< Exodus 25 >

1 Olúwa sì wí fún Mose pé,
Na ka korero a Ihowa ki a Mohi, ka mea,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn mú ọrẹ wá fún mi, ìwọ yóò gba ọrẹ náà fún mi ni ọwọ́ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan ti ọkàn rẹ bá fẹ́ láti fi fún mi.
Korero atu ki nga tama a Iharaira, kia maua mai e ratou he whakahere maku: me tango e koutou te whakahere maku i nga tangata katoa e hihiko noa mai ana o ratou ngakau.
3 “Wọ̀nyí ni ọrẹ ti ìwọ yóò gbà ni ọwọ́ wọn: “wúrà, fàdákà àti idẹ;
Ko te whakahere ano tenei e tangohia e koutou i a ratou; he koura, he hiriwa, he parahi,
4 aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó, ọ̀gbọ̀; irun ewúrẹ́.
Me te kakahu puru, me te papaura, me te ngangana, me te rinena pai, me te huruhuru koati,
5 Awọ àgbò tí a rẹ ní pupa àti awọ ewúrẹ́ igbó; igi kasia;
Me nga hiako hipi kua oti te whakawhero, me nga hiako pateri, me etahi rakau, he hitimi;
6 Òróró olifi fún iná títàn; òróró olóòórùn dídùn fún ìtasórí àti fún tùràrí olóòórùn dídùn;
Te hinu mo te whakamarama, nga mea kakara mo te hinu whakawahi, mo te whakakakara reka hoki,
7 àti òkúta óníkìsì àti òkúta olówó iyebíye ti a fi ṣe ọ̀ṣọ́ sí ara ẹ̀wù efodu àti ẹ̀wù ìgbàyà.
Nga kohatu onika, me nga kohatu hei whakanoho ki te epora, ki te kouma.
8 “Nígbà náà ni ìwọ yóò jẹ́ kí wọn kọ́ ibi mímọ́ fún mi. Èmi yóò sì máa gbé ní àárín wọn.
A kia hanga e ratou he wahi tapu moku; kia noho ai ahau i waenganui i a ratou.
9 Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí ti mo fihàn ọ́, nípa àpẹẹrẹ àgọ́, àti àpẹẹrẹ gbogbo ohun èlò inú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó sì ṣe é.
Kia rite a koutou e hanga ai ki nga mea katoa e whakakitea nei e ahau ki a koe, ki te tauira o te tapenakara, ki te tauira hoki o ona mea katoa.
10 “Wọn yóò sì fi igi ṣittimu ṣe àpótí, ìgbọ̀nwọ́ méjì ààbọ̀ ni gígùn rẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ni fífẹ̀ rẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ni gíga rẹ̀.
Me hanga ano hoki e ratou he aaka, ki te hitimi te rakau: kia rua nga whatianga me te hawhe te roa, kia kotahi whatianga me te hawhe te whanui, a kia kotahi whatianga me te hawhe te teitei.
11 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà, bò ó ní inú àti ní òde, ìwọ ó sì fi wúrà gbá etí rẹ̀ yíká.
A me whakakikorua e koe ki te koura parakore; me whakakikorua e koe taua mea, a roto, a waho, me hanga ano hoki e koe he niao koura a tawhio noa.
12 Ìwọ ó sì da òrùka wúrà mẹ́rin fún. Ìwọ ó sì fi wọ́n sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ẹsẹ̀ rẹ̀, òrùka wúrà méjì yóò wà ní ẹ̀gbẹ́ kìn-ín-ní, òrùka wúrà méjì yóò wà ní ẹgbẹ́ kejì.
Kia wha ano nga mowhiti koura e whakarewaia mo taua aaka, ka whakanoho ai ki nga poti e wha; kia rua mowhiti ki tetahi taha ona, kia rua mowhiti ki tetahi taha ona.
13 Ìwọ ó sì fi igi kasia ṣe ọ̀pá mẹ́rin, ìwọ ó sì fi wúrà bò wọ́n.
Me hanga ano e koe etahi rakau amo, ki te hitimi te rakau, ka whakakikorua hoki ki te koura;
14 Ìwọ ó sì fi ọ̀pá náà bọ òrùka ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan àpótí ẹ̀rí náà láti fi gbé e.
Ka kuhu ai i nga rakau amo ki roto ki nga mowhiti i nga taha o te aaka, kia ai aua mea hei maunga mo te aaka.
15 Òpó náà yóò wá nínú òrùka lára àpótí ẹ̀rí; a kò ní yọ wọ́n kúrò.
Hei nga mowhiti o te aaka nga amo mau ai; kaua e unuhia ki waho.
