< Exodus 21 >

1 “Wọ̀nyí ni àwọn òfin tí ìwọ yóò gbé sí iwájú wọn.
“Maya nĩmo mawatho marĩa ũkũhe andũ a Isiraeli:
2 “Bí ìwọ bá yá ọkùnrin Heberu ní ìwẹ̀fà, òun yóò sìn ọ́ fún ọdún mẹ́fà. Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, òun yóò lọ ni òmìnira láìsan ohunkóhun padà.
“Ũngĩgũra Mũhibirania arĩ ndungata, agaakũrutĩra wĩra mĩaka ĩtandatũ. No mwaka wa mũgwanja, nĩũkamũrekereria athiĩ, na ndagakũrĩha kĩndũ.
3 Bí ó bá wá ní òun nìkan, òun nìkan náà ni yóò padà lọ ní òmìnira; ṣùgbọ́n tí ó bá mú ìyàwó wá, ó ní láti mú ìyàwó rẹ̀ padà lọ.
Angĩgooka arĩ wiki, akaarekererio athiĩ arĩ o wiki; no angĩgooka arĩ na mũtumia, makaarekererio mathiĩ marĩ hamwe.
4 Bí olówó rẹ̀ bá fún un ní aya, tí aya náà sì bímọ ọkùnrin àti obìnrin, aya àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ́ ti olówó rẹ̀, yóò sì lọ ní òmìnira ní òun nìkan.
Mwathi wa ndungata ĩyo angĩmĩhe mũtumia nake mũtumia ũcio amũciarĩre ciana cia aanake na airĩtu, mũtumia ũcio na ciana ciake magaatuĩka a mwathi ũcio wake, na no ndungata ĩyo ya mũndũ mũrũme ĩkaarekererio ĩthiĩ.
5 “Bí ẹrú náà bá sì wí ní gbangba pé, mo fẹ́ràn olúwa mi, ìyàwó mi àti àwọn ọmọ, èmi kò sì fẹ́ ẹ́ gba òmìnira mọ́,
“No ndungata ĩyo ĩngĩkaaria, ĩmwĩre atĩrĩ, ‘Nĩnyendete mwathi wakwa, na mũtumia wakwa na ciana na ndikwenda kũrekererio thiĩ,’
6 nígbà náà ni olúwa rẹ̀ yóò mu wá sí iwájú ìdájọ́. Òun yóò sì mú un lọ sí ẹnu-ọ̀nà tàbí lọ sí ibi ọ̀wọ̀n, yóò sì fi ìlu lu etí rẹ̀, òun yóò sì máa sin olówó rẹ̀ títí ayé.
hĩndĩ ĩyo mwathi wa ndungata ĩyo nĩakamĩtwara mbere ya atuithania ciira. Akaamĩtwara mũrango-inĩ, kana hingĩro-inĩ ya mũrango, na amĩtũre gũtũ na mũkuha. Nayo ndungata ĩyo ĩgaatuĩka ya mwathi ũcio matukũ ma muoyo wayo wothe.
7 “Bí ọkùnrin kan bá ta ọmọbìnrin rẹ̀ bí ìwẹ̀fà, ọmọbìnrin yìí kò ní gba òmìnira bí i ti ọmọkùnrin.
“Mũndũ angĩendia mwarĩ agatuĩke ndungata, ndĩkarekererio ĩthiĩ ta ũrĩa ndungata cia arũme ciĩkagwo.
8 Bí òun kò bá sì tẹ́ olówó rẹ̀ lọ́rùn, ẹni tí ó fẹ́ ẹ fún ara rẹ̀, yóò jẹ́ kí wọn ó rà á padà, òun kò ní ẹ̀tọ́ láti tà á bí ẹrú fún àjèjì, nítorí pé òun ni kò ṣe ojúṣe rẹ̀ pẹ̀lú ìwẹ̀fà náà.
Ĩngĩaga gũkenia mwathi ũrĩa wamĩthuurĩte, no nginya etĩkĩre ndungata ĩyo ĩkũũrwo. Ndarĩ na kĩhooto gĩa kwendia ndungata ĩyo kũrĩ ageni, tondũ nĩagĩte kwĩhokeka harĩ yo.
9 Bí ó bá fẹ́ ẹ fún ọmọkùnrin rẹ̀, kò ní máa lò ó bí ìwẹ̀fà mọ́, ṣùgbọ́n yóò máa ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀ obìnrin.
