< Exodus 28 >

1 “Ìwọ sì mú Aaroni arákùnrin rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, mú un kúrò ni àárín àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ Nadabu, Abihu, Eleasari, àti Itamari, kí wọn kí ó lè sìn mí gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Fais aussi approcher de toi Aaron ton frère avec ses fils du milieu des enfants d’Israël, afin qu’ils exercent les fonctions du sacerdoce pour moi: Aaron, Nadab et Abiu, Eléazar et Ithamar.
2 Ìwọ yóò sì dá aṣọ mímọ́ fún Aaroni arákùnrin rẹ, láti fún un ni ọ̀ṣọ́ àti ọlá.
Et tu feras un vêtement saint à Aaron ton frère pour la gloire et l’ornement.
3 Ìwọ yóò sì sọ fún gbogbo àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn, àwọn ẹni tí mo fún ní ọgbọ́n, kí wọn kí ó lè dá aṣọ fún Aaroni, fún ìyàsímímọ́ rẹ̀, kí ó lè ba à sìn mí gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Et tu parleras à tous les sages de cœur, que j’ai remplis de l’esprit de prudence, pour qu’ils fassent à Aaron des vêtements, par lesquels étant sanctifié, il me servira.
4 Wọ̀nyí ni àwọn aṣọ tí wọn yóò dá: ìgbàyà kan, ẹ̀wù efodu, ọ̀já àmùrè kan, ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ ọlọ́nà, fìlà àti aṣọ ìgúnwà. Kí wọn kí ó dá àwọn aṣọ mímọ́ yìí fún Aaroni arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọn kí ó lè sìn mí gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Or voici les vêtements qu’ils feront: Un rational, un éphod, une robe et une tunique de lin étroite, une tiare, et une ceinture. Ainsi, ils feront des vêtements saints à ton frère Aaron et à ses fils, afin qu’ils exercent les fonctions du sacerdoce, pour moi.
5 Wọn yóò sì lo wúrà, aṣọ aláró, elése àlùkò àti ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ dáradára.
Et ils prendront l’or, l’hyacinthe, la pourpre, l’écarlate deux fois teinte et le fin lin.
6 “Wọn yóò sì dá ẹ̀wù efodu ti wúrà, tí aṣọ aláró, elése àlùkò àti ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́, iṣẹ́ ọlọ́nà.
Or ils feront l’éphod d’or, d’hyacinthe, de pourpre, d’écarlate deux fois teinte, et de fin lin retors, d’un ouvrage en tissu de diverses couleurs.
7 Kí ó ni aṣọ èjìká méjì tí a so mọ́ igun rẹ̀ méjèèjì, kí a lè so ó pọ̀.
Il aura aux deux côtés de ses sommités deux bandes jointes, de manière à former une seule pièce.
8 Àti onírúurú ọnà ọ̀já rẹ̀, tí ó wà ni orí rẹ̀, yóò rí bákan náà, gẹ́gẹ́ bi iṣẹ́ rẹ̀, tí wúrà, ti aṣọ aláró, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́.
Le tissu lui-même et tous les ouvrages divers seront d’or, d’hyacinthe, de pourpre, d’écarlate deux fois teinte et de fin lin retors.
9 “Ìwọ yóò sì mú òkúta óníkìsì méjì, ìwọ yóò sì fín orúkọ àwọn ọmọ Israẹli sára wọn.
Et tu prendras deux pierres d’onyx, et tu graveras sur elles les noms des fils d’Israël:
10 Ní ti ìbí wọn, orúkọ àwọn mẹ́fà sára òkúta kan àti orúkọ àwọn mẹ́fà tókù sára òkúta kejì.
Six noms sur une pierre, et les six autres sur une autre, selon l’ordre de leur naissance.
11 Iṣẹ́ ọnà òkúta fínfín, bí ìfín èdìdì àmì, ni ìwọ yóò fún òkúta méjèèjì gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ọmọ Israẹli: ìwọ yóò sì dè wọ́n sí ojú ìdè wúrà.
