< Exodus 20 >

1 Ọlọ́run sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí pé,
Tad Dievs runāja visus šos vārdus un sacīja:
2 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
Es esmu Tas Kungs, tavs Dievs, kas tevi izvedis no Ēģiptes zemes, no tā vergu nama.
3 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
Tev nebūs citus Dievus turēt priekš Manis.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
Tev nebūs sev darīt nekādu tēlu nedz līdzību, ne no tā, kas augšā debesīs, ne no tā, kas apakšā virs zemes, nedz no tā, kas ūdenī apakš zemes.
5 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
Tev nebūs priekš tiem zemē mesties nedz tiem kalpot; jo Es Tas Kungs, tavs Dievs, esmu stiprs un dusmīgs Dievs, kas piemeklē tēvu grēkus pie bērniem līdz trešam un ceturtam augumam pie tiem, kas Mani ienīst,
6 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
Un dara žēlastību tūkstošiem, kas Mani mīļo un Manus baušļus tur.
7 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
Tev nebūs Tā Kunga, sava Dieva, vārdu nelietīgi velti valkāt, jo Tas Kungs to nepametīs nesodītu, kas Viņa vārdu nelietīgi velti valkā.
8 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́.
Piemini to svēto dienu, ka tu to svētī.
9 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,
Sešas dienas tev būs strādāt un visu savu darbu darīt.
10 ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti ẹran ọ̀sìn rẹ, àti àlejò rẹ, tí ń bẹ nínú ibodè rẹ.
Bet tā septītā diena ir Tā Kunga, tava Dieva, dusēšanas diena; tad tev nebūs nekādu darbu darīt, ne tev pašam, ne tavam dēlam, ne tavai meitai, ne tavam kalpam, ne tavai kalponei, ne tavam lopam, ne tavam svešiniekam, kas tavos vārtos.
11 Nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ó sì sinmi ní ọjọ́ keje: nítorí náà ni Olúwa ṣe bùkún ọjọ́ ìsinmi tí ó sì yà á sí mímọ́.
Jo sešās dienās Tas Kungs ir darījis debesis un zemi, jūru un visu, kas tur iekšā, un septītā dienā dusējis, tādēļ Tas Kungs to dusēšanas dienu ir svētījis un to iesvētījis.
12 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
Godā savu tēvu un savu māti, lai tu ilgi dzīvo tai zemē, ko Tas Kungs, tavs Dievs, tev dos.
13 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
Tev nebūs nokaut.
14 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
Tev nebūs laulību pārkāpt.
15 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
Tev nebūs zagt.
16 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
Tev nebūs nepatiesu liecību dot pret savu tuvāko.
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéjì rẹ. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéjì rẹ.”
Tev nebūs iekārot sava tuvākā namu. Tev nebūs iekārot sava tuvākā sievu, nedz viņa kalpu, nedz viņa kalponi, nedz viņa vērsi, nedz viņa ēzeli, nedz kaut ko, kas tavam tuvākam pieder.
18 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà rí mọ̀nàmọ́ná tí wọ́n sí gbọ́ ohùn ìpè àti èéfín tí ń rú láti orí òkè, tí wọ́n sì gbọ́ sísán àrá, dídún ìpè kíkankíkan; wọ́n dúró ní òkèrè wọ́n sì ń gbọ̀n ṣìgàṣìgà fún ìbẹ̀rù.
Un visi ļaudis redzēja tos pērkonus un zibeņus un to bazūnes skaņu un to kalnu kūpam. Kad tie ļaudis to redzēja, tad tie bēga un stāvēja no tālienes.
19 Wọ́n wí fún Mose pé, “Ìwọ fúnra rẹ̀ máa bá wa sọ̀rọ̀, àwa yóò sì gbọ́. Má ṣe jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kí ó bá wa sọ̀rọ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò kú.”
Un sacīja uz Mozu: runā tu ar mums, un mēs klausīsimies, bet lai Dievs ar mums nerunā, ka nemirstam.
20 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù. Ọlọ́run wá láti dán an yín wò, kí ẹ̀rù Ọlọ́run kí ó lè máa wà ní ara yín, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣẹ̀.”
Tad Mozus sacīja uz tiem ļaudīm: nebīstaties, jo Dievs ir nācis jūs pārbaudīt, un lai Viņa bijāšana ir priekš jūsu acīm, ka jūs negrēkojat.
21 Àwọn ènìyàn sì dúró ní òkèèrè nígbà tí Mose súnmọ́ ibi òkùnkùn biribiri níbi tí Ọlọ́run wà.
Un tie ļaudis stāvēja no tālienes, bet Mozus gāja tai tumšumā, kur Dievs bija.
22 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli, ‘Ẹ̀yin ti rí i fúnra yín bí èmi ti bá a yín sọ̀rọ̀ láti ọ̀run wá.
Un Tas Kungs sacīja uz Mozu: tā tev būs sacīt Israēla bērniem: jūs esat redzējuši, ka Es ar jums esmu runājis no debesīm.
23 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ sin ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi: ẹ̀yin kò gbọdọ̀ rọ ọlọ́run fàdákà tàbí ọlọ́run wúrà fún ara yín.
Jums nebūs neko celt Man līdzās; jums nebūs sev taisīt sudraba nedz zelta dievus.
24 “‘Pẹpẹ erùpẹ̀ ni kí ìwọ mọ fún mi. Ní orí pẹpẹ yìí ni kí ìwọ ti máa rú ẹbọ sísun rẹ sí mi àti ẹbọ àlàáfíà rẹ, àgùntàn rẹ, ewúrẹ́ àti akọ màlúù rẹ. Ní ibi gbogbo tí mo gbé fi ìrántí orúkọ mi sí, èmi yóò sì máa tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bùkún ọ níbẹ̀.
Cel Man altāri no zemes un upurē uz tā savus dedzināmos upurus un savus pateicības upurus, savas avis un savus vēršus. Ikkurā vietā, kur Es likšu pieminēt Savu vārdu, tur Es pie tevis nākšu un tevi svētīšu.
25 Bí ìwọ bá ṣe pẹpẹ òkúta fún mi, má ṣe fi òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ kọ́ ọ, nítorí bí ìwọ bá lo ohun ọnà rẹ lórí rẹ̀, ìwọ sọ ọ di àìmọ́.
Bet ja tu Man gribi celt akmeņu altāri, tad tev to nebūs taisīt no cirstiem akmeņiem; ja tu ar dzelzi pie tā strādāsi, tad tu to apgānīsi.
26 Ìwọ kò gbọdọ̀ gun àkàsọ̀ lọ sí ibi pẹpẹ mi, kí àwọn ènìyàn má ba à máa wo ìhòhò rẹ láti abẹ́ aṣọ tí ìwọ wọ̀ nígbà tí ìwọ bá ń gòkè lọ sí ibi pẹpẹ.’
Tev arī nebūs kāpt pa trepēm uz Manu altāri, ka pie viņa tavs plikums netop atsegts.

< Exodus 20 >