< Exodus 29 >

1 “Èyí ni ohun tí ìwọ yóò ṣe láti yà wọ́n sí mímọ́, kí wọn lè máa ṣe àlùfáà fún mi. Mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan àti àgbò méjì tí kò ní àbùkù.
EIA ka mea au e hana'i ia lakou, e hoolaa ia lakou, e lawelawe na'u ma ka oihana kahuna. E lawe oe i hookahi bipi opiopio, a i elua hipakane kina ole,
2 Láti ara ìyẹ̀fun aláìwú dídùn, ṣe àkàrà àti àkàrà tí a pò pẹ̀lú òróró, àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ aláìwú tí a da òróró sí.
A i berena hu ole, a i mau popoberena hu ole i miko i ka aila, a me na papa hu ole i hamoia i ka aila: he palaoa o ka huita kau e hana'i ia mau mea.
3 Ìwọ yóò sì kó wọn sínú apẹ̀rẹ̀ kan, ìwọ yóò sì mú wọn wà nínú apẹ̀rẹ̀ náà papọ̀ pẹ̀lú akọ màlúù àti àgbò méjì náà.
A e uhao oe ia mau mea iloko o ka hinai hookahi, a e lawe mai oe ia mau mea ma ka hinai, me ka bipi a me na hipakane elua.
4 Nígbà náà ni ìwọ yóò mú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ, ìwọ yóò sì fi omi wẹ̀ wọ́n.
A e kai mai oe ia Aarona, a me kana mau keikikane, a i ka puka o ka halelewa o ke anaina kanaka, a e holoi ia lakou i ka wai.
5 Ìwọ yóò sì fi ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ Aaroni, àti aṣọ ìgúnwà efodu, àti efodu, àti ìgbàyà, kí ó sì fi onírúurú ọnà ọ̀já ẹ̀wù efodu dì í.
A lawe oe i na aahu, a e hookomo i ka palule maluna o Aarona, a i ka holoku o ka epoda, a me ka epoda, a me ka paleumauma, a e kaei ia ia i ke kaei o ka epoda;
6 Ìwọ yóò sì fi fìlà dé e ní orí, ìwọ yóò sì ṣe adé mímọ́ sára fìlà náà.
A e kau oe i ka papale hainaka maluna o kona poo, a e kau hoi i ka lei kapu, maluna o ka papale.
7 Nígbà náà ni ìwọ yóò sì mú òróró ìtasórí, ìwọ yóò sì yà á sí mímọ́ nípa dída òróró sí i ní orí.
Alaila e lawe oe i ka aila poni, a e ninini iho maluna o kona poo, a e poni hoi ia ia.
8 Ìwọ yóò sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ ìwọ yóò sì fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀ wọ́n
A e kai mai hoi oe i kana mau keikikane, a e hookomo i na palule maluna o lakou.
9 ìwọ yóò sì fi fìlà dé wọn ni orí. Nígbà náà fi ọ̀já àmùrè di Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Iṣẹ́ àlùfáà yóò máa jẹ́ tiwọn ní ìlànà títí ayé. “Báyìí ni ìwọ yóò sì ya Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sí mímọ́.
A e kaei ia lakou i na kaei, ia Aarona, a me kana mau keikikane pu, a e nakiikii hoi i na papale maluna o lakou; a o ka oihana a ke kahuna, na lakou no, he kanawai mau loa ia: a e hoolaa oe ia Aarona, a me kana mau keikikane.
10 “Ìwọ yóò sì mú akọ màlúù wá síwájú àgọ́ àjọ, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì fi ọwọ́ wọn lé akọ màlúù ní orí.
E kai mai hoi oe i bipi imua o ka halelewa o ke anaina kanaka; a e kau o Aarona, a me kana mau keikikane i ko lakou mau lima ma ke poo o ka bipi.
