< Exodus 25 >

1 Olúwa sì wí fún Mose pé,
Yahvé habló a Moisés diciendo:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn mú ọrẹ wá fún mi, ìwọ yóò gba ọrẹ náà fún mi ni ọwọ́ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan ti ọkàn rẹ bá fẹ́ láti fi fún mi.
“Habla a los hijos de Israel para que tomaréis una ofrenda para mí. De todo aquel cuyo corazón lo haga querer, tomarás mi ofrenda.
3 “Wọ̀nyí ni ọrẹ ti ìwọ yóò gbà ni ọwọ́ wọn: “wúrà, fàdákà àti idẹ;
Esta es la ofrenda que tomaréis de ellos: oro, plata, bronce,
4 aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó, ọ̀gbọ̀; irun ewúrẹ́.
azul, púrpura, escarlata, lino fino, pelo de cabra,
5 Awọ àgbò tí a rẹ ní pupa àti awọ ewúrẹ́ igbó; igi kasia;
pieles de carnero teñidas de rojo, cueros de vacas marinas, madera de acacia,
6 Òróró olifi fún iná títàn; òróró olóòórùn dídùn fún ìtasórí àti fún tùràrí olóòórùn dídùn;
aceite para la luz, especias para el aceite de la unción y para el incienso aromático,
7 àti òkúta óníkìsì àti òkúta olówó iyebíye ti a fi ṣe ọ̀ṣọ́ sí ara ẹ̀wù efodu àti ẹ̀wù ìgbàyà.
piedras de ónice, y piedras de engaste para el efod y para el pectoral.
8 “Nígbà náà ni ìwọ yóò jẹ́ kí wọn kọ́ ibi mímọ́ fún mi. Èmi yóò sì máa gbé ní àárín wọn.
Que me hagan un santuario, para que yo habite en medio de ellos.
9 Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí ti mo fihàn ọ́, nípa àpẹẹrẹ àgọ́, àti àpẹẹrẹ gbogbo ohun èlò inú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó sì ṣe é.
Conforme a todo lo que te muestre, el modelo del tabernáculo y el modelo de todos sus muebles, así lo harás.
10 “Wọn yóò sì fi igi ṣittimu ṣe àpótí, ìgbọ̀nwọ́ méjì ààbọ̀ ni gígùn rẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ni fífẹ̀ rẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ni gíga rẹ̀.
“Harán un arca de madera de acacia. Su longitud será de dos codos y medio, su anchura un codo y medio, y un codo y medio su altura.
11 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà, bò ó ní inú àti ní òde, ìwọ ó sì fi wúrà gbá etí rẹ̀ yíká.
La cubrirás de oro puro. Lo cubrirás por dentro y por fuera, y harás una moldura de oro alrededor.
12 Ìwọ ó sì da òrùka wúrà mẹ́rin fún. Ìwọ ó sì fi wọ́n sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ẹsẹ̀ rẹ̀, òrùka wúrà méjì yóò wà ní ẹ̀gbẹ́ kìn-ín-ní, òrùka wúrà méjì yóò wà ní ẹgbẹ́ kejì.
Le fundirás cuatro anillos de oro y los pondrás en sus cuatro pies. Dos anillos estarán a un lado de él, y dos anillos al otro lado.
13 Ìwọ ó sì fi igi kasia ṣe ọ̀pá mẹ́rin, ìwọ ó sì fi wúrà bò wọ́n.
Harás varas de madera de acacia y las cubrirás de oro.
14 Ìwọ ó sì fi ọ̀pá náà bọ òrùka ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan àpótí ẹ̀rí náà láti fi gbé e.
Pondrás las varas en las argollas a los lados del arca para transportarla.
15 Òpó náà yóò wá nínú òrùka lára àpótí ẹ̀rí; a kò ní yọ wọ́n kúrò.
Las varas estarán en los anillos del arca. No se sacarán de ella.
16 Nígbà náà ni ìwọ yóò fi ẹ̀rí ti èmi yóò fi fún ọ sínú àpótí náà.
Pondrás en el arca el pacto que yo te daré.