Au moyen d’un travail de sculpteur et de la taille d’un lapidaire, tu graveras sur les pierres les noms des fils d’Israël, après les avoir enchâssées dans l’or et les en avoir environnées;
12 Ìwọ yóò sì so wọ́n pọ̀ mọ́ èjìká efodu náà ní òkúta ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli. Aaroni yóò sì máa ní orúkọ wọn níwájú Olúwa ní èjìká rẹ̀ méjèèjì fún ìrántí.
Et tu les mettras sur les deux côtés de l’éphod, souvenir pour les enfants d’Israël. Et Aaron portera sur ses épaules leur nom devant le Seigneur, pour souvenir.
13 Ìwọ yóò sì ṣe ojú ìdè wúrà,
Tu feras encore des agrafes d’or.
14 àti okùn ẹ̀wọ̀n méjì ti kìkì wúrà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀já àmùrè kí o sì so ẹ̀wọ̀n náà mọ́ ojú ìdè náà.
Et deux chaînettes d’un or très pur, se tenant l’une à l’autre, que tu attacheras aux agrafes.
15 “Ìwọ yóò fi iṣẹ́ ọgbọ́n ṣe ìgbàyà fún ìpinnu iṣẹ́ ọnà gbẹ́nàgbẹ́nà. Ìwọ yóò ṣe é bí ẹ̀wù efodu ti wúrà, ti aṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́ dáradára.
Tu feras aussi le rational du jugement, d’un ouvrage en tissu de diverses couleurs, selon la tissure de l’éphod, d’or, d’hyacinthe, de pourpre, d’écarlate deux teinte et de fin lin retors.
16 Kí ìhà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ṣe déédé—kí ó jẹ́ ìwọ̀n ìka kan ní ìnà àti ìwọ̀n ìka kan ní ìbú, kí o sì ṣe é ní ìṣẹ́po méjì.
Il sera carré et double, et il aura la mesure d’une palme, tant en longueur qu’en largeur.
17 Nígbà náà ni ìwọ yóò de òkúta oníyebíye mẹ́rin sára ẹsẹ̀ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ àkọ́kọ́ ni kí rúbì, topasi àti berili wà;
Tu y mettras quatre rangs de pierres: à la première rangée il y aura une sardoine, une topaze et une émeraude;
18 ní ẹsẹ̀ kejì turikuose, emeradi, safire, àti diamọndi;
À la seconde, une escarboucle, un saphir et un jaspe;
19 ní ẹsẹ̀ kẹta, jasiniti, agate, àti ametisiti;
À la troisième, un ligure, une agate et une améthyste;
20 ní ẹsẹ̀ kẹrin, topasi, àti óníkìsì àti jasperi. A ó sì tò wọ́n sí ojú wúrà ní dìde wọn.
À la quatrième, un chrysolite, un onyx, et un béryl; ils seront enchâssés dans de l’or, selon leurs rangs.
21 Òkúta méjìlá yóò wà, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún orúkọ àwọn ọmọ Israẹli olúkúlùkù èdìdì àmì pẹ̀lú orúkọ ẹnìkọ̀ọ̀kan bí ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
Et ils porteront les noms des fils d’Israël: leurs douze noms seront gravés, chaque nom sur chaque pierre, selon les douze tribus.
22 “Fún ìgbàyà náà, ìwọ yóò ṣe okùn ẹ̀wọ̀n ti kìkì wúrà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀já àmùrè.
Tu feras pour le rational des chaînes se tenant l’une à l’autre, d’un or très pur,
23 Ìwọ yóò ṣe òrùka wúrà méjì fún un, kí o sì so wọ́n mọ́ igun méjèèjì ìgbàyà náà.
Et deux anneaux d’or que tu mettras aux deux sommités du rational;
24 Ìwọ yóò so ẹ̀wọ̀n wúrà méjèèjì mọ́ òrùka ní igun ìgbàyà náà,
Puis tu joindras les deux chaînes d’or par les anneaux qui sont aux bords du rational;
25 àti etí ẹ̀wọ̀n méje ni kí o so mọ́ ojú ìdè méjèèjì, kí o sì fi sí èjìká ẹ̀wù efodu náà níwájú.
Et tu attacheras les extrémités des chaînes elles-mêmes aux agrafes aux deux côtés de l’éphod qui regarde le rational.