11 Ìwọ yóò sì pa àwọn akọ màlúù náà níwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
A e pepehi oe i ka bipi imua o Iehova, ma ka puka o ka halelewa o ke anaina kanaka.
12 Ìwọ yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ìka rẹ tọ́ ọ sára ìwo pẹpẹ náà, kí o sì da gbogbo ẹ̀jẹ̀ tókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ náà.
A e lawe oe i kekahi koko o ka bipi, a e kau ma na pepeiao o ke kuahu me kou manamana lima, a e ninini iho i ke koko a pau ma ke kumu o ke kuahu.
13 Kí o mú gbogbo ọ̀rá tí ó yí inú ká, èyí tí ó bo ẹ̀dọ̀ àti ìwé méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lára wọn, ìwọ yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ.
E lawe hoi oe i ke kaikea a pau e wahi ana i na naau, a me ke aa maluna o ke ake, a me na konahua elua, a me ke kaikea e pili ana, a e puhi ia mau mea i ke ahi maluna o ke kuahu.
14 Ṣùgbọ́n fi iná sun ẹran akọ màlúù, awọ rẹ̀ àti ìgbẹ́ rẹ̀ lẹ́yìn òde. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Aka, o ka io o ka bipi, a me kona ili, a me kona lepo, e puhi oe ia i ke ahi, mawaho o ke kahua hoomoana. He mohai hala ia.
15 “Ìwọ yóò sì mú àgbò kan, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì gbọ́wọ́ lé orí àgbò náà.
E lawe hoi oe i hookahi hipakane, a e kau no o Aarona, a me kana mau keikikane i ko lakou mau lima ma ke poo o ka hipa.
16 Ìwọ yóò sì pa àgbò náà, ìwọ yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ìwọ yóò sì fi wọ́n pẹpẹ náà yíká.
A e pepehi oe i ka hipa, a e lawe i kona koko, a e kapii iho maluna iho o ke kuahu a puni.
17 Ìwọ yóò sì gé àgbò náà sí wẹ́wẹ́, ìwọ yóò sì fọ inú àti àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀, ìwọ yóò sì tò wọ́n pẹ̀lú orí rẹ̀ lé ara wọn.
A e oki liilii oe i ka hipa, a e holoi i ko loko ona, a me kona mau wawae, a e hoolilo i kona mau apana, a me kona poo.
18 Nígbà náà ni ìwọ yóò sun àgbò náà lórí pẹpẹ. Ẹbọ sísun ni sí Olúwa, olóòórùn dídùn ni, ẹbọ ti a fi iná ṣe sí Olúwa ni.
A e puhi oe i ka hipa a pau maluna o ke kuahu; he mohaikuni ia na Iehova, he mea ala, i puhiia na Iehova.
19 “Ìwọ yóò mú àgbò kejì, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò fi ọwọ́ wọn lé àgbò náà lórí.
E lawe no hoi oe i kekahi hipakane, a e kau no o Aarona a me kana mau keikikane i na lima o lakou ma ke poo o ka hipa.
20 Ìwọ yóò sì pa àgbò náà, ìwọ yóò mú nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ìwọ yóò sì tọ́ ọ sí etí ọ̀tún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, sí àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún wọn, àti sí àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún wọn. Ìwọ yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n pẹpẹ náà yíká.
Alaila, e pepehi oe i ka hipa, a e lawe i kekahi o kona koko, a e kau ma ka piko o ka pepeiao akau o Aarona, a ma ka piko o ka pepeiao akau o kana mau keikikane, a ma ka manamana nui o ko lakou lima akau, a ma ka manamana nui o ko lakou wawae akau, a e kapii hoi i ke koko maluna o ke kuahu a puni.
21 Ìwọ yóò mú nínú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà lórí pẹpẹ àti nínú òróró ìtasórí, ìwọ yóò sì wọ́n ọn sára Aaroni àti sára aṣọ rẹ̀, sára àwọn ọmọ rẹ àti sára aṣọ wọn. Nígbà náà ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ àti aṣọ wọn yóò di mímọ́.
