< Exodus 29 >

1 “Èyí ni ohun tí ìwọ yóò ṣe láti yà wọ́n sí mímọ́, kí wọn lè máa ṣe àlùfáà fún mi. Mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan àti àgbò méjì tí kò ní àbùkù.
Tā nu dari viņiem, tos Man iesvētīdams par priesteriem: ņem vienu jaunu vērsi un divus aunus, kas bez vainas,
2 Láti ara ìyẹ̀fun aláìwú dídùn, ṣe àkàrà àti àkàrà tí a pò pẹ̀lú òróró, àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ aláìwú tí a da òróró sí.
Un neraudzētu maizi un neraudzētas karašas ar eļļu sajauktas un neraudzētus raušus ar eļļu svaidītus; no kviešu miltiem tev visu to būs taisīt.
3 Ìwọ yóò sì kó wọn sínú apẹ̀rẹ̀ kan, ìwọ yóò sì mú wọn wà nínú apẹ̀rẹ̀ náà papọ̀ pẹ̀lú akọ màlúù àti àgbò méjì náà.
Un tev to būs likt kurvī un tai kurvī to atnest līdz ar to vērsi un tiem abiem auniem.
4 Nígbà náà ni ìwọ yóò mú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ, ìwọ yóò sì fi omi wẹ̀ wọ́n.
Tad tev būs pievest Āronu un viņa dēlus pie saiešanas telts durvīm un mazgāt ar ūdeni.
5 Ìwọ yóò sì fi ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ Aaroni, àti aṣọ ìgúnwà efodu, àti efodu, àti ìgbàyà, kí ó sì fi onírúurú ọnà ọ̀já ẹ̀wù efodu dì í.
Pēc tam tev būs ņemt tās drēbes un Āronam apvilkt tos šauros svārkus un to efoda uzvalku un to efodu un to krūšu glītumu un apjozt viņam to jostu ap to efodu.
6 Ìwọ yóò sì fi fìlà dé e ní orí, ìwọ yóò sì ṣe adé mímọ́ sára fìlà náà.
Un tev to cepuri būs likt viņam galvā un to svētības kroni tev būs likt pie tās cepures.
7 Nígbà náà ni ìwọ yóò sì mú òróró ìtasórí, ìwọ yóò sì yà á sí mímọ́ nípa dída òróró sí i ní orí.
Un tev būs ņemt to svaidāmo eļļu un uzliet uz viņa galvu. Tā tev viņu būs svaidīt.
8 Ìwọ yóò sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ ìwọ yóò sì fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀ wọ́n
Pēc tam tev būs atvest arī viņa dēlus un tiem tos svārkus apvilkt.
9 ìwọ yóò sì fi fìlà dé wọn ni orí. Nígbà náà fi ọ̀já àmùrè di Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Iṣẹ́ àlùfáà yóò máa jẹ́ tiwọn ní ìlànà títí ayé. “Báyìí ni ìwọ yóò sì ya Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sí mímọ́.
Un tev tos būs apjozt ar to jostu, proti Āronu un viņa dēlus, un tev tiem būs uzsiet tās cepures, ka tiem ir tas priesteru amats par likumu mūžīgi. Tā tev būs amatā iecelt Āronu un viņa dēlus.
10 “Ìwọ yóò sì mú akọ màlúù wá síwájú àgọ́ àjọ, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì fi ọwọ́ wọn lé akọ màlúù ní orí.
Un to vērsi būs atvest priekš saiešanas telts, un Āronam un viņa dēliem būs savas rokas likt uz tā vērša galvu.
11 Ìwọ yóò sì pa àwọn akọ màlúù náà níwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
Un tev to vērsi būs nokaut Tā Kunga priekšā, priekš saiešanas telts durvīm.
12 Ìwọ yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ìka rẹ tọ́ ọ sára ìwo pẹpẹ náà, kí o sì da gbogbo ẹ̀jẹ̀ tókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ náà.
Pēc tam tev būs ņemt no tā vērša asinīm un ar savu pirkstu likt uz altāra ragiem, un visas citas asinis tev būs izliet uz altāra grīdu.
13 Kí o mú gbogbo ọ̀rá tí ó yí inú ká, èyí tí ó bo ẹ̀dọ̀ àti ìwé méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lára wọn, ìwọ yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ.
Un tev būs ņemt visus taukus, kas iekšas apklāj, un tos taukus, kas pār aknām, un tās abas īkstis ar tiem taukiem, kas tur klāt, un tev tos būs iededzināt uz altāra.
