< Exodus 24 >
1 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gòkè tọ Olúwa wá, ìwọ àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli. Ẹ̀yin kì ó sìn ni òkèèrè réré.
Rəbbee Mısayk'le eyhen: – Ğu, Harun, Harunun dixbı Nadav, Avihuyiy sayir İzrailybışde ağsaqqalaaşike yights'al insan Zasqa ılqeepç'ı, Zas əq'ənançecab k'yoozre.
2 Ṣùgbọ́n Mose nìkan ṣoṣo ni yóò súnmọ́ Olúwa; àwọn tókù kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí ibẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò gbọdọ̀ gòkè wá pẹ̀lú rẹ̀.”
Qiyğaler, Zasqana saccu ğu qixhe mansabı deş. Millet inyaqa ılqımeç'ecen.
3 Nígbà ti Mose lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn, gbogbo ọ̀rọ̀ àti òfin Olúwa, wọ́n wí ní ohùn kan pé, “Gbogbo ohun ti Olúwa wí ni àwa yóò ṣe.”
Mısee Rəbbee uvhuynbıyiy Mang'un g'ayda-q'aanun milletıs yuşan hı'ımee, milletıncad mang'us cuvab qele: – Şi gırgın Rəbbee uvhuyn xhinne ha'as!
4 Nígbà náà ni Mose kọ gbogbo ohun tí Olúwa sọ sílẹ̀. Ó dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mọ pẹpẹ ni ẹsẹ̀ òkè náà. Ó ṣe ọ̀wọ́n òkúta méjìlá. Èyí ti ó dúró fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
Mısee Rəbbee uvhuyn gırgın oyk'anan. Mana miç'eer çakra suğots'u suveeqa ı'lqəəne cigee q'urbanbı allya'an ciga alya'a. Qiyğale İzrailyne yits'ıq'öne nasılıs curayda-curayda mang'vee g'ayeyn dirakbı ulyozar ha'a.
5 Nígbà náà ni ó rán àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n fi ọ̀dọ́ màlúù rú ẹbọ àlàáfíà si Olúwa.
Mançile qiyğa mang'vee İzrailyne mek'vunbışisqa Rəbbis mek'vun congariy medın-medın q'urbanna allya'as ilekka.
6 Mose bu ìlàjì ẹ̀jẹ̀ ẹran sínú abọ́, ó sì fi ìlàjì tókù wọn ara pẹpẹ.
Mısee həyvanaaşike gyopts'una sura eb lyagameeqa saa'a, avxunab q'urbanbı allya'an cigalqa k'yaa'a.
7 Nígbà náà ni ó sì mú ìwé májẹ̀mú, ó sì kà á sí àwọn ènìyàn. Wọ́n dáhùn pé, “Àwa yóò ṣe gbogbo ohun tí Olúwa wí. Àwa yóò sì gbọ́rọ̀.”
Mang'vee Rəbbika mugaavilenan kitab alyaat'u, maa'ad otk'uninbı milletıs qədəqqə. Milletın eyhen: – Şi Rəbbee uvhuyne gırgınçil k'ırı gyaqqı, gırgın Mang'vee eyhəxüd ha'as.
8 Nígbà náà ni Mose gbé ẹ̀jẹ̀, ó sì wọn sí àwọn ènìyàn náà lára pé, “Èyí ni ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú tí Olúwa ti ṣe pẹ̀lú yín ni ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.”
Qiyğa Mısee lyagameena eb alyapt'ı milletılqa hooçav'u eyhen: – Haane Rəbbee şoka hav'uyne mugaavileyna eb. Mang'vee uvhuyn karbı mugaavile vob.
9 Mose àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli gòkè lọ.
Mançile qiyğa Mısa, Harun, Nadaviy Avihu, sayir yights'al İzrailyna ağsaqqal suvalqa ılqeebaç'e.
10 Wọ́n sì rí Ọlọ́run Israẹli. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀ ni ohun kan bí i pèpéle ti a fi òkúta safire ṣe wà. Èyí ti ó mọ́ nigínnigín bí àwọ̀ sánmọ̀ fúnra rẹ̀.
Maa'ar manbışik'le İzrailybışda Allah g'ece. Mang'une g'elybışik avud lagarane gıranne g'ayeyke hı'iyn, məttın xəy xhinnen sa kariyne.
11 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn àgbàgbà Israẹli wọ̀nyí; wọ́n ri Ọlọ́run, wọ́n jẹ, wọ́n sì mu.
Allahee İzrailyne ç'ak'ınbışilqa xıl g'oyt'al deş. Manbışe otxhun-ulyooğan, Allahır g'ecena.
12 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Gòkè wá sí ọ̀dọ̀ mi, kí o sì dúró níhìn-ín. Èmi yóò sì fún ọ ní wàláà òkúta pẹ̀lú òfin àti ìlànà tí mo ti kọ sílẹ̀ fún ìtọ́sọ́nà wọn.”
Rəbbee Mısayk'le eyhen: – Suvalqa Zasqa ılqeç'u, maa ulyozre. Zı vasqa, millet xət qa'asva hets'uyne g'ayebışil Zı opk'unna q'aanun, g'ayda qevles.
13 Nígbà náà ni Mose jáde lọ pẹ̀lú Joṣua arákùnrin rẹ̀. Mose lọ sí orí òkè Ọlọ́run.
Mısa Allahne suvalqa ılqeç'esva cus kumag ha'ane Yeşuayka ayk'an.
14 Ó sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ẹ dúró dè wá níhìn-ín yìí, títí àwa yóò fi tún padà tọ̀ yín wá, sì kíyèsi i, Aaroni àti Huri ń bẹ pẹ̀lú yín, bí ẹnìkan bá ni ọ̀ràn kan, kí ó tọ̀ wọ́n lọ.”
Mang'vee ağsaqqalaaşik'le eyhen: – Şi şosqa savk'alasmee inyaa ulyoozre. Haruniy Xur şoka aaxva, vuşuyiy dağamiyvaleeqa girxhu manbışisqa hak'necen.
15 Nígbà tí Mose gun orí òkè lọ, ìkùùkuu bo orí òkè náà.
Man uvhu Mısa suvalqa ılqeç'e. Mane gahıl suva buludun avqqaqqa.
16 Ògo Olúwa sì wà ní orí òkè Sinai. Ìkùùkuu bo orí òkè náà fún ọjọ́ mẹ́fà, ni ọjọ́ keje ni Olúwa kọ sí Mose láti inú ìkùùkuu náà wá.
Rəbbin Nurud Sinayne suval g'ece eyxhe. Yixhne yiğna buludun suva avqu vuxha. Yighıd'esde yiğıl Rəbbee Mısa buludeençe qoyt'al.
17 Ni ojú àwọn ọmọ Israẹli ògo Olúwa náà dàbí iná ajónirun ni orí òkè.
İzrailybışik'le Rəbbin Nur suvane q'oma, maane gırgın gyoxhxhan ha'ane yalavne ad g'ece.
18 Nígbà náà ni Mose wọ inú ìkùùkuu náà bí ó ti ń lọ ní orí òkè. Ó sì wà ni orí òkè náà ni ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.
Mısa buludeeqa k'iç'u suvalqa ılqeç'e. Mana suval yoq'ts'al yiğnayiy yoq'ts'al xəmna axva.