< Exodus 24 >

1 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gòkè tọ Olúwa wá, ìwọ àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli. Ẹ̀yin kì ó sìn ni òkèèrè réré.
Also he seide to Moises, `Stie thou to the Lord, thou, and Aaron, and Nadab, and Abyu, and seuenti eldere men of Israel; and ye schulen worschipe afer,
2 Ṣùgbọ́n Mose nìkan ṣoṣo ni yóò súnmọ́ Olúwa; àwọn tókù kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí ibẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò gbọdọ̀ gòkè wá pẹ̀lú rẹ̀.”
and Moises aloone stie to the Lord, and thei schulen not neiye, nether the puple schal stie with hym.
3 Nígbà ti Mose lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn, gbogbo ọ̀rọ̀ àti òfin Olúwa, wọ́n wí ní ohùn kan pé, “Gbogbo ohun ti Olúwa wí ni àwa yóò ṣe.”
Therfore Moises cam, and telde to the puple alle the wordis and domes of the Lord; and al the puple answeride with o vois, We schulen do alle the wordis of the Lord, whiche he spak.
4 Nígbà náà ni Mose kọ gbogbo ohun tí Olúwa sọ sílẹ̀. Ó dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mọ pẹpẹ ni ẹsẹ̀ òkè náà. Ó ṣe ọ̀wọ́n òkúta méjìlá. Èyí ti ó dúró fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
Forsothe Moises wroot alle the wordis of the Lord; and he roos eerli, and bildide an auter to the Lord at the rootis of the hil, and he bildide twelue titlis bi twelue lynagis of Israel.
5 Nígbà náà ni ó rán àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n fi ọ̀dọ́ màlúù rú ẹbọ àlàáfíà si Olúwa.
And he sente yonge men of the sones of Israel, and thei offriden brent sacrifices, and `thei offriden pesible sacrifices `to the Lord, twelue calues.
6 Mose bu ìlàjì ẹ̀jẹ̀ ẹran sínú abọ́, ó sì fi ìlàjì tókù wọn ara pẹpẹ.
And so Moises took half the part of the blood, and sente in to grete cuppis; forsothe he schedde the residue part on the auter.
7 Nígbà náà ni ó sì mú ìwé májẹ̀mú, ó sì kà á sí àwọn ènìyàn. Wọ́n dáhùn pé, “Àwa yóò ṣe gbogbo ohun tí Olúwa wí. Àwa yóò sì gbọ́rọ̀.”
And he took the book of the boond of pees, and redde, while the puple herde; whiche seiden, We schulen do alle thingis which the Lord spak, and we schulen be obedient.
8 Nígbà náà ni Mose gbé ẹ̀jẹ̀, ó sì wọn sí àwọn ènìyàn náà lára pé, “Èyí ni ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú tí Olúwa ti ṣe pẹ̀lú yín ni ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.”
Forsothe he took, and sprengide `the blood on the puple, and seide, This is the blood of the boond of pees, which the Lord couenauntide with yow on alle these wordis.
9 Mose àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli gòkè lọ.
And Moises, and Aaron, and Nadab, and Abyu, and seuenti of the eldere men of Israel stieden,
10 Wọ́n sì rí Ọlọ́run Israẹli. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀ ni ohun kan bí i pèpéle ti a fi òkúta safire ṣe wà. Èyí ti ó mọ́ nigínnigín bí àwọ̀ sánmọ̀ fúnra rẹ̀.
and seiyen God of Israel, vndur hise feet, as the werk of safire stoon, and as heuene whanne it is cleer.
11 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn àgbàgbà Israẹli wọ̀nyí; wọ́n ri Ọlọ́run, wọ́n jẹ, wọ́n sì mu.
And he sente not his hond on hem of the sones of Israel, that hadden go fer awei; and thei sien God, and eeten and drunkun.
12 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Gòkè wá sí ọ̀dọ̀ mi, kí o sì dúró níhìn-ín. Èmi yóò sì fún ọ ní wàláà òkúta pẹ̀lú òfin àti ìlànà tí mo ti kọ sílẹ̀ fún ìtọ́sọ́nà wọn.”
Forsothe the Lord seide to Moises, `Stie thou to me in to the hil, and be thou there, and Y schal yyue to thee tablis of stoon, and the lawe, and comaundementis, whiche Y haue write, that thou teche the children of Israel.
13 Nígbà náà ni Mose jáde lọ pẹ̀lú Joṣua arákùnrin rẹ̀. Mose lọ sí orí òkè Ọlọ́run.
Moises and Josue his mynystre risen, and Moises stiede in to the hil of God,
14 Ó sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ẹ dúró dè wá níhìn-ín yìí, títí àwa yóò fi tún padà tọ̀ yín wá, sì kíyèsi i, Aaroni àti Huri ń bẹ pẹ̀lú yín, bí ẹnìkan bá ni ọ̀ràn kan, kí ó tọ̀ wọ́n lọ.”
and seide to the eldere men, Abide ye here, til we turnen ayen to you; ye han Aaron and Hur with you, if ony thing of questioun is maad, ye schulen telle to hem.
15 Nígbà tí Mose gun orí òkè lọ, ìkùùkuu bo orí òkè náà.
And whanne Moises hadde stied,
16 Ògo Olúwa sì wà ní orí òkè Sinai. Ìkùùkuu bo orí òkè náà fún ọjọ́ mẹ́fà, ni ọjọ́ keje ni Olúwa kọ sí Mose láti inú ìkùùkuu náà wá.
a cloude hilide the hil, and the glorie of the Lord dwellide on Synai, and kyueride it with a cloude sixe daies; forsothe in the seuenthe dai the Lord clepide hym fro the myddis of the cloude; forsothe the licnesse of glorie of the Lord
17 Ni ojú àwọn ọmọ Israẹli ògo Olúwa náà dàbí iná ajónirun ni orí òkè.
was as fier brennynge on the cop of the hil in the siyt of the sones of Israel.
18 Nígbà náà ni Mose wọ inú ìkùùkuu náà bí ó ti ń lọ ní orí òkè. Ó sì wà ni orí òkè náà ni ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.
And Moises entride into the myddis of the cloude, and stiede in to the hil, and he was there fourti daies and fourti nyytis.

< Exodus 24 >