17 “Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà ṣe ìtẹ́ àánú; ìgbọ̀nwọ́ méjì àti ààbọ̀ ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀ ní fífẹ̀.
Harás un propiciatorio de oro puro. Su longitud será de dos codos y medio, y su anchura de codo y medio.
18 Ìwọ ó sì ṣe kérúbù méjì láti inú wúrà tí a fi òòlù sí igun ìtẹ́ àánú náà.
Harás dos querubines de oro martillado. Los harás en los dos extremos del propiciatorio.
19 Ìwọ ó ṣe kérúbù kan sí igun kìn-ín-ní àti kérúbù kejì sí igun kejì, kí kérúbù náà jẹ́ irú kan náà ní igun méjèèjì pẹ̀lú ìbòrí wọn.
Haz un querubín en un extremo y un querubín en el otro. Harás los querubines en sus dos extremos de una sola pieza con el propiciatorio.
20 Àwọn kérúbù sì na ìyẹ́ apá wọn sókè, tí wọn yóò sì fi ìyẹ́ apá wọn ṣe ibòòji sí orí ìtẹ́ àánú. Àwọn kérúbù náà yóò kọ ojú sí ara wọn, wọn yóò máa wo ọ̀kánkán ìtẹ́.
Los querubines extenderán sus alas hacia arriba, cubriendo el propiciatorio con sus alas, con sus rostros uno hacia el otro. Los rostros de los querubines estarán hacia el propiciatorio.
21 Gbé ọmọrí orí àpótí ẹ̀rí kí o sì fi ẹ̀rí èyí tí èmí yóò fi fún ọ sínú àpótí ẹ̀rí.
Pondrás el propiciatorio encima del arca, y en el arca pondrás el pacto que yo te daré.
22 Níbẹ̀, ni òkè ìtẹ́, ní àárín kérúbù méjèèjì ti ó wà ni orí àpótí ẹ̀rí ni èmi yóò ti pàdé rẹ, ti èmi yóò sì fún ọ ní àwọn òfin mi fún àwọn ọmọ Israẹli.
Allí me reuniré contigo, y te diré desde arriba del propiciatorio, desde entre los dos querubines que están sobre el arca de la alianza, todo lo que te mando para los hijos de Israel.
23 “Fi igi kasia kan tábìlì: ìgbọ̀nwọ́ méjì ní gígùn ìgbọ̀nwọ́ kan ní fífẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀ ní gíga.
“Harás una mesa de madera de acacia. Su longitud será de dos codos, su anchura de un codo y su altura de un codo y medio.
24 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà bò ó, ìwọ ó sì ṣe ìgbátí wúrà yí i ká.
La cubrirás de oro puro y le harás una moldura de oro alrededor.
25 Ìwọ sì ṣe etí kan ní ìbú àtẹ́lẹwọ́ sí i yíká, ó sì ṣe ìgbátí wúrà yí etí rẹ̀ ká.
Harás un borde de un palmo de ancho alrededor. Harás una moldura de oro en su borde alrededor.
26 Ìwọ ó sì da òrùka wúrà mẹ́rin fún tábìlì náà, ìwọ ó sì fi òrùka kọ̀ọ̀kan sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà ní ẹsẹ̀ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin.
Le harás cuatro anillos de oro y los pondrás en las cuatro esquinas que están sobre sus cuatro pies.
27 Ní abẹ́ ìgbátí náà ni àwọn òrùka náà yóò wà fún ibi ọ̀pá láti máa fi gbé tábìlì náà.
Los anillos estarán cerca del borde, como lugares para las varas para llevar la mesa.
28 Ìwọ ó sì fi igi kasia ṣe àwọn ọ̀pá, ìwọ ó sì fi wúrà bò wọ́n, láti máa fi wọ́n gbé tábìlì náà.
Harás las varas de madera de acacia y las cubrirás de oro, para que la mesa pueda ser transportada con ellas.