A e lawe oe i kekahi o ke koko ma ke kuahu, a me kahi o ka aila poni, a e kapii maluna o Aarona, a maluna o kona kahiko, a maluna o kana mau keikikane, a maluna o ke kahiko o kana mau keikikane pu me ia. A e hoolaaia oia, a me kona kahiko, a o kana mau keikikane, a me ke kahiko o kana mau keikikane pu me ia.
22 “Ìwọ yóò mú lára ọ̀rá àgbò náà, ìrù tí ó lọ́ràá, ọ̀rá tí ó yí inú ká, èyí ti ó bo ẹ̀dọ̀, ìwé méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lára wọn àti itan ọ̀tún. (Èyí ni àgbò fún ìyàsímímọ́.)
A e lawe hoi oe i ko ka hipa, i ke kelekele, a me ka huelo a me ke kaikea e wahi ana i na naau, a me ke aa maluna o ke ake, a me na konahua elua a me ke kaikea e pili ana, a me ka uha mua akau, no ka mea, he hipa ia e hoolaa ai:
23 Láti inú apẹ̀rẹ̀ ìṣù àkàrà aláìwú, èyí tí ó wà níwájú Olúwa, mú ìṣù kan, àkàrà tí a fi òróró dín àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ kan.
A i hookahi popo berena, a i hookahi papa berena, he berena me ka aila, a hookahi papa mailoko mai o ka hinai berena hu ole, ka mea imua o Iehova.
24 Ìwọ yóò fi gbogbo rẹ̀ lé Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì fì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì níwájú Olúwa.
A e haawi oe ia mau mea a pau iloko o na lima o Aarona, a iloko o na lima a kana mau keikikane, a e hoali lakou i mohai hoali imua o Iehova.
25 Nígbà náà ni ìwọ yóò sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ìwọ yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ pẹ̀lú ẹbọ sísun fún òórùn dídùn níwájú Olúwa, ẹbọ ti a fi iná sun sí Olúwa.
A e lawe oe ia mau mea mai ko lakou lima, a e puhi maluna o ke kuahu, i mohai kuni, i mea ala imua o Iehova; he mohai ahi ia na Iehova.
26 Ìwọ yóò sì mú igẹ̀ àgbò ìyàsímímọ́ Aaroni, ìwọ yóò si fí ì ni ẹbọ fífì níwájú Olúwa; ìpín tìrẹ ni èyí.
E lawe hoi oe i ka umauma o ka hipa o ko Aarona hoolaaia, a e hoali ae, i mohai hoali imua o Iehova, oia hoi kau apana.
27 “Ìwọ yóò sì ya igẹ̀ ẹbọ fífì náà sí mímọ́, àti ìtàn ẹbọ à gbé sọ sókè tí a fì, tí a sì gbé sọ sókè nínú àgbò ìyàsímímọ́ náà, àní nínú èyí tí í ṣe Aaroni àti nínú èyí tí ì ṣe tí àwọn ọmọ rẹ̀.
A e hoolaa oe i ka umauma o ka mohai hoali, a me ka uha mua o ka mohai kaikai, ka mea i hoaliia, a kaikaiia hoi, o ka hipakane o ka hoolaa ana, ka mea no Aarona, a no kana mau keikikane;
28 Èyí ni yóò sì máa ṣe ìpín ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli nígbà gbogbo. Nítorí ẹbọ à gbé sọ sókè ni ẹbọ tí yóò ṣì ṣe èyí ni ẹbọ tí àwọn ọmọ Israẹli yóò máa ṣe sí Olúwa láti inú ẹbọ àlàáfíà wọn.
A e lilo ia na Aarona, a na kana mau keikikane, mai na mamo a Iseraela ae, he kanawai mau loa ia; no ka mea, he mohai kaikai ia: a e lilo ia i mohai kaikai, mai na mamo a Iseraela ae, i alana hoi no na mohai hoomalu o ko lakou mohai kaikai no Iehova.