14 Ṣùgbọ́n fi iná sun ẹran akọ màlúù, awọ rẹ̀ àti ìgbẹ́ rẹ̀ lẹ́yìn òde. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Bet tā vērša gaļu un viņa ādu un viņa sūdus tev būs ar uguni sadedzināt ārā aiz lēģera; tas ir grēku upuris.
15 “Ìwọ yóò sì mú àgbò kan, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì gbọ́wọ́ lé orí àgbò náà.
Pēc tam tev būs ņemt to vienu aunu un Āronam un viņa dēliem būs savas rokas likt uz tā auna galvu.
16 Ìwọ yóò sì pa àgbò náà, ìwọ yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ìwọ yóò sì fi wọ́n pẹpẹ náà yíká.
Un tev būs to aunu nokaut un ņemt viņa asinis un slacīt visapkārt ap altāri.
17 Ìwọ yóò sì gé àgbò náà sí wẹ́wẹ́, ìwọ yóò sì fọ inú àti àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀, ìwọ yóò sì tò wọ́n pẹ̀lú orí rẹ̀ lé ara wọn.
Un to aunu tev būs dalīt gabalos un mazgāt viņa iekšas un viņa kājas un tās uzlikt uz viņa gabaliem un uz viņa galvu.
18 Nígbà náà ni ìwọ yóò sun àgbò náà lórí pẹpẹ. Ẹbọ sísun ni sí Olúwa, olóòórùn dídùn ni, ẹbọ ti a fi iná ṣe sí Olúwa ni.
Tā tev visu to aunu būs iededzināt uz altāra; tas ir dedzināms upuris Tam Kungam par saldu smaržu, tas ir uguns upuris Tam Kungam.
19 “Ìwọ yóò mú àgbò kejì, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò fi ọwọ́ wọn lé àgbò náà lórí.
Pēc tam tev būs ņemt to otru aunu, un Āronam un viņa dēliem būs savas rokas likt uz tā auna galvu.
20 Ìwọ yóò sì pa àgbò náà, ìwọ yóò mú nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ìwọ yóò sì tọ́ ọ sí etí ọ̀tún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, sí àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún wọn, àti sí àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún wọn. Ìwọ yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n pẹpẹ náà yíká.
Un tev to aunu būs nokaut un ņemt no viņa asinīm un likt uz Ārona labās auss skripstiņu un uz viņa dēlu labās auss skripstiņu, tāpat uz viņa dēlu labās rokas īkšķi un uz viņu labās kājas īkšķi, un tās asinis tev būs slacīt uz altāri visapkārt.
21 Ìwọ yóò mú nínú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà lórí pẹpẹ àti nínú òróró ìtasórí, ìwọ yóò sì wọ́n ọn sára Aaroni àti sára aṣọ rẹ̀, sára àwọn ọmọ rẹ àti sára aṣọ wọn. Nígbà náà ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ àti aṣọ wọn yóò di mímọ́.
Tad tev būs ņemt no tām asinīm, kas ir uz altāra, un no tās svaidāmās eļļas un slacīt uz Āronu un viņa drēbēm un uz viņa dēliem un uz viņa dēlu drēbēm, lai viņš ir svētīts un viņa drēbes un viņa dēli un viņa dēlu drēbes.
22 “Ìwọ yóò mú lára ọ̀rá àgbò náà, ìrù tí ó lọ́ràá, ọ̀rá tí ó yí inú ká, èyí ti ó bo ẹ̀dọ̀, ìwé méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lára wọn àti itan ọ̀tún. (Èyí ni àgbò fún ìyàsímímọ́.)
Un tev no tā auna būs ņemt taukus un asti un tos taukus, kas iekšas apklāj, un aknu taukus un abējas īkstis ar tiem taukiem, kas pie tām, un to labo pleci, jo tas ir tas iesvētīšanas auns,
23 Láti inú apẹ̀rẹ̀ ìṣù àkàrà aláìwú, èyí tí ó wà níwájú Olúwa, mú ìṣù kan, àkàrà tí a fi òróró dín àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ kan.
Un vienu kukuli maizes un vienu eļļas karašu un vienu rausi no tā neraudzētās maizes kurvja, kam būs būt priekš Tā Kunga vaiga.
24 Ìwọ yóò fi gbogbo rẹ̀ lé Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì fì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì níwájú Olúwa.
Un tev visu to būs likt uz Ārona un uz viņa dēlu plaukstām, un to līgot par līgojamu upuri Tā Kunga priekšā.
25 Nígbà náà ni ìwọ yóò sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ìwọ yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ pẹ̀lú ẹbọ sísun fún òórùn dídùn níwájú Olúwa, ẹbọ ti a fi iná sun sí Olúwa.
