< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Og Mose vogtede Kvæg hos Jetro, sin Svigerfader, Præsten i Midian, og han drev Kvæget bag Ørken og kom til det Guds Bjerg, til Horeb.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
Og Herrens Engel aabenbaredes for ham i en Ildslue, midt af Tornebusken, og han saa, og se, Tornebusken brændte i Ilden, dog blev Tornebusken ikke fortæret.
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Og Mose sagde: Jeg vil nu gaa hen og se dette store Syn, hvi Tornebusken ikke opbrændes.
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Der Herren saa, at han gik hen for at se, da raabte Gud til ham midt af Tornebusken og sagde: Mose! Mose! og han sagde: Se, her er jeg.
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Og han sagde: Kom ikke nær her hid, drag dine Sko af dine Fødder; thi det Sted, som du staar paa, det er hellig Jord.
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Og han sagde: Jeg er din Faders Gud, Abrahams Gud, Isaks Gud og Jakobs Gud; og Mose skjulte sit Ansigt, thi han frygtede for at se paa Gud.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
Og Herren sagde: Jeg har grant set mit Folks Elendighed i Ægypten, og hørt deres Skrig over dem, som trænge dem; thi jeg ved deres Smerter.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
Og jeg er nedfaren for at redde dem af Ægypternes Haand og for at føre dem op af dette Land, til et godt og vidt Land, til et Land, som flyder med Mælk og Honning, til Kananitens og Hethitens og Amoritens og Feresitens og Hevitens og Jebusitens Sted.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Og nu se, Israels Børns Skrig er kommet for mig, og jeg har ogsaa set den Trængsel, hvormed Ægypterne trænge dem.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Saa gak nu og jeg vil sende dig til Farao, og udfør mit Folk, Israels Børn, af Ægypten.
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Og Mose sagde til Gud: Hvo er jeg, at jeg skulde gaa til Farao, og at jeg skulde udføre Israels Børn af Ægypten?
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Og han sagde: Sandelig, jeg vil være med dig; og dette skal være dig et Tegn, at jeg har sendt dig: Naar du udfører Folket af Ægypten, da skulle I tjene Gud paa dette Bjerg.
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Og Mose sagde til Gud: Se, naar jeg kommer til Israels Børn og siger til dem: Eders Fædres Gud har sendt mig til eder, og de sige til mig: Hvad er hans Navn? hvad skal jeg da sige til dem?
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Og Gud sagde til Mose: Jeg er den, som jeg er; og han sagde: Saa skal du sige til Israels Børn: „Jeg er” har sendt mig til eder.
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
Og Gud sagde ydermere til Mose: Saa skal du sige til Israels Børn: Herren, eders Fædres Gud, Abrahams Gud, Isaks Gud og Jakobs Gud, sendte mig til eder; dette er mit Navn evindeligen, og dette min Ihukommelse fra Slægt til Slægt.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Gak, og du skal samle de ældste af Israel og sige til dem: Herren, eders Fædres Gud, er aabenbaret for mig, Abrahams, Isaks og Jakobs Gud, og har sagt: Jeg har visselig besøgt eder og set, hvad eder er vederfaret i Ægypten.
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
Og jeg har sagt: Jeg vil føre eder op af Ægyptens Elendighed til Kananitens og Hethitens og Amoritens og Feresitens og Hevitens og Jebusitens Land, til et Land, som flyder med Mælk og Honning.
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Og de skulle høre din Røst, og du skal gaa ind, du og de ældste af Israel, til Kongen af Ægypten, og I skulle sige til ham: Herren, Hebræernes Gud, har mødt os, og nu, lad os dog gaa tre Dages Rejse hen i Ørken og ofre til Herren vor Gud.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Men jeg ved, at Kongen af Ægypten skal ikke lade eder fare, end ikke ved en stærk Haand.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Og jeg skal udstrække min Haand og slaa Ægypten med alle mine underlige Ting, som jeg vil gøre midt i det, og derefter skal han lade eder fare.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
Og jeg vil give dette Folk Naade hos Ægypterne, og det skal ske, naar I skulle rejse, skulle I ikke rejse tomhændede.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Men hver Kvinde skal begære af sin Naboerske og af den, hun er i Huset med, Sølvkar og Guldkar og Klæder, og dem skulle I lægge paa eders Sønner og paa eders Døtre, og skille Ægypterne derved.

< Exodus 3 >