< Exodus 20 >

1 Ọlọ́run sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí pé,
I mówił Bóg wszystkie te słowa a rzekł:
2 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
Jam jest Pan Bóg twój, którym cię wywiódł z ziemi Egipskiej, z domu niewoli.
3 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
Nie będziesz miął bogów innych przede mną.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
Nie czyń sobie obrazu rytego, ani żadnego podobieństwa rzeczy tych, które są na niebie wzgórę, i które na ziemi nisko, i które są w wodach pod ziemią.
5 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
Nie będziesz się im kłaniał, ani im będziesz służył; bom Ja Pan Bóg twój, Bóg zawistny w miłości, nawiedzający nieprawości ojców nad syny w trzeciem i w czwartem pokoleniu tych, którzy mię nienawidzą;
6 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
A czyniący miłosierdzie nad tysiącami tych, którzy mię miłują, i strzegą przykazania mego.
7 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
Nie bierz imienia Pana Boga twego nadaremno; bo się Pan mścić będzie nad tym, który imię jego nadaremno bierze.
8 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́.
Pamiętaj na dzień odpocznienia, abyś go święcił.
9 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,
Sześć dni robić będziesz, i wykonasz wszystkę robotę twoję.
10 ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti ẹran ọ̀sìn rẹ, àti àlejò rẹ, tí ń bẹ nínú ibodè rẹ.
Ale dnia siódmego odpocznienie jest Pana Boga twego; nie będziesz czynił żadnej roboty weń, ty i syn twój, i córka twoja, sługa twój, i służebnica twoja, bydlę twoje, i gość twój, który jest w bramach twoich;
11 Nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ó sì sinmi ní ọjọ́ keje: nítorí náà ni Olúwa ṣe bùkún ọjọ́ ìsinmi tí ó sì yà á sí mímọ́.
Bo przez sześć dni stworzył Pan niebo i ziemię, morze, i cokolwiek w nich jest, i odpoczął dnia siódmego; przetoż błogosławił Pan dzień odpocznienia, i poświęcił go.
12 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
Czcij ojca twego i matkę twoję, aby przedłużone były dni twoje na ziemi, którą Pan Bóg twój da tobie.
13 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
Nie będziesz zabijał.
14 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
Nie będziesz cudzołożył.
15 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
Nie będziesz kradł.
16 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
Nie będziesz mówił przeciw bliźniemu twemu świadectwa fałszywego.
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéjì rẹ. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéjì rẹ.”
Nie będziesz pożądał domu bliźniego twego, ani będziesz pożądał żony bliźniego twego, ani sługi jego, ani dziewki jego, ani wołu jego, ani osła jego, ani żadnej rzeczy bliźniego twego.
18 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà rí mọ̀nàmọ́ná tí wọ́n sí gbọ́ ohùn ìpè àti èéfín tí ń rú láti orí òkè, tí wọ́n sì gbọ́ sísán àrá, dídún ìpè kíkankíkan; wọ́n dúró ní òkèrè wọ́n sì ń gbọ̀n ṣìgàṣìgà fún ìbẹ̀rù.
Tedy wszystek lud widząc gromy, i błyskawice, i głos trąby, i górę kurzącą się, to widząc lud cofnęli się, i stanęli z daleka;
19 Wọ́n wí fún Mose pé, “Ìwọ fúnra rẹ̀ máa bá wa sọ̀rọ̀, àwa yóò sì gbọ́. Má ṣe jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kí ó bá wa sọ̀rọ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò kú.”
I mówili do Mojżesza: Mów ty z nami, a będziemy słuchać; a niech nie mówi do nas Bóg, byśmy snać nie pomarli.
20 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù. Ọlọ́run wá láti dán an yín wò, kí ẹ̀rù Ọlọ́run kí ó lè máa wà ní ara yín, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣẹ̀.”
I odpowiedział Mojżesz ludowi: Nie bójcie się; bo aby was doświadczył, przyszedł Bóg, żeby bojaźń jego była przed obliczem waszem, byście nie grzeszyli.
21 Àwọn ènìyàn sì dúró ní òkèèrè nígbà tí Mose súnmọ́ ibi òkùnkùn biribiri níbi tí Ọlọ́run wà.
Stał tedy lud z daleka; a Mojżesz przystąpił do ciemnej mgły, w której był Bóg.
22 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli, ‘Ẹ̀yin ti rí i fúnra yín bí èmi ti bá a yín sọ̀rọ̀ láti ọ̀run wá.
I rzekł Pan do Mojżesza: Tak powiesz synom Izraelskim: Wyście widzieli, żem z nieba mówił do was:
23 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ sin ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi: ẹ̀yin kò gbọdọ̀ rọ ọlọ́run fàdákà tàbí ọlọ́run wúrà fún ara yín.
Nie będziecie czynić przy mnie bogów srebrnych, ani bogów złotych nie będziecie sobie czynić.
24 “‘Pẹpẹ erùpẹ̀ ni kí ìwọ mọ fún mi. Ní orí pẹpẹ yìí ni kí ìwọ ti máa rú ẹbọ sísun rẹ sí mi àti ẹbọ àlàáfíà rẹ, àgùntàn rẹ, ewúrẹ́ àti akọ màlúù rẹ. Ní ibi gbogbo tí mo gbé fi ìrántí orúkọ mi sí, èmi yóò sì máa tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bùkún ọ níbẹ̀.
Ołtarz z ziemi uczynisz mi, a ofiarować będziesz na nim całopalenie twoje, i spokojne ofiary twoje, owce twoje, i woły twoje; na któremkolwiek miejscu pamiątkę uczynię imienia mego, przyjdę do ciebie, i będęć błogosławił.
25 Bí ìwọ bá ṣe pẹpẹ òkúta fún mi, má ṣe fi òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ kọ́ ọ, nítorí bí ìwọ bá lo ohun ọnà rẹ lórí rẹ̀, ìwọ sọ ọ di àìmọ́.
A jeźli ołtarz kamienny uczynisz mi, nie buduj go z ciosanego kamienia; bo jeźlibyś żelazne naczynie twoje podniósł nań, splugawisz go.
26 Ìwọ kò gbọdọ̀ gun àkàsọ̀ lọ sí ibi pẹpẹ mi, kí àwọn ènìyàn má ba à máa wo ìhòhò rẹ láti abẹ́ aṣọ tí ìwọ wọ̀ nígbà tí ìwọ bá ń gòkè lọ sí ibi pẹpẹ.’
Nie będziesz wstępował po stopniach do ołtarza mojego, aby nie była odkryta nagość twoja przy nim.

< Exodus 20 >