< Exodus 28 >

1 “Ìwọ sì mú Aaroni arákùnrin rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, mú un kúrò ni àárín àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ Nadabu, Abihu, Eleasari, àti Itamari, kí wọn kí ó lè sìn mí gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Ty pak přijmi k sobě Arona bratra svého s syny jeho z prostředku synů Izraelských, aby úřad kněžský konali přede mnou: Aron, Nádab, Abiu, Eleazar a Itamar, synové Aronovi.
2 Ìwọ yóò sì dá aṣọ mímọ́ fún Aaroni arákùnrin rẹ, láti fún un ni ọ̀ṣọ́ àti ọlá.
A uděláš roucha svatá Aronovi bratru svému k slávě a k ozdobě.
3 Ìwọ yóò sì sọ fún gbogbo àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn, àwọn ẹni tí mo fún ní ọgbọ́n, kí wọn kí ó lè dá aṣọ fún Aaroni, fún ìyàsímímọ́ rẹ̀, kí ó lè ba à sìn mí gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Ty také mluviti budeš se všechněmi umělými řemeslníky, kteréž jsem naplnil duchem moudrosti, aby dělali roucha Aronovi ku posvěcení jeho, v nichž by úřad kněžský konal přede mnou.
4 Wọ̀nyí ni àwọn aṣọ tí wọn yóò dá: ìgbàyà kan, ẹ̀wù efodu, ọ̀já àmùrè kan, ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ ọlọ́nà, fìlà àti aṣọ ìgúnwà. Kí wọn kí ó dá àwọn aṣọ mímọ́ yìí fún Aaroni arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọn kí ó lè sìn mí gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Tato pak jsou roucha, kteráž udělají, náprsník, náramenník, plášť a sukni s oky, čepici a pás. Takové šaty svaté udělají Aronovi bratru tvému a synům jeho, aby úřad kněžský konali přede mnou.
5 Wọn yóò sì lo wúrà, aṣọ aláró, elése àlùkò àti ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ dáradára.
A vezmou řemeslníci zlato a modrý postavec, a šarlat a červec dvakrát barvený a kment.
6 “Wọn yóò sì dá ẹ̀wù efodu ti wúrà, tí aṣọ aláró, elése àlùkò àti ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́, iṣẹ́ ọlọ́nà.
Udělají pak náramenník z zlata, z postavce modrého a šarlatu, z červce dvakrát barveného a hedbáví bílého, přesukovaného dílem řemeslným.
7 Kí ó ni aṣọ èjìká méjì tí a so mọ́ igun rẹ̀ méjèèjì, kí a lè so ó pọ̀.
Dva vrchní kraje spojená míti bude na dvou koncích svých, a tak se spolu držeti bude.
8 Àti onírúurú ọnà ọ̀já rẹ̀, tí ó wà ni orí rẹ̀, yóò rí bákan náà, gẹ́gẹ́ bi iṣẹ́ rẹ̀, tí wúrà, ti aṣọ aláró, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́.
Přepásaní pak přes ten náramenník, kteréž na něm bude, podobné bude dílu jeho; z týchž věcí bude, totiž z zlata, z postavce modrého a z šarlatu, a z červce dvakrát barveného, a z hedbáví bílého přesukovaného.
9 “Ìwọ yóò sì mú òkúta óníkìsì méjì, ìwọ yóò sì fín orúkọ àwọn ọmọ Israẹli sára wọn.
Vezmeš také dva kameny onychinové, a vyryješ na nich jména synů Izraelských.
10 Ní ti ìbí wọn, orúkọ àwọn mẹ́fà sára òkúta kan àti orúkọ àwọn mẹ́fà tókù sára òkúta kejì.
Šest jmen jejich na kameni jednom, a jmen šest ostatních na kameni druhém, podlé pořádku narození jejich.
11 Iṣẹ́ ọnà òkúta fínfín, bí ìfín èdìdì àmì, ni ìwọ yóò fún òkúta méjèèjì gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ọmọ Israẹli: ìwọ yóò sì dè wọ́n sí ojú ìdè wúrà.
Dílem řemeslníka, kterýž řeže na kameni, a kterýž vyrývá pečeti, vyryješ na těch dvou kameních jména synů Izraelských; do zlata je vsadíš.
