< Exodus 23 >

1 “Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀. Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.
Yalƣan gǝpni yaymiƣin wǝ ya yalƣan guwaⱨliⱪ berip rǝzil adǝmgǝ yan basmiƣin.
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Topⱪa ǝgixip rǝzil ixta bolma yaki dǝwa-dǝsturlarda guwaⱨliⱪ bǝrgǝndǝ topⱪa ǝgixip ⱨǝⱪiⱪǝtni burmilima.
3 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.
Kǝmbǝƣǝl dǝwa ⱪilsa, uningƣa yan basma.
4 “Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.
Düxminingning kala ya exiki ezip ketip, sanga uqrap ⱪalsa, uni elip kelip, igisigǝ qoⱪum tapxurup bǝr.
5 Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.
Əgǝr sanga ɵq bolƣanning exiki yükni kɵtürǝlmǝy yükning astida yatⱪinini kɵrsǝng, uni yardǝmsiz taxlimay, bǝlki uningƣa yardǝmlixip exikini ⱪopuruxup berixing zɵrür.
6 “Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.
Arangdiki kǝmbǝƣǝlning dǝwasida adalǝtni burmilima.
7 Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.
Ⱨǝrⱪandaⱪ sahta ixtin ɵzüngni neri tart; bigunaⱨ adǝm bilǝn ⱨǝⱪⱪaniy adǝmni ɵltürmigin; qünki Mǝn rǝzil adǝmni ⱨǝrgiz adil dǝp aⱪlimaymǝn.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
Xuningdǝk ⱨeqⱪandaⱪ para yemǝ; qünki para kɵzi oquⱪlarni kor ⱪilip, ⱨǝⱪⱪaniylarning sɵzlirini burmilaydu.
9 “Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.
Musapir kixilǝrgǝ zulum ⱪilma; qünki ɵzünglar Misir zeminida musapir bolup turƣan bolƣaqⱪa, musapirning roⱨiy ⱨalini bilisilǝr.
10 “Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀.
Altǝ yil ɵz yeringni terip, ⱨosullirini al.
11 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.
Lekin yǝttinqi yili yǝrgǝ aram berip uni box ⱪoy; hǝlⱪingning namratliri uningdin yiƣip yesun, ulardin axⱪinini janggaldiki ⱨaywanlar yesun; xundaⱪla üzümzarliⱪing bilǝn zǝytunzarliⱪingnimu xundaⱪ ⱪilƣin.
12 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.
Altǝ kün iqidǝ ɵz ixingni ada ⱪilip, yǝttinqi küni aram elixing zɵrür. Buning bilǝn kala-exǝkliring aram tapidu, dedikingning oƣli bilǝn musapir kiximu ⱨarduⱪini qiⱪiridu.
13 “Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.
Mǝn sanga eytⱪinimning ⱨǝmmisini kɵngül bɵlüp ada ⱪil; baxⱪa ilaⱨlarning namini tilingƣa alma; bular ⱨǝtta aƣzingƣimu qiⱪmisun.
14 “Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.
Ⱨǝr yilda üq ⱪetim mening üqün ⱨeyt ɵtküzgin.
15 “Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.
Aldi bilǝn «petir nan ⱨeyti»ni ɵtküz; sanga ǝmr ⱪilƣinimdǝk Abib eyidiki bekitilgǝn künlǝrdǝ yǝttǝ kün petir nan yegin; qünki xu ayda sǝn Misirdin qiⱪⱪaniding. Xu ⱨeytta ⱨeqkixi aldimƣa ⱪuruⱪ ⱪol kǝlmisun.
16 “Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ. “Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.
Sǝn ǝjir ⱪilip teriƣan etizdiki ziraitingning tunji ⱨosulini orƣanda «orma ⱨeyti»ni ɵtküz; xundaⱪla sǝn ǝjir singdürüp yǝrdin ahirⱪi ⱨosul-mǝⱨsulatliringni yil ahirida yiƣⱪanda «ⱨosul yiƣix ⱨeyti»ni ɵtküz.
17 “Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.
Yilda üq ⱪetim ǝrkǝkliringning ⱨǝmmisi Rǝb Pǝrwǝrdigarning ⱨuzuriƣa ⱨazir bolsun.
18 “Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà. “Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.
Sǝn manga atalƣan ⱪurbanliⱪning ⱪenini hemirturuq selinƣan nan bilǝn sunmiƣin; ⱨeyt ⱪurbanliⱪining yeƣini bolsa keqiqǝ ⱪondurup ǝtigiqigǝ saⱪlima.