29 “Aṣọ mímọ́ Aaroni yóò jẹ́ ti irú àwọn ọmọ rẹ̀, nítorí kí a lè máa fi òróró yàn wọ́n kí a sì lè máa yà wọ́n sì mímọ́.
A o na kahiko laa o Aarona, na kana mau keikikane ia mahope ona; i poniia lakou maloko o ia mau mea, a hoolaaia maloko olaila.
30 Ọmọ rẹ̀ tí ó bá jẹ àlùfáà ní ipò rẹ̀, tí ó bá wọ̀ yóò máa sì wá sí àgọ́ àjọ láti ṣiṣẹ́ ní Ibi Mímọ́, yóò sì máa wọ̀ wọ́n ní ọjọ́ méje.
A o ke keiki e lilo ana i kahuna ma kona hakahaka, nana no e hookomo ia mau mea i ehiku la, i kona manawa e hele mai ai iloko o ka helelewa o ke anaina kanaka, e lawelawe ma kahi hoano.
31 “Ìwọ yóò sì mú àgbò fún ìyàsímímọ́, ìwọ yóò sì bọ ẹran rẹ̀ ní ibi mímọ́ kan.
A e lawe oe i ka hipakane o ka hoolaa ana, a e hoolapalapa i kona io maloko o kahi hoano.
32 Ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ ni Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò ti jẹ ẹran àgbò náà àti àkàrà náà tí ó wà nínú apẹ̀rẹ̀.
A e ai no o Aarona, a me kana mau keikikane i ka io o ka hipakane, a me ka berena maloko o ka hinai, ma ka puka o ka halelewa o ke anaina kanaka.
33 Wọn yóò sì jẹ nǹkan wọ̀nyí èyí tí a fi ṣe ètùtù náà fún ìyàsímímọ́ àti ìsọdimímọ́ wọn. Ṣùgbọ́n àlejò ni kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀, nítorí pé mímọ́ ni.
A e ai no lakou ia mau mea i huikalaia'i, e hookahuna, a e hoolaa ia lakou: aole e ai ka malihini, no ka mea, ua laa ia mau mea.
34 Bí ohun kan nínú ẹran àgbò ìyàsímímọ́ tàbí nínú àkàrà náà bá kù di òwúrọ̀, nígbà náà ni kí ìwọ fi iná sun wọn. A kò gbọdọ̀ jẹ ẹ́, nítorí mímọ́ ni.
A ina e koe iho kekahi io o ka hoolaa ana, a kekahi berena paha, a kakahiaka, alaila e puhi oe i ke koena i ke ahi; aole ia e aiia, no ka mea, ua laa ia.
35 “Báyìí ni ìwọ yóò ṣì ṣe fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ bí ohun gbogbo ti mo paláṣẹ fún ọ, ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi yà wọ́n sí mímọ́.
A pela oe e hana'i ia Aarona, a i kana mau keikikane, e like me na mea a pau a'u i kauoha aku ai ia oe, i ehiku la e hoolaa ai oe ia lakou.
36 Ìwọ yóò sì máa pa akọ màlúù kọ̀ọ̀kan ní ojoojúmọ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù. Ìwọ yóò sì wẹ pẹpẹ mọ́ nípa ṣíṣe ètùtù fún un, ìwọ yóò sì ta òróró sí i láti sọ ọ́ dí mímọ́.
A e kaumaha oe i kela la i keia la, i bipi, he mohai hala, i mea e kalahala ai: a e hoomaemae oe i ke kuahu, i ka wa au e hookalahala ai nona, a e poni oe ia mea, a e hoolaa hoi.