Angĩmĩũrĩria mũriũ, no nginya amĩtue ta ĩrĩ mwarĩ wake mwene.
10 Bí ó bá fẹ́ obìnrin mìíràn, kò gbọdọ̀ kùnà ojúṣe rẹ̀ nípa fífún un ní oúnjẹ àti aṣọ, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ kùnà ojúṣe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọkọ sí aya.
Mũriũ angĩhikia mũtumia ũngĩ, ndakaime ũrĩa wa mbere irio na nguo, na ndakamũime kĩhooto gĩake ta mũtumia wake.
11 Bí ó bá kùnà láti ṣe àwọn nǹkan mẹ́ta wọ̀nyí fún un, òun yóò lọ ní òmìnira láìsan owó kankan padà.
Angĩaga kũmũhingĩria maũndũ maya matatũ-rĩ, akĩrekererio athiĩ, gũtarĩ na mbeeca ikũrĩhwo.
12 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá lu arákùnrin rẹ̀ pa, pípa ni a ó pa á.
“Mũndũ ũrĩa ũngĩgũtha mũndũ amũũrage, ti-itherũ o nake no akooragwo.
13 Ṣùgbọ́n bí kò bá mọ̀ ọ́n mọ̀ pa á, tí ó bá jẹ́ àmúwá Ọlọ́run ni, òun yóò lọ sí ibi tí èmi yóò yàn fún un.
No rĩrĩ, angĩkorwo ekĩte ũguo atekwenda-rĩ, no gũtuĩke nĩ Ngai ũtũmĩte ũndũ ũcio wĩkĩke, nake mũndũ ũcio nĩakoorĩra kũndũ kũrĩa ngaathuura.
14 Ṣùgbọ́n tí ó bá mú arákùnrin rẹ̀, tí ó sì fi ẹ̀tàn pa á. Ẹ mú un kúrò ní iwájú pẹpẹ mi kí ẹ sì pa á.
No mũndũ angĩtũmĩra mawara na oorage mũndũ ũrĩa ũngĩ akĩendaga-rĩ, mweheriei kĩgongona-inĩ gĩakwa, na mũmũũrage.
15 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa baba tàbí ìyá rẹ̀, pípa ni a ó pa á.
“Mũndũ ũrĩa ũngĩtharĩkĩra ithe kana nyina no nginya ooragwo.
16 “Ẹnikẹ́ni ti ó bá jí ènìyàn gbé, tí ó sì tà á tàbí tí ó fi pamọ́, pípa ni a ó pa á.
“Mũndũ ũngĩiya mũndũ ũngĩ na hinya akamwendie, kana o na anyiitwo arĩ nake atanamwendia-rĩ, no nginya ooragwo.
17 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀, pípa ni a ó pa á.
“Mũndũ ũrĩa ũngĩruma ithe kana nyina no nginya ooragwo.
18 “Bí àwọn ọkùnrin méjì bá ń jà, ti ọ̀kan sọ òkúta tàbí fi ìkùùkuu lu ẹnìkejì rẹ̀, tí ó sì pa á lára, ti irú ìpalára bẹ́ẹ̀ mu kí ó wà lórí ìdùbúlẹ̀ àìsàn.
“Andũ mangĩũgitana na ũmwe aringe ũrĩa ũngĩ na ihiga kana na ngundi na aage gũkua, no akome ũrĩrĩ kwa ihinda-rĩ,
19 Ẹni tó lu ẹnìkejì rẹ̀ kò ní ní ẹ̀bi, níwọ̀n ìgbà ti ẹni tí a lù bá ti lè dìde, tí ó sì lé è fi ọ̀pá ìtìlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ rìn káàkiri. Ẹni náà ni láti san owó ti ó fi tọ́jú ara rẹ̀ padà fún un, lẹ́yìn ìgbà tí ara rẹ̀ bá ti yá tan pátápátá.
ũcio mũringani ndagacookererwo nĩ mahĩtia angĩkorwo ũrĩa waringĩtwo nĩakehota na etware nja na mũtirima wake. No rĩrĩ, no nginya arĩhe mahinda ma mũndũ ũcio mũtihie marĩa morĩte na one atĩ nĩahona biũ.
20 “Bí ọkùnrin kan bá fi ọ̀pá lu ẹrúkùnrin tàbí ẹrúbìnrin rẹ̀, ti ẹrú náà sì kú lójú ẹsẹ̀, a ó fi ìyà jẹ ẹ́.
