< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Moïse gardait le troupeau de Jéthro, son beau-père, prêtre de Madian. Il conduisit le troupeau au fond du désert et arriva à la montagne de Dieu, à Horeb.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
L'ange de Yahvé lui apparut dans une flamme de feu, au milieu d'un buisson. Il regarda, et voici, le buisson brûlait de feu, et le buisson ne se consumait pas.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Moïse dit: « Je vais maintenant aller voir ce grand spectacle, pourquoi le buisson ne se consume pas. »
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Lorsque Yahvé vit qu'il venait pour voir, Dieu l'appela du milieu du buisson et dit: « Moïse! Moïse! » Il a dit: « Je suis là. »
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Il dit: « N'approchez pas. Enlève tes sandales, car le lieu sur lequel tu te tiens est une terre sainte. »
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Il dit encore: « Je suis le Dieu de ton père, le Dieu d'Abraham, le Dieu d'Isaac et le Dieu de Jacob. » Moïse a caché son visage parce qu'il avait peur de regarder Dieu.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
Yahvé dit: « J'ai vu la détresse de mon peuple qui est en Égypte, j'ai entendu ses cris à cause de ses maîtres, car je connais ses souffrances.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
Je suis descendu pour les délivrer de la main des Égyptiens et pour les faire monter de ce pays dans un bon et vaste pays, dans un pays où coulent le lait et le miel, dans le lieu où vivent les Cananéens, les Héthiens, les Amoréens, les Phéréziens, les Héviens et les Jébusiens.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Maintenant, voici, le cri des enfants d'Israël est venu jusqu'à moi. Et j'ai vu l'oppression que leur font subir les Égyptiens.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Viens donc maintenant, et je t'enverrai vers Pharaon, afin que tu fasses sortir d'Égypte mon peuple, les enfants d'Israël. »
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Moïse dit à Dieu: « Qui suis-je, pour aller vers Pharaon, et pour faire sortir d'Égypte les enfants d'Israël? »
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Il dit: « Certainement, je serai avec toi. Ceci sera pour toi le signe que je t'ai envoyé: quand tu auras fait sortir le peuple d'Égypte, tu serviras Dieu sur cette montagne. »
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Moïse dit à Dieu: « Voici, quand je viendrai vers les enfants d'Israël et que je leur dirai: « Le Dieu de vos pères m'a envoyé vers vous », et qu'ils me demanderont: « Quel est son nom? », que leur dirai-je? »
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Dieu dit à Moïse: « JE SUIS QUI JE SUIS », et il ajouta: « Tu diras ceci aux enfants d'Israël: « Je Suis, je vous ai envoyé. »
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
Dieu dit encore à Moïse: « Tu diras aux enfants d'Israël: « Yahvé, le Dieu de vos pères, le Dieu d'Abraham, le Dieu d'Isaac et le Dieu de Jacob, m'a envoyé vers vous. C'est là mon nom pour toujours, et c'est là mon souvenir pour toutes les générations.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Allez rassembler les anciens d'Israël et dites-leur: « Yahvé, le Dieu de vos pères, le Dieu d'Abraham, d'Isaac et de Jacob, m'est apparu et m'a dit: Je vous ai visités et j'ai vu ce qu'on vous a fait en Égypte.
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
J'ai dit: Je vous ferai monter de la détresse de l'Égypte au pays des Cananéens, des Héthiens, des Amoréens, des Phéréziens, des Héviens et des Jébusiens, dans un pays où coulent le lait et le miel ».
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Ils écouteront ta voix. Tu iras, toi et les anciens d'Israël, vers le roi d'Égypte et tu lui diras: « Yahvé, le Dieu des Hébreux, nous a rencontrés. Laisse-nous maintenant faire trois jours de marche dans le désert, afin que nous puissions sacrifier à Yahvé, notre Dieu.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Je sais que le roi d'Égypte ne vous donnera pas la permission de partir, non, pas par une main puissante.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
J'étendrai ma main et je frapperai l'Égypte par tous les prodiges que je ferai au milieu d'elle, et après cela, il vous laissera partir.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
J'accorderai à ce peuple une faveur aux yeux des Égyptiens, et il arrivera que, lorsque vous partirez, vous ne partirez pas les mains vides.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Mais chaque femme demandera à sa voisine et à celle qui visite sa maison des bijoux d'argent, des bijoux d'or et des vêtements. Vous les mettrez sur vos fils et sur vos filles. Vous pillerez les Égyptiens. »

< Exodus 3 >