Pēc tam ņem to no viņu rokām un iededzini to uz altāra pār to dedzināmo upuri, par saldu smaržu Tā Kunga priekšā; - tas ir uguns upuris Tam Kungam.
26 Ìwọ yóò sì mú igẹ̀ àgbò ìyàsímímọ́ Aaroni, ìwọ yóò si fí ì ni ẹbọ fífì níwájú Olúwa; ìpín tìrẹ ni èyí.
Tad ņem tās krūtis no Ārona iesvētīšanas auna, un līgo tās Tā Kunga priekšā; - tā būs tava daļa.
27 “Ìwọ yóò sì ya igẹ̀ ẹbọ fífì náà sí mímọ́, àti ìtàn ẹbọ à gbé sọ sókè tí a fì, tí a sì gbé sọ sókè nínú àgbò ìyàsímímọ́ náà, àní nínú èyí tí í ṣe Aaroni àti nínú èyí tí ì ṣe tí àwọn ọmọ rẹ̀.
Un tev būs svētīt tās līgojama upura krūtis un tā cilājama upura pleci, kas ir cilāts un līgots no Ārona un viņa dēlu iesvētīšanas auna.
28 Èyí ni yóò sì máa ṣe ìpín ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli nígbà gbogbo. Nítorí ẹbọ à gbé sọ sókè ni ẹbọ tí yóò ṣì ṣe èyí ni ẹbọ tí àwọn ọmọ Israẹli yóò máa ṣe sí Olúwa láti inú ẹbọ àlàáfíà wọn.
Un tam būs būt Āronam un viņa dēliem par mūžīgu iestādījumu no Israēla bērniem; jo tas ir cilājams upuris, un Israēla bērnu cilājamam upurim būs būt pie viņu pateicības upuriem, viņu cilājamam upurim priekš Tā Kunga.
29 “Aṣọ mímọ́ Aaroni yóò jẹ́ ti irú àwọn ọmọ rẹ̀, nítorí kí a lè máa fi òróró yàn wọ́n kí a sì lè máa yà wọ́n sì mímọ́.
Ārona svētās drēbes piederēs viņa dēliem pēc viņa, ka tie iekš tām top svaidīti un amatā iecelti.
30 Ọmọ rẹ̀ tí ó bá jẹ àlùfáà ní ipò rẹ̀, tí ó bá wọ̀ yóò máa sì wá sí àgọ́ àjọ láti ṣiṣẹ́ ní Ibi Mímọ́, yóò sì máa wọ̀ wọ́n ní ọjọ́ méje.
Septiņas dienas tās būs valkāt tam no viņa dēliem, kas viņa vietā būs par priesteri, kam jāiet saiešanas teltī un jākalpo tai svētā vietā.
31 “Ìwọ yóò sì mú àgbò fún ìyàsímímọ́, ìwọ yóò sì bọ ẹran rẹ̀ ní ibi mímọ́ kan.
Tev būs ņemt iesvētīšanas upura aunu un viņa gaļu vārīt svētā vietā.
32 Ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ ni Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò ti jẹ ẹran àgbò náà àti àkàrà náà tí ó wà nínú apẹ̀rẹ̀.
Tad Āronam un viņa dēliem būs ēst tā auna gaļu ar to maizi, kas kurvī, priekš saiešanas telts durvīm.
33 Wọn yóò sì jẹ nǹkan wọ̀nyí èyí tí a fi ṣe ètùtù náà fún ìyàsímímọ́ àti ìsọdimímọ́ wọn. Ṣùgbọ́n àlejò ni kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀, nítorí pé mímọ́ ni.
Un tiem to būs ēst, ar ko tā salīdzināšana ir notikusi, lai viņi top amatā iecelti un iesvētīti, bet svešiniekiem to nebūs ēst, jo tā ir svēta barība.
34 Bí ohun kan nínú ẹran àgbò ìyàsímímọ́ tàbí nínú àkàrà náà bá kù di òwúrọ̀, nígbà náà ni kí ìwọ fi iná sun wọn. A kò gbọdọ̀ jẹ ẹ́, nítorí mímọ́ ni.
Un ja kas atliek no tās iesvētīšanas upura gaļas vai no šīs maizes līdz rītam, tad tev to atlikumu būs sadedzināt ar uguni, to nebūs ēst, jo tas ir svēts.
35 “Báyìí ni ìwọ yóò ṣì ṣe fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ bí ohun gbogbo ti mo paláṣẹ fún ọ, ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi yà wọ́n sí mímọ́.
Tā tev būs darīt Āronam un viņa dēliem, kā es tev esmu pavēlējis; septiņas dienas tev būs viņus iesvētīt.