“Mũndũ angĩhũũra ngombo yake ya mũndũ mũrũme kana ya mũndũ-wa-nja na rũthanju, nayo ngombo ĩyo ĩkue nĩ ihũũra rĩu-rĩ, no nginya aherithio,
21 Ṣùgbọ́n a kò ní fi ìyà jẹ ẹ́, ti ẹrú náà bá yè, tí ó dìde lẹ́yìn ọjọ́ kan tàbí méjì, nítorí ẹrú náà jẹ́ dúkìá rẹ̀.
no ndangĩherithio ngombo ĩyo ĩngĩarahũka thuutha wa mũthenya ũmwe kana ĩĩrĩ, tondũ ngombo ĩyo nĩ kĩndũ gĩake.
22 “Bí àwọn ènìyàn ti ń jà bá pa aboyún lára, tí aboyún náà bá bímọ láìpé ọjọ́, ṣùgbọ́n tí kò sí aburú mìíràn mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, ẹni tí ó fa ìpalára yìí yóò san iyekíye tí ọkọ aboyún náà bá béèrè fún, bí ilé ẹjọ́ bá ṣe gbà láààyè gẹ́gẹ́ bí owó ìtánràn.
“Andũ mangĩkorwo makĩrũa, maringe mũtumia ũrĩ nda, ahune no ndagĩe na thĩĩna ũngĩ-rĩ, ũrĩa ũmũringĩte nĩakarĩha kĩrĩa gĩothe mũthuuri wa mũtumia ũcio ageetia, igooti rĩetĩkĩria.
23 Ṣùgbọ́n bí ìpalára náà bá yọrí sí ikú aboyún náà, pípa ni a ó pa ẹni ti ó fa ikú aboyún náà.
No mũtumia ũcio angĩtihio ũũru, muoyo nĩũrĩhagio na muoyo, na
24 Ojú fún ojú, eyín fún eyín, ọwọ́ fún ọwọ́, ẹsẹ̀ fún ẹsẹ̀,
riitho rĩrĩhagio na riitho, na igego rĩrĩhagio na igego, na guoko kũrĩhagio na guoko, na kũgũrũ kũrĩhagio na kũgũrũ, na
25 ìjóná fún ìjóná, ọgbẹ́ fún ọgbẹ́, ìnà fún ìnà.
ihĩa rĩrĩhagio na ihĩa, na itihia rĩrĩhagio na itihia, naruo rũhara rũrĩhagio na rũhara.
26 “Bí ọkùnrin kan bá lu ẹrúkùnrin tàbí ẹrúbìnrin rẹ̀ ní ojú, ti ojú náà sì fọ́, ó ni láti jẹ́ kí ẹrú náà lọ ní òmìnira fún ìtánràn ojú rẹ̀ ti ó fọ́.
“Mũndũ angĩgũtha ndungata ya mũndũ mũrũme kana ya mũndũ-wa-nja riitho narĩo rĩthũke-rĩ, no nginya akaarekereria ndungata ĩyo ĩĩthiĩre, ũndũ ũcio ũtuĩke nĩguo irĩhi rĩa riitho.
27 Bí ó bá sì lu ẹrúkùnrin tàbí ẹrúbìnrin rẹ̀ ti eyín rẹ̀ fi ká, ó ni láti jẹ́ kí ó lọ ní òmìnira ni ìtánràn fún eyín rẹ̀ tí ó ká.
Na angĩkũũra igego rĩa ndungata ya mũndũ mũrũme kana ya mũndũ-wa-nja, no nginya arekererie ndungata ĩyo ĩĩthiĩre, ũndũ ũcio ũtuĩke nĩguo irĩhi rĩa igego.
28 “Bí akọ màlúù bá kan ọkùnrin tàbí obìnrin kan pa, a ó sọ akọ màlúù náà ní òkúta pa, a kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀. Ṣùgbọ́n a kò ní dá ẹni tí ó ni akọ màlúù náà lẹ́bi, ọrùn oní akọ màlúù náà yóò sì mọ́.
“Ndegwa ĩngĩtheeca mũndũ mũrũme kana mũndũ-wa-nja na rũhĩa akue, ndegwa ĩyo no nginya ĩhũũrwo na mahiga nginya ĩkue, na nyama ciayo itikarĩĩo. No mwene ndegwa ndangĩũrio.