12 Ìwọ yóò sì so wọ́n pọ̀ mọ́ èjìká efodu náà ní òkúta ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli. Aaroni yóò sì máa ní orúkọ wọn níwájú Olúwa ní èjìká rẹ̀ méjèèjì fún ìrántí.
A položíš dva kameny ty na vrchních krajích náramenníku, kameny pro pamět na syny Izraelské; a nositi bude Aron jména jejich před Hospodinem na obou ramenách svých na památku.
13 Ìwọ yóò sì ṣe ojú ìdè wúrà,
Uděláš i haklíky zlaté.
14 àti okùn ẹ̀wọ̀n méjì ti kìkì wúrà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀já àmùrè kí o sì so ẹ̀wọ̀n náà mọ́ ojú ìdè náà.
A dva řetízky z zlata čistého jednostejně uděláš dílem točeným, a zavěsíš řetízky ty stočené na ty haklíky.
15 “Ìwọ yóò fi iṣẹ́ ọgbọ́n ṣe ìgbàyà fún ìpinnu iṣẹ́ ọnà gbẹ́nàgbẹ́nà. Ìwọ yóò ṣe é bí ẹ̀wù efodu ti wúrà, ti aṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́ dáradára.
Uděláš také náprsník soudu dílem řemeslným, takovým dílem, jako náramenník uděláš jej z zlata, z postavce modrého, z šarlatu, z červce dvakrát barveného, a z bílého hedbáví přesukovaného.
16 Kí ìhà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ṣe déédé—kí ó jẹ́ ìwọ̀n ìka kan ní ìnà àti ìwọ̀n ìka kan ní ìbú, kí o sì ṣe é ní ìṣẹ́po méjì.
Ètverhraný bude a dvojnásobní; pídi dlouhost, a pídi širokost jeho bude.
17 Nígbà náà ni ìwọ yóò de òkúta oníyebíye mẹ́rin sára ẹsẹ̀ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ àkọ́kọ́ ni kí rúbì, topasi àti berili wà;
A vysadíš jej všudy kamením drahým. Ètyřmi řady ať jest kamení, pořádkem tímto: Sardius, topazius a smaragdus v prvním řadu;
18 ní ẹsẹ̀ kejì turikuose, emeradi, safire, àti diamọndi;
V druhém pak zpořádaní karbunkulus, zafir a jaspis;
19 ní ẹsẹ̀ kẹta, jasiniti, agate, àti ametisiti;
A v řadu třetím linkurius, achates a ametyst;
20 ní ẹsẹ̀ kẹrin, topasi, àti óníkìsì àti jasperi. A ó sì tò wọ́n sí ojú wúrà ní dìde wọn.
V čtvrtém řadu chryzolit, onychin a beryl. Vsazeni budou do zlata v svém pořádku.
21 Òkúta méjìlá yóò wà, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún orúkọ àwọn ọmọ Israẹli olúkúlùkù èdìdì àmì pẹ̀lú orúkọ ẹnìkọ̀ọ̀kan bí ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
Těch pak kamenů s jmény synů Izraelských bude dvanácte, podlé jmen jejich, dílem řežících pečeti; jeden každý podlé jména svého, pro dvanáctero pokolení budou.
22 “Fún ìgbàyà náà, ìwọ yóò ṣe okùn ẹ̀wọ̀n ti kìkì wúrà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀já àmùrè.
Uděláš i k náprsníku řetízky jednostejné dílem točeným z zlata čistého.
23 Ìwọ yóò ṣe òrùka wúrà méjì fún un, kí o sì so wọ́n mọ́ igun méjèèjì ìgbàyà náà.
Uděláš také k náprsníku dva kroužky zlaté, a dáš je na dva kraje náprsníka.
24 Ìwọ yóò so ẹ̀wọ̀n wúrà méjèèjì mọ́ òrùka ní igun ìgbàyà náà,
A prostrčíš dva řetízky zlaté skrze dva kroužky po krajích náprsníka.
25 àti etí ẹ̀wọ̀n méje ni kí o so mọ́ ojú ìdè méjèèjì, kí o sì fi sí èjìká ẹ̀wù efodu náà níwájú.