16 Nígbà náà ni ìwọ yóò fi ẹ̀rí ti èmi yóò fi fún ọ sínú àpótí náà.
A me hoatu e koe ki roto ki te aaka te whakaaturanga e hoatu e ahau ki a koe.
17 “Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà ṣe ìtẹ́ àánú; ìgbọ̀nwọ́ méjì àti ààbọ̀ ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀ ní fífẹ̀.
Me hanga ano e koe te taupoki ki te koura parakore: kia rua nga whatianga me te hawhe tona roa, kia kotahi hoki whatianga me te hawhe tona whanui.
18 Ìwọ ó sì ṣe kérúbù méjì láti inú wúrà tí a fi òòlù sí igun ìtẹ́ àánú náà.
Me hanga ano etahi kerupima, kia rua, he mea patu te koura e hanga ai aua mea a puta noa, mo nga pito e rua o te taupoki.
19 Ìwọ ó ṣe kérúbù kan sí igun kìn-ín-ní àti kérúbù kejì sí igun kejì, kí kérúbù náà jẹ́ irú kan náà ní igun méjèèjì pẹ̀lú ìbòrí wọn.
Me hanga hoki tetahi kerupi ki tetahi pito, me tetahi kerupi ki tetahi pito: me hono nga kerupima ki te taupoki, ki ona pito e rua.
20 Àwọn kérúbù sì na ìyẹ́ apá wọn sókè, tí wọn yóò sì fi ìyẹ́ apá wọn ṣe ibòòji sí orí ìtẹ́ àánú. Àwọn kérúbù náà yóò kọ ojú sí ara wọn, wọn yóò máa wo ọ̀kánkán ìtẹ́.
A ka roha whakarunga nga parirau o nga kerupima, me te uhi ano i te taupoki ki o raua parirau, ka anga ano o raua mata ki a raua; ka anga ki te taupoki nga mata o nga kerupima.
21 Gbé ọmọrí orí àpótí ẹ̀rí kí o sì fi ẹ̀rí èyí tí èmí yóò fi fún ọ sínú àpótí ẹ̀rí.
A me whakanoho e koe te taupoki ki runga ki te aaka; me hoatu ano ki roto ki te aaka te whakaaturanga e hoatu e ahau ki a koe.
22 Níbẹ̀, ni òkè ìtẹ́, ní àárín kérúbù méjèèjì ti ó wà ni orí àpótí ẹ̀rí ni èmi yóò ti pàdé rẹ, ti èmi yóò sì fún ọ ní àwọn òfin mi fún àwọn ọmọ Israẹli.
A ka tutaki ahau ki a koe ki reira, ka korerotia ano ki a koe i runga i te taupoki i waenganui i nga kerupima e rua, i era i runga i te aaka o te whakaaturanga, nga mea katoa e whakahau ai ahau ki a koe mo nga tama a Iharaira.
23 “Fi igi kasia kan tábìlì: ìgbọ̀nwọ́ méjì ní gígùn ìgbọ̀nwọ́ kan ní fífẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀ ní gíga.
Me hanga ano e koe tetahi tepu, ki te hitimi te rakau: kia rua nga whatianga te roa, kia kotahi whatianga te whanui, kia kotahi whatianga me te hawhe te teitei.
24 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà bò ó, ìwọ ó sì ṣe ìgbátí wúrà yí i ká.
Me whakakikorua taua mea ki te koura parakore, ka hanga ai i tetahi niao koura mona a tawhio noa.
25 Ìwọ sì ṣe etí kan ní ìbú àtẹ́lẹwọ́ sí i yíká, ó sì ṣe ìgbátí wúrà yí etí rẹ̀ ká.
Me hanga ano he awhi mo taua mea, hei te whanui ringa a tawhio noa; me hanga ano he niao koura mo tona awhi a tawhio noa.
26 Ìwọ ó sì da òrùka wúrà mẹ́rin fún tábìlì náà, ìwọ ó sì fi òrùka kọ̀ọ̀kan sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà ní ẹsẹ̀ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin.
Me hanga ano etahi mowhiti koura, kia wha, mo taua mea, ka whakanoho ai i nga mowhiti ki nga poti e wha i ona waewae e wha.
27 Ní abẹ́ ìgbátí náà ni àwọn òrùka náà yóò wà fún ibi ọ̀pá láti máa fi gbé tábìlì náà.
Hei te taha tonu ake o te awhi nga mowhiti, hei kuhunga atu mo nga amo hei maunga mo te tepu.
28 Ìwọ ó sì fi igi kasia ṣe àwọn ọ̀pá, ìwọ ó sì fi wúrà bò wọ́n, láti máa fi wọ́n gbé tábìlì náà.