37 Ní ọjọ́ méje ni ìwọ yóò ṣe ètùtù sí pẹpẹ náà, ìwọ yóò sì sọ ọ́ di mímọ́. Nígbà náà ni pẹpẹ náà yóò jẹ́ mímọ́ jùlọ, àti ohunkóhun tí ó bá fi ọwọ́ kàn án yóò jẹ́ mímọ́.
Ehiku la e kalahala'i oe no ke kuahu, a e hoolaa ia men; a e lilo ia i kuahu laa loa. E laa no na mea a pau i pa mai i ke kuahu.
38 “Èyí ni ìwọ yóò máa fi rú ẹbọ ní orí pẹpẹ náà: Ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kan ni ojoojúmọ́ láéláé.
Eia hoi ka mea au e kaumaha'i maluna o ke kuahu a mau i kela la i keia la, elua keikihipa o ka makahiki hookahi.
39 Ọ̀dọ́-àgùntàn kan ni ìwọ yóò fi rú ẹbọ ní òwúrọ̀ àti ọ̀dọ́-àgùntàn èkejì ní àṣálẹ́.
E kaumaha oe i hookahi keikihipa i ke kakahiaka, a o kekahi keikihipa kau e kaumaha ai i ke ahiahi.
40 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn ti àkọ́kọ́ rú ẹbọ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dídára tí a fi ìdámẹ́rin hínì òróró lára olifi tí a gún, àti ìdámẹ́rin hínì wáìnì bí ẹbọ mímu.
Me ke keikihipa hookahi, he hapaumi o ka epa palaoa, i huiia me ka hapaha o ka hina aila i kuiia; a me ka hapaha o ka hina waina, i mea mohai inu.
41 Ọ̀dọ́-àgùntàn kejì ni kí ìwọ kí ó pa rú ẹbọ ní àṣálẹ́ ìwọ yóò sì ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ mímu bí ti òwúrọ̀ fún òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná ṣe ni sí Olúwa.
E kaumaha hoi oe i kekahi keikihipa i ke ahiahi, a e hana aku hoi ia mea, e like me ka mohai makana o ke kakahiaka, a e like hoi me kona mohai inu, i mea ala, he mohai ahi hoi ia no Iehova.
42 “Fún ìrandíran tó ń bọ̀, ni ẹ ó máa ṣe ẹbọ sísun nígbà gbogbo ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ níwájú Olúwa. Níbẹ̀ èmi yóò pàdé yín, èmi yóò sì bá a yín sọ̀rọ̀;
He mohaikuni mau ia no ko oukou hanauna, ma ka puka o ka halelewa o ke anaina, imua o Iehova; kahi a'u e halawai ai me oe, e kamailio pu me oe malaila.
43 níbẹ̀ sì tún ni èmi yóò pàdé àwọn ọmọ Israẹli, a ó sì fi ògo mi ya àgọ́ náà sí mímọ́.
A malaila wau e halawai ai me na mamo a Iseraela, a e hoolaaia mai ai, e ko'u nani.
44 “Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ya àgọ́ àjọ náà sí mímọ́ àti pẹpẹ náà, èmi yóò sì ya Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sí mímọ́ láti máa ṣe iṣẹ́ bí àlùfáà fún mi.
A e hoolaa no wau i ka halelewa o ke anaina kanaka, a me ke kuahu: e hoolaa no hoi au ia Aarona. a me kana mau keikikane, e lawelawe no'u ma ka oihana kahuna.
45 Nígbà náà ni èmi yóò máa gbé láàrín àwọn ọmọ Israẹli, èmi yóò sì máa ṣe Ọlọ́run wọn.
A e noho no wau iwaena konu o na mamo a Iseraela, a owau auanei ko lakou Akua.
46 Wọn yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, nítorí kí èmi lè máa gbé àárín wọn. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
A e ike auanei lakou, owau no Iehova, ko lakou Akua, ka mea i lawe mai ia lakou, mai ka aina o Aigupita mai, i noho wau iwaena o lakou. Owau, o Iehova no ko lakou Akua.

< Exodus 29 >