26 Ìwọ yóò ṣe òrùka wúrà méjì, ìwọ yóò sì so wọ́n mọ́ igun méjì ìgbàyà kejì ní ìhà inú tí ó ti ẹ̀wù efodu náà.
Tu feras aussi deux anneaux d’or que tu mettras aux sommités du rational sur les bords qui sont vis-à-vis de l’éphod, et regardent sa partie de derrière.
27 Ìwọ yóò sì ṣe òrùka wúrà méjì, ìwọ yóò sì fi wọ́n sí èjìká ẹ̀wù efodu méjèèjì ní ìsàlẹ̀, sí ìhà iwájú rẹ̀, tí ó súnmọ́ ojú sí ìránṣọ náà, lókè onírúurú ọnà ọ̀já ẹ̀wù efodu náà.
Tu feras de plus deux autres anneaux d’or qui devront être posés aux deux côtés de l’éphod par en bas; côtés qui regardent en face de la jonction inférieure, afin que le rational puisse s’adapter à l’éphod.
28 Wọn yóò sì so òrùka ìgbàyà mọ́ òrùka ẹ̀wù efodu pẹ̀lú ọ̀já aláró, pa á pọ̀ mọ́ ìgbànú, kí a má ba à tú ìgbàyà náà kúrò lára ẹ̀wù efodu náà.
Et que le rational soit attaché par ses anneaux aux anneaux de l’éphod au moyen d’un ruban d’hyacinthe, afin que la jonction habilement faite se maintienne, et que le rational et l’éphod ne puissent être séparés l’un de l’autre.
29 “Nígbàkígbà tí Aaroni bá wọ Ibi Mímọ́, òun yóò ru orúkọ àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo ọ̀kan rẹ̀ ni ìgbàyà ìpinnu bí ìrántí nígbà gbogbo níwájú Olúwa.
Et Aaron portera les noms des fils d’Israël dans le rational du jugement sur sa poitrine, lorsqu’ils entrera dans le sanctuaire, souvenir en présence du Seigneur pour toujours.
30 Bákan náà ìwọ yóò sì mu Urimu àti Tumimu sínú ìgbàyà, kí wọn kí ó wà ní ọkàn Aaroni nígbàkígbà tí ó bá ń wólẹ̀ níwájú Olúwa. Aaroni yóò sì máa ru ohun ti a ń fi ṣe ìpinnu fún àwọn ọmọ Israẹli ní ọkàn rẹ̀ nígbà gbogbo níwájú Olúwa.
Or tu mettras sur le rational du jugement: La Doctrine et la Vérité, qui seront sur la poitrine d’Aaron, lorsqu’il entrera devant le Seigneur; ainsi il portera toujours le jugement des fils d’Israël sur sa poitrine en la présence du Seigneur.
31 “Ìwọ yóò ṣì ṣe aṣọ ìgúnwà ẹ̀wù efodu náà ní kìkì aṣọ aláró,
Tu feras encore, toute de couleur d’hyacinthe, la tunique de l’éphod.
32 pẹ̀lú ojú ọrùn kí ó wà láàrín rẹ̀ fún orí. Kí iṣẹ́ ọ̀nà wà létí rẹ̀ bí ìṣẹ́tí yí i ká bí agbádá, kí ó má ba à ya.
Au milieu de laquelle il y aura dans le haut une ouverture, et autour d’elle un bord tissu, comme on a coutume d’en faire aux extrémités des vêtements, pour ne pas qu’il se déchire facilement.
33 Ṣe pomegiranate ti aṣọ aláró, ti elése àlùkò àti ti òdòdó yí ìṣẹ́tí ọ̀já àmùrè náà ká, pẹ̀lú ṣaworo wúrà láàrín wọn.
Mais en bas, aux pieds de la même tunique, tu feras tout autour comme des grenades d’hyacinthe, de pourpre, d’écarlate deux fois teinte, en entremêlant des sonnettes,
34 Àwọn ṣaworo wúrà àti àwọn pomegiranate ni kí ó yí ìṣẹ́tí ọ̀já àmùrè náà ká.
En sorte qu’il y ait une sonnette d’or et une grenade, et de nouveau, une autre sonnette d’or et une grenade.
