< Exodus 20 >

1 Ọlọ́run sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí pé,
Și Dumnezeu a vorbit toate aceste cuvinte, spunând:
2 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
Eu sunt DOMNUL Dumnezeul tău, care te-a scos din țara Egiptului, afară din casa robiei.
3 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
Să nu ai alți dumnezei în afară de mine.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
Să nu îți faci niciun chip cioplit, sau vreo asemănare a oricărui lucru care este în cer deasupra, sau care este în pământ dedesubt, sau care este în apa de sub pământ;
5 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
Să nu te prosterni lor, nici să nu le servești, fiindcă eu, DOMNUL Dumnezeul tău, sunt un Dumnezeu gelos, pedepsind nelegiuirea părinților peste copii până la a treia și a patra generație a celor ce mă urăsc;
6 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
Și arătând milă la mii dintre cei ce mă iubesc și țin poruncile mele.
7 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
Să nu iei în deșert numele DOMNULUI Dumnezeul tău, fiindcă DOMNUL nu îl va ține nevinovat pe cel ce ia în deșert numele lui.
8 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́.
Adu-ți aminte de ziua sabatului, ca să o sfințești.
9 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,
Lucrează șase zile și fă toată munca ta,
10 ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti ẹran ọ̀sìn rẹ, àti àlejò rẹ, tí ń bẹ nínú ibodè rẹ.
Dar a șaptea zi este sabatul DOMNULUI Dumnezeul tău: în ea să nu faci nicio lucrare, nici tu, nici fiul tău, nici fiica ta, nici servitorul tău, nici servitoarea ta, nici vita ta, nici străinul tău care este înăuntrul porților tale;
11 Nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ó sì sinmi ní ọjọ́ keje: nítorí náà ni Olúwa ṣe bùkún ọjọ́ ìsinmi tí ó sì yà á sí mímọ́.
Căci în șase zile DOMNUL a făcut cerul și pământul, marea și tot ce este în ele și s-a odihnit în a șaptea zi, pentru aceasta DOMNUL a binecuvântat ziua sabatului și a sfințit-o.
12 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
Onorează pe tatăl tău și pe mama ta, ca zilele tale să fie lungi în țara pe care ți-o dă DOMNUL Dumnezeul tău.
13 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
Să nu ucizi.
14 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
Să nu comiți adulter.
15 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
Să nu furi.
16 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
Să nu aduci mărturie falsă împotriva aproapelui tău.
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéjì rẹ. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéjì rẹ.”
Să nu poftești casa aproapelui tău, să nu poftești soția aproapelui tău, nici servitorul lui, nici servitoarea lui, nici boul lui, nici măgarul lui, nici orice lucru care este al aproapelui tău.
18 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà rí mọ̀nàmọ́ná tí wọ́n sí gbọ́ ohùn ìpè àti èéfín tí ń rú láti orí òkè, tí wọ́n sì gbọ́ sísán àrá, dídún ìpè kíkankíkan; wọ́n dúró ní òkèrè wọ́n sì ń gbọ̀n ṣìgàṣìgà fún ìbẹ̀rù.
Și tot poporul a văzut tunetele și fulgerele și sunetul trâmbiței și muntele fumegând; și când poporul a văzut acestea, s-au îndepărtat și au stat departe.
19 Wọ́n wí fún Mose pé, “Ìwọ fúnra rẹ̀ máa bá wa sọ̀rọ̀, àwa yóò sì gbọ́. Má ṣe jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kí ó bá wa sọ̀rọ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò kú.”
Și i-au spus lui Moise: Vorbește tu cu noi și vom asculta, dar să nu vorbească Dumnezeu cu noi, ca nu cumva să murim.
20 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù. Ọlọ́run wá láti dán an yín wò, kí ẹ̀rù Ọlọ́run kí ó lè máa wà ní ara yín, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣẹ̀.”
Și Moise a spus poporului: Nu vă temeți, pentru că Dumnezeu a venit pentru a vă încerca și ca temerea lui să fie înaintea fețelor voastre, ca să nu păcătuiți.
21 Àwọn ènìyàn sì dúró ní òkèèrè nígbà tí Mose súnmọ́ ibi òkùnkùn biribiri níbi tí Ọlọ́run wà.
Și poporul a stat departe, iar Moise s-a apropiat de întunericul gros unde era Dumnezeu.
22 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli, ‘Ẹ̀yin ti rí i fúnra yín bí èmi ti bá a yín sọ̀rọ̀ láti ọ̀run wá.
Și DOMNUL i-a spus lui Moise: Astfel să spui copiilor lui Israel: Ați văzut că am vorbit cu voi din cer.
23 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ sin ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi: ẹ̀yin kò gbọdọ̀ rọ ọlọ́run fàdákà tàbí ọlọ́run wúrà fún ara yín.
Nu faceți dumnezei de argint alături de mine, nici să nu vă faceți dumnezei de aur.
24 “‘Pẹpẹ erùpẹ̀ ni kí ìwọ mọ fún mi. Ní orí pẹpẹ yìí ni kí ìwọ ti máa rú ẹbọ sísun rẹ sí mi àti ẹbọ àlàáfíà rẹ, àgùntàn rẹ, ewúrẹ́ àti akọ màlúù rẹ. Ní ibi gbogbo tí mo gbé fi ìrántí orúkọ mi sí, èmi yóò sì máa tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bùkún ọ níbẹ̀.
Fă-mi un altar de pământ și sacrifică pe acesta ofrandele tale arse și ofrandele tale de pace, oile tale și boii tăi; în toate locurile unde voi pune amintirea numelui meu voi veni la tine și te voi binecuvânta.
25 Bí ìwọ bá ṣe pẹpẹ òkúta fún mi, má ṣe fi òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ kọ́ ọ, nítorí bí ìwọ bá lo ohun ọnà rẹ lórí rẹ̀, ìwọ sọ ọ di àìmọ́.
Și dacă îmi vei face un altar de piatră, să nu îl zidești din piatră cioplită; căci dacă ridici unealta ta asupra acesteia, l-ai profanat.
26 Ìwọ kò gbọdọ̀ gun àkàsọ̀ lọ sí ibi pẹpẹ mi, kí àwọn ènìyàn má ba à máa wo ìhòhò rẹ láti abẹ́ aṣọ tí ìwọ wọ̀ nígbà tí ìwọ bá ń gòkè lọ sí ibi pẹpẹ.’
Nici nu urca pe trepte la altarul meu, ca să nu fie descoperită goliciunea ta pe acesta.

< Exodus 20 >