19 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.
Zeminingdiki dǝslǝpki ⱨosulning ǝng yahxsini Pǝrwǝrdigar Hudayingning ɵyigǝ elip kǝl. Oƣlaⱪni anisining sütidǝ ⱪaynitip pixurma.
20 “Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún.
Mana, Mǝn bir Pǝrixtini yolda seni ⱪoƣdap, Mǝn sanga tǝyyarliƣan yǝrgǝ elip barsun dǝp, aldingda yürüxkǝ ǝwǝtimǝn.
21 Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀.
Sǝn uning aldida ɵzünggǝ agaⱨ bol, uning awaziƣa ⱪulaⱪ sal. Uning zitiƣa tǝgmǝ; bolmisa, u itaǝtsizlikliringni kǝqürmǝydu; qünki Mening namim uningdidur.
22 Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín.
Lekin ǝgǝr sǝn uning awaziƣa ⱪulaⱪ selip, Mening barliⱪ buyruƣanlirimƣa ǝmǝl ⱪilsang, Mǝn düxmǝnliringgǝ düxmǝn, küxǝndiliringgǝ küxǝndǝ bolimǝn.
23 Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò.
Qünki Mening Pǝrixtǝm aldingda yürüp, seni Amoriy, Ⱨittiy, Pǝrizziy, Ⱪanaaniy, Ⱨiwiy wǝ Yǝbusiylarning zeminiƣa baxlap kiridu; Mǝn ularni yoⱪitimǝn.
24 Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú.
Sǝn ularning ilaⱨliriƣa bax urup ibadǝt ⱪilma wǝ yaki ular ⱪilƣandǝk ⱪilma; bǝlki ularning [butlirini] üzül-kesil qeⱪiwǝt, but tüwrüklirini üzül-kesil kukum-talƣan ⱪiliwǝt;
25 Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ.
Lekin Hudayinglar Pǝrwǝrdigarning ibaditidǝ bolunglar. Xundaⱪ ⱪilsanglar U nan bilǝn süyünglarni bǝrikǝtlǝydu; Mǝn barliⱪ kesǝllikni aranglardin qiⱪirip taxlaymǝn.
26 Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.
Buning bilǝn zeminingda boyidin ajrap ketidiƣan yaki tuƣmas ⱨeqbir ayal yaki qarpay bolmaydu; ɵmrüngning künlirini toluⱪ ⱪilimǝn.
27 “Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ.
Mǝn sening aldingda wǝⱨimimni ǝwǝtimǝn, ⱪaysi taipigǝ yeⱪinlaxsang xularni parakǝndǝ ⱪilimǝn; xuning bilǝn ⱨǝmmǝ düxmǝnliringni kǝynigǝ yandurup ⱪaqurimǝn.
28 Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ.
Ⱨiwiylar, Ⱪanaaniylar wǝ Ⱨittiylarni aldingdin ⱪoƣlap qiⱪiriwetixkǝ seriⱪ ⱨǝrilǝrni aldingda yürüxkǝ ǝwǝtimǝn.
29 Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ.
Əmma zeminning Harabilixip, dalada wǝⱨxiy ⱨaywanlar awup sanga hǝwp bolup ⱪalmasliⱪi üqün, xu ǝllǝrni aldingdin bir yilƣiqǝ ⱨǝydiwǝtmǝymǝn,
30 Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.
Bǝlki sǝn awup, zeminni [pütünlǝy] miras ⱪilip bolƣuqǝ, az-azdin ⱨǝydǝp turimǝn.
31 “Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun Pupa títí dé òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate, Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ.
Sening zeminingning qegrilirini Ⱪizil Dengizdin tartip Filistiylǝrning dengiziƣiqǝ, xuningdǝk qɵldin tartip [Əfrat] dǝryasiƣiqǝ bekitimǝn; qünki zeminda turuwatⱪanlarni ⱨǝydiwetip yerini igilixing üqün, ularni ⱪolungƣa tapxurimǝn.
32 Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn.
Sǝn ular bilǝn wǝ yaki ilaⱨliri bilǝn ⱨeqⱪandaⱪ bir ǝⱨdǝ tüzmǝ.
33 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”
Ularning seni aldimda gunaⱨⱪa patⱪuzmasliⱪi üqün ularni zeminingda ⱪǝt’iy turƣuzma. Qünki mubada sǝn ularning ilaⱨlirining ibaditidǝ bolsang, bu ix sanga tuzaⱪ bolidu.

< Exodus 23 >