< Exodus 24 >

1 Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gòkè tọ Olúwa wá, ìwọ àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli. Ẹ̀yin kì ó sìn ni òkèèrè réré.
To pacoengah Mosi khaeah, Nangmah hoi Aaron, Nadab, Abihu hoi Israel kacoehta qui sarihto Angraeng khaeah angzo o tahang ah, nihcae loe ahmuen kangthla hoiah bok o nasoe.
2 Ṣùgbọ́n Mose nìkan ṣoṣo ni yóò súnmọ́ Olúwa; àwọn tókù kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí ibẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò gbọdọ̀ gòkè wá pẹ̀lú rẹ̀.”
Mosi khue ni Angraeng taengah caeh tih; kalah kaminawk loe a taengah caeh o hmah; kaminawk doeh anih hoi nawnto caeh o hmah nasoe, tiah a naa.
3 Nígbà ti Mose lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn, gbogbo ọ̀rọ̀ àti òfin Olúwa, wọ́n wí ní ohùn kan pé, “Gbogbo ohun ti Olúwa wí ni àwa yóò ṣe.”
Mosi mah caeh moe, kaminawk khaeah lokcaekhaih hoi Angraeng ih loknawk boih to thuih naah, kaminawk boih mah, Angraeng mah thuih ih lok to ka sak o boih han, tiah nawnto a thuih o.
4 Nígbà náà ni Mose kọ gbogbo ohun tí Olúwa sọ sílẹ̀. Ó dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mọ pẹpẹ ni ẹsẹ̀ òkè náà. Ó ṣe ọ̀wọ́n òkúta méjìlá. Èyí ti ó dúró fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
Angraeng mah thuih ih loknawk boih loe Mosi mah tarik; khawnbang khawnthaw ah angthawk moe, mae tlim ah hmaicam maeto a sak pacoengah, Israel acaeng hathlai hnetto angmathaih thlung hathlai hnetto a tling.
5 Nígbà náà ni ó rán àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n fi ọ̀dọ́ màlúù rú ẹbọ àlàáfíà si Olúwa.
To pacoengah anih mah Israel thendoengnawk to patoeh, nihcae mah maitaw tae to lak o moe, Angraeng khaeah hmai angbawnhaih hoi angdaeh angbawnhaih to a sak o.
6 Mose bu ìlàjì ẹ̀jẹ̀ ẹran sínú abọ́, ó sì fi ìlàjì tókù wọn ara pẹpẹ.
Mosi mah athii ahap to lak moe, boengloeng pongah suek; athii ahap lak moe, hmaicam nuiah a haeh.
7 Nígbà náà ni ó sì mú ìwé májẹ̀mú, ó sì kà á sí àwọn ènìyàn. Wọ́n dáhùn pé, “Àwa yóò ṣe gbogbo ohun tí Olúwa wí. Àwa yóò sì gbọ́rọ̀.”
Anih mah lokmaihaih cabu to lak pacoengah, kaminawk hanah kroek pae; kaminawk mah Angraeng mah thuih ih loknawk to ka sak o boih moe, lok ka tahngai o han, tiah a naa o.
8 Nígbà náà ni Mose gbé ẹ̀jẹ̀, ó sì wọn sí àwọn ènìyàn náà lára pé, “Èyí ni ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú tí Olúwa ti ṣe pẹ̀lú yín ni ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.”
To pacoengah Mosi mah athii to lak moe, kaminawk nuiah haeh pacoengah, Khenah, hae ih loknawk baktih toengah, hae loe Angraeng mah nangcae hoi sak ih lokmaihaih athii ah oh, tiah a naa.
9 Mose àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli gòkè lọ.
Mosi, Aaron, Nadab, Abihu hoi Israel kacoehta qui sarihtonawk loe caeh o tahang moe,
10 Wọ́n sì rí Ọlọ́run Israẹli. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀ ni ohun kan bí i pèpéle ti a fi òkúta safire ṣe wà. Èyí ti ó mọ́ nigínnigín bí àwọ̀ sánmọ̀ fúnra rẹ̀.
Israel Sithaw to a hnuk o; a khok atlim bangah loe sapphire thlung kanglung hoi baih het ih hmuen baktiah oh moe, kacai pin van baktiah amdueng.
11 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn àgbàgbà Israẹli wọ̀nyí; wọ́n ri Ọlọ́run, wọ́n jẹ, wọ́n sì mu.
Toe Sithaw loe Israel kacoehtanawk bangah ban payangh ai; nihcae mah Sithaw to hnuk o, a caak o moe, naek o.
12 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Gòkè wá sí ọ̀dọ̀ mi, kí o sì dúró níhìn-ín. Èmi yóò sì fún ọ ní wàláà òkúta pẹ̀lú òfin àti ìlànà tí mo ti kọ sílẹ̀ fún ìtọ́sọ́nà wọn.”
Angraeng mah Mosi khaeah, Kai khaeah mae ah angzo tahang ah loe, haeah om ah; kaminawk to na patuk hanah, thlung kangphaek nuiah ka tarik ih, lokpaekhaih hoi kaalok to kang paek han, tiah a naa.
13 Nígbà náà ni Mose jáde lọ pẹ̀lú Joṣua arákùnrin rẹ̀. Mose lọ sí orí òkè Ọlọ́run.
To pacoengah Mosi loe anih bomkung Joshua hoi nawnto amsak hoi; Mosi loe Sithaw ih mae ah dawh tahang.
14 Ó sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ẹ dúró dè wá níhìn-ín yìí, títí àwa yóò fi tún padà tọ̀ yín wá, sì kíyèsi i, Aaroni àti Huri ń bẹ pẹ̀lú yín, bí ẹnìkan bá ni ọ̀ràn kan, kí ó tọ̀ wọ́n lọ.”
Anih mah kacoehtanawk khaeah, Nangcae khae kang zo hoi let ai karoek to haeah na zing oh; khenah, Aaron hoi Hur loe nangcae hoi nawnto oh; lokthuih han tawn kami loe nihnik khaeah caeh oh, tiah a naa.
15 Nígbà tí Mose gun orí òkè lọ, ìkùùkuu bo orí òkè náà.
Mosi mae ah caeh tahang naah, mae loe tamai mah khuk khoep.
16 Ògo Olúwa sì wà ní orí òkè Sinai. Ìkùùkuu bo orí òkè náà fún ọjọ́ mẹ́fà, ni ọjọ́ keje ni Olúwa kọ sí Mose láti inú ìkùùkuu náà wá.
Angraeng lensawkhaih loe Sinai mae ah oh; ni tarukto thung tamai mah mae to khuk khoep; ni sarihto naah loe Angraeng mah Mosi to tamai thung hoiah kawk.
17 Ni ojú àwọn ọmọ Israẹli ògo Olúwa náà dàbí iná ajónirun ni orí òkè.
Angraeng lensawkhaih loe, Israel kaminawk mikhnuk ah mae nuiah kangqong hmai baktiah aang.
18 Nígbà náà ni Mose wọ inú ìkùùkuu náà bí ó ti ń lọ ní orí òkè. Ó sì wà ni orí òkè náà ni ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.
Mosi loe tamai thungah caeh moe, mae nui a phak pacoengah, to ah ni qui palito hoi qum qui palito oh.

< Exodus 24 >