< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Un Mozus ganīja Jetrus, sava tēvoča, Midijanas priestera, avis un dzina tās avis aiz tuksneša un nāca pie Dieva kalna Horebā.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
Un Tā Kunga eņģelis viņam parādījās uguns liesmā no ērkšķu krūma, un viņš skatījās un redzi, tas ērkšķu krūms dega ar uguni, bet tas ērkšķu krūms nesadega.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Tad Mozus sacīja: es jel noiešu un apraudzīšu šo lielo parādīšanu, kādēļ tas ērkšķu krūms nesadeg.
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Un Tas Kungs redzēja, ka tas gāja lūkot, un Dievs sauca uz to no tā ērkšķu krūma un sacīja: Mozu! Mozu! Un tas sacīja: redzi, še es esmu.
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Un Viņš sacīja: nenāc klāt, novelc savas kurpes no kājām, jo tā vieta, kur tu stāvi, ir svēta zeme.
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Un Viņš sacīja: Es esmu tava tēva Dievs, Ābrahāma Dievs, Īzaka Dievs un Jēkaba Dievs. Un Mozus aizklāja savu vaigu, jo tas bijās Dievu uzlūkot.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
Un Tas Kungs sacīja: Es tiešām esmu redzējis Savu ļaužu bēdas, kas ir Ēģiptes zemē un esmu dzirdējis viņu brēkšanu par saviem dzinējiem, jo viņu sāpes Es esmu ņēmis vērā.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
Tādēļ Es esmu nolaidies, tos izpestīt no ēģiptiešu rokas un tos izvest no šās zemes uz labu un plašu zemi, uz zemi, kur piens un medus tek, uz Kanaāniešu, Hetiešu, Amoriešu, Fereziešu, Hiviešu un Jebusiešu vietu.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Un nu redzi, Israēla bērnu brēkšana ir nākusi Manā priekšā, un Es arī esmu redzējis to spaidīšanu, ar ko ēģiptieši tos spaida.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Tad nu ej, Es tevi sūtīšu pie Faraona, un izvedi Manus ļaudis, Israēla bērnus, no Ēģiptes zemes.
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Tad Mozus sacīja uz Dievu: kas es esmu, ka man būs iet pie Faraona un izvest Israēla bērnus no Ēģiptes?
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Un Viņš sacīja: Es būšu ar tevi: un šī būs tev tā zīme, ka Es tevi esmu sūtījis: kad tu tos ļaudis no Ēģiptes zemes būsi izvedis, tad jūs Dievam kalposiet uz šī kalna.
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Un Mozus sacīja uz Dievu: redzi, kad es nākšu pie Israēla bērniem un uz tiem sacīšu: jūsu tēvu Dievs mani pie jums ir sūtījis, un tie uz mani saka, kāds ir Viņa vārds? Ko man tiem būs sacīt?
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Tad Dievs sacīja uz Mozu: Es Esmu, Kas Es Esmu. Un Viņš sacīja: tā tev būs sacīt Israēla bērniem: Es Esmu, Tas mani pie jums ir sūtījis.
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
Un Dievs vēl sacīja Mozum: tā tev būs sacīt Israēla bērniem: Tas Kungs, jūsu tēvu Dievs, Ābrahāma Dievs, Īzaka Dievs un Jēkaba Dievs, mani pie jums ir sūtījis; šis ir Mans vārds mūžīgi, un šī ir Mana piemiņa uz bērnu bērniem.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Ej un sapulcini Israēla vecajus un saki tiem: Tas Kungs, jūsu tēvu Dievs, man ir parādījies, Ābrahāma, Īzaka un Jēkaba Dievs, un sacījis: Es esmu nācis jūs raudzīt un to, kas jums darīts Ēģiptes zemē.
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
Un Es esmu sacījis: Es jūs izvedīšu no ēģiptiešu spaidīšanas uz Kanaāniešu, Hetiešu, Amoriešu, Fereziešu, Hiviešu un Jebusiešu zemi, uz zemi, kur piens un medus tek.
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Un kad tie klausīs tavai balsij, tad tev ar Israēla vecajiem būs iet pie Ēģiptes ķēniņa un uz to sacīt: Tas Kungs, tas Ebreju Dievs, mūs ir sastapis. Un nu lai ejam treju dienu gājumu tuksnesī, upurēt Tam Kungam, savam Dievam.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Bet Es zinu, ka Ēģiptes ķēniņš jums neļaus iet, pat ne caur stipru roku.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Tad Es izstiepšu Savu roku un sitīšu Ēģiptes zemi ar visiem Saviem brīnumiem, ko Es viņas vidū darīšu; tad viņš jūs atlaidīs.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
Un Es tiem ļaudīm došu žēlastību ēģiptiešu priekšā, un kad jūs iziesiet, tad jūs neiziesiet tukši.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Bet ikvienai sievai no savas kaimiņienes un no tās, kas dzīvo viņas namā, būs prasīt zelta un sudraba traukus un drēbes, tos jums būs likt uz saviem dēliem un savām meitām un ēģiptiešiem atņemt.

< Exodus 3 >