< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Mojżesz pasał stado swego teścia Jetra, kapłana Midianitów. Zaprowadził stado na drugą stronę pustyni i przyszedł do góry Bożej, do Horebu.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
I Anioł PANA ukazał mu się w płomieniu ognia, ze środka krzewu. Spojrzał, a oto krzew płonął ogniem, lecz nie spłonął.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Wtedy Mojżesz powiedział: Podejdę i zobaczę to wielkie zjawisko, dlaczego ten krzew się nie spala.
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
A gdy PAN widział, że podchodził, aby to zobaczyć, zawołał do niego Bóg ze środka tego krzewu: Mojżeszu, Mojżeszu! A on odpowiedział: Oto jestem.
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Wtedy powiedział: Nie zbliżaj się tu. Zdejmij buty z nóg, bo miejsce, na którym stoisz, jest ziemią świętą.
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
I dodał: Ja jestem Bogiem twego ojca, Bogiem Abrahama, Bogiem Izaaka i Bogiem Jakuba. I Mojżesz zakrył twarz, bo bał się patrzeć na Boga.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
PAN powiedział: Przyjrzałem się utrapieniom mojego ludu, który jest w Egipcie, i słyszałem ich krzyk z powodu nadzorców, gdyż znam jego cierpienia.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
Dlatego zstąpiłem, aby wybawić go z ręki Egipcjan i wyprowadzić z tej ziemi do ziemi dobrej i przestronnej, do ziemi opływającej mlekiem i miodem, na miejsce Kananejczyków, Chetytów, Amorytów, Peryzzytów, Chiwwitów i Jebusytów.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Teraz oto dotarł do mnie krzyk synów Izraela. Widziałem też ucisk, jakim dręczą ich Egipcjanie.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Dlatego teraz idź, poślę cię do faraona, abyś wyprowadził mój lud, synów Izraela, z Egiptu.
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Mojżesz powiedział do Boga: Kimże ja jestem, abym miał iść do faraona i wyprowadzić synów Izraela z Egiptu?
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Bóg odpowiedział: Oto ja będę z tobą, a to będzie znakiem dla ciebie, że ja cię posłałem: gdy wyprowadzisz ten lud z Egiptu, będziecie służyć Bogu na tej górze.
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Mojżesz powiedział do Boga: Kiedy pójdę do synów Izraela i powiem im: Bóg waszych ojców posłał mnie do was, a oni zapytają mnie, jakie jest jego imię, cóż im odpowiem?
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Wtedy Bóg odrzekł do Mojżesza: JESTEM, KTÓRY JESTEM. I dodał: Tak powiesz synom Izraela: JESTEM posłał mnie do was.
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
I mówił jeszcze Bóg do Mojżesza: Tak powiesz synom Izraela: PAN, Bóg waszych ojców, Bóg Abrahama, Bóg Izaaka i Bóg Jakuba, posłał mnie do was. To jest moje imię na wieki i takim ma pozostać w pamięci po wszystkie pokolenia.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Idź, zgromadź starszych Izraela i mów do nich: Ukazał mi się PAN, Bóg waszych ojców, Bóg Abrahama, Izaaka i Jakuba, i powiedział: Nawiedziłem was i [widziałem], co wam uczyniono w Egipcie.
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
I postanowiłem: Wyprowadzę was z utrapienia Egiptu do ziemi Kananejczyków, Chetytów, Amorytów, Peryzzytów, Chiwwitów i Jebusytów, do ziemi opływającej mlekiem i miodem.
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Wtedy usłuchają twego głosu. I pójdziesz ty i starsi Izraela do króla Egiptu i powiecie do niego: PAN, Bóg Hebrajczyków, spotkał się z nami. Dlatego teraz pozwól nam pójść, proszę, w trzy dni drogi na pustynię, aby złożyć ofiarę PANU, naszemu Bogu.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Wiem, że król Egiptu nie pozwoli wam odejść, chyba że przez potężną rękę.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Wyciągnę więc rękę i uderzę Egipt wszystkimi moimi cudami, które będę czynił pośród niego. A potem was wypuści.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
Sprawię, że ten lud znajdzie przychylność w oczach Egipcjan. I stanie się tak, gdy będziecie wychodzić, [że] nie wyjdziecie z pustymi rękami.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Ale każda kobieta pożyczy od swojej sąsiadki i od tej, która u niej przebywa, srebrne i złote przedmioty oraz szaty. Włożycie je na waszych synów i na wasze córki i złupicie Egipt.

< Exodus 3 >