão, o Deus de Isaac, e o Deus de Jacó”. Moisés escondeu seu rosto porque tinha medo de olhar para Deus.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
Yahweh disse: “Eu certamente vi a aflição de meu povo que está no Egito, e ouvi seu grito por causa de seus mestres, pois eu conheço suas tristezas.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
Desci para libertá-los da mão dos egípcios, e para trazê-los para fora daquela terra para uma terra boa e grande, para uma terra que flui com leite e mel; para o lugar do cananeu, do hitita, do amorreu, do perizeu, do hivita, e do jebuseu.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Agora, eis que o grito dos filhos de Israel chegou até mim. Além disso, vi a opressão com que os egípcios os oprimem.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Vinde agora, portanto, e eu vos enviarei ao Faraó, para que tireis meu povo, os filhos de Israel, do Egito”.
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Moisés disse a Deus: “Quem sou eu, que devo ir ao Faraó, e que devo tirar os filhos de Israel do Egito”?
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Ele disse: “Certamente eu estarei com você”. Este será o sinal para você, que eu lhe enviei: quando você tiver trazido o povo para fora do Egito, você servirá a Deus nesta montanha”.
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Moisés disse a Deus: “Eis que, quando eu for ter com os filhos de Israel e lhes disser: 'O Deus de vossos pais me enviou a vós', e eles me perguntarem: 'Qual é o seu nome?' o que devo dizer-lhes?
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Deus disse a Moisés: “EU SOU QUEM SOU”, e ele disse: “Diga isto aos filhos de Israel”: EU SOU me enviou a vocês””.
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
Deus disse ainda mais a Moisés: “Dirás isto aos filhos de Israel: 'Javé, o Deus de teus pais, o Deus de Abraão, o Deus de Isaac e o Deus de Jacó, me enviou a ti'. Este é meu nome para sempre, e este é o meu memorial para todas as gerações.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Ide reunir os anciãos de Israel e dizei-lhes: 'Javé, o Deus de vossos pais, o Deus de Abraão, de Isaac e de Jacó, me apareceu, dizendo: “Certamente vos visitei e vi o que vos foi feito no Egito.
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
Eu disse: “Eu vos tirarei da aflição do Egito para a terra do cananeu, do hitita, do amorreu, do perizeu, do hivita e do jebuseu, para uma terra que flui com leite e mel””.
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Eles ouvirão a sua voz. Virão, você e os anciãos de Israel, ao rei do Egito, e lhe dirão: 'Javé, o Deus dos hebreus, se encontrou conosco'. Agora, por favor, deixe-nos ir três dias de viagem ao deserto, para que possamos sacrificar a Javé, nosso Deus”.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Eu sei que o rei do Egito não lhe dará permissão para ir, não, não por uma mão poderosa.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Estenderei minha mão e atingirei o Egito com todas as minhas maravilhas que farei entre eles, e depois disso ele o deixará ir.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
Darei a este povo um favor aos olhos dos egípcios, e acontecerá que quando você for, não irá de mãos vazias.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Mas toda mulher deverá pedir ao seu próximo, e àquele que visitar sua casa, jóias de prata, jóias de ouro e roupas. Você as colocará em seus filhos, e em suas filhas. Pilhareis os egípcios”.