A druhé konce těch dvou řetízků připneš k haklíkům, a dáš na vrchní kraje náramenníka po předu.
26 Ìwọ yóò ṣe òrùka wúrà méjì, ìwọ yóò sì so wọ́n mọ́ igun méjì ìgbàyà kejì ní ìhà inú tí ó ti ẹ̀wù efodu náà.
Uděláš i dva kroužky zlaté, kteréž dáš na dva kraje náprsníka, na tu obrubu jeho, kteráž jest po té straně k náramenníku do vnitřku.
27 Ìwọ yóò sì ṣe òrùka wúrà méjì, ìwọ yóò sì fi wọ́n sí èjìká ẹ̀wù efodu méjèèjì ní ìsàlẹ̀, sí ìhà iwájú rẹ̀, tí ó súnmọ́ ojú sí ìránṣọ náà, lókè onírúurú ọnà ọ̀já ẹ̀wù efodu náà.
Uděláš ještě dva jiné kroužky zlaté, kteréž dáš na dvě strany náramenníka zespod po předu naproti spojení jeho, svrchu nad přepásaním náramenníka.
28 Wọn yóò sì so òrùka ìgbàyà mọ́ òrùka ẹ̀wù efodu pẹ̀lú ọ̀já aláró, pa á pọ̀ mọ́ ìgbànú, kí a má ba à tú ìgbàyà náà kúrò lára ẹ̀wù efodu náà.
Tak svíží náprsník ten, kroužky jeho s kroužky náramenníka, tkanicí z postavce modrého, aby byl nad přepásaním náramenníka, a neodevstával náprsník od náramenníka.
29 “Nígbàkígbà tí Aaroni bá wọ Ibi Mímọ́, òun yóò ru orúkọ àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo ọ̀kan rẹ̀ ni ìgbàyà ìpinnu bí ìrántí nígbà gbogbo níwájú Olúwa.
I bude nositi Aron jména synů Izraelských na náprsníku soudu na srdci svém, když vcházeti bude do svatyně, na památku před Hospodinem ustavičně.
30 Bákan náà ìwọ yóò sì mu Urimu àti Tumimu sínú ìgbàyà, kí wọn kí ó wà ní ọkàn Aaroni nígbàkígbà tí ó bá ń wólẹ̀ níwájú Olúwa. Aaroni yóò sì máa ru ohun ti a ń fi ṣe ìpinnu fún àwọn ọmọ Israẹli ní ọkàn rẹ̀ nígbà gbogbo níwájú Olúwa.
Položíš pak do náprsníku soudu urim a thumim, aby bylo na srdci Aronově, když vcházeti bude před Hospodina; a nositi bude Aron soud synů Izraelských na srdci svém před Hospodinem vždycky.
31 “Ìwọ yóò ṣì ṣe aṣọ ìgúnwà ẹ̀wù efodu náà ní kìkì aṣọ aláró,
Uděláš také plášť pod náramenník, všecken z postavce modrého.
32 pẹ̀lú ojú ọrùn kí ó wà láàrín rẹ̀ fún orí. Kí iṣẹ́ ọ̀nà wà létí rẹ̀ bí ìṣẹ́tí yí i ká bí agbádá, kí ó má ba à ya.
A bude na vrchu v prostřed něho díra; okolek její všudy vůkol dílem tkaným, jako obojek u pancíře bude, aby se neroztrhl.
33 Ṣe pomegiranate ti aṣọ aláró, ti elése àlùkò àti ti òdòdó yí ìṣẹ́tí ọ̀já àmùrè náà ká, pẹ̀lú ṣaworo wúrà láàrín wọn.
Uděláš i na podolku jeho jablka zrnatá z hedbáví modrého, z šarlatu a z červce dvakrát barveného, na podolku jeho vůkol, a zvonečky zlaté mezi nimi vůkol.
34 Àwọn ṣaworo wúrà àti àwọn pomegiranate ni kí ó yí ìṣẹ́tí ọ̀já àmùrè náà ká.
Zvonček zlatý a jablko zrnaté, opět za tím zvonček zlatý a jablko zrnaté na podolku pláště vůkol.