29 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà ṣe àwo àti ṣíbí rẹ̀, kí o sì ṣe àwokòtò àti ago pẹ̀lú fún dída ọrẹ jáde.
Harás sus platos, sus cucharas, sus cucharones y sus tazones con los que se vierten las ofrendas. Los harás de oro puro.
30 Gbé àkàrà ìfihàn sí orí tábìlì yìí, kí ó le wà ní iwájú mi ni gbogbo ìgbà.
En la mesa pondrás siempre el pan de la presencia delante de mí.
31 “Ìwọ ó sì ojúlówó wúrà, lù ú dáradára, ṣe ọ̀pá fìtílà kan, ìsàlẹ̀ àti apá rẹ̀, kọ́ọ̀bù rẹ̀ ti ó dàbí òdòdó, ìṣọ àti ìtànná rẹ̀ yóò jẹ́ ara kan náà pẹ̀lú rẹ̀.
“Harás un candelabro de oro puro. El candelabro se hará de obra martillada. Su base, su fuste, sus copas, sus capullos y sus flores serán de una sola pieza con él.
32 Ẹ̀ka mẹ́fà ni yóò yọ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pá fìtílà: mẹ́ta ní ẹ̀gbẹ́ kìn-ín-ní mẹ́ta ni ẹ̀gbẹ́ kejì.
De sus lados saldrán seis ramas: tres brazos del candelabro salen de un lado, y tres brazos del candelabro salen del otro lado;
33 Àwo mẹ́ta ni kí a ṣe bí ìtànná almondi, tí ó ṣọ tí ó sì tanná ni yóò wà ni ẹ̀ka kan, mẹ́ta yóò sì wà ní ẹ̀ka kejì, àti bẹ́ẹ̀ fún àwọn ẹ̀ka mẹ́fẹ̀ẹ̀fà tí ó jáde lára ọ̀pá fìtílà.
tres copas hechas como flores de almendro en un brazo, un capullo y una flor; y tres copas hechas como flores de almendro en el otro brazo, un capullo y una flor, así para los seis brazos que salen del candelabro;
34 Ní ara ọ̀pá fìtílà ni àwo mẹ́rin ti a ṣe gẹ́gẹ́ bí òdòdó almondi ti ó ni ìṣọ àti ìtànná yóò wà.
y en el candelabro cuatro copas hechas como flores de almendro, sus capullos y sus flores;
35 Irúdì kan yóò sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì àkọ́kọ́ tí ó yọ lára ọ̀pá fìtílà, irúdì kejì ó sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì kejì, irúdì kẹta yóò sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì kẹta, ẹ̀ka mẹ́fà ní àpapọ̀.
y un capullo debajo de dos ramas de una pieza con él, y un capullo debajo de dos ramas de una pieza con él, y un capullo debajo de dos ramas de una pieza con él, para las seis ramas que salen del candelabro.
36 Irúdì wọn àti ẹ̀ka wọn kí ó rí bákan náà, kí gbogbo rẹ̀ kí ó jẹ́ lílù ojúlówó wúrà.
Sus capullos y sus ramas serán de una sola pieza con ella, toda ella de una sola pieza batida de oro puro.
37 “Nígbà náà ni ìwọ yóò ṣe fìtílà méje. Ìwọ yóò sì gbe ka orí rẹ̀, kí wọn kí ó lè máa ṣe ìmọ́lẹ̀ sí iwájú rẹ̀.
Harás sus lámparas de siete, y ellas encenderán sus lámparas para alumbrar el espacio que está frente a ella.
38 Àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alimagaji rẹ̀, kí ó jẹ́ kìkì wúrà.
Sus apagadores y sus tabaqueras serán de oro puro.
39 Tálẹ́ǹtì kìkì wúrà ni ó fi ṣe é, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò wọ̀nyí.
Se hará de un talento de oro puro, con todos estos accesorios.
40 Kíyèsí i, kí ìwọ kí ó ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ wọn, ti a fi hàn ọ́ ni orí òkè.
Procura hacerlos según su modelo, que te ha sido mostrado en la montaña.

< Exodus 25 >