< Exodus 20 >

1 Ọlọ́run sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí pé,
Nake Ngai akĩaria ciugo ici ciothe, akiuga atĩrĩ:
2 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
“Nĩ niĩ Jehova Ngai waku, ũrĩa wakũrutire bũrũri wa Misiri, kuuma bũrũri wa ũkombo.
3 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
“Ndũkanagĩe na ngai ingĩ tiga niĩ.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
“Ndũkanethondekere mũhianano mũicũhie wa mũhianĩre wa kĩndũ o gĩothe kĩrĩ kũũrĩa igũrũ kana gũkũ thĩ, kana kĩrĩ maaĩ-inĩ marĩa marĩ mũhuro wa thĩ.
5 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
Ndũkanacinamĩrĩre kana ũcihooe, nĩgũkorwo niĩ, Jehova Ngai waku, ndĩ Ngai ũrĩ ũiru, herithagia ciana nĩ ũndũ wa mehia ma maithe mao nginya rũciaro rwa gatatũ na rwa kana rwa andũ arĩa maathũire,
6 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
no ngonania wendo kũrĩ njiarwa ngiri na ngiri cia andũ arĩa manyendete na magaathĩkĩra maathani makwa.
7 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
“Ndũkanagwete rĩĩtwa rĩa Jehova Ngai waku na itherũ, nĩgũkorwo Jehova ndagatua atĩ mũndũ ndehĩtie ũrĩa ũgwetaga rĩĩtwa rĩake na itherũ.
8 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́.
“Ririkanaga mũthenya wa Thabatũ ũwamũrage.
9 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,
Rutaga wĩra waku wothe mĩthenya ĩtandatũ,
10 ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti ẹran ọ̀sìn rẹ, àti àlejò rẹ, tí ń bẹ nínú ibodè rẹ.
no mũthenya wa mũgwanja nĩ Thabatũ ya Jehova Ngai waku. Mũthenya ũcio ndũkanarute wĩra o na ũrĩkũ, wee mwene, kana mũrũ-guo, kana mwarĩ-guo, kana ndungata yaku ya mũndũ mũrũme, kana ya mũndũ-wa-nja, kana ũhiũ waku, kana mũgeni ũrĩ gwaku mũciĩ.
11 Nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ó sì sinmi ní ọjọ́ keje: nítorí náà ni Olúwa ṣe bùkún ọjọ́ ìsinmi tí ó sì yà á sí mímọ́.
Nĩgũkorwo Jehova ombire igũrũ na thĩ, na iria rĩrĩa inene na indo ciothe iria irĩ kuo, na mĩthenya ĩtandatũ, no akĩhurũka mũthenya wa mũgwanja. Nĩ ũndũ ũcio Jehova akĩrathima mũthenya ũcio wa Thabatũ, akĩwaamũra.
12 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
“Tĩĩa thoguo na nyũkwa, nĩgeetha ũtũũre matukũ maingĩ bũrũri ũrĩa Jehova Ngai waku egũkũhe.
13 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
“Ndũkanoragane.
14 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
“Ndũkanatharanie.
15 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
“Ndũkanaiye.
16 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
“Ndũkanaigĩrĩre mũndũ ũrĩa ũngĩ kĩgeenyo.
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéjì rẹ. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéjì rẹ.”
“Ndũkanacumĩkĩre nyũmba ya mũndũ ũrĩa ũngĩ. Ndũkanacumĩkĩre mũtumia wa mũndũ ũngĩ, kana ũcumĩkĩre ndungata yake ya mũndũ mũrũme kana ya mũndũ-wa-nja, kana ndegwa yake kana ndigiri yake, o na kana kĩndũ gĩothe gĩake.”
18 Nígbà tí àwọn ènìyàn náà rí mọ̀nàmọ́ná tí wọ́n sí gbọ́ ohùn ìpè àti èéfín tí ń rú láti orí òkè, tí wọ́n sì gbọ́ sísán àrá, dídún ìpè kíkankíkan; wọ́n dúró ní òkèrè wọ́n sì ń gbọ̀n ṣìgàṣìgà fún ìbẹ̀rù.