35 Aaroni gbọdọ̀ máa wọ̀ ọ́ nígbà tí o bá ń ṣiṣẹ́. A ó sì máa gbọ́ ìró àwọn agogo nígbà tí ó bá ń wọ Ibi Mímọ́ níwájú Olúwa àti nígbà tí ó bá ń jáde bọ̀, kí ó má ba à kú.
A bude to míti na sobě Aron při službách, aby slyšán byl zvuk jeho, když vcházeti bude do svatyně před Hospodina, i když vycházeti bude, aby neumřel.
36 “Ìwọ yóò sì ṣe àwo kìkì wúrà, ìwọ yóò sì fín sára rẹ̀ bí, fínfín èdìdì àmì pé. Mímọ́ sí Olúwa.
Uděláš také plech z zlata čistého, a vyryješ na něm dílem vyrývajících pečeti: Svatost Hospodinu.
37 Ìwọ yóò fi ọ̀já aláró sára rẹ̀ ìwọ yóò sì so ó mọ́ fìlà náà; kí ó sì wà níwájú fìlà náà.
Kterýž dáš na tkanici z modrého postavce, a bude na čepici; napřed na čepici bude.
38 Kí ó wà níwájú orí Aaroni, kí ó sì lè máa ru ẹ̀bi tí ó jẹ mọ́ ẹ̀bùn mímọ́ ti àwọn ọmọ Israẹli ti yà sí mímọ́, èyíkéyìí tí ẹ̀bùn wọn lè jẹ́. Yóò máa wà níwájú orí Aaroni nígbà gbogbo, kí wọn lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa.
I bude nad čelem Aronovým, aby nesl Aron nepravosti posvěcených věcí, kterýchž by posvětili synové Izraelští při všech dařích posvěcených věcí svých; a bude nad čelem jeho vždycky, aby příjemné je činil před Hospodinem.
39 “Ìwọ yóò sì fi ọ̀gbọ̀ dáradára hun ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀, ìwọ yóò sì fi ọ̀gbọ̀ dáradára ṣe fìlà. Ìwọ yóò sì fi iṣẹ́ abẹ́rẹ́ ṣe ọ̀já àmùrè.
Uděláš také sukni z hedbáví bílého vázanou s oky; uděláš i čepici z hedbáví bílého; pás také uděláš dílem krumpéřským.
40 Ìwọ yóò sì dá ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀, ọ̀já àmùrè àti ìgbàrí fún àwọn ọmọ Aaroni, láti fún wọn ní ọ̀ṣọ́ àti ọlá.
Synům také Aronovým zděláš sukně; pasy také jim uděláš a klobouky k slávě a k ozdobě.
41 Lẹ́yìn tí ìwọ ti fi àwọn aṣọ wọ̀nyí wọ Aaroni arákùnrin rẹ, ìwọ yóò sì fi wọ àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú, ìwọ ó ta òróró sí wọn ní orí, ìwọ yóò sì ya wọ́n sí mímọ́. Ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, kí wọn kí o lè máa ṣe iṣẹ́ àlùfáà.
A oblečeš v ně Arona bratra svého a syny jeho s ním, a pomažeš jich, a naplníš ruce jejich, a posvětíš mi jich, aby úřad kněžský konali přede mnou.
42 “Ìwọ yóò dá ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ fún wọn, kí wọn lè máa fi bo ìhòhò wọn, kí ó dé ìbàdí dé itan.
Nadělej jim i košilek lněných k zakrytí nahoty těla; od bedr až do stehen budou.
43 Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gbọdọ̀ wọ̀ wọ́n nígbàkígbà tí wọ́n bá wọ àgọ́ àjọ lọ tàbí nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ pẹpẹ láti ṣiṣẹ́ ní Ibi Mímọ́ kí wọn kí ó má ba à dẹ́ṣẹ̀, wọn a sì kú. “Èyí jẹ́ ìlànà láéláé fún Aaroni àti fún irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
A ať je na sobě mají Aron i synové, když vcházeti budou do stánku úmluvy, aneb když přistupovati budou k oltáři, aby sloužili v svatyni; a neponesou nepravosti, aniž zemrou. Řád tento bude věčný jemu i potomkům jeho po něm.

< Exodus 28 >