< Exodus 20 >

1 Ọlọ́run sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí pé,
Na ka korerotia e te Atua enei kupu katoa, ka mea,
2 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
Ko Ihowa ahau, ko tou Atua, naku koe i whakaputa mai i te whenua o Ihipa, i te whare pononga.
3 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
Aua etahi atua ke atu mou ki mua i ahau.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
Kei hanga koe i te whakapakoko mou, i tetahi ritenga ranei o nga mea o te rangi i runga, o te whenua ranei i raro, o te wai ranei i raro i te whenua:
5 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
Kei koropiko koe ki ena mea, kei mahi ranei ki ena mea; ko Ihowa hoki ahau, ko tou Atua, he Atua hae, e mea ana i nga hara o nga matua kia tau iho ki nga tamariki a te toru, te wha ra ano o nga whakatupuranga o te hunga e kino ana ki ahau;
6 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
E whakaputa aroha ana hoki ki nga mano, ki te hunga e aroha ana ki ahau, e whakarite ana i aku ture.
7 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
Kei whakahuatia noatia e koe te ingoa o Ihowa, o tou Atua; e kore hoki a Ihowa e mea, he harakore te tangata e whakahua noa ana i tona ingoa.
8 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́.
Kia mahara ki te ra hapati, kia whakatapua.
9 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,
E ono nga ra e mahi ai koe, e mea ai hoki i au mea katoa;
10 ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti ẹran ọ̀sìn rẹ, àti àlejò rẹ, tí ń bẹ nínú ibodè rẹ.
Tena ko te ra whitu, he hapati no Ihowa, no tou Atua: kaua e mahia tetahi mahi i reira e koe, e tau tama, e tau tamahine, e tau pononga tane, e tau pononga wahine, e au kararehe hoki, me tou tangata ke i roto i ou tatau;
11 Nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ó sì sinmi ní ọjọ́ keje: nítorí náà ni Olúwa ṣe bùkún ọjọ́ ìsinmi tí ó sì yà á sí mímọ́.
E ono hoki nga ra i hanga ai e Ihowa te rangi, me te whenua, te moana, me nga mea katoa i roto, a okioki ana i te ra whitu: na reira i whakapaingia ai te ra hapati e Ihowa, a whakatapua ana.
12 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
Whakahonoretia tou papa me tou whaea; kia roa ai ou ra ki te whenua e homai nei e Ihowa, e tou Atua, ki a koe.
13 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
Kaua e patu.
14 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
Kaua e puremu.
15 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
Kaua e tahae.
16 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
Kaua e whakapae teka ki tou hoa.
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéjì rẹ. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéjì rẹ.”
Kaua e hiahia ki te whare o tou hoa, kaua e hiahia ki te wahine a tou hoa, ki tana pononga tane ranei, ki tana pononga wahine ranei, ki tana kau ranei, ki tana kaihe ranei, ki tetahi mea ranei a tou hoa.
18 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà rí mọ̀nàmọ́ná tí wọ́n sí gbọ́ ohùn ìpè àti èéfín tí ń rú láti orí òkè, tí wọ́n sì gbọ́ sísán àrá, dídún ìpè kíkankíkan; wọ́n dúró ní òkèrè wọ́n sì ń gbọ̀n ṣìgàṣìgà fún ìbẹ̀rù.
A i kite te iwi katoa i nga whatitiri, i nga uira, i te tangi o te tetere, i te maunga hoki e paowa ana: a, i te kitenga o te iwi, ka wiri ratou, a tu rawa i tawhiti.
19 Wọ́n wí fún Mose pé, “Ìwọ fúnra rẹ̀ máa bá wa sọ̀rọ̀, àwa yóò sì gbọ́. Má ṣe jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kí ó bá wa sọ̀rọ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò kú.”
A ka mea ratou ki a Mohi, Mau e korero mai ki a matou, a ka whakarongo atu matou; engari kaua te Atua e korero ki a matou, kei mate matou.
20 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù. Ọlọ́run wá láti dán an yín wò, kí ẹ̀rù Ọlọ́run kí ó lè máa wà ní ara yín, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣẹ̀.”
Na ka mea a Mohi ki te iwi, Kaua e wehi: he whakamatau hoki i a koutou i haere mai ai te Atua, kia mau ai hoki tona wehi i o koutou kanohi, kei hara koutou.
21 Àwọn ènìyàn sì dúró ní òkèèrè nígbà tí Mose súnmọ́ ibi òkùnkùn biribiri níbi tí Ọlọ́run wà.
A tu ana te iwi i tawhiti; ko Mohi ia, i whakatata ki te pouri kerekere i noho ai te Atua.
22 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli, ‘Ẹ̀yin ti rí i fúnra yín bí èmi ti bá a yín sọ̀rọ̀ láti ọ̀run wá.
A ka mea a Ihowa ki a Mohi, Kia penei tau kupu ki nga tama a Iharaira, Ka kite koutou kua korero ahau i te rangi ki a koutou.
23 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ sin ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi: ẹ̀yin kò gbọdọ̀ rọ ọlọ́run fàdákà tàbí ọlọ́run wúrà fún ara yín.
Kei hanga koutou he atua ke atu ki toku taha; kei hanga koutou he atua hiriwa, he atua koura ranei, mo koutou.
24 “‘Pẹpẹ erùpẹ̀ ni kí ìwọ mọ fún mi. Ní orí pẹpẹ yìí ni kí ìwọ ti máa rú ẹbọ sísun rẹ sí mi àti ẹbọ àlàáfíà rẹ, àgùntàn rẹ, ewúrẹ́ àti akọ màlúù rẹ. Ní ibi gbogbo tí mo gbé fi ìrántí orúkọ mi sí, èmi yóò sì máa tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bùkún ọ níbẹ̀.
Hanga he aata oneone maku, ki runga patu ai koe i au tahunga tinana, i au whakahere mo te pai, i au hipi, i au kau: i nga wahi katoa e whakamaharatia ai e ahau toku ingoa ka haere atu ahau ki a koe, ka manaaki i a koe.
25 Bí ìwọ bá ṣe pẹpẹ òkúta fún mi, má ṣe fi òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ kọ́ ọ, nítorí bí ìwọ bá lo ohun ọnà rẹ lórí rẹ̀, ìwọ sọ ọ di àìmọ́.
A ki te hanga koe i te aata kohatu maku, kei hanga e koe ki te kohatu hahau; ki te hapai hoki koe i tau toki ki taua mea, kua whakanoatia e koe.
26 Ìwọ kò gbọdọ̀ gun àkàsọ̀ lọ sí ibi pẹpẹ mi, kí àwọn ènìyàn má ba à máa wo ìhòhò rẹ láti abẹ́ aṣọ tí ìwọ wọ̀ nígbà tí ìwọ bá ń gòkè lọ sí ibi pẹpẹ.’
Kaua ano e piki na te arawhata ki toku aata, kei kitea koe i reira e tu tahanga ana.

< Exodus 20 >