< Exodus 3 >

1 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
Mosi ni Midian vaihma, a masei Jethro e tu hoi hmaenaw a khoum navah, thingyeiyawn e kanîloumlah a ceikhai teh, Horeb tie Cathut e mon koe a pha.
2 Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
Hatnavah, BAWIPA e kalvantami teh buruk dawk hoi ka tâcawt e hmaito lahoi a kamnue. Mosi ni a khet navah, hmai a to ei, buruk teh a kak hoeh e hah a hmu navah,
3 Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
Bangkongmaw buruk kang laipalah ao. Hete kângairu e hno heh ka cei vaiteh ka khet han telah ati.
4 Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
Mosi ni a khet e BAWIPA ni a hmu navah, Mosi, Mosi telah buruk thung hoiyah a kaw. Mosi ni hai ka o telah atipouh.
5 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
Cathut ni hai hnai hanh. Na khokkhawm hah rading haw. Na kangduenae hmuen teh kathounge talai doeh.
6 Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
Kai teh nange na pa e Cathut, Abraham e Cathut, Isak e Cathut, Jakop e Cathut, doeh telah atipouh. Mosi ni Cathut teh a khet ngam hoeh dawkvah a minhmai a ramuk.
7 Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
BAWIPA ni hai Izip ram kaawm e ka taminaw e a khang e rektapnae hah kai ni khei ka hmu toe. Ahnimouh thaw ka tawksak e bawinaw kecu dawk ahnimae hramnae lawk ka thai teh, reithai khangnae hai ka panue.
8 Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
Ahnimouh teh Izip ram, Izip taminaw e kut dawk hoi ratang vaiteh, Kanaannaw, Hitnaw, Amornaw, Periznaw, Hivnaw hoi Jebusitnaw onae ram, sanutui hoi khoitui a lawngnae ram dawk hrawi hanlah kai ka kum.
9 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
Atu haiyah, Isarelnaw khuika lawk kai koe a pha teh, Izipnaw ni ahnimouh rektapnae hai ka hmu toe.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Hatdawkvah, atu cet leih. Nang teh ka tami, Isarelnaw hah Izip ram hoi hrawi tâcokhai hanlah, nang teh Faro siangpahrang koe kai ni na patoun han telah atipouh.
11 Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
Mosi nihai, kai teh bang patet e tami lah maw ka o teh, Faro siangpahrang koe ka cei vaiteh, Isarelnaw hah Izip ram hoi hrawi tâcokhai han telah Cathut koe atipouh navah,
12 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
Cathut ni atangcalah kai teh nang koe lah ka o han. Kai ni nang na patounnae mitnoutnae teh, nang ni hote taminaw hah Izip ram hoi hrawi tâcokhai hnukkhu, hete mon dawk Cathut na bawk han telah atipouh.
13 Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
Mosi nihai, kai ni Isarelnaw onae hmuen koe ka pha teh, nangmae mintoenaw e Cathut ni kai teh nangmouh koe na patoun toe telah kai ni ka dei pawiteh, ahnimouh ni hote Cathut e min teh apimaw telah kai bout na pacei awh navah, bangtelamaw bout ka dei pouh han telah Cathut koe a pacei.
14 Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
Cathut ni hai KAI teh KAI doeh. KAI ka tet e ni kai teh nangmouh na onae hmuen koe na patoun toe telah Isarelnaw koe bout dei pouh telah Mosi koe atipouh.
15 Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
Cathut ni Mosi koe bout a dei pouh e teh, nangmae mintoenaw e Cathut, Abraham e Cathut, Isak e Cathut, Jakop e Cathut lah kaawm e BAWIPA ni kai teh nangmouh koe na patoun toe, telah Isarelnaw koe na dei pouh han. Hote min teh a yungyoe e ka min lah ao teh catounnaw ni pahnim hoeh nahanelah ao.
16 “Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
Cet nateh Isarel kacuenaw hah pâkhueng nateh, nangmae mintoenaw e Cathut, Abraham e Cathut, Isak e Cathut, Jakop e Cathut lah kaawm e BAWIPA ni kai koe a kamnue teh, nangmouh na khet awh navah, Izip ram vah nangmouh lathueng bangmaw a sak awh tie kamcengcalah ka hmu awh toe.
17 Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
Izip ram vah na khang a e rucatnae dawk hoi nangmouh na ratang vaiteh, Kanaannaw, Hit naw, Amor naw, Periznaw, Hiv naw hoi Jebusitnaw ram, sanutui hoi khoitui a lawngnae ram dawk hrawi kâenkhai hanlah kai ni lawk ka kam telah ahnimouh koe dei pouh.
18 “Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
Ahnimouh ni nange lawk a ngâi awh vaiteh, nang ni Isarel kacuenaw hoi Izip siangpahrang koe na kâen vaiteh, Hebrunaw e BAWIPA Cathut teh kaimouh ni kâhmo awh toe. Ramke dawk hnin thum touh lam cei koe kamamae BAWIPA Cathut thuengnae sak thai hanelah, kâ na poe haw, telah na ti pouh han.
19 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
Izip siangpahrang ni a thaonae kut laipalah teh, cei nahane kâ na poe awh mahoeh tie ka panue.
20 Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
Kai ni hai kut ka daw vaiteh, Izip ram dawk ka sak hane kaie kângairunae hoi hote ram teh runae ka poe han. Hathnukkhu, Izip siangpahrang ni nangmouh teh na tâco sak awh han.
21 “Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
Hote miphun teh Izipnaw koe minhmai kahawi a hmu sak vaiteh, nangmouh ni na tâco awh navah, kuthrawng hoi na tâcawt awh mahoeh.
22 Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”
Bangkongtetpawiteh, napui pueng ni imri, amamae im dawk kaawm e koe sui ngun hoi khohnanaw a hei awh vaiteh, nangmae na canaw hah a pathoup awh vaiteh, Izipnaw e hnopai hah na lawp awh han telah Mosi koe a dei pouh.

< Exodus 3 >