< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Na, i te tiaki a Mohi i nga hipi a tona hungawai, a Ietoro, tohunga o Miriana; a ka arahi ia i nga hipi ki te taha ki muri o te koraha, ka tae ki te maunga o te Atua, ki Horepa.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
A ka puta ki a ia te anahera a Ihowa i roto i te mura ahi, i waenganui o tetahi rakau; a ka titiro ia, na, e toro ana te rakau i te ahi, a kihai i pau te rakau.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Na ka mea a Mohi, Ka tahuri ahau, ka matakitaki atu ki tenei mea nui kua puta nei, he aha te rakau te pau ai.
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
A ka kite a Ihowa e tahuri ana ia ki te matakitaki, ka karanga te Atua ki a ia i waenganui o te rakau, ka mea, E Mohi, e Mohi! A ka mea ia, Tenei ahau.
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Na ka mea ia, Kaua e whakatata mai ki konei; wetekina ou hu i ou waewae, ko te wahi hoki e tu na koe, he wahi tapu.
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Ka mea ano ia, Ko ahau te Atua o tou papa, te Atua o Aperahama, te Atua o Ihaka, te Atua o Hakopa. A huna ana a Mohi i tona kanohi; i wehi hoki ia ki te titiro atu ki te Atua.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
A ka mea a Ihowa, Kua kite pu ahau i te tukino o taku iwi i Ihipa, kua rongo hoki ki ta ratou aue i o ratou kaiakiaki; e mohio ana hoki ahau ki o ratou mamae;
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
A kua heke iho nei ahau ki te whakaora i a ratou i te ringa o nga Ihipiana, ki te kawe atu i a ratou i tera whenua ki tetahi whenua pai, whenua nui, ki tetahi whenua e rerengia ana e te waiu, e te honi, ki te wahi o nga Kanaani, o nga Hiti, o nga Amori, o nga Perihi, o nga Hiwi, o nga Iepuhi.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Na, kua tae ake te karanga a nga tama a Iharaira ki ahau: kua kite hoki ahau i te tukino e tukinotia nei ratou e nga Ihipiana.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Na reira, haere mai, maku koe e unga ki a Parao, a mau e whakaputa mai taku iwi, nga tama a Iharaira, i Ihipa.
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Na ka mea a Mohi ki te Atua, He aha ahau, kia haere ahau ki a Parao, kia whakaputa mai hoki i nga tama a Iharaira i Ihipa?
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
A ka mea ia, Kei a koe tonu ra ahau: ko te tohu ano tenei mou ka unga nei e ahau: ka whakaputaina mai e koe te iwi i Ihipa, ka mahi koutou ki te Atua ki runga i tenei maunga.
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Na ka mea a Mohi ki te Atua, Na ka tae ahau ki nga tama a Iharaira, ka mea ki a ratou, Na te Atua o o koutou matua ahau i ngare mai ki a koutou; a ka mea mai ratou ki ahau, Ko wai tona ingoa? Me pehea atu ahau ki a ratou?
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Na ka mea te Atua ki a Mohi, Ko AHAU ANO AHAU NEI: i mea ano ia, Kia penei atu koe ki nga tama a Iharaira, Na te AHAU NEI ahau i ngare mai ki a koutou.
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
A ka mea ano te Atua ki a Mohi, Kia penei atu koe ki nga tama a Iharaira, Na Ihowa, na te Atua o o koutou matua, na te Atua o Aperahama, na te Atua o Ihaka, na te Atua hoki o Hakopa, i tono mai ahau ki a koutou; ko toku ingoa tenei ake ake, ko t oku whakamaharatanga hoki tenei ki nga whakapaparanga katoa.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Haere, whakaminea nga kaumatua o Iharaira, mea atu ki a ratou, Kua puta mai ki ahau a Ihowa, te Atua o o koutou matua, te Atua o Aperahama, o Ihaka, o Hakopa: e ai tana, Kua tikina mai, kua tirohia marietia koutou e ahau, me nga mea e meatia ana ki a koutou i Ihipa:
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
Kua mea nei ano ahau, ka whakaputaina mai koutou e ahau i te whakawhiu a Ihipa ki te whenua o nga Kanaani, o nga Hiti, o nga Amori, o nga Perihi, o nga Hiwi, o nga Iepuhi, ki te whenua e rerengia ana e te waiu, e te honi.
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
A e rongo ratou ki tou reo; a ka haere koe, koutou tahi ko nga kaumatua o Iharaira, ki te kingi o Ihipa, ka mea ki a ia, Kua tutaki a Ihowa, te Atua o nga Hiperu ki a matou: tukua matou kia haere, kia toru nga ra e haere ana i te koraha, kia pat u ai matou he whakahere ma Ihowa, ma to matou Atua.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
A e mohio ana ahau e kore te kingi o Ihipa e tuku i a koutou, kahore, ki te kahore he ringa kaha.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
A ka takiritia toku ringa, ka patua hoki a Ihipa ki aku merekara katoa, e mea ai ahau i waenganui ona; a, muri iho, ka tukua mai koutou e ia.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
A maku e mea kia paingia tenei iwi i te aroaro o nga Ihipiana: a ka haere koutou, e kore e haere kau;
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Engari me tono e ia wahine, e ia wahine, ki tona hoa tata, ki te wahine hoki e noho ana i tona whare, he mea hiriwa, he mea korua, he kakahu; a ka hoatu ki a koutou tama, ki a koutou tamahine; a ka pahuatia e koutou nga Ihipiana.

< Exodus 3 >