< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Na rĩrĩ, Musa nĩ kũrĩithia arĩithagia rũũru rwa mbũri rwa mũthoni-we Jethero, mũthĩnjĩri-ngai wa Midiani, nake agĩtongoria rũũru rũu rwa mbũri mwena ũũrĩa ũngĩ wa werũ kũraya ma, na agĩkinya Horebu, kĩrĩma-inĩ kĩa Ngai.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
Arĩ kũu-rĩ, akiumĩrĩrwo nĩ mũraika wa Jehova arĩ nĩnĩmbĩ-inĩ cia mwaki ikiuma kĩhinga-inĩ. Musa akĩona atĩ o na gũtuĩka kĩhinga nĩgĩakanaga-rĩ, gĩtiahĩaga.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Nĩ ũndũ ũcio Musa agĩĩciiria atĩrĩ, “Nĩngũthiĩ ho nĩgeetha nyone ũndũ ũyũ mũgeni, menye kĩrĩa kĩragiria kĩhinga kĩhĩe.”
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Rĩrĩa Jehova onire atĩ nĩathiĩ hau gũcũthĩrĩria, Ngai akĩmwĩta arĩ kĩhinga-inĩ, “Musa! Musa!” Nake Musa agĩĩtĩka, akiuga atĩrĩ, “Niĩ ũyũ haha.”
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Nake Ngai akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũgakuhĩrĩrie haha. Ruta iraatũ ciaku magũrũ, nĩgũkorwo handũ hau ũrũgamĩte nĩ handũ hatheru.”
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Ningĩ akĩmwĩra atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ Ngai wa thoguo, Ngai wa Iburahĩmu, Ngai wa Isaaka, o na Ngai wa Jakubu.” Kahinda kau Musa akĩhitha ũthiũ wake, tondũ nĩetigĩrire kũrora Ngai.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
Jehova akiuga atĩrĩ; “Ti-itherũ nĩnyonete mĩnyamaro ya andũ akwa kũu bũrũri wa Misiri. Nĩnjiguĩte kĩrĩro kĩao nĩ ũndũ wa arũgamĩrĩri a ngombo arĩa mamahinyagĩrĩria, na nĩngũrũmbũiya ũhoro wa kũnyamarĩka kwao.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
Nĩ ũndũ ũcio nĩnjikũrũkĩte nĩguo ndĩmateithũre kuuma moko-inĩ ma andũ a Misiri, ndĩmarute bũrũri ũcio, ndĩmatware bũrũri mwega na mwariĩ, bũrũri ũrĩ bũthi wa iria na ũũkĩ, kũrĩa gũtũũragwo nĩ Akaanani, na Ahiti, na Aamori, na Aperizi, na Ahivi, na Ajebusi.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Na rĩu kĩrĩro kĩa andũ a Isiraeli nĩkĩnginyĩire, na nĩnyonete ũrĩa andũ a bũrũri wa Misiri maramahinyĩrĩria.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Nĩ ũndũ ũcio, thiĩ. Ndĩragũtũma kũrĩ Firaũni ũkarute andũ akwa a Isiraeli moime bũrũri wa Misiri.”
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
No Musa akĩũria Ngai atĩrĩ, “Niĩ ndĩ ũ wa gũthiĩ kwa Firaũni ngarute andũ a Isiraeli moime bũrũri wa Misiri?”
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Nake Ngai agĩcookia atĩrĩ, “Ndĩrĩkoragwo hamwe nawe. Naguo ũndũ ũyũ nĩguo ũgaatuĩka kĩmenyithia gĩa atĩ nĩ niĩ ngũtũmĩte: Rĩrĩa ũkaaruta andũ a Isiraeli moime bũrũri wa Misiri, nĩmũkahooyagĩra Ngai kĩrĩma-inĩ gĩkĩ.”
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Musa akĩĩra Ngai atĩrĩ, “Ingĩthiĩ kũrĩ andũ a Isiraeli ndĩmeere atĩrĩ, ‘Nĩ Ngai wa maithe manyu wandũma kũrĩ inyuĩ,’ nao manjũũrie atĩrĩ, ‘Ngai ũcio etagwo atĩa?’ ngaamacookeria atĩa?”
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Ngai akĩĩra Musa atĩrĩ, “NIĨ NDŨIRE O TA ŨRĨA NDŨIRE. Ĩra andũ a Isiraeli atĩrĩ, Ũrĩa wĩtagwo ‘NIĨ NDŨIRE nĩwe ũndũmĩte kũrĩ inyuĩ.’”
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
Ningĩ Ngai agĩcooka akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ĩra andũ a Isiraeli atĩrĩ, ‘Jehova, o we Ngai wa maithe manyu, Ngai wa Iburahĩmu, na Ngai wa Isaaka na Ngai wa Jakubu nĩandũmĩte kũrĩ inyuĩ.’ Rĩĩrĩ nĩrĩo rĩĩtwa rĩakwa nginya tene, rĩĩtwa rĩrĩa ndĩĩririkanagwo narĩo kuuma njiarwa na njiarwa.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
“Thiĩ, ũcookanĩrĩrie athuuri a Isiraeli, ũmeere atĩrĩ, ‘Jehova, Ngai wa maithe manyu o we Ngai wa Iburahĩmu, na Isaaka, na Jakubu nĩanyumĩrĩire akanjĩĩra atĩrĩ: Nĩndorete na ngoona maũndũ marĩa mwĩkĩtwo kũu bũrũri wa Misiri,
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
na nĩnduĩte nĩngũmũruta kuuma mĩnyamaro-inĩ yanyu kũu bũrũri wa Misiri, ndĩmũtware bũrũri wa Akaanani, na Ahiti, na Aamori, na Aperizi, na Ahivi, na Ajebusi, bũrũri ũrĩ bũthi wa iria na ũũkĩ.’
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
“Athuuri acio a Isiraeli nĩmagagũthikĩrĩria. Ningĩ wee na athuuri acio nĩmũgathiĩ kũrĩ mũthamaki wa bũrũri wa Misiri na mũmwĩre atĩrĩ, ‘Jehova, o we Ngai wa Ahibirania, nĩarĩtie na ithuĩ. Nĩ ũndũ ũcio twĩtĩkĩrie tũthiĩ rũgendo rwa mĩthenya ĩtatũ werũ-inĩ tũkarutĩre Jehova Ngai witũ magongona.’
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
No nĩnjũũĩ atĩ mũthamaki ũcio wa bũrũri wa Misiri ndakamwĩtĩkĩria mũthiĩ, tiga guoko gwakwa kwa hinya kũmũhatĩrĩirie gwĩka ũguo.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Nĩ ũndũ ũcio nĩngatambũrũkia guoko gwakwa hũũre andũ a Misiri na maũndũ mothe ma magegania marĩa ngeeka thĩinĩ wao. Thuutha ũcio, nĩakamwĩtĩkĩria mũthiĩ.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
“Na nĩngatũma mwĩtĩkĩrĩke nĩ andũ a Misiri, nĩgeetha rĩrĩa mũkoimagara, mũtikanathiĩ moko matheri.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Mũndũ-wa-nja o wothe Mũisiraeli nĩakahooya mũndũ wa itũũra rĩake, na ahooe mũndũ-wa-nja o wothe matũũranagia nake gwake nyũmba indo cia betha na thahabu o na nguo, iria mũkaahumba ciana cianyu cia aanake na cia airĩtu. Na nĩ ũndũ ũcio nĩmũgataha andũ acio a Misiri.”

< Exodus 3 >