< Exodus 23 >

1 “Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀. Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.
Kei puaki i a koe te korero tito noa: kei totoro tahi tou ringa me te tangata kino, kei meinga hei kaiwhakaatu teka.
2 “Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Kei whai tahi me te tokomaha ki te kino; kaua ano hoki e hamumu i te totohenga, hei mea kia riro ai i ta te tokomaha, hei whakapeau ke i te tika:
3 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.
Kaua ano e whakanuia te rawakore, ina tohe ia.
4 “Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.
Ki te tutaki koe ki te kau a tou hoariri, ki tana kaihe ranei, e atiti noa ana, me ata whakahoki e koe ki a ia.
5 Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.
Ki te kite koe i te kaihe a tou hoariri e takoto ana i raro i tana pikaunga, a ka ngakaukore koe ki te whakaara, me ata whakaara tahi e korua.
6 “Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.
Kei whakapeaua ketia e koe te whakawa mo tou tangata rawakore, ina tohe ia.
7 Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.
Kia matara koe i te teka; kaua ano e whakamatea te tangata harakore raua ko te tangata tika: e kore hoki ahau e whakatika i ta te tangata hara.
8 “Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
Kaua ano e tango i te utu whakapati: he mea whakamatapo hoki te utu whakapati i te kanohi kite, he mea whakaparori ke hoki i nga kupu a te hunga tika.
9 “Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.
Kaua ano e tukinotia te manene; e mohio ana hoki koutou ki te ngakau o te manene; he manene hoki koutou i mua, i te whenua o Ihipa.
10 “Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀.
Kia ono hoki nga tau e rui ai koe i tou oneone, e kohikohi ai hoki i ona hua:
11 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.
I te whitu ia me waiho kia takoto kau ana, kia pariri, a ka kai nga tangata rawakore o tou iwi; a ma nga kirehe o te parae a ratou toenga e kai. Kia pena ano koe ki tau mara waina, ki tau mara oriwa.
12 “Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.
E ono nga ra e mahi ai koe i au mahi, a i te whitu ka okioki: kia okioki ai tau kau, me tau kaihe, kia whai taanga manawa ai hoki te tama a tau pononga wahine me te manene.
13 “Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.
Kia tupato ano ki nga mea katoa kua korerotia nei e ahau ki a koutou: kaua hoki e whakahuatia te ingoa o nga atua ke, kei rangona hoki ki tou mangai.
14 “Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.
E toru nga wa o te tau e tuku hakari ai koe ki ahau.
15 “Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.
Kia mau ki te hakari o te taro rewenakore: e whitu nga ra e kai ai koe i te taro rewenakore, e pera ai me taku i whakahau ai ki a koe, i te wa ano i whakaritea o te marama, o Apipi; no reira hoki koe i haere mai ai i Ihipa: kaua ano hoki tetahi e puta kau mai ki toku aroaro;
16 “Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ. “Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.
Ki te hakari o te kotinga, o te matamua o au mahi, i ruia e koe ki te mara: ki te hakari o te kohikohinga i te mutunga o te tau, ina oti te kohikohi mai e koe au mahi i te mara.
17 “Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.
E toru nga wa o te tau e kitea ai ou tane katoa ki te aroaro o te Ariki, o Ihowa.
18 “Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà. “Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.
Kaua e whakaherea tahitia me te taro rewena te toto o taku patunga tapu; kei toe ano hoki ki te ata te ngako o taku hakari.
19 “Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.
Me kawe e koe ki te whare o Ihowa, o tou Atua nga mea mataati o nga matamua o tou oneone. Kaua e kohuatia te kuao koati ki te waiu o tona whaea.
20 “Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún.
Nana, ka tonoa nei e ahau he anahera ki mua i a koe, hei tiaki i a koe i te ara, hei kawe hoki i a koe ki te wahi i whakaritea e ahau.
21 Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀.
Kia tupato ki a ia, whakarongo hoki ki tona reo, kaua e whakapataritari ki a ia; no te mea e kore ia e whakarere noa iho i to koutou hara: kei a ia nei hoki toku ingoa.
22 Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín.
Ki te ata whakarongo i a koe ki tona reo, ki te mea hoki i nga mea katoa e korero ai ahau; na, ko ahau hei hoariri mo ou hoariri, hei hoa whawhai hoki ki ou hoa whawhai.
23 Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò.
Ka haere hoki taku anahera ki mua i a koe, hei kawe i a koe ki nga Amori, ki nga Hiti, ki nga Perihi, ki nga Kanaani, ki nga Hiwi, ki nga Iepuhi: a ka huna ratou e ahau.
24 Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú.
Kei koropiko koe ki o ratou atua, kei mahi hoki ki a ratou, kei rite hoki au mahi ki a ratou mahi: engari me turaki rawa e koe, me wawahi rawa ano hoki a ratou whakapakoko.
25 Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ.
A me mahi koutou ki a Ihowa, ki to koutou Atua, a ka manaakitia e ia tau taro, me tou wai; ka whakakorea atu ano hoki e ahau te mate i roto i a koe.
26 Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.
E kore tetahi mea e whanau whakatahe, e pakoko ranei, i tou whenua: ka ata tutuki ano i ahau te maha o ou ra.
27 “Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ.
Ka tukua atu e ahau taku wehi ki mua i a koe, a ka whakamatea nga iwi katoa e haere atu nei koe ki a ratou, ka meinga ano hoki e ahau kia tahuri nga tuara o ou hoariri katoa ki a koe.
28 Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ.
Ka unga ano e ahau te horonete ki mua i a koe, mana e pei nga Hiwi, nga Kanaani, me nga Hiti i tou aroaro.
29 Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ.
E kore ratou e peia e ahau i tou aroaro i te tau kotahi; kei ururuatia te whenua, a ka nui rawa i a koe te kirehe o te parae.
30 Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.
Ka peia rikirikitia atu ratou e ahau i tou aroaro, kia hua ra ano koe, kia riro ra ano hoki te whenua i a koe.
31 “Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun Pupa títí dé òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate, Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ.
A ka whakatakotoria e ahau tou rohe ki te Moana Whero a tae noa ki te Moana o nga Pirihitini, ki te koraha hoki a tae noa ki te awa: ka tukua atu nei hoki e ahau ki o koutou ringa nga tangata o te whenua, a ka peia ratou e koe i tou aroaro.
32 Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn.
Kaua e whakarite kawenata ki a ratou, ki o ratou atua ranei.
33 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”
Kaua ratou e noho ki tou whenua, kei mea ratou i a koe kia hara ki ahau: ta te mea, ki te mahi koe ki o ratou atua, ka ai tena hei rore mou.

< Exodus 23 >