He hitimi te rakau e hanga ai e koe nga amo; me whakakikorua ano ki te koura; a ka ai aua mea hei maunga mo te tepu.
29 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà ṣe àwo àti ṣíbí rẹ̀, kí o sì ṣe àwokòtò àti ago pẹ̀lú fún dída ọrẹ jáde.
Me hanga ano ona rihi, ona koko, ona kapu, me nga peihana mo nga ringihanga: me hanga ki te koura parakore.
30 Gbé àkàrà ìfihàn sí orí tábìlì yìí, kí ó le wà ní iwájú mi ni gbogbo ìgbà.
Me whakatakoto tonu te taro aroaro ki te tepu, ki toku aroaro.
31 “Ìwọ ó sì ojúlówó wúrà, lù ú dáradára, ṣe ọ̀pá fìtílà kan, ìsàlẹ̀ àti apá rẹ̀, kọ́ọ̀bù rẹ̀ ti ó dàbí òdòdó, ìṣọ àti ìtànná rẹ̀ yóò jẹ́ ara kan náà pẹ̀lú rẹ̀.
Me hanga ano te turanga rama ki te koura parakore: me patu te mahina o te turanga rama tae noa ki tona take, ki ona peka; ko ona kapu, ko ona puku, me ona puawai he kotahi me ia.
32 Ẹ̀ka mẹ́fà ni yóò yọ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pá fìtílà: mẹ́ta ní ẹ̀gbẹ́ kìn-ín-ní mẹ́ta ni ẹ̀gbẹ́ kejì.
A kia ono nga peka e puta ake i ona taha; e toru nga peka o te turanga rama i tetahi taha, e toru hoki nga peka o te turanga rama i tetahi taha:
33 Àwo mẹ́ta ni kí a ṣe bí ìtànná almondi, tí ó ṣọ tí ó sì tanná ni yóò wà ni ẹ̀ka kan, mẹ́ta yóò sì wà ní ẹ̀ka kejì, àti bẹ́ẹ̀ fún àwọn ẹ̀ka mẹ́fẹ̀ẹ̀fà tí ó jáde lára ọ̀pá fìtílà.
Kia toru nga kapu, he mea rite ki te puawai aramona, te puku, me te puawai, ki te peka kotahi; me nga kapu e toru, he mea rite ki te puawai aramona ki tetahi atu peka, te puku, me te puawai: me pera tonu i nga peka e ono e puta ake ana i te tura nga rama.
34 Ní ara ọ̀pá fìtílà ni àwo mẹ́rin ti a ṣe gẹ́gẹ́ bí òdòdó almondi ti ó ni ìṣọ àti ìtànná yóò wà.
Kia wha ia nga kapu o te turanga rama, kia rite ki te puawai aramona, te puku, me te puawai, o tetahi, o tetahi.
35 Irúdì kan yóò sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì àkọ́kọ́ tí ó yọ lára ọ̀pá fìtílà, irúdì kejì ó sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì kejì, irúdì kẹta yóò sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì kẹta, ẹ̀ka mẹ́fà ní àpapọ̀.
A e rua ona peka, kia kotahi puku o raro ake, he mea kotahi; e rua ona peka, kia kotahi puku o raro ake, he mea kotahi; e rua ona peka, kia kotahi puku o raro ake, he mea kotahi ano, o nga peka e ono e puta mai ana i te turanga rama.
36 Irúdì wọn àti ẹ̀ka wọn kí ó rí bákan náà, kí gbogbo rẹ̀ kí ó jẹ́ lílù ojúlówó wúrà.
No te mea kotahi nga puku, nga peka: ko taua mea katoa, he mea patu, kotahi tonu, he korua parakore.
37 “Nígbà náà ni ìwọ yóò ṣe fìtílà méje. Ìwọ yóò sì gbe ka orí rẹ̀, kí wọn kí ó lè máa ṣe ìmọ́lẹ̀ sí iwájú rẹ̀.
Me hanga ona rama e whitu: a me tahu ona rama, hei whakamarama i tona hangaitanga atu.
38 Àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alimagaji rẹ̀, kí ó jẹ́ kìkì wúrà.
Me koura parakore ano ona kuku me ona oko ngarahu.
39 Tálẹ́ǹtì kìkì wúrà ni ó fi ṣe é, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò wọ̀nyí.
Kia kotahi taranata koura parakore e hanga ai taua mea, me ena oko katoa.
40 Kíyèsí i, kí ìwọ kí ó ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ wọn, ti a fi hàn ọ́ ni orí òkè.
Kia tupato ano kia hanga aua mea kia rite ki te tauira i whakakitea ki a koe i te maunga.

< Exodus 25 >