Rĩrĩa andũ maiguire marurumĩ, na makĩona rũheni, na makĩigua coro ũkĩgamba, na makĩona kĩrĩma gĩgĩtoga ndogo, makĩinaina nĩ guoya. Magĩikara o haraaya,
19 Wọ́n wí fún Mose pé, “Ìwọ fúnra rẹ̀ máa bá wa sọ̀rọ̀, àwa yóò sì gbọ́. Má ṣe jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ kí ó bá wa sọ̀rọ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò kú.”
na makĩĩra Musa atĩrĩ, “Twarĩrie arĩ we, na nĩtũgũkũigua, no tiga kũreka twarĩrio nĩ Ngai, tũtigakue.”
20 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù. Ọlọ́run wá láti dán an yín wò, kí ẹ̀rù Ọlọ́run kí ó lè máa wà ní ara yín, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣẹ̀.”
Musa akĩĩra andũ acio atĩrĩ, “Tigai gwĩtigĩra. Ngai okĩte kũmũgeria, nĩgeetha mũtũũre mwĩtigĩrĩte Ngai, mwagage kwĩhia.”
21 Àwọn ènìyàn sì dúró ní òkèèrè nígbà tí Mose súnmọ́ ibi òkùnkùn biribiri níbi tí Ọlọ́run wà.
Andũ acio magĩgĩikara o haraaya, nowe Musa agĩthengerera harĩa haarĩ nduma ndumanu, harĩa Ngai aarĩ.
22 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli, ‘Ẹ̀yin ti rí i fúnra yín bí èmi ti bá a yín sọ̀rọ̀ láti ọ̀run wá.
Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ĩra andũ a Isiraeli ũndũ ũyũ: ‘Nĩmweyonera inyuĩ ene atĩ ndaaria na inyuĩ ndĩ o igũrũ:
23 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ sin ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi: ẹ̀yin kò gbọdọ̀ rọ ọlọ́run fàdákà tàbí ọlọ́run wúrà fún ara yín.
Mũtikanathondeke ngai ingĩ cia kũhooyagwo hamwe na niĩ; mũtikanethondekere ngai cia betha kana ngai cia thahabu.
24 “‘Pẹpẹ erùpẹ̀ ni kí ìwọ mọ fún mi. Ní orí pẹpẹ yìí ni kí ìwọ ti máa rú ẹbọ sísun rẹ sí mi àti ẹbọ àlàáfíà rẹ, àgùntàn rẹ, ewúrẹ́ àti akọ màlúù rẹ. Ní ibi gbogbo tí mo gbé fi ìrántí orúkọ mi sí, èmi yóò sì máa tọ̀ ọ́ wá, èmi yóò sì máa bùkún ọ níbẹ̀.
“‘Njakĩrai kĩgongona gĩa tĩĩri, na mũrutĩre ngʼondu na mbũri na ngʼombe cianyu ho irĩ magongona manyu ma njino na ma ũiguano. Kũrĩa guothe ngaatũma rĩĩtwa rĩakwa rĩtĩĩagwo, nĩndĩũkaga kũrĩ inyuĩ na ngamũrathima.
25 Bí ìwọ bá ṣe pẹpẹ òkúta fún mi, má ṣe fi òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ kọ́ ọ, nítorí bí ìwọ bá lo ohun ọnà rẹ lórí rẹ̀, ìwọ sọ ọ di àìmọ́.
Mũngĩnjakĩra kĩgongona kĩa mahiga, mũtigagĩake na mahiga marĩa maacũhie, nĩgũkorwo mũngĩgaatũmĩra kĩndũ gĩa gwacũhia nĩmũgagĩthaahia.
26 Ìwọ kò gbọdọ̀ gun àkàsọ̀ lọ sí ibi pẹpẹ mi, kí àwọn ènìyàn má ba à máa wo ìhòhò rẹ láti abẹ́ aṣọ tí ìwọ wọ̀ nígbà tí ìwọ bá ń gòkè lọ sí ibi pẹpẹ.’
Mũtikanahaice kĩgongona gĩakwa na ngathĩ, nĩguo njaga yanyu ndĩkanonekanĩre ho.’

< Exodus 20 >