< Exodus 23 >

1 “Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀. Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.
“Ungahambi ukhuluma izindaba zamanga. Ungahlanganyeli lomuntu omubi ngoba ngufakazi olomona.
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Ungenzi okubi ulandela inengi labantu. Nxa ufakaza emthethwandaba, ungaphenduleli iqiniso ngokuvumelana labanengi,
3 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.
njalo ungazweli umuntu ecaleni ngoba engumyanga.
4 “Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.
Ungahlangana lenkomo kumbe ubabhemi wesitha sakho elahlekile, mnqande umbuyisele kumnikazi.
5 Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.
Nxa ufica ubabhemi womuntu okuzondayo ewiswe ngumthwalo, ungamtshiyi, umncedise umvuse.
6 “Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.
Ahlulela kuhle abayanga bakini emacaleni.
7 Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.
Ungabungeni ubufakazi bamanga, njalo ungabulali muntu ongelacala loba oqotho ngoba kangiyi kumyekela olecala.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
Lingavumi ukufunjathiswa ngoba ukufunjathiswa kufiphaza ababonayo besebeguqula amazwi omuntu omsulwa.
9 “Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.
Ungancindezeli owezizweni, lina ngokwenu liyakwazi ukuthi kunjani ukuba ngabezizweni, njengoba lalingabezizweni eGibhithe.”
10 “Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀.
“Okweminyaka eyisithupha lizalima amasimu enu livune amabele,
11 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.
kodwa kuzakuthi ngomnyaka wesikhombisa liyekele amasimu enu alaluke engalinywanga. Ngakho abangabayanga phakathi kwenu bazazuza ukudla kuwo, kuthi lezinyamazana zeganga zidle okuseleyo. Lizakwenza njalo okufananayo ngezivini zenu kanye lezihlahla zenu zama-oliva.
12 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.
Uzakwenza imisebenzi yakho okwensuku eziyisithupha, kodwa ngosuku lwesikhombisa ungasebenzi, ukuze inkabi yakho lobabhemi wakho kuphumule, kuthi isigqili esazalelwa endlini yakho kanye lowezizweni baphumule.
13 “Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.
Qaphelisisani lenze konke engilitshela khona. Lingamemezi amabizo abanye onkulunkulu; kawangezwakali ephuma ezindebeni zenu.”
14 “Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.
“Kathathu ngomnyaka kufanele lingithakazelele umkhosi.
15 “Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.
Lizathakazelela uMkhosi weSinkwa esingelaMvubelo; okwensuku eziyisikhombisa dlanini isinkwa esingelamvubelo, njengokulilaya kwami. Kwenzeni lokhu ngesikhathi esimisiweyo senyanga ka-Avivi, ngoba ngaleyonyanga yikho elaphuma khona eGibhithe. Kakungabi lamuntu ozakuma phambi kwami engaphathanga lutho.
16 “Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ. “Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.
Lithakazelele uMkhosi wokuVuna lokolibo kwenu ezilimweni zenu zemasimini. Lithakazelele uMkhosi wokuButhelela nxa selibutha izilimo zenu emasimini.
17 “Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.
Kathathu ngomnyaka amadoda wonke kufanele ayebonakala phambi kukaThixo Wobukhosi.
18 “Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà. “Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.
Linganikeli igazi lomhlatshelo kimi ndawonye laloba yini elemvubelo. Amahwahwa eminikelo yemikhosi yami akumelanga agcinwe kuze kuse.
19 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.
Lethani okolibo kwenu okuhle kakhulu endlini kaThixo uNkulunkulu wenu. Lingapheki izinyane lembuzi ngochago lukanina.”
20 “Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún.
“Khangelani, sengithumela ingilosi phambi kwenu ukuze ilivikele endleleni yenu njalo ize ilifikise endaweni engililungisele yona.
21 Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀.
Liyinanzelele ingilosi yami njalo lilalele ekutshoyo. Lingayihlamukeli ngoba kayizukulithethelela nxa lingayihlamukela, njengoba iBizo lami likuyo.
22 Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín.
Nxa lingalalelisisa ekutshoyo njalo lenze konke engikutshoyo, ngizakuba yisitha sezitha zenu njalo ngizamelana lalabo abamisana lani.
23 Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò.
Ingilosi yami izahamba phambi kwenu ize ilingenise elizweni lama-Amori, lamaHithi, lamaPherizi, lamaKhenani lamaHivi kanye lamaJebusi njalo ngizababhubhisa.
24 Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú.
Lingabakhothameli onkulunkulu babo, lingabakhonzi njalo lingalandeli imikhuba yabo. Kufanele libhidlize onkulunkulu babo njalo lidilize amatshe abo abawakhonzayo.
25 Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ.
Mkhonzeni uThixo uNkulunkulu wenu, kuzakuthi isibusiso sakhe sibe phezu kokudla laphezu kwamanzi enu. Ngizasusa imikhuhlane phakathi kwenu,
26 Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.
njalo kakho ozaswela loba abe yinyumba ezweni lenu. Ngizaphelelisa insuku zenu.
27 “Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ.
Ngizathumela uchuku lwami phambi kwenu njalo ngisanganise zonke izizwe elizahlangana lazo. Ngizakwenza zonke izitha zenu zifulathele zilibalekele.
28 Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ.
Ngizathumela olonyovu phambi kwenu ukuze basuse amaHivi, amaKhenani kanye lamaHithi endleleni yenu.
29 Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ.
Kodwa angiyikubasusa ngomnyaka munye, ngoba ilizwe lingasala lingasela muntu besekusithi izinyamazana zeganga zande zilikhulele.
30 Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.
Ngizabasusa kancanekancane phambi kwenu, lani lize lande lenelise ukuthatha ilizwe.
31 “Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun Pupa títí dé òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate, Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ.
Ngizabeka imingcele kusukela oLwandle oluBomvu kusiya oLwandle lwamaFilistiya, njalo kusuka enkangala kusiya emfuleni uYufrathe. Ngakho abantu abahlala kulelolizwe ngizabanikela ezandleni zenu ukuze libadudule.
32 Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn.
Lingenzi isivumelwano labo loba labonkulunkulu babo.
33 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”
Kabangahlali lani ezweni lenu, funa balenze lingonele, ngoba ukukhonza kwabo onkulunkulu babo kuzakuba yisifu kini.”

< Exodus 23 >