29 Ṣùgbọ́n tí ó bá ti di ìgbà gbogbo ti akọ màlúù náà ti máa ń kan ènìyàn, tí a sì ti ń kìlọ̀ fún olówó rẹ̀, ti olówó rẹ̀ kò sì mú un so, tí ó bá kan ọkùnrin tàbí obìnrin pa, a ó sọ akọ màlúù náà ní òkúta pa, a ó sì pa olówó rẹ̀ pẹ̀lú.
No rĩrĩ, angĩkorwo ndegwa ĩyo nĩĩmenyerete gũtheeca andũ na rũhĩa, na mwene nĩamenyithĩtio ũhoro ũcio nake akaaga kũmĩhingĩra, nayo ĩcooke yũrage mũndũ mũrũme kana mũndũ-wa-nja-rĩ, ndegwa ĩyo no nginya ĩhũũrwo na mahiga ĩkue, na mwene o nake no nginya ooragwo.
30 Bí àwọn ará ilé ẹni tí ó kú bá béèrè fún owó ìtánràn, yóò san iye owó tí wọ́n bá ní kí ó san fún owó ìtánràn láti fi ra ẹ̀mí ara rẹ̀ padà.
Na rĩrĩ, angĩtuĩka nĩ gwĩtio irĩhi-rĩ, no akũũre muoyo wake na kũrĩha kĩrĩa gĩothe angĩĩtio.
31 Bí akọ màlúù bá kan ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin pa, a ó ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ti là á kalẹ̀.
Watho ũyũ noguo ũrũgamĩrĩire ndegwa ĩngĩtheeca mwanake kana mũirĩtu wa mũndũ na rũhĩa.
32 Bí akọ màlúù bá kan ẹrúkùnrin tàbí ẹrúbìnrin pa, olówó rẹ̀ yóò san ọgbọ̀n ṣékélì fàdákà fún ẹni tó ni ẹrú, a ó sì sọ akọ màlúù náà ni òkúta pa.
Ndegwa ĩngĩtheeca ngombo ya mũndũ mũrũme kana mũndũ-wa-nja, mwene no nginya arĩhe cekeri mĩrongo ĩtatũ cia betha kũrĩ mwathi wa ngombo ĩyo, nayo ndegwa ĩyo no nginya ĩhũũrwo na mahiga.
33 “Bí ọkùnrin kan bá ṣí kòtò sílẹ̀ láìbò tàbí kí ó gbẹ́ kòtò sílẹ̀ láìbò, tí màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ bá ṣe bẹ́ẹ̀ bọ́ sínú kòtò náà.
“Mũndũ angĩkunũra irima, kana enje rĩmwe na aage kũrĩkunĩka, nayo ndegwa kana ndigiri ĩgwe thĩinĩ warĩo,
34 Ẹni tí ó ni kòtò yóò san owó àdánù yìí fún ẹni tí ó ni ẹran. Òkú ẹran náà yóò sì di tirẹ̀.
mwene irima rĩu no nginya arĩhe hathara ĩyo; no nginya arĩhe mwene nyamũ, nayo nyamũ ĩyo ĩkuĩte ĩtuĩke yake.
35 “Bí akọ màlúù ọkùnrin kan bá pa akọ màlúù ẹlòmíràn lára tí ó sì kú, wọn yóò ta akọ màlúù tó wà láààyè, wọn yóò sì pín owó èyí tiwọn tà àti ẹran èyí tí ó kú dọ́gbadọ́gba.
“Ndegwa ya mũndũ ĩngĩtihia ndegwa ya mũndũ ũngĩ ĩkue, andũ acio nĩmakendia ndegwa ĩrĩa ĩrĩ muoyo, magayane mbeeca na magayane nyamũ ĩyo ĩkuĩte.
36 Ṣùgbọ́n tí ó bá ti di ìgbà gbogbo tí akọ màlúù náà máa ń kan òmíràn, tí olówó rẹ̀ kò sì mú un so, olówó rẹ̀ yóò san ẹran dípò ẹran. Ẹran tí ó kú yóò sì jẹ́ tirẹ̀.
No rĩrĩ, kũngĩkorwo nĩkũmenyekete atĩ ndegwa ĩyo nĩĩmenyerete gũtheecana na rũhĩa, nake mwene akaaga kũmĩhingĩra-rĩ, no nginya mwene arĩhe, nyamũ ĩrĩhio na nyamũ ĩngĩ, na ĩrĩa ĩkuĩte ĩtuĩke yake.

< Exodus 21 >