< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Now Moses [Drawn out] was keeping the flock of Jethro [Abundance], his father-in-law, the priest of Midian [Strife], and he led the flock to the back of the wilderness, and came to God’s mountain, to Horeb [Desert].
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
Ha mal'ak Yahweh [The Angel of He sustains breathing] appeared to him in a flame of fire out of the middle of a bush. He looked, and behold, the bush burned with fire, and the bush was not consumed.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Moses [Drawn out] said, “I will turn aside now and see this great sight; why the bush is not being burned up?”
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
When Adonai saw that he turned aside to see, God called to him out of the middle of the bush, and said, “Moses [Drawn out]! Moses [Drawn out]!” He said, “Here I am.”
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
He said, “Don’t come close. Take your sandals off of your feet, for the place you are standing on is holy ground.”
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Moreover he said, “I am the God of your father, the God of Abraham [Father of a multitude], the God of Isaac [Laughter], and the God of Jacob [Supplanter].” Moses [Drawn out] hid his face; for he was afraid to look at God.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
Adonai said, “I have surely seen the affliction of my people who are in Egypt [Abode of slavery], and have sh'ma ·heard obeyed· their cry because of their taskmasters, for I know their sorrows.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
I have come down to deliver them out of the hand of the Egyptians [people from Abode of slavery], and to bring them up out of that land to a good and large land, to a land flowing with milk and honey; to the place of the Canaanite [Descendant of Humbled], the Hittite [Descendant of Trembling fear], the Amorite [Descendants of Talkers], the Perizzite [Descendant of Belonging to village], the Hivite [Wicked], and the Jebusite [Descendants of Thresher].
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Now, behold, the cry of the children of Israel [God prevails] has come to me. Moreover I have seen the oppression with which the Egyptians [people from Abode of slavery] oppress them.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Come now therefore, and I will send you to Pharaoh, that you may bring my people, the children of Israel [God prevails], out of Egypt [Abode of slavery].”
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Moses [Drawn out] said to God, “Who am I, that I should go to Pharaoh, and that I should bring the children of Israel [God prevails] out of Egypt [Abode of slavery]?”
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
He said, “Certainly I will be with you. This will be the token to you, that I have sent you: when you have brought the people out of Egypt [Abode of slavery], you shall abad ·serve· God on this mountain.”
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Moses [Drawn out] said to God, “Behold, when I come to the children of Israel [God prevails], and tell them, ‘The God of your fathers has sent me to you;’ and they ask me, ‘What is his name?’ What should I tell them?”
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
God said to Moses [Drawn out], “I Am Who I Am,” and he said, “You shall tell the children of Israel [God prevails] this: ‘I AM has sent me to you.’”
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
God said moreover to Moses [Drawn out], “You shall tell the children of Israel [God prevails] this, ‘Yahweh, the God of your fathers, the God of Abraham [Father of a multitude], the God of Isaac [Laughter], and the God of Jacob [Supplanter], has sent me to you.’ This is my name forever, and this is my memorial to all generations.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Go, and gather the elders of Israel [God prevails] together, and tell them, ‘Yahweh, the God of your fathers, the God of Abraham [Father of a multitude], of Isaac [Laughter], and of Jacob [Supplanter], has appeared to me, saying, “I have surely visited you, and seen that which is done to you in Egypt [Abode of slavery];
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
and I have said, I will bring you up out of the affliction of Egypt [Abode of slavery] to the land of the Canaanite [Descendant of Humbled], the Hittite [Descendant of Trembling fear], the Amorite [Descendants of Talkers], the Perizzite [Descendant of Belonging to village], the Hivite [Wicked], and the Jebusite [Descendants of Thresher], to a land flowing with milk and honey.”’
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
They will sh'ma ·hear obey· your voice, and you shall come, you and the elders of Israel [God prevails], to the king of Egypt [Abode of slavery], and you shall tell him, ‘Adonai, the God of the Hebrews [Immigrants], has met with us. Now please let us go three days’ journey into the wilderness, that we may sacrifice to Adonai, our God.’
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
I know that the king of Egypt [Abode of slavery] won’t give you permission to go, no, not by a mighty hand.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
I will reach out my hand and strike Egypt [Abode of slavery] with all my wonders which I will do among them, and after that he will let you go.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
I will give this people chen ·grace· in the sight of the Egyptians [people from Abode of slavery], and it will happen that when you go, you shall not go empty handed.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
But every woman shall ask of her neighbor, and of her who visits her house, jewels of silver, jewels of gold, and clothing; and you shall put them on your sons, and on your daughters. You shall plunder the Egyptians [people from Abode of slavery].”

< Exodus 3 >