35 Aaroni gbọdọ̀ máa wọ̀ ọ́ nígbà tí o bá ń ṣiṣẹ́. A ó sì máa gbọ́ ìró àwọn agogo nígbà tí ó bá ń wọ Ibi Mímọ́ níwájú Olúwa àti nígbà tí ó bá ń jáde bọ̀, kí ó má ba à kú.
Aaron en sera revêtu dans les fonctions du ministère, afin qu’on entende le son, quand il entrera dans le sanctuaire en la présence du Seigneur, et qu’il en sortira, et qu’il ne meure point.
36 “Ìwọ yóò sì ṣe àwo kìkì wúrà, ìwọ yóò sì fín sára rẹ̀ bí, fínfín èdìdì àmì pé. Mímọ́ sí Olúwa.
Tu feras encore une lame d’un or très pur, sur laquelle tu graveras, en ouvrage de ciseleur: La sainteté est au Seigneur.
37 Ìwọ yóò fi ọ̀já aláró sára rẹ̀ ìwọ yóò sì so ó mọ́ fìlà náà; kí ó sì wà níwájú fìlà náà.
Et tu la lieras avec un ruban d’hyacinthe, et elle sera sur la tiare,
38 Kí ó wà níwájú orí Aaroni, kí ó sì lè máa ru ẹ̀bi tí ó jẹ mọ́ ẹ̀bùn mímọ́ ti àwọn ọmọ Israẹli ti yà sí mímọ́, èyíkéyìí tí ẹ̀bùn wọn lè jẹ́. Yóò máa wà níwájú orí Aaroni nígbà gbogbo, kí wọn lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa.
Dominant le front du pontife. Et Aaron portera les iniquités de ce que les enfants d’Israël auront offert et consacré dans tous leurs dons et présents. Or cette lame sera toujours sur son front, afin que le Seigneur leur soit propice.
39 “Ìwọ yóò sì fi ọ̀gbọ̀ dáradára hun ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀, ìwọ yóò sì fi ọ̀gbọ̀ dáradára ṣe fìlà. Ìwọ yóò sì fi iṣẹ́ abẹ́rẹ́ ṣe ọ̀já àmùrè.
Et tu feras la tunique étroite de fin lin; tu feras aussi une tiare de fin lin, et une ceinture, en ouvrage de brodeur.
40 Ìwọ yóò sì dá ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀, ọ̀já àmùrè àti ìgbàrí fún àwọn ọmọ Aaroni, láti fún wọn ní ọ̀ṣọ́ àti ọlá.
Mais aux fils d’Aaron, tu prépareras des tuniques de lin, des ceintures et des tiares pour la gloire et l’ornement;
41 Lẹ́yìn tí ìwọ ti fi àwọn aṣọ wọ̀nyí wọ Aaroni arákùnrin rẹ, ìwọ yóò sì fi wọ àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú, ìwọ ó ta òróró sí wọn ní orí, ìwọ yóò sì ya wọ́n sí mímọ́. Ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, kí wọn kí o lè máa ṣe iṣẹ́ àlùfáà.
Et tu revêtiras de tous ces vêtements Aaron ton frère, et ses fils avec lui. Et tu consacreras les mains de tous, et tu les sanctifieras afin qu’ils exercent les fonctions du sacerdoce pour moi.
42 “Ìwọ yóò dá ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ fún wọn, kí wọn lè máa fi bo ìhòhò wọn, kí ó dé ìbàdí dé itan.
Tu feras aussi des caleçons de lin, afin qu’ils couvrent la chair de leur nudité, depuis les reins jusqu’aux cuisses;
43 Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gbọdọ̀ wọ̀ wọ́n nígbàkígbà tí wọ́n bá wọ àgọ́ àjọ lọ tàbí nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ pẹpẹ láti ṣiṣẹ́ ní Ibi Mímọ́ kí wọn kí ó má ba à dẹ́ṣẹ̀, wọn a sì kú. “Èyí jẹ́ ìlànà láéláé fún Aaroni àti fún irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
Et Aaron et ses fils s’en serviront, quand ils entreront dans le tabernacle de témoignage, ou quand ils approcheront de l’autel pour servir dans le sanctuaire, afin qu’ils ne meurent point coupables d’iniquité. Ce sera une loi perpétuelle pour Aaron et pour sa postérité après lui.

< Exodus 28 >