< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
UMozisi wayeselusa-ke umhlambi kaJetro uyisezala, umpristi weMidiyani; waqhuba umhlambi waya ngaphambili kwenkangala waze wafika entabeni kaNkulunkulu, eHorebe.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
Njalo ingilosi yeNkosi yabonakala kuye elangabini lomlilo liphuma phakathi kwesihlahla; wasebona, khangela-ke, isihlahla sivutha umlilo, kodwa isihlahla sasingapheli.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
UMozisi wasesithi: Ngizaphambuka-ke ngibone lo umbono omkhulu, ukuthi kungani isihlahla singatshi.
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Kwathi iNkosi isibonile ukuthi uphambukile ukuyabona, uNkulunkulu wambiza ephakathi kwesihlahla, wathi: Mozisi, Mozisi! Wasesithi: Khangela ngilapha.
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Wasesithi: Ungasondeli lapha; khupha amanyathela akho enyaweni zakho, ngoba indawo omi kuyo ingumhlabathi ongcwele.
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Wathi futhi: NginguNkulunkulu kayihlo, uNkulunkulu kaAbrahama, uNkulunkulu kaIsaka, loNkulunkulu kaJakobe. UMozisi wasefihla ubuso bakhe, ngoba esesaba ukukhangela uNkulunkulu.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
INkosi yasisithi: Isibili ngibonile ukuhlupheka kwesizwe sami esiseGibhithe, ngizwile ukukhala kwabo ngenxa yabaqhubi besibhalo babo; ngoba ngiyazazi insizi zabo;
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
njalo ngehlile ukusikhulula ezandleni zamaGibhithe, lokusenyusa kulelolizwe, ngisise elizweni elihle elibanzi, siye elizweni eligeleza uchago loluju, siye endaweni yamaKhanani lamaHethi lamaAmori lamaPerizi lamaHivi lamaJebusi.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Khathesi-ke, khangela, ukukhala kwabantwana bakoIsrayeli sekufikile kimi; njalo lami ngibonile ucindezelo amaGibhithe abacindezela ngalo.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Khathesi-ke, woza, ngizakuthuma kuFaro ukuze ukhuphe isizwe sami, abantwana bakoIsrayeli, eGibhithe.
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Kodwa uMozisi wathi kuNkulunkulu: Ngingubani mina ukuthi ngiye kuFaro, lokuthi ngikhuphe abantwana bakoIsrayeli eGibhithe?
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Wasesithi: Isibili ngizakuba lawe; lalokhu kuzakuba yisibonakaliso kuwe sokuthi mina ngikuthumile; lapho ususikhuphile isizwe eGibhithe, lizamkhonza uNkulunkulu kulintaba.
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
UMozisi wasesithi kuNkulunkulu: Khangela, nxa ngifika kubantwana bakoIsrayeli ngisithi kubo: UNkulunkulu waboyihlo ungithumile kini; bazakuthi kimi: Ungubani ibizo lakhe? Ngizathini kubo?
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
UNkulunkulu wasesithi kuMozisi: NGINGUYE ENGINGUYE. Wathi futhi: Uzakutsho njalo kubantwana bakoIsrayeli ukuthi: UNGINGUYE ungithumile kini.
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
UNkulunkulu wasesithi njalo kuMozisi: Uzakutsho njalo kubantwana bakoIsrayeli ukuthi: INkosi uNkulunkulu waboyihlo, uNkulunkulu kaAbrahama, uNkulunkulu kaIsaka, loNkulunkulu kaJakobe ungithumile kini; leli libizo lami kuze kube nininini, njalo lesi yisikhumbuzo sami kusizukulwana kusiya kusizukulwana.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Hamba, ubuthanise abadala bakoIsrayeli, uthi kubo: INkosi uNkulunkulu waboyihlo ibonakele kimi, uNkulunkulu kaAbrahama, kaIsaka, lokaJakobe, isithi: Ngokulihambela ngilihambele, lalokho elikwenziwe eGibhithe;
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
futhi ngathi ngizalenyusa enhluphekweni yeGibhithe, ngilise elizweni lamaKhanani lelamaHethi lelamaAmori lelamaPerizi lelamaHivi lelamaJebusi, liye elizweni eligeleza uchago loluju.
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Njalo bazalalela ilizwi lakho. Futhi uzakuya, wena labadala bakoIsrayeli, enkosini yeGibhithe, lithi kuyo: INkosi, uNkulunkulu wamaHebheru, ihlangene lathi; khathesi-ke, ake usiyekele sihambe ummango wensuku ezintathu siye enkangala ukuze sihlabele iNkosi uNkulunkulu wethu.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Kodwa mina ngiyazi ukuthi inkosi yeGibhithe kayiyikuliyekela lihambe, ngitsho langesandla esilamandla.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Ngakho ngizakwelula isandla sami ngilitshaye iGibhithe ngezimangaliso zami zonke engizazenza phakathi kwalo; njalo emva kwalokho izaliyekela lihambe.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
Njalo ngizanika lesisizwe umusa emehlweni amaGibhithe. Kuzakuthi-ke mhla lisukayo, kaliyikusuka lingelalutho,
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
kodwa wonke owesifazana uzacela kumakhelwane wakhe, lakuye ohlezihleziyo endlini yakhe, izinto zesiliva, lezinto zegolide, lemvunulo; lizazifaka emadodaneni enu lemadodakazini enu; lizawaphanga amaGibhithe.

< Exodus 3 >