36 Ìwọ yóò sì máa pa akọ màlúù kọ̀ọ̀kan ní ojoojúmọ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù. Ìwọ yóò sì wẹ pẹpẹ mọ́ nípa ṣíṣe ètùtù fún un, ìwọ yóò sì ta òróró sí i láti sọ ọ́ dí mímọ́.
Tev ikdienas arī vienu vērsi būs nokaut par grēku upuri, par salīdzināšanu, un to altāri tev būs šķīstīt, salīdzināšanu darot par viņu, un tev viņu būs svaidīt, ka viņš top svētīts.
37 Ní ọjọ́ méje ni ìwọ yóò ṣe ètùtù sí pẹpẹ náà, ìwọ yóò sì sọ ọ́ di mímọ́. Nígbà náà ni pẹpẹ náà yóò jẹ́ mímọ́ jùlọ, àti ohunkóhun tí ó bá fi ọwọ́ kàn án yóò jẹ́ mímọ́.
Septiņas dienas tev būs salīdzināšanu darīt par to altāri un viņu iesvētīt, un tad tas altāris būs augsti svēts; ikviens, kas to altāri aizskar, lai ir svēts.
38 “Èyí ni ìwọ yóò máa fi rú ẹbọ ní orí pẹpẹ náà: Ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kan ni ojoojúmọ́ láéláé.
Šis nu ir, ko tev būs upurēt uz altāra: divus jērus, gadu vecus, ikdienas allažiņ.
39 Ọ̀dọ́-àgùntàn kan ni ìwọ yóò fi rú ẹbọ ní òwúrọ̀ àti ọ̀dọ́-àgùntàn èkejì ní àṣálẹ́.
To vienu jēru tev būs upurēt no rīta un to otru tev būs upurēt ap vakara laiku;
40 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn ti àkọ́kọ́ rú ẹbọ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dídára tí a fi ìdámẹ́rin hínì òróró lára olifi tí a gún, àti ìdámẹ́rin hínì wáìnì bí ẹbọ mímu.
Ar desmito tiesu kviešu miltu, ko būs sajaukt ar vienu ceturtdaļu inna sagrūstas eļļas, un par dzeramo upuri vienu ceturtdaļu inna vīna, priekš tā viena jēra.
41 Ọ̀dọ́-àgùntàn kejì ni kí ìwọ kí ó pa rú ẹbọ ní àṣálẹ́ ìwọ yóò sì ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ mímu bí ti òwúrọ̀ fún òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná ṣe ni sí Olúwa.
Un to otru jēru tev būs upurēt ap vakara laiku; tev ar to būs darīt, tā kā ar ēdamo upuri rītā un kā ar viņa dzeramo upuri; par saldu smaržu tas ir uguns upuris Tam Kungam.
42 “Fún ìrandíran tó ń bọ̀, ni ẹ ó máa ṣe ẹbọ sísun nígbà gbogbo ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ níwájú Olúwa. Níbẹ̀ èmi yóò pàdé yín, èmi yóò sì bá a yín sọ̀rọ̀;
Šis ir tas dienišķais dedzināmais upuris pie jūsu pēcnākamiem, pie saiešanas telts durvīm Tā Kunga priekšā; tur būs mūsu saiešanas vieta, tur Es ar tevi runāšu.
43 níbẹ̀ sì tún ni èmi yóò pàdé àwọn ọmọ Israẹli, a ó sì fi ògo mi ya àgọ́ náà sí mímọ́.
Un tur būs Mana saiešanas vieta ar Israēla bērniem, ka tie top svētīti iekš Manas godības.
44 “Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ya àgọ́ àjọ náà sí mímọ́ àti pẹpẹ náà, èmi yóò sì ya Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sí mímọ́ láti máa ṣe iṣẹ́ bí àlùfáà fún mi.
Un Es svētīšu to saiešanas telti līdz ar to altāri un svētīšu arī Āronu un viņa dēlus, ka tie ir Mani priesteri.
45 Nígbà náà ni èmi yóò máa gbé láàrín àwọn ọmọ Israẹli, èmi yóò sì máa ṣe Ọlọ́run wọn.
Un Es mitīšu Israēla bērnu vidū un Es tiem būšu par Dievu.
46 Wọn yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, nítorí kí èmi lè máa gbé àárín wọn. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
Un tiem būs atzīt, ka Es esmu Tas Kungs, viņu Dievs, kas tos izvedis no Ēģiptes zemes, lai Es viņu vidū dzīvoju, Es Tas Kungs, viņu Dievs.

< Exodus 29 >